< Genèse 10 >

1 Voici les générations des fils de Noé: Sem, Cham et Japhet; des fils leur naquirent après le déluge.
Èyí ni ìran àwọn ọmọ Noa: Ṣemu, Hamu àti Jafeti, tí àwọn náà sì bí ọmọ lẹ́yìn ìkún omi.
2 Fils de Japhet: Gomer, Magog, Madaï, Javan, Elisa, Thubal, Mosoch et Thiras.
Àwọn ọmọ Jafeti ni: Gomeri, Magogu, Madai, Jafani, Tubali, Meṣeki àti Tirasi.
3 Fils de Gomer: Ascenez, Riphat, et Thogorma.
Àwọn ọmọ Gomeri ni: Aṣkenasi, Rifati àti Togarma.
4 Fils de Javan: Elisa, Tharsis, Cettim et Dodanim.
Àwọn ọmọ Jafani ni: Eliṣa, Tarṣiṣi, Kittimu, àti Dodanimu.
5 Ceux-ci sont les pères des gentils, qui se partagèrent les îles et les eurent pour territoire, chacun selon sa langue, par tribus, par nations.
(Láti ọ̀dọ̀ àwọn wọ̀nyí ni àwọn tí ń gbé agbègbè tí omi wà ti tàn ká agbègbè wọn, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, ìdílé wọn ní orílẹ̀-èdè wọn, olúkúlùkù pẹ̀lú èdè tirẹ̀).
6 Fils de Cham: Chus, Mesraïm, Phuth et Chanaan.
Àwọn ọmọ Hamu ni: Kuṣi, Ejibiti, Puti àti Kenaani.
7 Fils de Chus: Saba, Hevila, Sabatha, Regma et Sabathaca. Fils de Regma: Saba et Dadan.
Àwọn ọmọ Kuṣi ni: Seba, Hafila, Sabta, Raama, àti Sabteka. Àwọn ọmọ Raama ni: Ṣeba àti Dedani.
8 Et Chus engendra Nemrod: celui-ci commença à être puissant sur la terre.
Kuṣi sì bí Nimrodu, ẹni tí ó di alágbára jagunjagun ní ayé.
9 Il était grand chasseur devant le Seigneur; c'est pourquoi l'on dit: Grand chasseur comme Nemrod devant le Seigneur.
Ó sì jẹ́ ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa; nítorí náà ni a ṣe ń wí pé, “Bí Nimrodu, ògbójú ọdẹ níwájú Olúwa.”
10 Le commencement de son royaume fut Babylone, puis il eut Arach, Archad, Chalané, et la terre de Sennaar.
Ìjọba rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ ni Babeli, Ereki, Akkadi, Kalne, gbogbo wọn wà ní ilẹ̀ Ṣinari.
11 De cette terre sortit Assur, qui bâtit Ninive, et la ville de Rhooboth et Chalé,
Láti ilẹ̀ náà ni ó ti lọ sí Asiria, níbi tí ó ti tẹ ìlú Ninefe, Rehoboti àti Kala,
12 Et Ressen, grande ville, entre Ninive et Chalé.
àti Resini, tí ó wà ní àárín Ninefe àti Kala, tí ó jẹ́ ìlú olókìkí.
13 Mesraïm engendra les Ludim, les Ananim, les Laabim, les Nephtuïm,
Ejibiti sì bí Ludimu, Anamimu, Lehabimu, Naftuhimu.
14 Les Phétrusim, les Chasluïm (d'où est sorti Philistin) et les Caphtorins.
Patrusimu, Kasluhimu (láti ọ̀dọ̀ ẹni tí àwọn ará Filistini ti wá) àti àwọn ará Kaftorimu.
15 Chanaan engendra Sidon son premier-né, puis le Hétéen,
Kenaani sì bí Sidoni àkọ́bí rẹ̀, àti Heti.
