< 1 Samuel 22 >
1 Ainsi, David s'éloigna et il fut sauvé; il se réfugia dans la caverne d'Odollam; ses frères, la famille de son père, l'apprirent, et ils l'y allèrent trouver.
Dafidi sì kúrò níbẹ̀, ó sì sá sí ihò Adullamu; nígbà tí àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìdílé baba rẹ̀ sì gbọ́, wọ́n sì sọ̀kalẹ̀ tọ̀ ọ́ wá níbẹ̀.
2 Et ils lui amenèrent tous les nécessiteux, tous les hommes perdus de dettes, tous ceux qui souffraient en leur âme; il fut leur chef, et il eut autour de lui quatre cents hommes.
Olúkúlùkù ẹni tí ó tí wà nínú ìpọ́njú, àti olúkúlùkù ẹni tí ó ti jẹ gbèsè, àti olúkúlùkù ẹni tí ó wà nínú ìbànújẹ́, sì kó ara wọn jọ sọ́dọ̀ rẹ̀, òun sì jẹ́ olórí wọn; àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀ sì tó ìwọ̀n irinwó ọmọkùnrin.
3 Et David partit pour Maspha en Moab, et il dit au roi des Moabites: Que mon père et ma mère demeurent chez toi jusqu'à ce que je sache ce que fera de moi le Seigneur.
Dafidi sì ti ibẹ̀ náà lọ sí Mispa tí Moabu: ó sì wí fún ọba Moabu pé, “Jẹ́ kí baba àti ìyá mi, èmi bẹ̀ ọ́ wá bá ọ gbé, títí èmi yóò fi mọ ohun ti Ọlọ́run yóò ṣe fún mi.”
4 Il toucha le roi de Moab, et ses parents demeurèrent auprès du roi tout le temps que David passa dans le fort.
Ó sì mú wọn wá síwájú ọba Moabu; wọ́n sì bá á gbé ní gbogbo ọjọ́ tí Dafidi fi wà nínú ihò náà.
5 Enfin, Gad le prophète dit à David: Ne te tiens pas renfermé dans une forteresse; mets-toi en campagne, et tu entreras en la terre de Juda. David partit donc, et il s'établit dans la ville de Saric.
Gadi wòlíì sí wí fún Dafidi pé, “Ma ṣe gbé inú ihò náà, yẹra, kí o sí lọ sí ilẹ̀ Juda.” Nígbà náà ni Dafidi sì yẹra, ó sì lọ sínú igbó Hereti.
6 Et Saül fut informé que l'on avait reconnu David et les hommes qui l'accompagnaient. Saül demeurait alors sur la colline qui domine les champs de Rhama; il avait en main sa javeline, et tous ses serviteurs l'entouraient.
Saulu si gbọ́ pé a rí Dafidi àti àwọn ọkùnrin tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀; Saulu sì ń bẹ ní Gibeah lábẹ́ igi tamariski ní Rama; ọ̀kọ̀ rẹ̀ sì ń bẹ lọ́wọ́ rẹ̀, àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ sì dúró tì í.
7 Et Saül dit à ses serviteurs qui l'entouraient: Écoutez-moi, fils de Benjamin; croyez-vous que véritablement le fils de Jessé vous donne à tous des terres ou des vignes, qu'il fasse de vous tous des centeniers ou des commandants de mille hommes,
Nígbà náà ni Saulu wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ tí ó dúró tì í, pé, “Ǹjẹ́ ẹ gbọ́ ẹ̀yin ará Benjamini, ọmọ Jese yóò ha fún olúkúlùkù yín ni oko ọgbà àjàrà bí? Kí ó sì sọ gbogbo yin dì olórí ẹgbẹẹgbẹ̀rún àti olórí ọ̀rọ̀ọ̀rún bí?
8 Vous qui êtes tous conjurés contre moi, sans que nul m'informe de l'alliance faite entre mon fils Jonathan et le fils de Jessé, sans que nul ait souci de moi et m'apprenne que mon fils a excité contre moi mon serviteur pour m'en faire un ennemi, comme il l'est maintenant?
