< Isaïe 57 >

1 Voyez comme le Juste a péri, et nul ne le porte en son cœur; et des hommes justes sont retirés de la terre, et nul n'y fait attention. Car le Juste a été enlevé du milieu de l'iniquité.
Olódodo ṣègbé kò sí ẹnìkan tí ó rò ó lọ́kàn ara rẹ̀; a mú àwọn ẹni mímọ́ lọ, kò sì ṣí ẹni tó yé pé a ti mú àwọn olódodo lọ láti yọ wọ́n kúrò nínú ibi.
2 Son sépulcre sera en paix; il a été enlevé de la voie d'iniquité.
Gbogbo àwọn tí ń rìn déédé ń wọ inú àlàáfíà; wọ́n rí ìsinmi bí wọ́n ti ń sùn nínú ikú.
3 Et vous, venez ici, fils pervers, race d'adultères et de prostituées.
“Ṣùgbọ́n ẹ súnmọ́ ìhìn-ín, ẹ̀yin ọmọ aláfọ̀ṣẹ, ẹ̀yin irú-ọmọ panṣágà àti àgbèrè!
4 De qui vous êtes-vous joués? contre qui avez-vous ouvert la bouche? contre qui s'est exercée votre langue? N'êtes-vous pas des enfants de perdition, une race sans loi,
Ta ni ó fi ń ṣẹlẹ́yà? Ta ni o ń yọ ṣùtì sí tí o sì yọ ahọ́n síta? Ẹ̀yin kì í ha ṣe ọlọ̀tẹ̀ ènìyàn bí, àti ìran àwọn òpùrọ́?
5 Vous qui invoquez des idoles sous des arbres touffus, vous qui sacrifiez vos enfants dans des vallons au milieu des rochers?
Ẹ gbinájẹ fún ìṣekúṣe láàrín igi óákù àti lábẹ́ gbogbo igi tí ń gbilẹ̀; ẹ fi àwọn ọmọ yín rú ẹbọ nínú kòtò jíjìn àti lábẹ́ àwọn pàlàpálá òkúta.
6 C'est là ton partage, c'est là ton lot; tu as répandu des libations pour ces idoles, tu leur as offert des victimes: et je n'en serais pas irrité!
Àwọn ère tí ó wà ní àárín òkúta dídán wọ́n n nì, nínú kòtò jíjìn ni ìpín in yín; àwọ̀n ni ìpín in yín. Bẹ́ẹ̀ ni, sí wọn ni ẹ ti ta ọrẹ ohun mímu yín sílẹ̀ àti láti ta ọrẹ ìyẹ̀fun. Nítorí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ǹjẹ́ ó yẹ kí n dáwọ́ dúró?
7 Là est ton lit, sur une haute montagne, élevée dans les airs; là tu as transporté tes oblations.
Ìwọ ti ṣe ibùsùn rẹ lórí òkè gíga tí ó rẹwà; níbẹ̀ ni ẹ lọ láti lọ ṣe ìrúbọ yín.
8 Et derrière les jambages de ta porte tu as placé ton mémorial; pensais-tu qu'à t'éloigner de moi tu aurais quelque profit? Tu as aimé ceux qui partageaient ta couche;
Lẹ́yìn àwọn ìlẹ̀kùn yín àti òpó ìlẹ̀kùn yín níbẹ̀ ni ẹ fi àwọn àmì òrìṣà yín sí. Ní kíkọ̀ mí sílẹ̀, ẹ ṣí ibùsùn yín sílẹ̀, ẹ gun orí rẹ̀ lọ, ẹ sì ṣí i sílẹ̀ gbagada; ẹ ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn tí ẹ fẹ́ràn ibùsùn wọn, ẹ̀yin sì ń wo ìhòhò wọn.
9 Et tu as multiplié tes adultères avec eux, et tu en as gagné beaucoup qui étaient loin de toi, et tu as envoyé des messagers au delà de tes frontières, et tu as été abaissée jusqu'à l'enfer. (Sheol h7585)
Ẹ̀yin lọ sí Moleki pẹ̀lú òróró olifi ẹ sì fi kún òórùn dídùn yín. Ẹ rán ikọ̀ yín lọ jìnnà réré; ẹ sọ̀kalẹ̀ sí ibojì pẹ̀lú! (Sheol h7585)
10 Tu t'es fatiguée en maints voyages, et tu n'as pas dit: Je cesserai de me fortifier dans le mal; ainsi as-tu fait; c'est pourquoi tu ne m'as plus prié.
Àwọn ọ̀nà yín gbogbo ti mú àárẹ̀ ba á yín, ṣùgbọ́n ẹ kò ní sọ pé, ‘Kò sí ìrètí mọ́?’ Ẹ rí okun kún agbára yín, nípa bẹ́ẹ̀ òòyì kò kọ́ ọ yín.
11 Qui as-tu craint, qui t'a retenue, quand tu m'as menti, quand tu m'as oublié, et que tu ne m'as plus donné place dans ta pensée ni dans ton cœur? Et moi, en te voyant, je te dédaigne à mon tour; et tu n'as pas eu peur de moi.
