< 1 Samuel 6 >
1 L'arche fut sept mois sur la terre des étrangers, et les rats y fourmillèrent.
Nígbà tí àpótí ẹ̀rí Olúwa sì ti wà ní agbègbè Filistini fún oṣù méje,
2 Alors, les Philistins appelèrent leurs prêtres, leurs devins, leurs magiciens, et ils leur dirent: Que ferons-nous de l'arche du Seigneur? Apprenez-nous comment nous la renverrons au lieu où elle réside.
àwọn ará Filistini pe àwọn àlùfáà, àti àwọn alásọtẹ́lẹ̀, wọ́n sì sọ pé, “Kí ni kí a ṣe pẹ̀lú àpótí ẹ̀rí Olúwa? Sọ fún wa bí àwa yóò ti dá a padà sí ààyè rẹ̀.”
3 Et ils dirent: Si vous renvoyez l'arche de l'alliance du Seigneur Dieu d'Israël, ne la renvoyez point vide; mais en la rendant faites des dons à cause de votre plaie; cela fait, vous serez guéris, l'arche vous sera propice, et la main du Seigneur ne pèsera plus sur vous.
Wọ́n dáhùn wí pé, “Tí ẹ bá dá àpótí ẹ̀rí Ọlọ́run ti àwọn ọmọ Israẹli padà, ẹ má ṣe dá a padà ní òfìfo, ṣùgbọ́n bí ó ti wù kí ó rí, ẹ fún un ní ẹbọ ẹ̀bi. Nígbà náà ni a ó mú un yín láradá, ẹ̀yin yóò sì mọ ìdí tí ọwọ́ rẹ̀ kò fi tí ì kúrò lára yín.”
4 Que donnerons-nous à cause de notre plaie? dirent-ils; les prêtres répondirent:
Àwọn ará Filistini béèrè pé, “Irú ẹbọ ẹ̀bi wo ni kí a fi fún un?” Wọ́n dáhùn, “Wúrà oníkókó márùn-ún àti eku ẹ̀lírí wúrà márùn-ún, gẹ́gẹ́ bí iye àwọn aláṣẹ Filistini, nítorí àjàkálẹ̀-ààrùn kan náà ni ó kọlù yín àti olórí yín.
5 Et autant de rats d'or semblables aux rats qui ont dévasté votre contrée. Vous glorifierez ainsi le Seigneur afin que sa main cesse de peser sur vous, sur vos dieux et sur votre pays.
Mọ àwòrán ààrùn oníkókó àti ti eku ẹ̀lírí yin tí ó ń ba orílẹ̀-èdè náà jẹ́ kí o sì bu ọlá fún Ọlọ́run Israẹli. Bóyá yóò gbé ọwọ́ rẹ̀ kúrò lára yín, lára ọlọ́run yín àti lára ilẹ̀ yín.
6 Pourquoi vous endurcir le cœur, comme l'ont endurci l'Égypte et le Pharaon? N'est-ce pas après que le Seigneur se fut joué d'eux, qu'ils congédièrent les Hébreux et que ceux-ci partirent.
Kí ni ó dé tí ẹ fi ń sé ọkàn yín le gẹ́gẹ́ bí àwọn ará Ejibiti àti Farao ti ṣe? Nígbà tí ó fi ọwọ́ líle mú wọn, ṣé wọn kò rán àwọn ọmọ Israẹli jáde kí wọn kí ó lè lọ ní ọ̀nà wọn?
7 Maintenant donc prenez du bois et faites un chariot neuf; prenez deux vaches n'ayant vêlé qu'une fois, séparez-les de leurs veaux; attelez-les au chariot, et renvoyez les veaux à l'étable.
“Nísinsin yìí ẹ pèsè kẹ̀kẹ́ ẹrù tuntun sílẹ̀, pẹ̀lú màlúù méjì tí ó ti fi ọmú fún ọmọ, èyí tí a kò tí ì gba àjàgà sí ọrùn rí, kí ẹ sì so ó mọ́ kẹ̀kẹ́ náà, kí ẹ sì mú ọmọ wọn kúrò lọ́dọ̀ wọn wá sí ilé láti so.
