< Isaïe 51 >
1 Pour vous, écoutez-moi, vous qui suivez la justice et qui cherchez le Seigneur. Regardez la roche solide que vous avez taillée, et le fond de la source que vous avez creusée.
“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin tí ó ń lépa òdodo àti ẹ̀yin tí ń wá Olúwa. Wo àpáta, nínú èyí tí a ti gé yín jáde àti ihò òkúta níbi tí a ti gbẹ́ yín jáde;
2 Regardez Abraham votre père, et Sara qui vous a enfantés dans la douleur; car il était unique, et je l'ai appelé, je l'ai béni, je l'ai chéri et multiplié.
ẹ wo Abrahamu baba yín, àti Sara, ẹni tó bí i yín. Nígbà tí mo pè é, òun nìkan ni, Èmi sì bùkún un, mo sì ṣọ́ ọ di ọ̀pọ̀lọpọ̀.
3 De même, je vais maintenant te consoler, ô Sion; j'ai déjà consolé toutes ses solitudes, je changerai ses déserts en jardins, et ceux qui s'étendent au couchant seront comme le paradis du Seigneur; en elle on trouvera joie et allégresse, actions de grâces et paroles de louanges.
Dájúdájú, Olúwa yóò tu Sioni nínú yóò sì bojú àánú wo gbogbo ahoro rẹ̀; Òun yóò sọ gbogbo aṣálẹ̀ rẹ̀ di Edeni, àti aṣálẹ̀ rẹ̀ yóò rí bí ọgbà Olúwa. Ayọ̀ àti inú dídùn ni a ó rí nínú rẹ̀, ọpẹ́ àti ariwo orín kíkọ.
4 Écoutez-moi, mon peuple, écoutez-moi, et vous, rois, prêtez-moi une oreille attentive; car la loi sortira de moi, et ma justice sera la lumière des nations.
“Tẹ́tí sí mi, ẹ̀yin ènìyàn mi; gbọ́ tèmi, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè mi. Òfin yóò ti ọ̀dọ̀ mi jáde wá; ìdájọ́ mi yóò di ìmọ́lẹ̀ sí àwọn orílẹ̀-èdè.
5 Elle est proche ma justice, et mon salut va se lever comme une lumière; et les Gentils espèreront en mon bras; les îles m'attendront et elles espèreront aussi en mon bras.
Òdodo mi ń bọ̀ wá kíkankíkan, ìgbàlà mi ń bọ̀ lójú ọ̀nà, àti apá mi yóò sì mú ìdájọ́ wá sí àwọn orílẹ̀-èdè. Àwọn erékùṣù yóò wò mí wọn yóò sì dúró ní ìrètí fún apá mi.
6 Levez les yeux au ciel, et regardez au-dessous la terre; le ciel n'est pas plus solide que la fumée, la terre vieillira comme un manteau, et comme eux mourront ceux qui l'habitent; mais mon salut subsistera durant tous les siècles, et ma justice ne défaillira point.
Gbé ojú rẹ sókè sí àwọn ọ̀run, wo ilẹ̀ ní ìsàlẹ̀ ilẹ̀; àwọn ọ̀run yóò pòórá bí èéfín, ilẹ̀ yóò sì gbó bí ẹ̀wù àwọn olùgbé inú rẹ̀ yóò kú gẹ́gẹ́ bí àwọn eṣinṣin. Ṣùgbọ́n ìgbàlà mi yóò wà títí láé, òdodo mi kì yóò yẹ̀ láé.
7 Écoutez-moi, vous qui connaissez le jugement, et vous, mon peuple, qui conservez ma loi dans votre cœur. Ne craignez pas les outrages des hommes; ne soyez pas abattus par leur mépris;
“Ẹ gbọ́ mi, ẹ̀yin tí ó mọ ohun òtítọ́, ẹ̀yin ènìyàn tí ó ní òfin mi ní àyà yín. Ẹ má ṣe bẹ̀rù ẹ̀gàn àwọn ènìyàn tàbí kí ẹ̀rù èébú wọn já a yín láyà.
