< Daniel 9 >
1 En la première année du règne de Darius, fils d'Assuérus, de la race des Mèdes, qui régna sur l'empire des Chaldéens,
Ní ọdún kìn-ín-ní Dariusi ọmọ Ahaswerusi, ẹni tí a bí ní Media, òun ló jẹ ọba lórí ìjọba Babeli.
2 Moi, Daniel, je compris, au moyen des livres, le nombre des années que la parole du Seigneur avait fait connaître à Jérémie le prophète, sur le temps que devait durer la désolation de Jérusalem, et qui devait être de soixante-dix années.
Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba rẹ̀, èmi Daniẹli fi iyè sí i láti inú ìwé, gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ Olúwa tí wòlíì Jeremiah, wá pé, àádọ́rin ọdún ni Jerusalẹmu yóò fi wà ní ahoro.
3 Et je tournai mon visage vers le Seigneur mon Dieu, pour l'implorer et le prier, en jeûnant, et revêtu d'un cilice.
Nígbà náà, ni mo yípadà sí Olúwa Ọlọ́run, mo bẹ̀ ẹ́ pẹ̀lú àdúrà àti ẹ̀bẹ̀, pẹ̀lú àwẹ̀, aṣọ ọ̀fọ̀ àti eérú.
4 Et je fis ma prière au Seigneur mon Dieu, et je lui rendis gloire, et je dis: Seigneur, Dieu grand et admirable, qui gardez votre alliance, et réservez votre miséricorde en faveur de ceux qui vous aiment et observent vos commandements;
Mo gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run mi, mo sì jẹ́wọ́ wí pé: “Ìwọ Olúwa, Ọlọ́run tí ó tóbi, tí ó sì ní ẹ̀rù, ẹni tí ń pa májẹ̀mú ìfẹ́ mọ́, pẹ̀lú àwọn tí ó ní ìfẹ́ rẹ̀ àti àwọn tí ó ń pa àwọn òfin rẹ̀ mọ́.
5 Nous avons péché; nous avons commis l'injustice et l'iniquité; nous nous sommes retirés de vous; nous avons dévié de vos ordonnances et de vos jugements,
Àwa ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú. Àwa ti hu ìwà búburú, a sì ti ṣe ọ̀tẹ̀, a ti yí padà kúrò nínú àwọn àṣẹ àti àwọn ìlànà rẹ̀.
6 Et nous n'avons point écouté vos serviteurs les prophètes, qui, en votre nom, parlaient à nos rois, à nos princes, à nos pères et à tout le peuple de la terre.
Àwa kò fetí sí àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ, ẹni tí ó sọ̀rọ̀ ní orúkọ rẹ sí àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé àti àwọn baba wa, àti sí gbogbo ènìyàn ilẹ̀ náà.
7 À vous, Seigneur, est la justice; à nous la honte au visage, comme aujourd'hui à tout homme de Juda, à tout habitant de Jérusalem, à tout Israël, soit près d'ici, soit au loin, en toute région où vous les avez dispersés à cause des prévarications qu'ils ont commises.
“Olúwa ìwọ ni olódodo, ṣùgbọ́n báyìí ìtìjú dé bá àwọn ènìyàn Juda, àwọn ènìyàn Jerusalẹmu àti gbogbo Israẹli ní gbogbo orílẹ̀-èdè tí ìwọ ti fọ́n wa ká sí nítorí àìṣòótọ́ ọ wa sí ọ.
8 En vous, Seigneur, est notre justice; à nous la honte au visage, à nous, à nos rois, à nos princes et à nos pères; car nous avons tous péchés contre vous.
Háà! Olúwa, àwa àti àwọn ọba wa, àwọn ọmọ-aládé, àti àwọn baba wa, ìtìjú dé bá wa nítorí àwa ti dẹ́ṣẹ̀ sí ọ.
9 À vous, Seigneur notre Dieu, les miséricordes et le pardon; car nous nous sommes retirés de vous,
Olúwa Ọlọ́run wa ní àánú, ó sì ń dáríjì, bí àwa tilẹ̀ ti ṣe ọ̀tẹ̀ sí i;
10 Et nous n'avons point écouté la voix du Seigneur notre Dieu, pour marcher dans les lois qu'il nous a données, face à face, par les mains de ses serviteurs les prophètes.
àwa kò gbọ́rọ̀ sí Olúwa Ọlọ́run wa, a kò sì pa àwọn òfin rẹ mọ́, èyí tí ó fún wa nípasẹ̀ àwọn wòlíì ìránṣẹ́ rẹ̀.
11 Tout Israël a transgressé votre loi; il s'est détourné tout entier, pour ne pas entendre votre parole. Et votre malédiction est tombée sur nous, ainsi que l'imprécation écrite dans la loi de Moise, serviteur de Dieu, parce que nous avons péché contre vous.
Gbogbo Israẹli ti ṣẹ̀ sí òfin rẹ, wọ́n ti yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ, wọ́n kọ̀ láti ṣe ìgbọ́ràn sí ọ. “Nígbà náà ni ègún àti ìdájọ́ tí a kọ sílẹ̀ pẹ̀lú ìbúra nínú òfin Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run dà sórí i wa, nítorí tí àwa ti sẹ̀ sí ọ.
