< Isaïe 47 >
1 Descends et assieds-toi sur la terre, vierge, fille de Babylone; assieds- toi sur la terre, fille des Chaldéens; on ne t'appellera plus la tendre et voluptueuse Babylone.
“Sọ̀kalẹ̀, jókòó nínú eruku, wúńdíá ọmọbìnrin Babeli; jókòó ní ilẹ̀ láìsí ìtẹ́, ọmọbìnrin àwọn ará Babeli. A kì yóò pè ọ́ ní aláìlókun àti ẹlẹgẹ́ mọ́.
2 Prends une meule, mouds de la farine, lève ton voile, montre tes cheveux blancs, dépouille tes jambes, et traverse les fleuves.
Mú òkúta-ọlọ kí o sì lọ ìyẹ̀fun; mú ìbòjú rẹ kúrò. Ká aṣọ ẹsẹ̀ rẹ sókè, ká aṣọ itan, kí o sì la odò wọ̀n-ọn-nì kọjá.
3 Ta honte sera mise à nu, et ton opprobre apparaîtra; et je tirerai de toi une juste vengeance. Pour toi, mon peuple, je ne te livrerai plus aux hommes.
Ìhòhò rẹ ni a ó sí síta àti ìtìjú rẹ ni a ó ṣí sílẹ̀. Èmi yóò sì gba ẹ̀san, Èmi kì yóò sì dá ẹnìkan sí.”
4 Celui qui t'a délivré, c'est le Seigneur des armées; son nom est le Saint d'Israël.
Olùràpadà wa Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀ òun ni Ẹni Mímọ́ Israẹli.
5 Assieds-toi le cœur attristé; entre dans les ténèbres, fille des Chaldéens; tu ne seras plus appelée force du royaume.
“Jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, lọ sínú òkùnkùn, ọmọbìnrin àwọn ará Babeli; a kì yóò pè ọ́ ní ọbabìnrin àwọn ilẹ̀ ọba mọ́.
6 J'ai été courroucé contre mon peuple, et tu as souillé mon héritage. Et moi, je les ai livrés à tes mains, et tu ne leur as pas donné de pitié; tu as rendu bien pesant le joug du vieillard.
Inú bí mi sí àwọn ènìyàn mi tí mo sì ba ogún mi jẹ́, mo fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́, Ìwọ kò sì síjú àánú wò wọ́n. Lórí àwọn arúgbó pẹ̀lú ní o gbé àjàgà tí ó wúwo lé.
7 Et tu as dit: Je serai reine dans tous les siècles! N'as-tu donc pas soupçonné ces choses en ton cœur? N'as-tu point songé à la fin?
Ìwọ wí pé, ‘Èmi yóò tẹ̀síwájú títí láé— ọbabìnrin ayérayé!’ Ṣùgbọ́n ìwọ kò kíyèsi nǹkan wọ̀nyí tàbí kí o ronú nípa ohun tí ó lè ṣẹlẹ̀.
8 Or maintenant écoute, fille voluptueuse, qui t'assieds pleine d'assurance, et qui dis en ton cœur: Je suis reine, et il n'en est point d'autre; je ne serai jamais veuve, et je ne connaîtrai point la perte de mes enfants.
“Nísinsin yìí, tẹ́tí sílẹ̀, ìwọ oníwọ̀ra ẹ̀dá tí o kẹ̀tẹ̀ǹfẹ̀ nínú ààbò rẹ tí o sì ń sọ fún ara rẹ pé, ‘Èmi ni, kò sì ṣí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi. Èmi kì yóò di opó tàbí kí n pàdánù àwọn ọmọ.’
9 Et maintenant sur toi soudain vont fondre ces deux afflictions en un seul jour; le veuvage et la perte de tes enfants te viendront tout à coup, malgré tes enchantements et la puissance de tes magiciens,
Méjèèjì yìí ni yóò wá sórí rẹ láìpẹ́ jọjọ, ní ọjọ́ kan náà: pípàdánù ọmọ àti dídi opó. Wọn yóò wá sórí rẹ ní ẹ̀kúnrẹ́rẹ́, pẹ̀lúpẹ̀lú àwọn ìṣe oṣó rẹ àti àwọn èpè rẹ tí ko lágbára.