8 Car ils seront consumés comme un manteau par l'effet du temps; ils seront rongés des vers comme de la laine; mais ma justice subsistera dans tous les siècles, et mon salut durant les générations des générations.
Nítorí kòkòrò yóò mú wọn lá bí aṣọ, ìdin yóò sì mú wọn jẹ bí ẹ̀gbọ̀n òwú. Ṣùgbọ́n òdodo mi yóò wà títí ayérayé, àti ìgbàlà mi láti ìrandíran.”
9 Réveille-toi, réveille-toi, Jérusalem, arme de force ton bras; réveille- toi comme au commencement des jours, comme les antiques générations. N'es-tu pas
Dìde, dìde! Kí o sì wọ ara rẹ ní agbára ìwọ apá Olúwa; dìde gẹ́gẹ́ bí i ti ọjọ́ ìgbà n nì, àti gẹ́gẹ́ bí i ti ìran àtijọ́. Ìwọ kọ́ lo ké Rahabu sí wẹ́wẹ́ tí o sì fa ẹ̀mí búburú ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ?
10 Celle qui a desséché la mer et la plénitude des eaux de l'abîme? N'as-tu pas fait du fond de la mer une voie pour le passage de mon peuple délivré
Ìwọ kọ́ ni ó gbẹ omi Òkun bí àti àwọn omi inú ọ̀gbun, tí o sì ṣe ọ̀nà nínú ìsàlẹ̀ Òkun tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn ẹni ìràpadà yóò fi le là á kọjá?
11 Et racheté? Car tes enfants seront ramenés par le Seigneur, et ils reviendront dans Sion pleins d'une joie et d'une allégresse éternelle; ils seront couronnés de louanges et transportés de joie; les douleurs, la tristesse, les gémissements se sont enfuis.
Àwọn ẹni ìràpadà Olúwa yóò padà wá. Wọn yóò wọ Sioni wá pẹ̀lú orin kíkọ; ayọ̀ ayérayé ni yóò sì bo orí wọn. Ayọ̀ àti inú dídùn yóò sì bà lé wọn ìbànújẹ́ àti ìtìjú yóò sì sá kúrò.
12 C'est moi, c'est moi ton consolateur; sache qui tu es, et si tu devais craindre un homme mortel, un fils de l'homme, qui sèchera comme l'herbe des champs.
“Èmi, àní Èmi, èmi ni ẹni tí ó tù ọ́ nínú. Ta ni ọ́ tí o fi ń bẹ̀rù ènìyàn ẹlẹ́ran ara, àti ọmọ ènìyàn, tí ó jẹ́ koríko lásán,
13 Et tu avais oublié Dieu ton créateur, le créateur du ciel et de la terre; et tous les jours tu avais peur en voyant en face la furie de ton persécuteur! Il a péri comme il avait résolu de te faire périr; et la furie de ton persécuteur, où est-elle à présent?
tí ìwọ sì gbàgbé Olúwa ẹlẹ́dàá rẹ, ẹni tí ó ta àwọn ọ̀run tí ó sì fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀, tí ẹ sì ń gbé nínú ìpayà lójoojúmọ́ nítorí ìbínú àwọn aninilára, tí wọ́n sì gbẹ́kẹ̀lé ìpanirun? Nítorí ibo ni ìbínú àwọn aninilára gbé wà?
14 Le Seigneur ne s'arrêtera point, il ne mettra point de lenteur à te sauver.
Àwọn ẹlẹ́wọ̀n tí ń ṣojo la ó dá sílẹ̀ ní àìpẹ́ jọjọ wọn kò ní kú sínú túbú wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò ní ṣe aláìní àkàrà.
15 Car je suis ton Dieu; c'est moi qui trouble la mer, et qui fais retentir ses flots. Mon nom est le Seigneur des armées.
Nítorí Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ, tí ó ń ru Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìgbì rẹ̀ fi ń pariwo Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
16 Je mettrai mes paroles en ta bouche; je t'abriterai à l'ombre de ma main, qui a fixé le ciel et affermi la terre, et je dirai à Sion: Tu es mon peuple.
