< Ézéchiel 44 >
1 Et l'homme me ramena par le chemin de la porte intérieure du sanctuaire qui regarde l'orient, et elle était fermée.
Lẹ́yìn náà ni ọkùnrin náà mú mi padà lọ sí ibi mímọ́, èyí tí ó kọjú sí ìhà ìlà-oòrùn, ó sì wà ní títì.
2 Et le Seigneur me dit: Cette porte restera fermée, et jamais elle ne sera ouverte, et nul n'y passera; parce que le Seigneur Dieu d'Israël entrera par cette porte, et elle sera fermée pour tout autre.
Olúwa sọ fún mi, “Ẹnu-ọ̀nà yìí ni kí ó wà ní títì. A kò gbọdọ̀ ṣí i sílẹ̀; kò sí ẹni tí o gbọdọ̀ gba ibẹ̀ wọlé. Ó gbọdọ̀ wà ní títì nítorí pé Olúwa Ọlọ́run Israẹli tí gbà ibẹ̀ wọlé.
3 Quant au prince, il s'y assiéra pour manger du pain devant le Seigneur. Il entrera par le chemin de la porte du vestibule, et sortira par cette même porte.
Ọmọ-aládé fúnra rẹ̀ ní o lè jókòó ní ẹnu-ọ̀nà náà kí o sì jẹun níwájú Olúwa. Ó gbọdọ̀ gba ọ̀nà ìloro ẹnu-ọ̀nà wọlé kí ó sì gba ibẹ̀ jáde.”
4 Et l'homme me fit entrer par le chemin de la porte qui regarde l'aquilon devant le temple. Et je regardai, et voilà que le temple était plein de la gloire de Dieu; et je tombai la face contre terre.
Lẹ́yìn náà, ọkùnrin náà mú mi gba ẹnu-ọ̀nà àríwá lọ sí iwájú ilé Ọlọ́run. Mo wò ó mo sì rí ògo Olúwa tí ó kún inú ilé Olúwa, mo sì dojúkọ ilẹ̀.
5 Et le Seigneur me dit: Fils de l'homme, mets en ton cœur, vois de tes yeux, entends de tes oreilles ce que je vais te dire sur les ordonnances du temple du Seigneur et sur ses règlements, et prépare ton cœur à ton entrée dans le temple, et à toutes les issues qui mènent à tous les lieux saints.
Olúwa sì sọ fún mì pé, “Ọmọ ènìyàn, wò dáradára, fetísílẹ̀ dáradára kí o sì fiyèsí ohun gbogbo tí mo sọ fún ọ nípa òfin lórí ilé Olúwa náà. Fiyèsí ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run náà àti gbogbo àbájáde ibi mímọ́.
6 Et tu diras à cette maison qui m'irrite, à la maison d'Israël: Voici ce que dit le Seigneur Dieu: Qu'il vous suffise, maison d'Israël, d'avoir commis tous vos péchés;
Sọ fún ọlọ̀tẹ̀ ilé Israẹli pé, ‘Èyí yìí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: Ìwà ìríra rẹ tí tó gẹ́ẹ́, ìwọ ilé Israẹli!
7 D'avoir introduit parmi vous des fils d'étrangers incirconcis par le cœur, et incirconcis par la chair, pour qu'ils se tinssent dans mon saint des saints, et qu'ils se souillassent quand vous offriez des pains, des chairs et du sang; vous avez transgressé mon alliance par toutes vos iniquités;
Ní àfikún pẹ̀lú gbogbo àwọn ìwà ìríra rẹ tí ó kù, ìwọ mú àwọn àjèjì aláìkọlà àyà àti ara wá sí inú ibi mímọ́ mi, ní lílo ilé mi ní ìlòkulò nígbà tí ìwọ fi oúnjẹ fún mi, ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ìwọ sì ba májẹ̀mú mi jẹ́.
8 Et à la garde de mon sanctuaire vous avez préposé d'autres hommes que les lévites.
Dípò kí ìwọ pa òfin mi mọ́, ìwọ fi àwọn mìíràn sí ibi mímọ́ mi.
