< Osée 9 >

1 Ne te réjouis pas, Israël, ne te mets pas en fête, comme les gentils, parce que tu t'es prostitué en t'éloignant de ton Dieu, tu as aimé les dons plus que des aires pleines de blé.
Má ṣe yọ̀, ìwọ Israẹli; má ṣe hó ìhó ayọ̀ bí àwọn orílẹ̀-èdè yòókù. Nítorí ẹ ti jẹ́ aláìṣòótọ́ si Ọlọ́run yín. Ẹ fẹ́ràn láti gba owó iṣẹ́ àgbèrè ní gbogbo ilẹ̀ ìpakà.
2 Mais l'aire et le pressoir les ont méconnus, et le vin les a trompés.
Àwọn ilẹ̀ ìpakà àti ilé ìfun wáìnì kò ní fún àwọn ènìyàn lóúnjẹ wáìnì tuntun yóò tàn láìròtẹ́lẹ̀.
3 Ils ne sont point restés en la terre du Seigneur; Éphraïm a demeuré en Égypte, et ils mangeront des viandes impures chez les Assyriens.
Wọn kò ní ṣẹ́kù sí ilé Olúwa Efraimu yóò padà sí Ejibiti, yóò sì jẹ oúnjẹ àìmọ́ ní Asiria.
4 Ils n'ont point fait au Seigneur des libations de vin, et ils ne lui ont point été agréables. Leurs victimes sont pour eux comme des pains d'affliction; tous ceux qui en mangent seront souillés, parce que leurs pains, s'ils soutiennent la vie, n'entreront point dans la maison du Seigneur.
Wọn kò ní fi ọrẹ ohun mímu fún Olúwa. Bẹ́ẹ̀ ni ìrúbọ wọn kò ní mú, inú rẹ̀ dùn. Ìrú ẹbọ bẹ́ẹ̀ yóò dàbí oúnjẹ àwọn tí ń ṣọ̀fọ̀. Gbogbo àwọn tó bá sì jẹ ẹ́ yóò di aláìmọ́. Oúnjẹ yìí yóò wà fún wọn fúnra wọn kò ní wá sí orí tẹmpili Olúwa.
5 Que ferez-vous les jours de réunions solennelles, et les jours de fête du Seigneur?
Kí ni ẹ̀yin ó ṣe ní ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn ní àwọn ọjọ́ àjọ̀dún Olúwa?
6 À cause de cela, voilà qu'ils sortent des misères de l'Égypte, et Memphis les recevra, et Machmas les ensevelira. Quant à leur argent, la dévastation en héritera, et les ronces pousseront dans leurs demeures.
Bí wọ́n tilẹ̀ yọ́ kúrò lọ́wọ́ ìparun Ejibiti yóò kó wọn jọ, Memfisi yóò sì sin wọ́n. Ibi ìsọjọ̀ fàdákà wọn ni ẹ̀gún yóò jogún, Ẹ̀gún yóò bo àpótí ìṣúra fàdákà wọn. Ẹ̀gún yóò sì bo gbogbo àgọ́ wọn.
7 Ils sont venus les jours de la vengeance, ils sont venus les jours de rétribution, et Israël sera maltraité, comme un prophète en délire, comme un homme possédé par un malin esprit. Tes folies se sont multipliées à cause de la multitude de tes iniquités.
Àwọn ọjọ́ ìjìyà ń bọ̀; àwọn ọjọ́ ìṣirò iṣẹ́ ti dé. Jẹ́ kí Israẹli mọ èyí. Nítorí pé ẹ̀ṣẹ̀ yín pọ̀ ìkórìíra yín sì pọ̀ gan an ni. A ka àwọn wòlíì sí òmùgọ̀, a ka ẹni ìmísí sí asínwín.
8 La sentinelle d'Éphraïm était avec Dieu; mais un faux prophète a été comme un lacs tortueux sur toutes ses voies, et ils ont transplanté leur folie dans la maison du Seigneur.
Wòlíì, papọ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run, ni olùṣọ́ ọ Efraimu. Síbẹ̀ ìdẹ̀kùn dúró dè é ní gbogbo ọ̀nà rẹ̀ àti ìkórìíra ní ilé Ọlọ́run rẹ̀.
