< Isaïe 1 >

1 Vision d'Isaïe, fils d'Amos, qu'il eut sur la Judée et Jérusalem, sous le règne d'Ozias et de Joatham, d'Achaz et d'Ézéchias, qui furent rois de la Judée.
Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
2 Écoute, ciel; prête l'oreille, terre, parce que le Seigneur a parlé, disant: J'ai engendré des fils, et je les ai élevés en gloire; mais eux, ils m'ont méprisé.
Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
3 Le bœuf connaît son possesseur, et l'âne, la crèche de son maître; pour Israël, il m'a méconnu, et son peuple ne m'a pas compris.
Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
4 Malheur à toi, peuple pécheur, nation pleine de péchés, race de méchants, fils pervertis! vous avez abandonné le Seigneur, et irrité le Saint d'Israël.
Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
5 A quoi bon vous frapper encore, en ajoutant à votre iniquité? Toute tête est en souffrance, et tout cœur en tristesse.
Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
6 Des pieds à la tête, rien n'est sain en lui, rien qui ne soit contusion, meurtrissure, plaie enflammée; point d'émollients à y appliquer, point d'huile, point de ligature.
Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
7 Votre terre est déserte, vos villes consumées par le feu; votre contrée, des étrangers la dévorent sous vos yeux; elle est désolée et bouleversée par des nations étrangères.
Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
8 La fille de Sion sera délaissée comme une tente dans une vigne, comme la cabane d'un garde dans un champ de concombres, comme une ville prise d'assaut.
Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
9 Et si le Seigneur des armées ne nous eût laissé une semence, nous serions comme Sodome, nous ressemblerions à Gomorrhe.
Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
10 Ecoutez la parole du Seigneur, princes de Sodome; soyez attentifs à la loi de Dieu, peuple de Gomorrhe.
Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
11 Qu'ai-je besoin de la multitude de vos victimes? Je suis rassasié des holocaustes de béliers; la graisse des agneaux, le sang des taureaux et des boucs, je n'en veux plus.
“Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
12 Ne venez plus vous montrer à moi; car qui vous a demandé ces offrandes de vos mains? Ne continuez plus de fouler mon parvis.
Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
13 Quand vous m'apportez de la fleur de farine, ou un encens inutile, c'est pour moi une abomination. Vos nouvelles lunes, vos sabbats, votre grand jour, je ne puis les souffrir; votre jeûne, votre repos,
Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
14 Vos nouvelles lunes, vos fêtes, mon âme les déteste. Je vous ai en dégoût, je ne vous remettrai plus vos péchés.
Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
15 Si vous étendez la main, je détournerai de vous mes yeux; et si vous multipliez vos prières, je ne vous écouterai pas; car vos mains sont pleines de sang.
Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
16 Lavez-vous, soyez purs; ôtez de devant mes yeux la malice de vos âmes; mettez fin à vos méfaits.
“Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
17 Apprenez à faire le bien, cherchez la justice, protègez l'opprimé; jugez équitablement l'orphelin, rendez justice à la veuve.
kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
18 Et puis venez m'accuser, dit le Seigneur. Et quand même vos péchés seraient comme la pourpre, je les rendrai blancs comme la neige; et quand ils seraient comme de l'écarlate, je les rendrai blancs comme une toison.
“Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
19 Et si vous êtes de bonne volonté, si vous m'écoutez, vous mangerez les biens de la terre.
Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
20 Mais si vous n'êtes point de bonne volonté, si vous ne m'écoutez point, le glaive vous dévorera; car voici ce qu'a dit la bouche du Seigneur:
Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
21 Comment est devenue prostituée Sion, la cité fidèle, jadis pleine de justice? L'équité reposait en elle, et maintenant ce sont des meurtriers.
Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
22 Votre argent n'est pas de bon aloi; vos cabaretiers mêlent de l'eau à leur vin.
Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
23 Vos princes sont incrédules, associés aux voleurs, amis des présents, gagnés par les salaires, sans justice pour les orphelins, sans égard pour la cause des veuves.
Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
24 C'est pourquoi voici ce que dit le Seigneur, maître des armées: Malheur aux puissants d'Israël! car ma fureur contre mes adversaires ne s'apaisera point, et je tirerai vengeance de mes ennemis.
Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
25 Et je ferai tomber ma main sur toi, et je te purifierai par le feu; et j'exterminerai les incrédules, et j'enlèverai tous les prévaricateurs loin de toi.
Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
26 Et je rétablirai tes juges comme autrefois, et tes conseillers comme dès le commencement. Et après cela tu seras appelée Ville de justice, métropole fidèle, Sion.
Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
27 Car ses captifs seront délivrés par le jugement et par la miséricorde.
A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
28 Et les méchants seront écrasés, et avec eux les pécheurs; et ceux qui auront abandonné le Seigneur périront avec eux.
Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
29 C'est pourquoi ils seront confondus par les idoles mêmes qu'ils avaient voulues, et ils rougiront des jardins qu'ils avaient convoités.
“Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
30 Car ils seront comme un térébinthe dépouillé de ses feuilles, et comme un jardin sans eau.
Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
31 Et leur force sera comme le chaume du concombre, et leurs œuvres comme des étincelles, et les méchants seront consumés, et avec eux le pécheur; et nul ne sera là pour éteindre la flamme.
Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”

< Isaïe 1 >