12 Et Dieu a confirmé ses paroles prononcées contre nous et contre les juges qui nous jugeaient, et qui ont amené sur nous de si grands maux, que jamais rien sous le ciel n'advint comme ce qui est advenu à Jérusalem;
Ìwọ ti mú ọ̀rọ̀ tí o sọ sí wa sẹ àti lórí àwọn alákòóso wa, nípa mímú kí ibi ńlá bá wa, irú èyí tí kò tí ì ṣẹlẹ̀ rí lábẹ́ ọ̀run, bí ó ti ṣẹlẹ̀ sí Jerusalẹmu yìí.
13 Comme il est écrit en la loi de Moïse: Tous ces maux sont arrivés sur nous, et nous n'avons point prié devant la face du Seigneur notre Dieu, pour qu'il nous retirât de nos iniquités, et nous fit comprendre toute sa vérité.
Bí a ti kọ ọ́ sínú òfin Mose bẹ́ẹ̀ ni gbogbo ibi yìí ti dé bá wa, síbẹ̀ a kò bẹ̀bẹ̀ fún ojúrere Olúwa Ọlọ́run wa, nípa yíyí padà kí a kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ wa kí a sì mọ òtítọ́ rẹ.
14 Mais le Seigneur a veillé sur nous, et il a amené sur nous ces maux, parce que le Seigneur notre Dieu est juste en toutes ses œuvres, et que nous n'avions point écouté sa voix.
Olúwa kò jáfara láti mú ibi náà wá sórí wa, nítorí olódodo ni Olúwa Ọlọ́run wa nínú u gbogbo ohun tí ó ń ṣe; síbẹ̀ àwa kò ṣe ìgbọ́ràn sí i.
15 Et maintenant, Seigneur notre Dieu, qui par votre main puissante avez délivré votre peuple de la terre d'Égypte, et qui vous êtes fait alors un nom comme aujourd'hui, nous avons péché, nous avons commis l'iniquité!
“Ní ìsinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó mú àwọn ènìyàn rẹ̀ jáde láti ilẹ̀ Ejibiti wá, pẹ̀lú ọwọ́ agbára, tí ó fún ara rẹ̀ ní orúkọ tí ó wà títí di òní, a ti ṣẹ̀, a sì ti ṣe búburú.
16 Seigneur, votre miséricorde est pour tous; que votre indignation et votre colère se détourne de votre ville de Jérusalem et de votre montagne sainte; car nous avons péché, et à cause de nos iniquités et de celles de nos pères, Jérusalem et votre peuple sont devenus un sujet d'opprobre pour tous ceux qui nous entourent.
Olúwa, ní ìbámu pẹ̀lú ìwà òdodo rẹ, yí ìbínú àti ìrunú rẹ padà kúrò ní Jerusalẹmu ìlú u rẹ, òkè mímọ́ rẹ. Ẹ̀ṣẹ̀ wa àti àìṣedéédéé àwọn baba wa ti mú Jerusalẹmu àti ènìyàn rẹ di ẹ̀gàn fún gbogbo àwọn tí ó yí wọn ká.
17 Et maintenant, Seigneur notre Dieu, écoutez la prière de votre serviteur et ses supplications; faites briller votre face dans votre sanctuaire délaissé; faites-le pour vous, Seigneur!
“Nísinsin yìí, Ọlọ́run wa, gbọ́ àdúrà àti ẹ̀bẹ̀ ìránṣẹ́ rẹ, nítorí i tìrẹ Olúwa, fi ojú àánú wo ibi mímọ́ rẹ tí ó ti dahoro.
18 Inclinez votre oreille, Seigneur mon Dieu, et exaucez-nous; ouvrez les yeux, et voyez notre anéantissement et celui de la cité à laquelle était donné votre nom; car ce n'est point dans l'attente de vos jugements que nous jetons devant vous notre cri de pitié, mais en vue de vos abondantes miséricordes, O Seigneur.
Tẹ́ etí rẹ sílẹ̀, Ọlọ́run, kí o gbọ́; ya ojú rẹ sílẹ̀, kí o sì wo ìdahoro ìlú tí a ń fi orúkọ rẹ pè. Àwa kò gbé ẹ̀bẹ̀ wa kalẹ̀ níwájú u rẹ nítorí pé a jẹ́ olódodo, bí kò ṣe nítorí àánú ńlá rẹ.
19 Exaucez-moi, Seigneur; apaisez-vous, Seigneur; aimez-moi, Seigneur: ne différez pas, ô mon Dieu, pour l'amour de vous-même; car cette cité et ce peuple sont ceux à qui a été donné votre nom.
Olúwa, fetísílẹ̀! Olúwa, dáríjì! Olúwa, gbọ́ kí o sì ṣe é! Nítorí i tìrẹ, Ọlọ́run mi, má ṣe pẹ́ títí, nítorí ìlú rẹ àti àwọn ènìyàn rẹ ń jẹ́ orúkọ mọ́ ọ lára.”