9 À cause de cela, voici ce que dit le Seigneur Dieu: Tout fils étranger incirconcis par le cœur et incirconcis par la chair, sera exclu de mon saint des saints, ainsi que tous les fils d'étrangers qui résident au milieu de la maison d'Israël.
Èyí yìí ní Olúwa Olódùmarè wí: Àjèjì aláìkọlà àyà àti ara kò gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi, àti pẹ̀lú àwọn àjèjì tí ń gbé ní àárín àwọn ọmọ Israẹli.
10 Quant aux lévites qui se sont éloignés de moi, lorsque la maison d'Israël s'est égarée loin de moi pour marcher à la suite de ses idoles, ils porteront la peine de leur iniquité.
“‘Àwọn Lefi tí wọn rìn jìnnà kúrò lọ́dọ̀ mi nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli ṣìnà, ti wọ́n sì ṣáko kúrò lọ́dọ̀ mi láti tọ àwọn ère wọn lẹ́yìn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
11 Toutefois ils demeureront dans mes lieux saints pour me servir, comme gardiens des portes du temple et serviteurs dans le temple; ils égorgeront les victimes et les holocaustes pour le peuple, ils se tiendront devant le peuple, prêts à le servir.
Wọn le sìn mi ní ibi mímọ́ mi, kí wọn ṣe ìtọ́jú àwọn ẹnu-ọ̀nà ilé Ọlọ́run, kí wọn sì ṣe ìránṣẹ́ nínú rẹ̀; wọn le pa ẹbọ sísun, ki wọn sì rú ẹbọ fún àwọn ènìyàn, kí wọn sì dúró níwájú àwọn ènìyàn, kí wọ́n sì ṣe ìránṣẹ́ fún wọn.
12 Mais en punition de ce qu'ils ont servi pour lui devant ses idoles, et qu'ils ont attiré sur la maison d'Israël le châtiment de cette iniquité (car c'est pour cela que j'ai levé la main contre elle, dit le Seigneur Dieu);
Ṣùgbọ́n nítorí pé wọn ṣe ìránṣẹ́ fún wọn níwájú àwọn ère wọn, tí wọn sì mu ilé Israẹli ṣubú sínú ẹ̀ṣẹ̀, nítorí náà, Èmi tí búra nípa nína ọwọ́ sókè pé, wọn gbọdọ̀ jèrè ẹ̀ṣẹ̀ wọn, ní Olúwa Olódùmarè wí.
13 Ils ne s'approcheront plus de moi pour être mes prêtres ni pour être employés, soit dans les saints des fils d'Israël, soit dans mon saint des saints. Ils porteront la honte de leurs égarements.
Wọn kò gbọdọ̀ súnmọ́ ọ̀dọ̀ mi láti ṣe ìránṣẹ́ fún mi, gẹ́gẹ́ bí àlùfáà tàbí súnmọ́ nǹkan kan nínú àwọn ohun mímọ́ mi tàbí ẹbọ mi mímọ́ jùlọ; wọn gbọdọ̀ gba ìtìjú ìwà ìríra wọn.
14 On les commettra à la garde du temple en tous les offices et en toutes les choses qu'ils feront.
Síbẹ̀ èmi yóò mu wọn sí ìtọ́jú ilé Ọlọ́run àti gbogbo iṣẹ́ tí a gbọdọ̀ ṣe níbẹ̀.
15 Pour les prêtres lévites, fils de Sadduc, qui ont gardé les offices de mon sanctuaire pendant que la maison d'Israël s'égarait loin de moi, ceux-là s'approcheront de moi pour me servir; ils se tiendront devant ma face pour m'offrir les sacrifices, le sang et la graisse, dit le Seigneur.
“‘Ṣùgbọ́n àwọn àlùfáà, tí ó jẹ́ Lefi àti àwọn ìran Sadoku tí fi tọkàntọkàn ṣe iṣẹ́ ibi mímọ́ mi nígbà tí àwọn Israẹli ṣáko lọ kúrò lọ́dọ̀ mi, wọn gbọdọ̀ súnmọ́ iwájú láti ṣe ìránṣẹ́ ní iwájú mi, láti rú ẹbọ ọ̀rá àti ẹ̀jẹ̀, ni Olúwa Olódùmarè wí.
