< Osée 12 >
1 Éphraïm a poursuivi un vent funeste qui a fait durer tout le jour l'ardente chaleur; il a multiplié les vanités et les folies; il a fait alliance avec les Assyriens; il a vendu de l'huile en Égypte.
Efraimu ń jẹ afẹ́fẹ́; o ń lépa afẹ́fẹ́ ìwọ̀-oòrùn ní gbogbo ọjọ́. O sì ń gbèrú nínú irọ́ o dá májẹ̀mú pẹ̀lú Asiria o sì fi òróró olifi ránṣẹ́ sí Ejibiti.
2 Et le Seigneur entrera en jugement avec Juda, afin de punir Jacob; et Il le rétribuera selon ses voies et ses œuvres.
Olúwa ní ẹjọ́ kan tí yóò bá Juda rò, yóò fì ìyà jẹ Jakọbu gẹ́gẹ́ bí ọ̀nà rẹ̀ yóò sì sán fún un gẹ́gẹ́ bí i ìṣe rẹ̀.
3 Dans les entrailles de sa mère, il supplanta son frère, et, de ses travaux, il fut fort contre Dieu.
Láti inú oyún ni ó ti di arákùnrin rẹ̀ mú ni gìgísẹ̀, àti nípa ipá rẹ̀ ó ni agbára pẹ̀lú Ọlọ́run
4 Il fut fort avec un ange, et il prévalut; et ils pleurèrent, et ils Me prièrent, ils Me trouvèrent en la maison d'On; et là il leur fut parlé.
Ó bá angẹli ja ìjàkadì, ó sì borí rẹ̀, o sọkún, ó sì bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere rẹ̀. Ó bá Olúwa ní Beteli, Ó sì bá a sọ̀rọ̀ níbẹ̀,
5 Et le Seigneur Dieu Tout-Puissant sera le mémorial de Jacob.
àní Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun; Olúwa ni orúkọ ìrántí rẹ̀.
6 Et toi, Éphraïm, tu te convertiras à ton Dieu; garde donc Sa miséricorde et Sa justice, et approche-toi toujours de ton Dieu.
Ṣùgbọ́n ìwọ gbọdọ̀ padà sọ́dọ̀ Ọlọ́run rẹ̀; di ìfẹ́ àti ìdájọ́ òdodo mú kí ẹ sì dúró de Ọlọ́run yín nígbà gbogbo.
7 Chanaan tient dans sa main une balance d'iniquité; il a aimé à opprimer avec violence.
Oníṣòwò ń lo òsùwọ̀n èké o fẹ́ràn láti rẹ́ ni jẹ.
8 Et Éphraïm a dit: Cependant je me suis enrichi, je me suis acquis le repos. Mais aucun de ses labeurs ne lui sera compté, à cause des injustices qu'il a commises.
Efraimu gbéraga, “Èmi ní ìní fún ara mi, mo sì ti di ọlọ́rọ̀, pẹ̀lú gbogbo ọrọ̀ mi yìí, wọn kò le ká àìṣedéédéé tàbí ẹ̀ṣẹ̀ kankan mọ́ mi lọ́wọ́.”
9 Moi, le Seigneur ton Dieu, Je t'ai fait sortir de l'Égypte; Je te ferai encore camper sous des tentes, comme dans les jours de fête.
“Èmi ni Olúwa Ọlọ́run rẹ; ẹni tí ó mu ọ jáde wá láti ilẹ̀ Ejibiti; èmi yóò tún mú yín gbé nínú àgọ́ bí i ọjọ́ àjọ̀dún tí a yàn wọ̀n-ọn-nì.
10 J'ai parlé aux prophètes, et J'ai multiplié les visions, et J'ai parlé par la bouche des prophètes.
Mo sọ fún àwọn wòlíì, mo fi ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìran hàn wọ́n mo sì pa òwe láti ẹnu wòlíì wọn.”
11 Si Galaad n'est plus, c'est qu'il y avait en Galaad des princes menteurs faisant des sacrifices, et leurs autels sont comme des amas de pierres dans un champ.
Gileadi ha burú bí? Àwọn ènìyàn rẹ̀ jẹ́ asán. Ǹjẹ́ wọ́n ń fi akọ màlúù rú ẹbọ ní Gilgali? Gbogbo pẹpẹ wọ́n sì dàbí ebè nínú aporo oko.
12 Et Jacob se retira en Syrie, et Israël servit pour une femme, et pour une femme il garda les troupeaux.
Jakọbu sálọ si orílẹ̀-èdè Aramu; Israẹli sìn kí o tó fẹ́ ìyàwó ó ṣe ìtọ́jú ẹran láti fi san owó ìyàwó.
13 Et par Son prophète le Seigneur conduisit Israël hors de la terre d'Égypte, et c'est encore par Son prophète qu'Il le sauva.
Olúwa lo wòlíì kan láti mú Israẹli jáde wá láti Ejibiti, nípasẹ̀ wòlíì kan ó ṣe ìtọ́jú rẹ̀.
14 Et Éphraïm le provoqua et souleva Sa colère; mais le sang versé par Éphraïm retombera sur sa tête, et le Seigneur le rétribuera selon Son opprobre.
Ṣùgbọ́n Efraimu ti mú un bínú gidigidi; Olúwa rẹ̀ yóò sì fi ẹ̀bi ìtàjẹ̀ sílẹ̀ sí orí rẹ̀ òun yóò sì san án padà fún un nítorí ìwà ẹ̀gàn an rẹ̀.