< Habacuc 1 >
1 Vision d'Habacuc, le prophète.
Àsọtẹ́lẹ̀ tí wòlíì Habakuku rí.
2 Jusques à quand, Seigneur, crierai-je sans que Tu m'écoutes? Jusques à quand Te crierai-je que l'on me fait violence? N'en me sauveras-Tu pas?
Olúwa, èmi yóò ti ké pẹ́ tó fún ìrànlọ́wọ́, ṣùgbọ́n ti ìwọ kò ni fetí sí mi? Tàbí kígbe sí ọ ní ti, “Ìwà ipá!” Ṣùgbọ́n tí ìwọ kò sì gbàlà?
3 Pourquoi m'as-Tu affligé et m'as-Tu donné la douleur de voir la misère et l'impiété? Je suis en procès, et le juge reçoit des présents.
Èéṣe tí ìwọ fi mú mi rí àìṣedéédéé? Èéṣe tí ìwọ sì fi ààyè gba ìwà ìkà? Ìparun àti ìwà ipá wà ní iwájú mi; ìjà ń bẹ, ìkọlù sì wà pẹ̀lú.
4 À cause de cela, la loi a été déchirée, et le jugement n'arrivera pas à bonne fin, parce que l'impie opprime le juste, et la sentence sera torturée.
Nítorí náà, òfin di ohun àìkàsí, ìdájọ́ òdodo kò sì borí. Àwọn ẹni búburú yí àwọn olódodo ká, nítorí náà ni ìdájọ́ òdodo ṣe yí padà.
5 Voyez, contempteurs de la loi, regardez et admirez ces merveilles, et soyez anéantis: car, de vos jours, Je vais faire une œuvre que vous ne croirez pas, quoiqu'on vous l'annonce.
“Ẹ wo inú àwọn kèfèrí, ki ẹ sí wòye, kí háà kí ó sì ṣe yin gidigidi. Nítorí èmi ó ṣe ohun kan ní ọjọ́ yín tí ẹ̀yin kò jẹ́ gbàgbọ́, bí a tilẹ̀ sọ fún yin.
6 Voilà que Je vais susciter les Chaldéens, nation cruelle et rapide, qui marche sur les plaines de la terre, pour prendre possession de tentes qui ne sont point les siennes.
Nítorí pé, èmi yóò gbé àwọn ara Babeli dìde, àwọn aláìláàánú àti onínú-fùfù ènìyàn tí ó rin gbogbo ilẹ̀ ayé já láti fi agbára gbà àwọn ibùgbé tí kì í ṣe tiwọn.
7 Redoutable et fameuse, c'est d'elle que le jugement procédera; tout son butin proviendra d'elle-même.
Wọn jẹ́ ènìyàn ti a bẹ̀rù, tí a sì páyà, ìdájọ́ wọn, àti ọláńlá wọn, yóò máa ti inú wọn jáde.
8 Et ses chevaux s'élanceront plus agiles que le léopard; ils courront plus rapides que les loups de l'Arabie. Et ses cavaliers sortiront à cheval, et ils prendront de loin leur élan, et ils se déploieront comme l'aigle ardent à dévorer sa proie.
Ẹṣin wọn yára ju ẹkùn lọ, wọ́n sì gbóná jú ìkookò àṣálẹ́ lọ àwọn ẹlẹ́ṣin wọn yóò sí tan ara wọn ká; wọn yóò sì wá láti ọ̀nà jíjìn réré, wọn yóò sí fò bí ẹyẹ igún tí ń wá láti jẹrun,
9 La perdition tombera sur les impies qui leur feront face, et leur tiendront tête; et l'envahisseur emmènera des captifs aussi nombreux que les grains de sable.
gbogbo wọn sì wà fún ìwà ipá ìwò ojú wọn yóò sì wá síwájú; wọn sì ko ìgbèkùn jọ bí iyanrìn.
10 Et il se raillera des rois, et les tyrans seront pour lui des jouets, et il rira de chaque forteresse, et il l'entourera de levées de terre, et il la prendra de force.
Wọn ó si máa fi àwọn ọba ṣẹ̀sín wọn ó sì tún kẹ́gàn àwọn aládé. Wọn yóò sì fi gbogbo ìlú odi alágbára nì rẹ́rìn-ín; nítorí pé, wọn yóò ko erùpẹ̀ jọ, wọn yóò sì gbà á.
11 Alors son esprit changera, et il se transformera, et il fera pitié; telle est la force de mon Dieu.
Nígbà náà ni inú rẹ̀ yóò yípadà, yóò sì rékọjá, yóò si ṣẹ̀ ní kíka agbára rẹ̀ yìí sí iṣẹ́ òrìṣà rẹ̀.”
12 Seigneur, mon Dieu et mon Saint, n'es-Tu pas dès le commencement? Est-ce que nous mourrons? Tu as établi ces choses pour le jugement, et Tu m'as formé, Seigneur, pour annoncer Ton châtiment.
Olúwa, ǹjẹ́ láti ayérayé kọ ni ìwọ tí wà? Olúwa Ọlọ́run mi. Ẹni mímọ́ mi, àwa kì yóò kú Olúwa, ìwọ tí yàn wọn fún ìdájọ́; Ọlọ́run alágbára, ìwọ tí fi ẹsẹ̀ wọn múlẹ̀ fún ìbáwí.
13 L'œil du Seigneur est trop dur pour regarder le mal et s'arrêter sur les labeurs de l'affliction. Pourquoi, Seigneur, considères-Tu ceux qui Te méprisent? Pourquoi gardes-Tu le silence quand l'impie dévore le juste?
Ojú rẹ mọ́ tónítóní láti wo ibi; ìwọ kò le gbà ìwà ìkà nítorí kí ni ìwọ ṣe gba àwọn alárékérekè láààyè? Nítorí kí ni ìwọ ṣe dákẹ́ nígbà tí ẹni búburú ń pa ẹni tí i ṣe olódodo ju wọn lọ run?
14 Traites-Tu les hommes comme les poissons de la mer, ou comme les reptiles qui n'ont point de guide?
Ìwọ sì tí sọ ènìyàn di bí ẹja inú Òkun, bí ohun tí ń rákò tí wọn ko ni alákòóso.
15 Il a pris toute l'espèce à l'hameçon; il en a tiré un avec le filet; il en a enfermé un autre dans sa nasse. À cause de cela, il sera plein d'allégresse, et se réjouira en son cœur.
Àwọn ènìyàn búburú fi àwọ̀n wọn gbé wọn sókè ó sì kó wọn jọ nínú àwọ̀n ńlá rẹ̀; nítorí náà, ó dunnú, ó sì yọ̀ pẹ̀lú.
16 À cause de cela, il sacrifiera à sa nasse, il encensera son filet, parce qu'avec leur aide il aura engraissé sa part, et recueilli des aliments de choix.
Nítorí náà, ó rú ẹbọ sí àwọ̀n rẹ̀, ó sì ń sun tùràrí fún àwọ̀n ńlá rẹ̀ nítorí pẹ̀lú àwọ̀n rẹ̀ ni ó fi ń gbé ní ìgbádùn tí ó sì ń gbádùn pẹ̀lú oúnjẹ tí ó bá wù ú.
17 Et, à cause de cela, il jettera encore son filet, et ne se fera jamais faute de tuer les nations.
Ǹjẹ́ wọn yóò ha máa pa àwọ̀n wọn mọ́ ní òfìfo bí, tí wọn yóò sì pa orílẹ̀-èdè run láìsí àánú?