16 Ceux-là entreront dans mon sanctuaire, ceux-là s'approcheront de ma table pour me servir; et ils garderont mes offices.
Àwọn nìkan ni ó gbọdọ̀ wọ ibi mímọ́ mi; àwọn nìkan ní o gbọdọ̀ súnmọ́ tábìlì mi láti ṣe ìránṣẹ́ ni iwájú mi, ki wọn sì ṣe iṣẹ́ ìsìn mi.
17 Et lorsqu'ils entreront par la porte du parvis intérieur, ils seront revêtus de robes de lin; ils ne porteront point de laine pour me servir, dès qu'ils auront franchi la porte du parvis intérieur.
“‘Nígbà ti wọ́n wọ àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú, wọn yóò wọ ẹ̀wù ọ̀gbọ̀, wọn kò gbọdọ̀ wọ aṣọ onírun nígbà tí wọ́n bá ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́ ní àwọn ẹnu-ọ̀nà àgbàlá ti inú tàbí ni inú ilé Ọlọ́run.
18 Et ils auront sur la tête des mitres de lin, et ils auront autour des reins des caleçons de lin; mais ils n'en serreront pas la ceinture.
Wọ́n yóò sì dé fìlà ọ̀gbọ̀ sí orí wọn àti ṣòkòtò ọ̀gbọ̀ sí ìdí wọn. Wọn kò sì gbọdọ̀ wọ ohunkóhun tí yóò mú wọn làágùn.
19 Et lorsqu'ils sortiront du parvis intérieur pour rejoindre le peuple, ils ôteront les robes avec lesquelles ils font leur service liturgique, et ils les déposeront dans les chambres du sanctuaire; ils mettront d'antres robes et ne sanctifieront pas le peuple avec leurs propres robes.
Nígbà tí wọ́n bá lọ sì àgbàlá òde níbi tí àwọn ènìyàn wà, wọn gbọdọ̀ bọ́ ẹ̀wù tí wọ́n fi ń ṣiṣẹ́ ìránṣẹ́, ki wọn sì fi wọn sílẹ̀ sí àwọn yàrá mímọ́ náà, kí wọn kí ó sì wọ ẹ̀wù mìíràn, wọn kì yóò sì fi ẹ̀wù wọn sọ àwọn ènìyàn di mímọ́.
20 Et ils ne se raseront point les cheveux, et ils ne les épileront point, et ils se couvriront soigneusement la tête.
“‘Wọn kò gbọdọ̀ fá irun, wọn kò sì gbọdọ̀ jẹ́ kí irun wọn gùn, ṣùgbọ́n wọn gbọdọ̀ jẹ́ kí irun orí wọn wà ní gígẹ̀.
21 Et nul prêtre ne boira de vin lorsqu'il devra entrer dans le parvis intérieur.
Àlùfáà kankan kò gbọdọ̀ mu ọtí nígbà tí ó bá wọ àgbàlá tí inú.
22 Et ils ne prendront pour femmes ni veuve ni épouse répudiée, mais des vierges de la race d'Israël; toutefois, s'il se trouve qu'une femme soit veuve d'un prêtre, ils pourront l'épouser.
Wọn ko gbọdọ̀ fẹ́ opó ni ìyàwó, wọn kò sì gbọdọ̀ kọ ìyàwó wọn sílẹ̀, wọ́n lè fẹ́ àwọn ọmọbìnrin ti kò tí i mọ ọkùnrin rí, tí ó sì jẹ́ ìran àwọn ọmọ Israẹli, tàbí kí wọn fẹ́ àwọn opó àlùfáà.