8 Ensuite, vous prendrez l'arche et vous la placerez sur le chariot avec tous les objets d'or que vous donnerez en expiation, et que vous renfermerez dans une cassette à côté d'elle; puis, vous la renverrez, vous pousserez l'attelage et vous vous en éloignerez.
Kí ẹ sì gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa sí orí kẹ̀kẹ́ ẹrù àti kí ẹ̀yin sì kó àwọn ohun èlò wúrà tí ẹ̀yin fi fún un gẹ́gẹ́ bí ti ẹbọ ẹ̀bi sí inú àpótí ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀, kí ẹ̀yin kí ó sì rán an lọ,
9 Après cela, vous serez attentifs: si elle prend par Bethsamys la route de son pays, c'est le Seigneur qui vous a frappés de ces grandes plaies; sinon, nous reconnaîtrons que ce n'est point sa main qui nous a touchés, mais qu'un accident nous est advenu.
ṣùgbọ́n kí ẹ sì máa ṣọ́ ọ. Tí ó bá ń lọ sí ilẹ̀ rẹ̀, ìlú rẹ̀, níhà Beti-Ṣemeṣi. Nígbà náà ni Olúwa mú àjálù ńlá yìí bá wa. Ṣùgbọ́n bí kò bá ṣe bẹ́ẹ̀ nígbà náà ni a mọ̀ pé kì í ṣe ọwọ́ rẹ̀ ni ó kọlù wá, ṣùgbọ́n ó wá bẹ́ẹ̀ ni.”
10 Les Philistins suivirent ces conseils; ils prirent deux vaches qui n'avaient encore vêlé qu'une fois; ils les attelèrent au chariot, et ils retinrent leurs veaux à l'étable.
Nígbà náà ni wọ́n ṣe èyí. Wọ́n mú abo màlúù méjì, tí ń fi ọmú fún ọmọ, wọn mọ́ ara, wọ́n sì dè é ni ilé kẹ̀kẹ́ ẹrù, wọn sì so àwọn ọmọ wọn mọ́lẹ̀ ni ilé.
11 ils posèrent sur le chariot l'arche du Seigneur et la cassette contenant les rats d'or.
Wọ́n gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé orí kẹ̀kẹ́ ní ẹ̀gbẹ́ rẹ̀ ni àpótí tí eku ẹ̀lírí wúrà àti àwòrán ààrùn oníkókó wà níbẹ̀.
12 Et les vaches marchèrent droit au chemin qui mène à Bethsamys; elles ne quittèrent point la voie, tirant avec effort, sans dévier ni à droite ni à gauche; les chefs des Philistins les suivirent à distance, jusqu'aux confins de Bethsamys.
Nígbà náà; àwọn màlúù lọ tààrà sí ìhà Beti-Ṣemeṣi, wọ́n ń lọ tààrà, wọ́n sì ń dún bí wọ́n ti ń lọ. Wọn kò yà sí ọ̀tún tàbí yà sí òsì. Àwọn aláṣẹ Filistini tẹ̀lé wọn títí dé ibodè Beti-Ṣemeṣi.
13 Or, ceux de Bethsamys moissonnaient les froments dans la vallée; ils virent l'arche du Seigneur et ils coururent pleins de joie au-devant d'elle.
Nísinsin yìí, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi ń kórè jéró wọn ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nígbà tí wọ́n wo òkè tí wọ́n sì rí àpótí ẹ̀rí Olúwa, wọ́n yọ̀ níwájú rẹ̀.
14 Et le chariot entra dans le champ d'Osée de Bethsamys; les hommes dressèrent auprès de l'arche une grande pierre; ils fendirent le bois du chariot, et ils offrirent les vaches en holocauste au Seigneur.
Kẹ̀kẹ́ ẹrù wá sí pápá Joṣua ti Beti-Ṣemeṣi, níbẹ̀ ni ó ti dúró ní ẹ̀bá àpáta ńlá kan. Àwọn ènìyàn gé igi ara kẹ̀kẹ́ ẹrù sí wẹ́wẹ́ wọ́n sì fi àwọn màlúù náà rú ẹbọ sísun sí Olúwa.