“Ta ni ó ń pá yín láyà tí ń bà yín lẹ́rù tí ẹ fi ń ṣèké sí mi, àti tí ẹ̀yin kò fi rántí mi tàbí kí ẹ rò yí nínú ọkàn yín? Ǹjẹ́ kì í ṣe nítorí dídákẹ́ jẹ́ẹ́ mi fún ìgbà pípẹ́ tí ẹ̀yin kò fi bẹ̀rù mi?
12 Et moi, je publierai ta justice et tes péchés, qui ne te profiteront pas.
Èmi yóò ṣí òdodo yín páyà àti iṣẹ́ yín, wọn kì yóò sì ṣe yín ní àǹfààní.
13 Et si tu jettes des cris, que tes complices te sauvent dans ton affliction; mais le vent les saisira tous, un tourbillon les emportera. Au contraire, ceux qui s'attachent à moi acquerront la terre, et ils auront ma montagne sainte pour héritage.
Nígbà tí ẹ bá kígbe fún ìrànlọ́wọ́ ẹ jẹ́ kí àkójọ àwọn ère yín gbà yín! Atẹ́gùn yóò gbá gbogbo wọn lọ, èémí lásán làsàn ni yóò gbá wọn lọ. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá fi mí ṣe ààbò rẹ̀ ni yóò jogún ilẹ̀ náà yóò sì jogún òkè mímọ́ mi.”
14 Et ils diront: Purifiez devant lui les voies; enlevez les pierres d'achoppement de la voie de mon peuple.
A ó sì sọ wí pé: “Tún mọ, tún mọ, tún ọ̀nà náà ṣe! Ẹ mú àwọn ohun ìkọ̀sẹ̀ kúrò ní ọ̀nà àwọn ènìyàn mi.”
15 Voici ce que dit le Très-Haut, qui réside éternellement au plus haut des cieux, le Saint des saints; son nom est le Très-Haut, reposant parmi les saints; c'est lui qui donne aux faibles la patience, et aux cœurs contrits la vie:
Nítorí èyí ni ohun tí Ẹni gíga àti ọlọ́lá jùlọ wí ẹni tí ó wà títí láé, tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ mímọ́: “Mo ń gbé ní ibi gíga àti ibi mímọ́, ṣùgbọ́n pẹ̀lú ẹni n nì tí ó ní ìròbìnújẹ́ àti ẹ̀mí ìrẹ̀lẹ̀, láti sọ ẹ̀mí onírẹ̀lẹ̀ náà jí àti láti sọ ẹ̀mí oníròbìnújẹ́ n nì jí.
16 Je ne vous punirai pas éternellement; je ne serai pas toujours irrité contre vous; car tout esprit est sorti de moi, et c'est moi qui ai créé toute vie.
Èmi kì yóò fẹ̀sùn kan ni títí láé, tàbí kí n máa bínú sá á, nítorí nígbà náà ni ọkàn ènìyàn yóò rẹ̀wẹ̀sì níwájú mi èémí ènìyàn tí mo ti dá.
17 A cause de son péché, j'ai affligé quelque temps mon peuple; je l'ai frappé et j'ai détourné de lui mon visage; et il en a éprouvé de la douleur, et triste il a marché dans ses voies.
Inú bí mi nítorí ẹ̀ṣẹ̀ ọ̀kánjúwà rẹ̀; mo fìyà jẹ ẹ́, mo sì fojú mi pamọ́ ní ìbínú; síbẹ̀, ó tẹ̀síwájú nínú tinú-mi-ni n ó ṣe ọ̀nà rẹ̀.
18 J'ai vu ses voies, et je l'ai guéri, et je l'ai consolé, et je lui ai donné une consolation véritable.
Èmi ti rí ọ̀nà rẹ̀ gbogbo, ṣùgbọ́n Èmi yóò wò ó sàn; Èmi yóò tọ́ ọ ṣọ́nà n ó sì mú ìtùnú tọ̀ ọ́ wá,
19 La paix, et encore la paix, à ceux qui sont au loin, et à ceux qui sont près. Et le Seigneur a dit: Je les guérirai.
ní dídá ìyìn sí ètè àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀ ní Israẹli. Àlàáfíà, àlàáfíà fún àwọn tí ó wà lókèèrè àti nítòsí,” ni Olúwa wí, “Àti pé, Èmi yóò wo wọ́n sàn.”
20 Quant aux méchants, ils seront agités comme les flots, et ils ne pourront se calmer.
Ṣùgbọ́n àwọn ìkà dàbí i ríru Òkun tí kò le è sinmi, tí ìgbì rẹ̀ ń rú pẹ̀tẹ̀pẹ́tẹ̀ àti ẹrọ̀fọ̀ sókè.
21 Il n'y a point de joie pour les impies, dit le Seigneur.
“Kò sí àlàáfíà fún àwọn ìkà,” ni Ọlọ́run mi wí.

< Isaïe 57 >