< Habacuc 3 >

1 Seigneur, j'ai entendu Ta voix, et j'ai eu crainte.
Àdúrà wòlíì Habakuku gẹ́gẹ́ bí sígónótì. Ohun èlò orin.
2 J'ai considéré Tes œuvres, et je me suis extasié. Entre deux animaux Tu Te manifestes; quand les années seront proches, on Te connaîtra; quand les temps seront venus, Tu apparaîtras; quand mon âme est troublée de Ta colère, souviens-Toi de Ta miséricorde.
Olúwa mo tí gbọ́ ohùn rẹ; ẹ̀rù sì ba mi fún iṣẹ́ rẹ Olúwa sọ wọn di ọ̀tún ní ọjọ́ ti wa, ní àkókò tiwa, jẹ́ kó di mí mọ̀; ni ìbínú, rántí àánú.
3 Dieu viendra de Théman, et le Saint de la montagne ténébreuse de Pharan. Sa vertu est le vêtement des cieux, et la terre est pleine de Sa louange.
Ọlọ́run yóò wa láti Temani, ibi mímọ́ jùlọ láti òkè Parani ògo rẹ̀ sí bo àwọn ọ̀run, ilé ayé sì kún fún ìyìn rẹ.
4 Sa splendeur sera comme la lumière; Il a dans Sa main des cornes (de puissance), et de la force Il a fait un puissant amour.
Dídán rẹ sí dàbí ìmọ́lẹ̀ oòrùn ìtànṣán ìmọ́lẹ̀ jáde wa láti ọwọ́ rẹ, níbi tí wọn fi agbára rẹ̀ pamọ́ sí.
5 Devant Sa face ira une parole; elle cheminera dans les plaines; sur Ses pieds
Àjàkálẹ̀-ààrùn ń lọ ni iwájú rẹ; ìyọnu sí ń tọ ẹsẹ̀ rẹ lọ.
6 Il S'est dressé, et la terre en a tremblé; Il a regardé, et les nations se sont évanouies. les montagnes ont été violemment agitées; les collines se sont fendues, sous les pas de Sa marche éternelle.
Ó dúró, ó sì mi ayé; ó wò, ó sì mú àwọn orílẹ̀-èdè wárìrì a sì tú àwọn òkè ńlá ayérayé ká, àwọn òkè kéékèèké ayérayé sì tẹríba: ọ̀nà rẹ ayérayé ni.
7 À cause des troubles, j'ai vu les tentes des Éthiopiens renversées; les tentes de la terre de Madian seront aussi frappées d'épouvante.
Mo rí àgọ́ Kuṣani nínú ìpọ́njú àti àwọn ibùgbé Midiani nínú ìrora.
8 Seigneur, est-ce contre les fleuves que Tu es irrité? Est-ce que Ta colère s'en prend aux fleuves? Attaques-Tu la mer? Car Tu es monté sur Ton char, et Tes chevaux amènent le salut.
Ǹjẹ́ ìwọ ha ń bínú sí àwọn odò nì, Olúwa? Ǹjẹ́ ìbínú rẹ wa lórí àwọn odò ṣíṣàn bí? Ìbínú rẹ ha wá sórí Òkun tí ìwọ fi ń gun ẹṣin, àti kẹ̀kẹ́ ìgbàlà rẹ?
9 Tu as fortement tendu ton arc contre les sceptres, dit le Seigneur. le cours des fleuves sera déchiré.
A ṣí ọrun rẹ sílẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí ìbúra àwọn ẹ̀yà, àní ọ̀rọ̀ rẹ, ìwọ sì fi odò pín ilẹ̀ ayé.
10 Les peuples Te verront, Seigneur, et ils auront des douleurs comme celles de l'enfantement. Quand Tu détruis la voie par une inondation, l'abîme a fait entendre sa voix, et il a élevé ses vagues contre Toi.
Àwọn òkè ńlá ri ọ wọn sì wárìrì àgbàrá òjò ń sàn án kọjá lọ; ibú ń ké ramúramù ó sì gbé irú omi sókè.