15 Ensuite, les lévites soulevèrent l'arche du Seigneur et la cassette avec les objets d'or qu'elle contenait; ils les posèrent sur la grande pierre, et les hommes de Bethsamys, ce jour-là, firent des holocaustes et des oblations au Seigneur.
Àwọn ará Lefi gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa wá sí ìsàlẹ̀ pẹ̀lú àpótí tí ohun èlò wúrà wà níbẹ̀, wọ́n sì gbé wọn ka orí àpáta ńlá náà. Ní ọjọ́ náà, àwọn ará Beti-Ṣemeṣi rú ẹbọ sísun, wọ́n sì ṣe ìrúbọ sí Olúwa.
16 Les cinq chefs des Philistins les ayant aperçus, retournèrent à Ascalon le jour même.
Àwọn aláṣẹ Filistini márààrún rí gbogbo èyí, wọ́n sì padà ní ọjọ́ náà sí Ekroni.
17 Voici d'où venaient les anus d'or que les Philistins donnèrent à cause de la plaie du Seigneur: un d'Azot, un de Gaza, un d'Ascalon, un de Geth et un d'Accaron.
Èyí ni kókó wúrà tí àwọn Filistini fún Olúwa gẹ́gẹ́ bí ẹbọ ẹ̀bi ọ̀kọ̀ọ̀kan fún Aṣdodu, ọ̀kan ti Gasa, ọ̀kan ti Aṣkeloni, ọ̀kan ti Gati, ọ̀kan ti Ekroni.
18 Et les rats d'or étaient en même nombre que toutes les villes des Philistins soumises aux cinq chefs, depuis les villes fortifiées, jusqu'au village du Phérézéen et à la grande pierre sur laquelle on posa l'arche de l'alliance du Seigneur, dans le champ d'Osée le Bethsamite.
Wúrà eku ẹ̀lírí jẹ́ iye ìlú tí àwọn aláṣẹ Filistini márààrún ti wá, ìlú olódi pẹ̀lú ìletò wọn. Àpáta ńlá náà, lórí èyí tí a gbé àpótí ẹ̀rí Olúwa lé jẹ́ ẹ̀rí títí di òní ní oko Joṣua ará Beti-Ṣemeṣi.
19 Parmi les hommes de Bethsamys, les fils de Jéchonie n'eurent point à se féliciter parce qu'ils regardèrent l'arche du Seigneur, qui frappa à mort soixante-dix de leurs chefs, outre cinquante mille hommes. Le peuple fut plongé dans le deuil parce que le Seigneur l'avait frappé d'une très grande plaie.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run kọlu díẹ̀ lára àwọn ọkùnrin Beti-Ṣemeṣi, ó pa àádọ́rin wọn, nítorí wọ́n ti wo inú àpótí ẹ̀rí Olúwa. Àwọn ènìyàn ṣọ̀fọ̀ nítorí àjálù ńlá tí Olúwa fi bá ọ̀pọ̀ wọn jà.
20 Et les hommes de Bethsamys dirent: Qui pourra aller et venir en présence du Seigneur, du Dieu saint? Chez qui, en nous quittant, ira l'arche du Seigneur?
Àwọn ọkùnrin ará Beti-Ṣemeṣi béèrè pé, “Ta ni ó le è dúró ní iwájú Olúwa Ọlọ́run mímọ́ yìí? Ọ̀dọ̀ ta ni àpótí ẹ̀rí Olúwa yóò gbà gòkè lọ láti ibí yìí?”
21 Et ils dépêchèrent des messagers aux habitants de Cariath-Iarim, disant: Les Philistins ont rendu l'arche du Seigneur, venez et emmenez l'arche avec vous.
Nígbà náà, wọ́n rán àwọn ìránṣẹ́ sí àwọn ènìyàn tí Kiriati-Jearimu wí pé, “Àwọn Filistini ti dá àpótí ẹ̀rí Olúwa padà. Ẹ sọ̀kalẹ̀ wá, kí ẹ gbé e gòkè lọ sí ọ̀dọ̀ yín.”