10 Au sein des désirs de ta perversité. Car tu as dit: Je suis reine, et il n'en est point d'autre. Sache donc que ta science et ta prostitution tourneront à ta honte. Tu as dit en ton cœur: Je suis reine, et il n'en est point d'autre.
Ìwọ ti ní ìgbẹ́kẹ̀lé nínú ìwà ìkà rẹ ó sì ti wí pé, ‘Kò sí ẹni tí ó rí mi?’ Ọgbọ́n àti òye rẹ ti ṣì ọ́ lọ́nà nígbà tí o wí fún ara rẹ pé, ‘Èmi ni, kò sí ẹlòmíràn lẹ́yìn mi.’
11 Or la perdition viendra sur toi, et tu ne l'auras point su; il y aura un abîme, et tu y tomberas; et sur toi viendra la misère, et tu ne pourras te purifier; et la perdition viendra sur toi tout à coup, et tu n'en auras rien su.
Ìparun yóò dé bá ọ bẹ́ẹ̀ ni ìwọ kì yóò mọ ọ̀nà láti ré e kúrò. Àjálù kan yóò ṣubú lù ọ́ tí o kì yóò le è fi ètùtù ré kúrò; òfò kan tí o kò le faradà ni yóò wá lójijì sí oríì rẹ.
12 Et maintenant repose-toi sur tes nombreux enchantements et sur les charmes magiques que tu as appris dès ta jeunesse; tu verras s'ils te peuvent être utiles.
“Tẹ̀síwájú nígbà náà, pẹ̀lú àfọ̀ṣẹ rẹ àti pẹ̀lú ìwà oṣó rẹ gbogbo, tí o ti ń ṣiṣẹ́ fún láti ìgbà èwe rẹ wá. Bóyá o le è ṣàṣeyọrí, bóyá o le è dá rúgúdù sílẹ̀.
13 Tu t'es fatiguée en tes conseils; que tes astrologues soient donc debout, qu'ils te sauvent; que ceux qui observent les étoiles te prédisent ce qui doit t'arriver.
Gbogbo ìmọ̀ràn tí o ti gbà ni ó ti sọ ọ́ di akúrẹtẹ̀! Jẹ́ kí àwọn awòràwọ̀ rẹ bọ́ síwájú, àwọn awòràwọ̀ tí wọ́n sọ àsọtẹ́lẹ̀ láti oṣù dé oṣù, jẹ́ kí wọ́n gbà ọ́ lọ́wọ́ ohun tí ó ń bọ̀ wá bá ọ.
14 Mais voilà qu'ils seront tous brûlés par le feu comme des broussailles; ils ne sauveront point leur vie de la flamme; et toi, puisque tu as des charbons embrasés, assieds-toi dessus.
Lóòótọ́ wọ́n dàbí ìṣẹ́pẹ́ igi; iná ni yóò jó wọn dànù. Wọn kò kúkú lè gba ara wọn là lọ́wọ́ agbára iná náà. Kò sí èédú láti mú ara ẹnikẹ́ni gbóná níhìn-ín kò sí iná tí ènìyàn le jókòó tì.
15 Tel sera pour toi leur secours; tu t'es fatiguée dès ta jeunesse au trafic; l'homme s'est égaré en lui-même; il n'y aura point de salut pour toi.
Gbogbo ohun tí wọ́n lè ṣe fún ọ nìyìí gbogbo èyí ní o tí ṣíṣẹ́ pẹ̀lú u rẹ̀ tí o sì ti ń rù kiri láti ìgbà èwe. Ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ń lọ nínú àṣìṣe rẹ̀; kò sí ẹyọ ẹnìkan tí ó lè gbà ọ́.