20 Et comme je parlais encore, comme je priais, et que je confessais mes péchés et les péchés d'Israël, mon peuple; comme je jetais en face du Seigneur mon Dieu mon cri de pitié pour la montagne sainte;
Bí mo ṣe ń sọ̀rọ̀, tí mo sì ń gba àdúrà, tí mo ń jẹ́wọ́ ẹ̀ṣẹ̀ mi àti ẹ̀ṣẹ̀ àwọn Israẹli ènìyàn mi, tí mo sì ń mú ẹ̀bẹ̀ mi tọ Olúwa Ọlọ́run mi nítorí òkè mímọ́ rẹ.
21 Tandis que je parlais encore, voilà que l'homme Gabriel, qui m'était apparu au commencement de ma vision, vint en volant, et me toucha vers l'heure du sacrifice du soir.
Bí mo ṣe ń gba àdúrà náà lọ́wọ́, Gabrieli ọkùnrin tí mo rí nínú ìran ìṣáájú, yára kánkán wá sí ọ̀dọ̀ mi ní àkókò ẹbọ àṣálẹ́.
22 Et il m'ouvrit l'intelligence, et il me parla et me dit: Daniel, je suis venu pour t'apporter l'intelligence.
Ó jẹ́ kí ó yé mi, ó sì wí fún mi pé, “Daniẹli, mo wá láti jẹ́ kí o mọ̀ kí o sì ní òye.
23 Au commencement de ta prière, un ordre m'est venu, et je suis venu pour t'instruire; car tu es l'homme des désirs, dit-il. Réfléchis donc à ma parole et comprends ta vision.
Bí o ṣe bẹ̀rẹ̀ sí nígbà àdúrà, a fún ọ ní ìdáhùn kan, èyí tí mo wá láti sọ fún ọ, nítorí ìwọ jẹ́ àyànfẹ́ gidigidi. Nítorí náà, gba ọ̀rọ̀ náà yẹ̀ wò kí ìran náà sì yé ọ:
24 Soixante-dix semaines ont été assignées à ton peuple et à la cité sainte, pour que le péché soit à sa fin, que les péchés soient abolis, que les iniquités soient effacées et expiées, que l'éternelle justice soit ramenée, que le sceau soit mis à la vision et au prophète, et que le Saint des saints soit marqué de l'onction.
“Àádọ́rin ọ̀sẹ̀ ni a pàṣẹ fún àwọn ènìyàn rẹ àti fún àwọn ìlú mímọ́ rẹ láti parí ìrékọjá, láti fi òpin sí ẹ̀ṣẹ̀, láti ṣe ètùtù sí ìwà búburú, láti mú òdodo títí ayé wá, láti ṣe èdìdì ìran àti wòlíì àti láti fi òróró yan Ibi Mímọ́ Jùlọ.
25 Sache donc et comprends qu'à partir de l'ordre qui sera donné de parler et de rebâtir Jérusalem, jusqu'au roi Christ, il y aura sept semaines et soixante-deux semaines; et l'ancien temps reviendra, les places et les remparts seront relevés, et les temps accomplis.
“Nítorí náà, mọ èyí pé, láti ìgbà tí a ti gbé ọ̀rọ̀ náà jáde wí pé kí a tún Jerusalẹmu ṣe, kí a sì tún kọ́, títí dé ìgbà ọmọ-aládé, ẹni òróró náà, alákòóso wa yóò fi dé, ó jẹ́ ọ̀sẹ̀ méje àti ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó sì tún ìgboro àti yàrá rẹ̀ mọ, ṣùgbọ́n ní àkókò wàhálà ni.
26 Et après les soixante-deux semaines le Christ sera mis à mort, et il n'y aura pas en lui de sujet de condamnation; et il détruira la ville et le sanctuaire, à l'aide d'un chef qui surviendra; et ils disparaîtront dans un cataclysme, et à la fin de la guerre, qui sera abrégée, il livrera la ville aux désolations.
Lẹ́yìn ọ̀sẹ̀ méjìlélọ́gọ́ta, a ó ké Ẹni òróró náà kúrò, kò sì ní ní ohun kan. Àwọn ènìyàn ọmọ-aládé náà tí yóò wá ni yóò pa ìlú náà àti ibi mímọ́ run. Òpin yóò dé bí ìkún omi, ogun yóò máa jà títí dé òpin, a sì ti pàṣẹ ìdahoro.
27 Et durant une semaine il confirmera l'alliance avec plusieurs. Et au milieu de la semaine la victime et les libations me seront ôtées, et l'abomination de la désolation sera sur le temple, et la désolation aura sa fin à la consommation des temps.
Yóò sì fi ìdí i májẹ̀mú kan múlẹ̀ pẹ̀lú ọ̀pọ̀lọpọ̀ fún ọ̀sẹ̀ kan. Ní àárín ọ̀sẹ̀ ni yóò mú òpin bá ẹbọ àti ọrẹ ẹbọ. Àti lórí apá kan ni yóò dà ìríra tí ó mú ìdahoro wá, títí tí òpin tí a ti pàṣẹ lórí asọnidahoro yóò fi padà fi dé bá a.”