Tí gbogbo yín di ìmọ̀lù sí mi, tí kò sì sí ẹnìkan tí ó sọ létí mi pé, ọmọ mi ti bá ọmọ Jese mulẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni kó sì sí ẹnìkan nínú yín tí ó ṣàánú mi, tí ó sì sọ ọ́ létí mi pé, ọmọ mi mú kí ìránṣẹ́ mi dìde sí mi láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
9 Et Doeg le Syrien, le surveillant des mulets de Saül, répondit: J'ai vu le fils de Jessé à Nomba chez Abimélech le prêtre, fils d'Achitob.
Doegi ará Edomu tí a fi jẹ olórí àwọn ìránṣẹ́ Saulu, sì dáhùn wí pé, “Èmi rí ọmọ Jese, ó wá sí Nobu, sọ́dọ̀ Ahimeleki ọmọ Ahitubu.
10 Le prêtre a consulté pour lui le Seigneur; il lui a donné des vivres, et il lui a donné le glaive de Goliath le Philistin.
Òun sì béèrè lọ́dọ̀ Olúwa fún un, ó sì fún un ní oúnjẹ, ó sí fún un ni idà Goliati ará Filistini.”
11 Le roi envoya chercher Abimélech, fils d'Achitob, et tous les fils de son père, et les prêtres de Nomba; ils comparurent tous devant Saül.
Ọba sì ránṣẹ́ pe Ahimeleki àlùfáà, ọmọ Ahitubu àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀, àwọn àlùfáà tí ó wà ni Nobu: gbogbo wọn ni ó sì wá sọ́dọ̀ ọba.
12 Et le roi dit: Écoute, fils d'Achitob. Sur quoi l'autre dit: Me voici; parle, seigneur.
Saulu sì wí pé, “Ǹjẹ́ gbọ́, ìwọ ọmọ Ahitubu.” Òun sì wí pé, “Èmi nìyìí olúwa mi.”
13 Et Saül reprit: Pourquoi es-tu d'intelligence contre moi avec le fils de Jessé? Ne lui as-tu pas donné des pains? N'as-tu pas pour lui consulté le Seigneur, afin qu'il se déclarât mon ennemi, comme il l'est maintenant?
Saulu sì wí fún un pé, “Kí ni ó dé tí ẹ̀yin fi ṣọ̀tẹ̀ sí mi, ìwọ àti ọmọ Jese, tí ìwọ fi fún un ní àkàrà, àti idà, àti ti ìwọ fi béèrè fún un lọ́dọ̀ Ọlọ́run kí òun lè dìde sí mi, láti ba dè mí, bí ó ti rí lónìí.”
14 Il répondit au roi: Qui donc, parmi tes serviteurs, t'était fidèle autant que David? N'était-il point le gendre du roi, le ministre de tes commandements, honoré en ta maison?
Ahimeleki sì dá ọba lóhùn, ó sì wí pé, “Ta ni ó jẹ́ olóòtítọ́ nínú gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ bí Dafidi, ẹni tí ó jẹ́ àna ọba, ẹni tí ó ń gbọ́ tìrẹ, tí ó sì ni ọlá ní ilé rẹ.
15 Est-ce aujourd'hui la première fois que j'aurais consulté pour lui le Seigneur? Nullement. Que le roi ne porte point une telle accusation contre son serviteur et contre toute la famille de mon père; car ton serviteur ne savait de ce qui se passe nulle chose, ni grande ni petite
Òní lèmi ó ṣẹ̀ṣẹ̀ máa béèrè lọ́wọ́ Ọlọ́run fún un bí? Kí èyí jìnnà sí mi: kí ọba má ṣe ka nǹkan kan sí ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ́rùn, tàbí sí gbogbo ìdílé baba mi: nítorí pé ìránṣẹ́ rẹ̀ kò mọ̀kan nínú gbogbo nǹkan yìí, díẹ̀ tàbí púpọ̀.”