16 Le Jebuséen, l'Amorrhéen, le Gergéséen,
Àti àwọn ará Jebusi, àti àwọn ará Amori, àti àwọn ará Girgaṣi,
17 L'Evéen, l'Arucéen, l'Asennéen,
àti àwọn ará Hifi, àti àwọn ará Arki, àti àwọn ará Sini,
18 L'Aradien, le Samaréen et l'Amathéen. Après cela, les tribus des Chananéens se dispersèrent.
àti àwọn ará Arfadi, àti àwọn ará Semari, àti àwọn ará Hamati. Lẹ́yìn èyí ni àwọn ẹ̀yà Kenaani tànkálẹ̀.
19 Les limites des Chananéens étaient la côte depuis Sidon jusqu'à Gérara et Gaza; puis elles s'étendirent jusqu'à Sodome et Gomorrhe, et passèrent par Adama et Séboïm jusqu'à Léba.
Ààlà ilẹ̀ àwọn ará Kenaani sì dé Sidoni, lọ sí Gerari títí dé Gasa, lọ sí Sodomu, Gomorra, Adma àti Seboimu, títí dé Laṣa.
20 Tels furent les fils de Cham et leurs tribus, selon leurs langues, par contrées, et par nations.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Hamu, gẹ́gẹ́ bí ẹ̀yà wọn, àti èdè wọn, ní ìpínlẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
21 Sem fut père aussi, et eut Héber de l'un de ses fils, frère de Japhet le plus grand.
A bí àwọn ọmọ fún Ṣemu tí Jafeti jẹ́ ẹ̀gbọ́n rẹ̀ ọkùnrin: Ṣemu sì ni baba gbogbo àwọn ọmọ Eberi.
22 Fils de Sem: Elam, Assur, Arphaxad, Lud, Aran et Caïnan.
Àwọn ọmọ Ṣemu ni: Elamu, Aṣuri, Arfakṣadi, Ludi àti Aramu.
23 Fils d'Aram: Hus, Hul, Gether et Mosoch.
Àwọn ọmọ Aramu ni: Usi, Huli, Geteri àti Meṣeki.
24 Arphaxad engendra Salé, et Salé engendra Héber.
Arfakṣadi sì bí Ṣela, Ṣela sì bí Eberi.
25 D'Héber naquirent deux fils, nommés, l'un Phaleg, parce que de son temps la terre fut partagée, et l'autre Jectan.
Eberi sì bí ọmọ méjì: ọ̀kan ń jẹ́ Pelegi, nítorí ní ìgbà ọjọ́ rẹ̀ ni ilẹ̀ ya; orúkọ arákùnrin rẹ̀ ni Joktani.
26 Or, Jectan engendra Elmodad, Saleph, Asarmoth Jaré,
Joktani sì bí Almodadi, Ṣelefi, Hasarmafeti, Jera.
27 Aduram, Uzal, Décla,
Hadoramu, Usali, Dikla,
28 Abimaël, Saba,
Obali, Abimaeli, Ṣeba.
29 Ophir, Hévila et Jobab: tels furent les fils de Jectan.
Ofiri, Hafila àti Jobabu. Gbogbo àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Joktani.
30 Ils habitèrent depuis Messa jusqu'à Séphar, montagne de l'Orient.
Agbègbè ibi tí wọn ń gbé bẹ̀rẹ̀ láti Meṣa títí dé Sefari, ní àwọn ilẹ̀ tó kún fún òkè ní ìlà-oòrùn.
31 Tels furent les fils de Sem et leurs tribus, selon leurs langues, par contrées et par nations.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Ṣemu gẹ́gẹ́ bí ìdílé wọn, ní èdè wọn, ní ilẹ̀ wọn àti ní orílẹ̀-èdè wọn.
32 Telles furent les tribus des fils de Noé, par familles et nations; et c'est ainsi que les fils de Noé peuplèrent les pays des nations, sur la terre, après le déluge.
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà ọmọ Noa gẹ́gẹ́ bí ìran wọn, ní orílẹ̀-èdè wọn. Ní ipasẹ̀ wọn ni àwọn ènìyàn ti tàn ká ilẹ̀ ayé lẹ́yìn ìkún omi.

< Genèse 10 >