< 2 Samuel 9 >
1 Et David dit: Reste-t-il encore un rejeton de la maison de Saül, afin que je sois envers lui miséricordieux pour l'amour de Jonathan?
Dafidi sì béèrè pé, ọ̀kan nínú àwọn ẹni tí ń ṣe ìdílé Saulu kù síbẹ̀ bí? Kí èmi lè ṣe oore fún un nítorí Jonatani.
2 Or, il y avait dans la maison de Saül un serviteur qui se nommait Siba; on le fit venir auprès de David, et le roi lui dit: Tu es Siba? Et il répondit: Je suis ton serviteur.
Ìránṣẹ́ kan sì ti wà ní ìdílé Saulu, orúkọ rẹ̀ sí ń jẹ́ Ṣiba, wọ́n sì pè é wá sọ́dọ̀ Dafidi, ọba sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Ìwọ ni Ṣiba bí?” Ó sì dáhùn wí pé, “Ìránṣẹ́ rẹ ni.”
3 Et le roi lui dit: Reste-t-il encore un homme de la maison de Saül pour que j'exerce envers lui la miséricorde de Dieu? Et Siba répondit au roi: Il existe un fils de Jonathan, infirme des pieds.
Ọba sì wí pé, “Kò ha sí ọ̀kan nínú ìdílé Saulu síbẹ̀, kí èmi ṣe oore Ọlọ́run fún un?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Jonatani ní ọmọ kan síbẹ̀ tó ya arọ.”
4 Le roi dit: Où est-il? Et Siba répondit au roi: Voici; il est en la maison de Machir, fils d'Amiel de Lodabar.
Ọba sì wí fún un pé, “Níbo ni ó gbé wà?” Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Wò ó, òun wà ní ilé Makiri, ọmọ Ammieli, ní Lo-Debari.”
5 Et le roi David envoya des gens, et il le retira de la maison de Machir, fils d'Amiel en Lodabar.
Dafidi ọba sì ránṣẹ́, ó sì mú un láti ilé Makiri ọmọ Ammieli láti Lo-Debari wá.
6 Et Miphiboseth fils de Jonathan, fils de Saül, comparut devant le roi David; il tomba la face contre terre et il le salua, et David lui dit: Miphiboseth; et il répondit: Voici ton serviteur.
Mefiboṣeti ọmọ Jonatani ọmọ Saulu sì tọ Dafidi wá, ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì bú ọlá fún un. Dafidi sì wí pé, “Mefiboṣeti!” Òun sì dáhùn wí pé, “Wò ó, ìránṣẹ́ rẹ!”
7 David lui dit: N'aie point crainte, car je serai miséricordieux envers toi pour l'amour de Jonathan, ton père; je te rendrai tous les champs de Saül, père de ton père, et tu mangeras tous les jours à ma table.
Dafidi sì wí fún un pé, “Má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé nítòótọ́ èmi ó ṣe oore fún ọ nítorí Jonatani baba rẹ, èmi ó sì tún fi gbogbo ilé Saulu baba rẹ fún ọ, ìwọ ó sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.”
8 Et Miphiboseth se prosterna, et il dit: Qui suis-je donc, moi, ton serviteur, pour que tu aies jeté les regards sur un chien mort tel que je suis?
Mefiboṣeti sì tẹríba, ó sì wí pé, “Kí ni ìránṣẹ́ rẹ jásí, tí ìwọ ó fi máa wo òkú ajá bí èmi.”
9 Et le roi appela Siba, le serviteur de Saül, et il lui dit: Tout ce qui appartenait à Saül et dépendait de sa maison, je l'ai donné au fils de ton maître.
Ọba sì pe Ṣiba ìránṣẹ́ Saulu, ó sì wí fún un pé, “Gbogbo nǹkan tí í ṣe ti Saulu, àti gbogbo èyí tí í ṣe ti ìdílé rẹ̀ ni èmi fi fún ọmọ olúwa rẹ.
10 Va donc, avec tes fils et tes serviteurs, labourer ses terres, et tu apporteras au fils de ton maître le pain qu'il mangera, et Miphiboseth, fils de ton maître, mangera toujours du pain à ma table. Or, Siba avait quinze fils et vingt serviteurs.
Ìwọ, àti àwọn ọmọ rẹ, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ ni yóò sì máa ro ilẹ̀ náà fún un, ìwọ ni yóò sì máa mú ìkórè wá, ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa rí oúnjẹ jẹ, ṣùgbọ́n Mefiboṣeti ọmọ olúwa rẹ yóò sì máa bá mi jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ mi.” (Ṣiba sì ní ọmọ mẹ́ẹ̀ẹ́dógún àti ogún ìránṣẹ́kùnrin.)
11 Et Siba répondit au roi: Tout ce que le roi mon maître a prescrit à son serviteur, son serviteur l'exécutera. Et Miphiboseth mangea à la table de David comme l'un des fils du roi.
Ṣiba sì wí fún ọba pé, “Gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí olúwa mi ọba ti pàṣẹ fún ìránṣẹ́ rẹ, bẹ́ẹ̀ náà ni ìránṣẹ́ rẹ ó ṣe.” Ọba sì wí pé, “Ní ti Mefiboṣeti, yóò máa jẹun ní ibi oúnjẹ mi, gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ọmọ ọba.”
12 Or, Miphiboseth avait un fils tout petit qui se nommait Micha; et tous ceux qui habitaient la maison de Siba étaient ses serviteurs.
Mefiboṣeti sì ní ọmọ kékeré kan, orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Mika. Gbogbo àwọn tí ń gbé ní ilé Ṣiba ni ó sì ń ṣe ìránṣẹ́ fún Mefiboṣeti.
13 Et Miphiboseth résida à Jérusalem, et il mangea toujours à la table du roi; or, il était boiteux des deux pieds.
Mefiboṣeti sì ń gbé ní Jerusalẹmu, òun a sì máa jẹun nígbà gbogbo ní ibi oúnjẹ ọba; òun sì yarọ ní ẹsẹ̀ rẹ̀ méjèèjì.