< Isaïe 19 >

1 Oracle sur l'Égypte. Voici que le Seigneur s'est assis sur une nuée légère, et il arrivera en Égypte, et les idoles de l'Égypte seront ébranlées devant sa face, et elle faiblira au fond de son cœur.
Ọ̀rọ̀-ìmọ̀ tí ó kan Ejibiti. Kíyèsi i, Olúwa gun àwọsánmọ̀ tí ó yára lẹ́ṣin ó sì ń bọ̀ wá sí Ejibiti. Àwọn ère òrìṣà Ejibiti wárìrì níwájú rẹ̀, ọkàn àwọn ará Ejibiti sì ti domi nínú wọn.
2 Et les Égyptiens s'élèveront contre les Égyptiens, et le frère combattra le frère, ami contre ami, ville contre ville, nom contre nom.
“Èmi yóò rú àwọn ará Ejibiti sókè sí ara wọn arákùnrin yóò bá arákùnrin rẹ̀ jà, aládùúgbò yóò dìde sí aládùúgbò rẹ̀, ìlú yóò dìde sí ìlú, ilẹ̀ ọba sí ilẹ̀ ọba.
3 Et l'esprit des Égyptiens sera troublé en eux-mêmes, et je dissiperai leurs conseils; et ils interrogeront leurs dieux, et leurs statues, et ceux qui font sortir leurs voix de la terre, et les magiciens.
Àwọn ará Ejibiti yóò sọ ìrètí nù, èmi yóò sì sọ èrò wọn gbogbo di òfo; wọn yóò bá àwọn òrìṣà àti ẹ̀mí àwọn òkú sọ̀rọ̀, àwọn awoṣẹ́ àti àwọn abókùúsọ̀rọ̀.
4 Et je livrerai l'Égypte aux mains de maîtres cruels, et des rois cruels y règneront: voilà ce que dit le Seigneur Dieu des armées.
Èmi yóò fi Ejibiti lé agbára àwọn ìkà amúnisìn lọ́wọ́, ọba aláìláàánú ni yóò jẹ ọba lé wọn lórí,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
5 Et les Égyptiens boiront de l'eau près de la mer; car leur fleuve tarira, et il sera desséché.
Gbogbo omi inú odò ni yóò gbẹ, gbogbo ilẹ̀ àyíká odò ni yóò gbẹ tí yóò sì sáàpá.
6 Et les fleuves tariront et les canaux du fleuve; et tout amas d'eau sera desséché, et tous les marais où croissent le roseau et le papyrus;
Adágún omi yóò sì di rírùn; àwọn odò ilẹ̀ Ejibiti yóò máa dínkù wọn yóò sì gbẹ. Àwọn koríko odò àti ìrẹ̀tẹ̀ yóò gbẹ,
7 Et le gazon verdoyant au bord du fleuve; et tout ce qui est semé le long du fleuve sera flétri et desséché par le vent.
àwọn igi ipadò Naili pẹ̀lú, tí ó wà ní orísun odò, gbogbo oko tí a dá sí ipadò Naili yóò gbẹ dànù tí yóò sì fẹ́ dànù tí kò sì ní sí mọ́.
8 Et les pêcheurs gémiront; et ils gémiront tous ceux qui jettent l'hameçon dans le fleuve; et ceux qui jettent des seines et des filets pleureront.
Àwọn apẹja yóò sọkún kíkorò, àti gbogbo àwọn tí ó ń ju ìwọ̀ sínú odò; odò náà yóò sì máa rùn.
9 Et ceux qui travaillent le lin et le byssus, ou qui font des robes, seront confondus.
Àwọn tí ó ń ṣiṣẹ́ pẹ̀lú ọ̀gbọ̀ yóò kọminú àwọn ahunṣọ ọ̀gbọ̀ yóò sọ ìrètí nù.
10 Et tous les artisans seront dans la douleur, et ceux Qui font la bière seront attristés, et ils souffriront en leur âme
Àwọn tí ń ṣiṣẹ́ aṣọ yóò rẹ̀wẹ̀sì, gbogbo àwọn oníṣẹ́ oṣù ni àìsàn ọkàn yóò ṣe.
11 Et les princes de Tanis, sages conseillers du roi, deviendront fous; leur conseil sera folie. Comment pourrez-vous dire au roi: Nous sommes les fils des sages, les fils des anciens rois?
Àwọn oníṣẹ́ Ṣoani ti di aláìgbọ́n, àwọn ọlọ́gbọ́n olùdámọ̀ràn Farao ń mú ìmọ̀ràn àìgbọ́n wá. Báwo ló ṣe lè sọ fún Farao pé, “Mo jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn, ọ̀kan nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn àwọn ọba àtijọ́.”
12 Où sont maintenant tes sages? Qu'ils prophétisent, et qu'ils disent: Qu'a résolu contre l'Égypte le Seigneur Dieu des armées?
Níbo ni àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn rẹ wà báyìí? Jẹ́ kí wọn fihàn ọ́ kí wọn sì sọ ọ́ di mí mọ̀ ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ti pinnu lórí Ejibiti.
13 Les princes de Tanis ont défailli; ceux de Memphis se sont enorgueillis, et ils ont égaré l'Égypte en toutes ses tribus.
Àwọn ọmọ-aládé Ṣoani ti di aṣiwèrè, a ti tan àwọn ọmọ-aládé Memfisi jẹ; àwọn òkúta igun ilé tí í ṣe ti ẹ̀yà rẹ ti ṣi Ejibiti lọ́nà.
