< Osée 13 >

1 À la parole de Jéroboam, Éphraïm a pris lui-même des commandements en Israël et les a mis devant Baal, et Éphraïm est mort.
Nígbà ti Efraimu bá ń sọ̀rọ̀, àwọn ènìyàn máa ń wárìrì, a gbé e ga ní Israẹli ṣùgbọ́n ó jẹ̀bi ẹ̀sùn pé ó ń sin òrìṣà Baali, ó sì kú.
2 Et maintenant ils continuent de pécher, et ils se sont fait de leur argent des statues en fonte à l'image des idoles, œuvres accomplies d'un artiste; et ils se disent entre eux: Sacrifiez des hommes, car il y a disette de bœufs!
Báyìí, wọ́n ń dá ẹ̀ṣẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀; wọn fi fàdákà ṣe ère òrìṣà fúnra wọn; ère tí a fi ọgbọ́n dá àrà sí, gbogbo wọn jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ oníṣọ̀nà. Wọn ń sọ nípa àwọn ènìyàn wọ̀nyí. Pé, “Jẹ́ kí àwọn ènìyàn tí ń rú ẹbọ fi ẹnu, ko àwọn ẹgbọrọ màlúù ni ẹnu.”
3 À cause de cela, ils seront comme le nuage du matin, comme la rosée qui vient à l'aurore, comme la poudre que le vent emporte hors de l'aire, comme la vapeur des larmes.
Nítorí náà wọn yóò dàbí ìkùùkuu òwúrọ̀, bí ìrì òwúrọ̀ kùtùkùtù tó máa ń parẹ́, bí i èèpo ìyẹ̀fun tí afẹ́fẹ́ gbé láti ibi ìpakà bí èéfín tó rú jáde gba ojú fèrèsé.
4 Moi, le Seigneur ton Dieu, qui ai affermi le ciel; Moi, le Créateur de la terre, Moi, dont les mains ont créé toute l'armée céleste, Je ne t'ai point montré ces créatures pour que tu chemines après elles; c'est Moi qui t'ai délivré de la terre d'Égypte, et tu ne connaîtras point d'autre Dieu que Moi, et nul autre que Moi ne sauve.
“Ṣùgbọ́n Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ̀, ẹni tó mú ọ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá. Ìwọ̀ kì yóò sì mọ ọlọ́run mìíràn àfi èmi kò sí olùgbàlà mìíràn lẹ́yìn mi.
5 J'ai été ton pasteur dans le désert, en une terre inhabitée
Mo ṣe ìtọ́jú rẹ ní aginjù, ní ilẹ̀ tí ó gbẹ tí kò ní omi.
6 et sans pâturages; et ils s'y sont rassasiés et remplis, et leurs cœurs se sont enorgueillis, et à cause de cela ils M'ont oublié.
Wọn ni ìtẹ́lọ́rùn nígbà tí mo fún wọn ní oúnjẹ, Nígbà tí wọ́n ní ìtẹ́lọ́rùn tan wọ́n di agbéraga. Nígbà náà ni wọ́n sì gbàgbé mi.
7 Et Je serai pour eux comme une panthère et comme un léopard, sur la route de l'Assyrie.
Nítorí náà, Èmi yóò dìde sí wọn bí i kìnnìún, Èmi yóò fi ara pamọ́ dè wọ́n lọ́nà bí i ẹkùn.
8 J'accourrai au-devant d'eux comme une ourse affamée, et Je briserai l'enveloppe de leurs cœurs, et les lionceaux de la forêt les dévoreront, et les bête fauves les mettront en lambeaux.
Beari igbó tí a já ọmọ rẹ̀ gbà, Èmi yóò bá wọn jà bí? Èmi yóò sì fà wọ́n ya bí ìgbà tí ẹkùn bá fa ara wọn ya bi ẹranko búburú ni èmi yóò fa wọn ya.
9 En ta destruction, ô Israël, qui te portera secours?
“A ti pa ọ́ run, ìwọ Israẹli, nítorí pé ìwọ lòdì sí mi, ìwọ lòdì sí olùrànlọ́wọ́ rẹ.
10 Où est celui-là? Est-ce ton roi? Qu'il te sauve en toutes tes villes; qu'il te juge celui à qui tu as dit: Donne-moi un roi et un prince!
Níbo ni ọba rẹ gbé wà nísinsin yìí kí ó bá à le gbà ọ là? Níbo ni àwọn olórí ìlú yín wà, àwọn tí ẹ sọ pé, ‘Fún wa ní ọba àti ọmọ-aládé’?
11 Je t'ai donné un roi dans Ma colère, et Je t'ai traité dans Mon courroux.
Nítorí èyí nínú ìbínú mi ni mo fún un yín ní ọba, nínú ìbínú gbígbóná mi, mo sì mú un kúrò.
12 Éphraïm a fait un complot d'iniquité; son impiété a été cachée.
Ẹ̀bi Efraimu ni a tí ko jọ gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ wà nínú àkọsílẹ̀.
13 Les douleurs de la femme qui enfante lui viendront. celui-là est ton fils, le Sage, parce qu'il ne se tiendra pas immobile pendant le massacre de tes enfants.
Ìrora bí obìnrin tó fẹ́ bímọ ti dé bá a, ṣùgbọ́n ó jẹ́ ọmọ tí kò lọ́gbọ́n, nígbà tí àsìkò tó, ó kọ̀ láti jáde síta láti inú.
14 Je les tirerai de l'enfer, dira-t-il; je les affranchirai tous de la mort. Ô mort, où est ta sentence? Enfer, où est ton aiguillon? Mais cette consolation est cachée à mes yeux. (Sheol h7585)
“Èmi yóò rà wọ́n padà kúrò lọ́wọ́ agbára isà òkú. Èmi yóò rà wọ́n padà lọ́wọ́ ikú, ikú, àjàkálẹ̀-ààrùn rẹ dà? Isà òkú, ìparun rẹ dà? “Èmi kò ní ṣàánú mọ́. (Sheol h7585)
15 Et quand l'enfer sèmera la division entre les frères, le Seigneur enverra contre lui un vent brûlant du désert, et Il desséchera les veines de la mort, et Il tarira ses sources; Lui-même fera de ses champs une terre aride, et enlèvera ses vases les plus précieux. (questioned)
Bí ó tilẹ̀ gbilẹ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀ afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn láti ọ̀dọ̀ Olúwa yóò wá, yóò fẹ́ wá láti inú aginjù orísun omi rẹ̀ yóò gbẹ kànga rẹ̀ yóò gbẹ pẹ̀lú olè yóò fọ́ ilé ẹrù àti gbogbo ilé ìṣúra rẹ̀.
16 Samarie sera détruite, parce qu'elle s'est révoltée contre son Dieu. Ils périront par le glaive; tous ses enfants à la mamelle seront écrasés à terre, et les femmes enceintes seront déchirées.
Ará Samaria gbọdọ̀ ru ẹ̀bi wọn, nítorí pé wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí Ọlọ́run wọn. Wọn ó ti ipa idà ṣubú; a ó fọ́ àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀, a ó sì la àwọn aboyún wọn nínú.”

< Osée 13 >