9 Ils se sont perdus comme aux jours de la colline; mais Dieu Se souviendra de leurs iniquités, et Il tirera vengeance de leurs crimes.
Wọ́n ti gbilẹ̀ nínú ìwà ìbàjẹ́ gẹ́gẹ́ bí i ọjọ́ Gibeah Ọlọ́run yóò rántí ìwà búburú wọn yóò sì jẹ wọ́n ní yà fún ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
10 J'ai aimé Israël comme une grappe de raisin dans le désert, et j'ai vu leurs pères comme un fruit mûr dans un figuier. pour eux, ils se sont approchés de Béelphégor, et dans leur opprobre ils se sont détournés de Moi, et ils Me sont devenus abominables autant qu'ils M'avaient été chers.
“Mo rí Israẹli bí èso àjàrà ní aginjù. Mo rí àwọn baba yín, bí àkọ́pọ́n nínú igi ọ̀pọ̀tọ́ ní àkọ́so rẹ̀. Ṣùgbọ́n wọ́n tọ Baali-Peori lọ, wọ́n yà wọn sọ́tọ̀ fún òrìṣà tó ń mú ìtìjú bá ni, ohun ìríra wọn sì rí gẹ́gẹ́ bí wọn ti fẹ́.
11 Éphraïm s'est envolé comme l'oiseau, et, à peine nées, ses gloires se sont évanouies, ou pendant l'enfantement, ou aussitôt conçues;
Ògo Efraimu yóò fò lọ bí ẹyẹ kò ní sí ìfẹ́rakù, ìlóyún àti ìbímọ.
12 car, eût-il élevé ses enfants, il n'en sera pas moins sans postérité: malheur donc à lui, Ma chair n'est plus avec eux!
Bí wọ́n tilẹ̀ tọ́ ọmọ dàgbà. Èmi yóò mú wọn ṣọ̀fọ̀ lórí gbogbo wọn. Ègbé ni fún wọn, nígbà tí mo yípadà kúrò lọ́dọ̀ wọn!
13 Éphraïm, Je l'ai vu, a fait une proie de ses enfants; Éphraïm a exposé ses fils à la mort.
Mo rí Efraimu bí ìlú Tire tí a tẹ̀dó sí ibi dáradára ṣùgbọ́n Efraimu yóò kó àwọn ọmọ rẹ̀ jáde fún àwọn apànìyàn.”
14 Donne-leur, ô mon Dieu; mais que peux-Tu leur donner? Donne-leur un sein stérile et des mamelles taries.
Fún wọn, Olúwa! Kí ni ìwọ yóò fún wọn? Fún wọn ní inú tí ń ba oyún jẹ́ àti ọyàn gbígbẹ.
15 Toutes leurs méchancetés se font en Galata; c'est là que Je les ai pris en haine pour leurs inventions abominables. Je les chasserai de Ma maison, et Je ne les aimerai plus, car tous leurs princes sont indociles.
“Nítorí gbogbo ìwà búburú tí wọ́n hù ní Gilgali, Mo kórìíra wọn níbẹ̀, nítorí ìwà ẹ̀ṣẹ̀ wọn. Èmi yóò lé wọn jáde ní ilé mi, Èmi kò ní ní ìfẹ́ wọn mọ́ ọlọ̀tẹ̀ ni gbogbo olórí wọn.
16 Éphraïm s'est épuisé; il a desséché ses racines; il ne portera plus de fruits, et, dût-il en naître, Je ferai mourir les fruits désirés de leurs entrailles.
Efraimu ti rẹ̀ dànù gbogbo rẹ̀ sì ti rọ, kò sì so èso. Bí wọ́n tilẹ̀ bímọ. Èmi ó pa àwọn ọmọ wọn tí wọ́n fẹ́ràn jùlọ.”
17 Dieu les a repoussés parce qu'ils ne Lui ont point obéi, et ils seront errants parmi les nations.
Ọlọ́run mi yóò kọ̀ wọ́n sílẹ̀ nítorí pé wọn kò gbọ́rọ̀ sí i; wọn yóò sì di alárìnkiri láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Osée 9 >