Mo ti fi ọ̀rọ̀ mi sí ẹnu rẹ mo sì ti fi òjìji ọwọ́ mi bò ọ́, Èmi tí mo tẹ́ àwọn ọ̀run sí ààyè rẹ̀, ẹni tí ó fi ìpìlẹ̀ ilẹ̀ ayé lélẹ̀, àti ẹni tí ó sọ fún Sioni pé, ‘Ẹ̀yin ni ènìyàn mi.’”
17 Réveille-toi, réveille-toi, lève-toi, Jérusalem, qui as bu de la main du Seigneur le calice de sa colère. Car tu as bu, tu as épuisé le calice de la ruine, la grande coupe de la fureur.
Jí, jí! Gbéra nílẹ̀ ìwọ Jerusalẹmu, ìwọ tí o ti mu láti ọwọ́ Olúwa ago ìbínú rẹ̀, ìwọ tí o ti fà á mu dé gẹ̀dẹ̀gẹ́dẹ̀ tí ó n mú kí ènìyàn ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n.
18 Et de tous les enfants que tu as mis au jour, nul ne t'a consolée; et de tous les fils que tu as élevés, nul ne t'a prise par la main.
Nínú gbogbo ọmọ tí ó bí kò sí ọ̀kankan tí ó lè tọ́ ọ ṣọ́nà nínú gbogbo ọmọ tí ó tọ́ kò sí èyí tí ó le fà á lọ́wọ́.
19 Quand ces choses fondront sur toi, qui partagera ta tristesse? Quand il y aura ruine et désolation, famine et coups de glaive, qui te consolera?
Àjálù ìlọ́po ìlọ́po yìí ti dé bá ọ— ta ni yóò tù ọ́ nínú? Ìparun àti ìdahoro, ìyàn àti idà ta ni yó pẹ̀tù sí ọ lọ́kàn?
20 Tes fils ont été pressés par la détresse, couchés au bout de chaque rue, comme une blette à demi cuite, pleins de la colère du Seigneur, énervés par le Seigneur Dieu.
Àwọn ọmọkùnrin rẹ ti dákú; wọ́n sùn sí oríta gbogbo òpópónà, gẹ́gẹ́ bí etu tí a dé mọ́nú àwọ̀n. Ìbínú Olúwa ti kún inú wọn fọ́fọ́ àti ìbáwí Ọlọ́run yín.
21 C'est pourquoi, écoute, ô toi qui es humiliée et enivrée, mais non de vin:
Nítorí náà ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí a ti ṣẹ́ níṣẹ̀ẹ́, tí ọtí ń pa, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún wáìnì.
22 Ainsi dit le Seigneur Dieu, juge de son peuple: Voilà que j'ai ôté de tes mains le calice de la ruine, la grande coupe de ma fureur; tu ne continueras plus d'y boire à l'avenir.
Ohun tí Olúwa Olódùmarè yín wí nìyìí, Ọlọ́run rẹ, ẹni tí ó ń pa ènìyàn rẹ̀ mọ́, “Kíyèsi i, mo ti mú un kúrò ní ọwọ́ rẹ ago tí ó mú ọ ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n; láti inú ago náà, ẹ̀kún ìbínú mi, ni ìwọ kì yóò mu mọ́.
23 Je la mettrai dans les mains de ceux qui t'ont nui injustement, de ceux qui t'ont abaissée, de ceux qui disaient à ton âme: Couche-toi, afin que nous passions; et tu faisais de ton corps un chemin pour ceux qui passaient.
Èmi yóò fi lé àwọn apọ́nilójú rẹ lọ́wọ́, àwọn tí ó wí fún ọ pé, ‘Dọ̀bálẹ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí a ó fi máa rìn lórí rẹ.’ Ìwọ náà ṣe ẹ̀yìn rẹ gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ gẹ́gẹ́ bí òpópónà láti máa rìn lórí i rẹ̀.”