< Osée 11 >

1 Israël est un enfant, et Moi Je l'aimais, et J'ai rappelé ses fils de l'Égypte.
“Nígbà tí Israẹli wà ní ọmọdé mo fẹ́ràn rẹ̀, mo sì pe ọmọ mi jáde láti Ejibiti wá.
2 Autant Je les ai rappelés, autant ils sont éloignés de Moi; ils ont sacrifié à Baal, et ils ont encensé des idoles.
Bí a ti ń pe wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ṣe ń sá kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn rú ẹbọ sí Baali, wọn sì fi tùràrí jóná sí ère fínfín.
3 Et Moi J'ai bandé les pieds d'Éphraïm, et Je l'ai pris dans Mes bras, et ils n'ont point connu que Je les guérissais.
Lóòtítọ́ mo kọ́ Efraimu pẹ̀lú ní ìrìn mo di wọ́n mú ní apá, ṣùgbọ́n wọn kò mọ̀ pé mo ti mú wọn láradá.
4 Au milieu de la perdition des hommes, je les ai enveloppés dans les nuages de Mon amour, et maintenant Je serai pour eux comme un homme qui en frappe un autre à la joue, et Je Me retournerai sur Éphraïm, et Je prévaudrai contre lui.
Mo fi okùn ènìyàn fà wọ́n àti ìdè ìfẹ́. Mo mú àjàgà kúrò ni ọrùn wọn, Mo sì fi ara balẹ̀ fún wọn ni oúnjẹ.
5 Éphraïm a demeuré en Égypte, et Assur lui-même a été son roi, parce qu'il n'a pas voulu se convertir.
“Ṣé wọn ò wá ní padà sí Ejibiti bí. Ṣé Asiria kò sì ní jẹ ọba lé wọn lórí bí nítorí pé wọ́n kọ̀ jálẹ̀ láti ronúpìwàdà?
6 Et dans ses villes il a été vaincu par le glaive, et il a cessé de le tenir en ses mains; et ils se nourriront des fruits de leurs conseils.
Idà yóò kọ mọ̀nà ní gbogbo ìlú wọn yóò si bá gbogbo irin ẹnu odi ìlú wọn jẹ́ yóò sì fi òpin sí gbogbo èrò wọn.
7 Et le peuple de Dieu sera en suspens dans le lieu de son exil, et Dieu S'irritera des choses mêmes qu'ils estiment le plus, et Il ne l'exaltera point.
Àwọn ènìyàn mi ti pinnu láti pẹ̀yìndà kúrò lọ́dọ̀ mi bí wọ́n tilẹ̀ pè wọ́n sọ́dọ̀ Ọ̀gá-ògo jùlọ, kò ní gbé wọn ga rárá.
8 Que ferai-Je avec toi, Éphraïm? Serai-Je ton protecteur? Ô Israël, que ferai-Je avec toi? Je te traiterai comme Adama et Seboïm. Mon cœur a changé pour toi, et tu as excité tous Mes regrets.
“Báwo ni èmi ó ṣe fi ọ́ sílẹ̀, Efraimu? Báwo ni èmi ó ṣe yọ̀ǹda rẹ̀, Israẹli? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Adma? Báwo ni mo ṣe lè ṣe ọ bi i Seboimu? Ọkàn mi yípadà nínú mi àánú mi sì ru sókè.
9 Mais Je n'agirai point selon le courroux de Mon âme; Je n'abandonnerai point Éphraïm, pour qu'il soit effacé; car Je suis Dieu, et non un homme; un Saint est en toi, et Je n'entrerai pas dans ta ville.
Èmi kò ni mú ìbínú gbígbóná mi ṣẹ, tàbí kí èmi wá sọ Efraimu di ahoro. Nítorí pé èmi ni Ọlọ́run, àní, èmi kì í ṣe ènìyàn. Ẹni mímọ́ láàrín yín, Èmi kò ní í wá nínú ìbínú.
10 Je marcherai après le Seigneur; Il rugira comme un lion; il rugira, et les enfants des eaux seront saisis de stupeur.
Wọn yóò máa tẹ̀lé Olúwa; òun yóò bú ramúramù bí i kìnnìún. Nígbà tó bá bú, àwọn ọmọ rẹ yóò wá ní ìwárìrì láti ìwọ̀-oòrùn.
11 Les enfants de Mon peuple aussi seront saisis de stupeur, et fuiront de l'Égypte comme un oiseau, et de la terre des Assyriens comme une colombe, et Je les ferai rentrer dans leurs demeures, dit le Seigneur.
Wọn ó wá pẹ̀lú ẹ̀rù bí i ẹyẹ láti Ejibiti, bí i àdàbà láti Asiria, Èmi ó mú wọn padà sí ilé wọn,” ni Olúwa wí.
12 Éphraïm M'a entouré de ses mensonges, Israël et Juda de leurs impiétés; maintenant Dieu les connaît, et le peuple saint s'appellera le peuple de Dieu.
Efraimu tí fi irọ́ yí mi ká ilé Israẹli pẹ̀lú ẹ̀tàn. Ṣùgbọ́n Juda sì dúró ṣinṣin pẹ̀lú Ọlọ́run. Ó sì ṣe olóòtítọ́ sí Ẹni mímọ́ Israẹli.

< Osée 11 >