14 Car le Seigneur a répandu sur eux un esprit d'erreur, et ils ont égaré l'Égypte en toutes ses œuvres, et ils l'ont fait marcher comme un homme ivre qui vomit.
Olúwa ti da ẹ̀mí òòyì sínú wọn; wọ́n mú Ejibiti ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú ohun gbogbo tí ó ń ṣe, gẹ́gẹ́ bí ọ̀mùtí ti í ta gbọ̀nọ́ngbọ̀nọ́n nínú èébì rẹ̀.
15 Et les Égyptiens ne feront plus rien qui ait une tête et une queue, un commencement et une fin.
Kò sí ohun tí Ejibiti le ṣe— orí tàbí ìrù, ọ̀wá ọ̀pẹ tàbí koríko odò.
16 Et, en ce jour, les Égyptiens seront comme des femmes effrayées et tremblantes sous la main du Seigneur des armées, qu'il fera tomber sur eux.
Ní ọjọ́ náà ni àwọn ará Ejibiti yóò dàbí obìnrin. Wọn yóò gbọ̀n jìnnìjìnnì pẹ̀lú ẹ̀rù nítorí ọwọ́ Olúwa àwọn ọmọ-ogun tí a gbé sókè sí wọn.
17 Et la terre de la Judée sera pour les Égyptiens un objet de terreur; et quiconque prononcera son nom devant eux les frappera de crainte, à cause des desseins que le Seigneur des armées a formés sur eux-mêmes.
Ilẹ̀ Juda yóò sì di ẹ̀rù fún Ejibiti; gbogbo àwọn tí a bá ti dárúkọ Juda létí wọn ni yóò wárìrì, nítorí ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbèrò láti ṣe sí wọn.
18 Ce jour-là, il y aura cinq villes d'Égypte qui parleront la langue de Chanaan, et jureront par le Seigneur Dieu des armées. L'une de ces villes s'appellera Asédec.
Ní ọjọ́ náà ìlú márùn-ún ní ilẹ̀ Ejibiti yóò sọ èdè àwọn ará Kenaani, wọn yóò sì búra àtìlẹ́yìn fún Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Ọ̀kan nínú wọn ni a ó sì máa pè ní ìlú ìparun.
19 Ce jour-là, il y aura sur le territoire d'Égypte un autel du Seigneur, et à sa frontière une colonne élevée au Seigneur.
Ní ọjọ́ náà pẹpẹ kan yóò wà fún Olúwa ní àárín gbùngbùn Ejibiti, àti ọ̀wọ́n kan fún Olúwa ní etí bodè rẹ̀.
20 Et ce sera un signe éternel au Seigneur en la terre d'Égypte. Dès lors ils crieront au Seigneur dans leurs tribulations, et il leur enverra un homme pour les sauver; et il les sauvera en les jugeant.
Yóò sì jẹ́ àmì àti ẹ̀rí sí Olúwa àwọn ọmọ-ogun ní ilẹ̀ Ejibiti. Nígbà tí wọ́n bá ké pe Olúwa nítorí àwọn aninilára wọn, yóò rán olùgbàlà àti olùgbèjà kan sí wọn tí yóò sì gbà wọ́n sílẹ̀.
21 Et le Seigneur sera connu des Égyptiens. Et les Égyptiens en ce jour connaîtront le Seigneur, et ils lui sacrifieront des victimes, et ils lui feront des vœux, et ils les accompliront.
Báyìí ni Olúwa yóò sọ ara rẹ̀ di mí mọ̀ fún àwọn ará Ejibiti àti ní ọjọ́ náà ni wọn yóò gba Olúwa gbọ́. Wọn yóò sìn ín pẹ̀lú ẹbọ ọrẹ ìyẹ̀fun, wọn yóò jẹ́ ẹ̀jẹ́ fún Olúwa wọn yóò sì mú un ṣẹ.
22 Et le Seigneur frappera d'une plaie les Égyptiens, puis il la guérira; et ils se convertiront au Seigneur, et il les exaucera, et il leur enverra une entière guérison.
Olúwa yóò fi àjàkálẹ̀-ààrùn kan bá Ejibiti jà; yóò bá wọn jà yóò sì tún wò wọ́n sàn. Wọn yóò yípadà sí Olúwa, Òun yóò sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn yóò sì wò wọ́n sàn.
23 En ce jour, il y aura une voie de l'Égypte à l'Assyrie; et les Assyriens entreront en Égypte; et les Égyptiens iront en Assyrie, et ils seront asservis aux Assyriens.
Ní ọjọ́ náà òpópónà kan yóò wá láti Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Asiria yóò lọ sí Ejibiti àti àwọn ará Ejibiti lọ sí Asiria. Àwọn ará Ejibiti àti ará Asiria yóò jọ́sìn papọ̀.
24 En ce jour, Israël sera la troisième avec les Égyptiens et les Assyriens, et il sera béni sur la terre
Ní ọjọ́ náà Israẹli yóò di ẹ̀kẹta pẹ̀lú Ejibiti àti Asiria, àní orísun ìbùkún ní ilẹ̀ ayé.
25 Que le Seigneur des armées a bénie, disant: Béni soit mon peuple qui est en Égypte et qui est en Assyrie; et béni soit Israël mon héritage!
Olúwa àwọn ọmọ-ogun yóò bùkún wọn yóò wí pé, “Ìbùkún ni fún Ejibiti ènìyàn mi, Asiria iṣẹ́ ọwọ́ mi, àti Israẹli ìní mi.”

< Isaïe 19 >