< Amos 8 >

1 Ceci est la vision que m'a envoyé le Seigneur Dieu; voilà un vase d'oiseleur à la glu.
Èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè fihàn mi: agbọ̀n èso pípọ́n.
2 Et le Seigneur me dit: Que vois-tu, Amos? et je dis: Un vase d'oiseleur à la glu; et le Seigneur me dit: La fin de Mon peuple d'Israël est arrivée; Je ne continuerai plus de Me montrer à lui.
Ó béèrè pé, “Amosi kí ni ìwọ rí.” Mo sì dáhùn pé, “Agbọ̀n èso pípọ́n.” Nígbà náà ni Olúwa wí fún mi pé, “Àsìkò náà pọ́n tó fún àwọn ènìyàn mi Israẹli; Èmi kì yóò dá wọn sí mọ́.”
3 Et en ce jour-là les lambris du temple pousseront des cris de douleur, dit le Seigneur. Une multitude d'hommes tomberont en tous lieux; et J'étendrai sur eux le silence.
Olúwa Olódùmarè wí pé, “Ní ọjọ́ náà, àwọn orin tẹmpili yóò yí padà sí ohùn réré ẹkún. Ọ̀pọ̀, àní ọ̀pọ̀ ara òkú ni yóò wà ni ibi gbogbo! Àní ni ìdákẹ́ jẹ́ẹ́!”
4 Écoutez donc ces choses, vous qui le matin opprimez l'indigent, et qui foulez aux pieds les pauvres de la terre,
Ẹ gbọ́ èyí, ẹ̀yin tí ń tẹ aláìní lórí ba, tí ẹ sì ń sọ tálákà di ilẹ̀.
5 disant: Quand donc le mois sera-t-il écoulé pour que nous vendions? Quand finira le sabbat pour que nous ouvrions nos greniers, que nous fassions petite mesure, que nous augmentions les poids et faussions le balance;
Tí ẹ ń wí pé, “Nígbà wo ni oṣù tuntun yóò parí kí àwa bá à lè ta ọkà kí ọjọ́ ìsinmi kí ó lè dópin kí àwa bá à le ta jéró?” Kí a sì dín ìwọ̀n wa kù kí a gbéraga lórí iye tí a ó tà á kí a sì fi òsùwọ̀n èké yàn wọ́n jẹ,
6 pour que nous achetions le pauvre à prix d'argent; l'indigent pour des sandales, et que nous trafiquions sur toutes les denrées?
kí àwa lè fi fàdákà ra àwọn tálákà, kí a sì fi bàtà ẹsẹ̀ méjèèjì ra aláìní, kí a sì ta jéró tí a kó mọ́ ilẹ̀.
7 Le Seigneur fait serment de punir l'orgueil de Jacob: Nulle de vos œuvres, en Ma victoire, ne sera oubliée.
Olúwa ti fi ìgbéraga Jakọbu búra pé, “Èmi kì yóò gbàgbé ọ̀kan nínú ohun tí wọ́n ṣe.
8 Et n'est-ce pas à cause de ces choses que la terre sera troublée, que tous ceux qui l'habitent seront dans la douleur; et que la destruction montera comme le fleuve d'Égypte, et descendra comme lui?
“Ǹjẹ́ ilẹ̀ náà kì yóò ha wárìrì fún èyí? Àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ kì yóò ha ṣọ̀fọ̀? Gbogbo ilẹ̀ yóò ru sókè bí omi Naili, yóò sì ru ú sókè pátápátá bí ìkún omi a ó sì tì í jáde, a ó sì tẹ̀ ẹ́ rì gẹ́gẹ́ bí odò Ejibiti.
9 En ce jour-là ceci arrivera, dit le Seigneur Maître: Le soleil se couchera à Midi, et sur la terre, la lumière fera place aux ténèbres,
“Yóò sì ṣe ní ọjọ́ náà,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “Èmi yóò mú oòrùn wọ̀ ní ọ̀sán, Èmi yóò mú kí ayé ṣókùnkùn ní ọ̀sán gangan.
10 et Je changerai vos fêtes en deuil, et tous vos cantiques en lamentations; et je ceindrai vos reins de cilices, et toute tête deviendra chauve; et Israël pleurera, comme on pleure un bien-aimé, et ceux qui l'accompagneront souffriront comme en un jour de douleurs.
Èmí yóò yí àsè ẹ̀sìn yín padà sí ọ̀fọ̀, gbogbo orin yín ni èmi yóò sọ di ẹkún. Èmi yóò mú kí gbogbo yín wọ aṣọ ọ̀fọ̀, kí a sì fá orí yín. Èmi yóò mú kí ìgbà náà rí bí ìṣọ̀fọ̀ fún ọmọkùnrin kan ṣoṣo tí a bí àti òpin rẹ̀ bí ọjọ́ kíkorò.
11 Voilà que ces jours arrivent, dit le Seigneur, et J'enverrai la famine sur la terre, non la disette de pain et d'eau, mais la soif d'entendre la parole du Seigneur.
“Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa Olódùmarè wí, “nígbà tí èmi yóò rán ìyàn sí ilẹ̀ náà, kì í ṣe ìyàn oúnjẹ tàbí òǹgbẹ fún omi. Ṣùgbọ́n ìyàn gbígbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Et d'une mer à l'autre les hommes seront agités, et du nord au levant ils courront, cherchant la parole du Seigneur, et ils ne la trouveront pas.
Àwọn ènìyàn yóò rìn kiri láti Òkun dé Òkun wọn yóò sì máa rìn ká láti gúúsù sí àríwá, wọn yóò máa wá ọ̀rọ̀ Olúwa ṣùgbọ́n wọn kì yóò rí i.
13 En ce jour-là, les vierges les plus belles et les jeunes hommes tomberont de soif.
“Ní ọjọ́ náà “àwọn arẹwà wúńdíá àti àwọn alágbára ọ̀dọ́mọkùnrin yóò dákú fún òǹgbẹ omi.
14 Ceux qui jurent par la propitiation de Samarie, et disent: Vive ton Dieu, Dan! vive ton Dieu, Bersabée! ceux-là tomberont et ne se relèveront plus.
Àwọn tí ó fi ẹ̀ṣẹ̀ Samaria búra, tí wọ́n sì wí pé, ‘Bí ó ti dájú pé ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Dani,’ bí ó ti dájú pè ọlọ́run rẹ ń bẹ láààyè, ìwọ Beerṣeba, wọ́n yóò ṣubú, wọn kì yóò si tún dìde mọ.”

< Amos 8 >