11 Le soleil s'est levé; la lune s'est tenue au lieu qui lui est prescrit: Tes rayons s'avanceront dans la lumière, à la lueur des éclairs qui jaillissent de Tes armes.
Òòrùn àti Òṣùpá dúró jẹ́ẹ́jẹ́ ni ibùgbé wọn, pẹ̀lú ìmọ́lẹ̀ ọfà rẹ ni wọn yára lọ, àti ni dídán ọ̀kọ̀ rẹ ti ń kọ mànà.
12 Par Tes menaces, Tu abaisses la terre, et dans Ton courroux Tu abats les nations.
Ní ìrunú ni ìwọ rin ilẹ̀ náà já, ní ìbínú ni ìwọ tí tẹ́ àwọn orílẹ̀-èdè rẹ.
13 Tu es venu pour le salut de Ton peuple, pour sauver Ton Christ; Tu enverras la mort sur la tête des impies; Tu les as chargés de chaînes jusqu'au cou.
Ìwọ jáde lọ láti tú àwọn ènìyàn rẹ sílẹ̀, àti láti gba ẹni àmì òróró rẹ là, Ìwọ ti run àwọn olórí kúrò nínú ilẹ̀ àwọn ènìyàn búburú, ó sì bọ ìhámọ́ra rẹ láti orí de ẹsẹ̀.
14 Tu as frappé de stupeur les bêtes des puissants; ils en trembleront; ils laisseront voir leur frein en ouvrant la bouche, comme un pauvre qui mange en se cachant.
Pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ kí ó fi gún orí rẹ nígbà tí àwọn jagunjagun rẹ̀ jáde láti tú wá ká, ayọ̀ wọn sì ni láti jẹ tálákà run ní ìkọ̀kọ̀.
15 Et, monté sur Tes chevaux, Tu es entré dans la mer, et ils en ont troublé l'eau profonde.
Ìwọ fi ẹṣin rẹ rìn Òkun já, ó sì da àwọn omi ńlá ru.
16 J'ai veillé, et mes entrailles ont frémi au son de la prière de mes lèvres, et l'effroi est entré dans mes os, et tout mon être a été bouleversé. Je me reposerai au jour de l'affliction, et je monterai chez le peuple où je suis passager.
Mo gbọ́, ọkàn mi sì wárìrì, ètè mi sì gbọ̀n sí ìró náà; ìbàjẹ́ sì wọ inú egungun mi lọ, ẹsẹ̀ mi sì wárìrì, mo dúró ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́ fún ọjọ́ ìdààmú láti de sórí àwọn ènìyàn tó ń dojúkọ wá.
17 Car alors le figuier ne portera pas de fruits; il n'y aura pas de raisin à la vigne; l'œuvre de l'olivier sera trompeuse, et les champs ne produiront pas de nourriture. Les brebis manqueront de fourrage, et il n'y aura pas de bœufs à la crèche.
Bí igi ọ̀pọ̀tọ́ ko tilẹ̀ tanná, tí èso kò sí nínú àjàrà; tí igi olifi ko le so, àwọn oko ko sì mú oúnjẹ wá; tí a sì ké agbo ẹran kúrò nínú agbo, tí kò sì sí ọwọ́ ẹran ni ibùso mọ́,
18 Pour moi, je tressaillirai dans le Seigneur; je mettrai ma joie en Dieu, mon Sauveur.
síbẹ̀, èmi ó láyọ̀ nínú Olúwa, èmi yóò sí máa yọ nínú Ọlọ́run ìgbàlà mi.
19 Le Seigneur mon Dieu est ma force; Il placera mes pieds sur une base inébranlable; Il m'a fait monter sur les hautes cimes, pour chanter en Son honneur un chant de triomphe.
Olúwa Olódùmarè ni agbára mi, òun yóò sí ṣe ẹsẹ̀ mi bí ẹsẹ̀ abo àgbọ̀nrín, yóò sí mú mi rìn lórí ibi gíga. Sí olórí akọrin lórí ohun èlò orin olókùn mi.

< Habacuc 3 >