16 Et le roi Saül dit: Tu mourras, Abimélech, toi et toute la famille de ton père.
Ọba sì wí pé, “Ahimeleki, kíkú ni ìwọ yóò kú, ìwọ àti gbogbo ìdílé baba rẹ̀.”
17 Puis, le roi dit aux émissaires qui se tenaient auprès de lui: Emmenez les prêtres du Seigneur, et mettez-les à mort; parce que leur main est avec David; ils le savaient en fuite, et ils ne me l'ont point révélé. Mais les serviteurs du roi refusèrent de porter la main sur les prêtres du Seigneur.
Ọba sì wí fún àwọn aṣáájú ti máa ń sáré níwájú ọba, tí ó dúró tì í pé, “Yípadà kí ẹ sì pa àwọn àlùfáà Olúwa; nítorí pé ọwọ́ wọn wà pẹ̀lú Dafidi, àti nítorí pé wọ́n mọ ìgbà tí òun sá, wọn kò sì sọ ọ́ létí mi.” Ṣùgbọ́n àwọn ìránṣẹ́ ọba kò sì jẹ́ fi ọwọ́ wọn lé àwọn àlùfáà Olúwa láti pa wọ́n.
18 Le roi dit donc à Doeg: Ceci te regarde, tombe sur les prêtres. Et Doeg le Syrien s'en chargea; et, ce jour-là, il tua tous les prêtres du Seigneur, au nombre de trois cent cinq hommes, tous portant l'éphod.
Ọba sì wí fún Doegi pé, “Ìwọ yípadà, kí o sì pa àwọn àlùfáà!” Doegi ará Edomu sì yípadà, ó sì kọlu àwọn àlùfáà, ó sì pa wọ́n ní ọjọ́ náà, àrùnlélọ́gọ́rin ènìyàn ti ń wọ aṣọ ọ̀gbọ̀ efodu.
19 Ensuite, il passa au fil de l'épée Nomba, la ville des prêtres: hommes et femmes, nourrissons et nourrices; bœufs, ânes et brebis.
Ó sì fi ojú idà pa ara Nobu, ìlú àwọn àlùfáà náà àti ọkùnrin àti obìnrin, ọmọ wẹ́wẹ́, àti àwọn tí ó wà lẹ́nu ọmú, àti màlúù, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, àti àgùntàn.
20 Un seul fils d'Abimélech, fils d'Achitob, fut sauvé; il se nommait Abiathar, et il se réfugia auprès de David.
Ọ̀kan nínú àwọn ọmọ Ahimeleki ọmọ Ahitubu tí a ń pè ní Abiatari sì bọ́; ó sì sá àsálà tọ Dafidi lọ.
21 Et Abiathar apprit à David que Saül avait fait périr tous les prêtres du Seigneur.
Abiatari sì fihan Dafidi pé Saulu pa àwọn àlùfáà Olúwa tán.
22 Et David dit à Abiathar: J'avais prévu, ce jour-là, que Doeg le Syrien dirait tout à Saül. Je suis cause de la mort de ton père et de sa famille.
Dafidi sì wí fún Abiatari pé, “Èmi ti mọ̀ ní ọjọ́ náà, nígbà tí Doegi ará Edomu ti wà níbẹ̀ pé, nítòótọ́ yóò sọ fún Saulu: nítorí mi ni a ṣe pa gbogbo ìdílé baba rẹ.
23 Demeure avec moi, n'aie point de crainte; car partout où je chercherai à mettre en sûreté ma vie, je chercherai à mettre en sûreté la tienne, puisque tu t'es placé sous ma garde.
Ìwọ jókòó níhìn-ín lọ́dọ̀ mi, má ṣe bẹ̀rù, nítorí pé ẹni ti ń wá ẹ̀mí mi, ó ń wá ẹ̀mí rẹ, ṣùgbọ́n lọ́dọ̀ mi ni ìwọ ó wà ní àìléwu.”