23 Et ils instruiront mon peuple à distinguer le sacré du profane, et le pur de l'impur.
Wọn yóò sì fi ìyàtọ̀ tí ó wà láàrín mímọ́ àti àìmọ́ kọ́ àwọn ènìyàn mi, wọn yóò sì fihàn wọ́n bi wọn yóò ṣe dá aláìmọ́ mọ̀ yàtọ̀ sí mímọ́.
24 Et dans les causes où il y aura du sang ils auront mission de juger; et ils feront justice selon mes ordonnances; ils jugeront selon mes jugements; ils garderont mes lois et mes préceptes concernant toutes les fêtes, et ils sanctifieront mes sabbats.
“‘Nínú èyíkéyìí èdè-àìyedè, àwọn àlùfáà ní yóò dúró gẹ́gẹ́ bí onídàájọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin mi. Wọ́n ní láti pa àwọn òfin àti àṣẹ mi mọ́ ní gbogbo àjọ̀dún tí a yàn, wọn sì gbọdọ̀ ya ọjọ́ ìsinmi mi ní mímọ́.
25 Ils n'entreront point auprès d'un homme mort, de peur d'être souillés; néanmoins le prêtre se souillera sans devenir impur, si le mort est son père, sa mère, son fils, sa fille, son frère ou sa sœur non mariée.
“‘Àlùfáà kò gbọdọ̀ sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́ nípa sísún mọ́ òkú ènìyàn; ṣùgbọ́n ti òkú ènìyàn yẹn bá jẹ́ baba tàbí ìyá rẹ̀, àbúrò rẹ̀ ọkùnrin tàbí àbúrò rẹ̀ obìnrin ti kò i ti lọ́kọ, nígbà náà o le sọ ara rẹ̀ di aláìmọ́.
26 Et lorsqu'un prêtre aura été purifié, on lui comptera encore sept jours.
Lẹ́yìn ìwẹ̀nùmọ́ rẹ̀, ki òun kí ó dúró fún ọjọ́ méje.
27 Et quel que soit le jour où il rentrera dans le parvis intérieur, pour le service du sanctuaire, il offrira une victime propitiatoire, dit le Seigneur Dieu.
Ní ọjọ́ ti yóò wọ àgbàlá ti inú ni ibi mímọ́ láti ṣe ìránṣẹ́ ibi mímọ́, ni kí òun kí ó rú ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ ni Olúwa Olódùmarè wí.
28 Et voici quel sera leur héritage: c'est moi qui serai leur héritage, et il ne leur sera point donné de partage parmi les fils d'Israël; car c'est moi qui serai leur partage.
“‘Èmi ni yóò jẹ́ ogún kan ṣoṣo tí àwọn àlùfáà yóò ní. Ẹ kì yóò fún wọn ni ìpín kankan ní Israẹli, Èmi ni yóò jẹ́ ìní wọn.
29 Et ils mangeront les victimes: celles pour le péché, celles pour l'inadvertance; et toute part réservée en Israël leur appartiendra,
Wọn yóò jẹ ọrẹ ẹbọ jíjẹ, ọrẹ ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀ àti ọrẹ ẹbọ ìrékọjá; gbogbo ohun tí a bá yà sọ́tọ̀ fún Olúwa ni Israẹli ni yóò jẹ́ tiwọn.
30 Les prémices de toutes choses, les premiers-nés de tous les troupeaux et toutes les parts réservées. Les prêtres auront de toutes vos prémices, et vous donnerez aux prêtres tous vos premiers fruits pour attirer les bénédictions sur vos demeures.
Èyí tí ó dára jùlọ nínú gbogbo àkọ́so èso àti ọrẹ yín yóò jẹ́ ti àwọn àlùfáà. Ẹ ó sì fi àkọ́pò ìyẹ̀fun yín fún wọn kí ìbùkún lè wà lórí gbogbo ilé yín.
31 Et les prêtres ne mangeront, parmi les oiseaux ou le bétail, ni corps mort, ni animal pris par d'autres bêtes.
Àwọn àlùfáà kì yóò jẹ́ ohunkóhun bí i ẹyẹ tàbí ẹranko, tí ó ti kú fúnra rẹ̀ tàbí èyí ti ẹranko ńlá fàya.