< 1 Samuel 19 >
1 Et Saül parla à Jonathan son fils, ainsi qu'à tous ses serviteurs, pour qu'ils tuassent David. Or, Jonathan, fils de Saül, aimait beaucoup David,
Saulu sọ fún Jonatani ọmọ rẹ̀ àti gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé kí wọ́n pa Dafidi. Ṣùgbọ́n Jonatani fẹ́ràn Dafidi púpọ̀
2 Et Jonathan avertit David, disant: Saül cherche à te tuer; prends donc garde à toi; dès demain à l'aurore, cache-toi et demeure caché.
Jonatani sì kìlọ̀ fún Dafidi pé, “Baba mi Saulu wá ọ̀nà láti pa ọ́, kíyèsi ara rẹ di òwúrọ̀ ọ̀la; lọ sí ibi ìkọ̀kọ̀, kí o sì sá pamọ́ sí ibẹ̀.
3 Quant à moi, je sortirai et je m'arrêterai avec mon père dans le champ où tu seras; je lui parlerai de toi; je verrai ce qu'il en est, et je te le ferai savoir.
Èmi yóò jáde lọ láti dúró ní ọ̀dọ̀ baba mi ní orí pápá níbi tí ó wà. Èmi yóò sọ̀rọ̀ fún un nípa à rẹ, èmi yóò sì sọ ohun tí òun bá wí fún ọ.”
4 Et Jonathan parla favorablement de David à son père, et il lui dit: Que le roi ne se rende pas coupable envers David, son serviteur, car il n'est point coupable envers toi, et toutes ses actions sont bonnes.
Jonatani sọ̀rọ̀ rere nípa Dafidi fún Saulu baba rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Má ṣe jẹ́ kí ọba kí ó ṣe ohun tí kò dára fún Dafidi ìránṣẹ́ rẹ̀; nítorí tí kò ṣẹ̀ ọ́, ohun tí ó sì ṣe pé ọ púpọ̀.
5 Il a placé sa vie dans sa main, il a tué l'étranger, et le Seigneur nous a sauvés d'une manière éclatante; tout Israël l'a vu et s'en est réjoui: pourquoi donc pècherais-tu contre le sang innocent, en tuant sans sujet David?
Ó fi ẹ̀mí rẹ̀ wéwu nígbà tí ó pa Filistini. Olúwa ṣẹ́ ogun ńlá fún gbogbo Israẹli, ìwọ rí i inú rẹ dùn. Ǹjẹ́ nítorí kí ni ìwọ yóò ṣe dẹ́ṣẹ̀ sí Dafidi aláìṣẹ̀, tí ìwọ yóò fi pa á láìnídìí?”
6 Saül se rendit aux paroles de Jonathan; Saül prêta serment, et il dit: Vive le Seigneur, David ne mourra point.
Saulu fetísí Jonatani, ó sì búra báyìí, “Níwọ́n ìgbà tí Olúwa bá ti ń bẹ láààyè, a kì yóò pa Dafidi.”
7 Et Jonathan appela David; il lui répéta tout cet entretien, et il l'amena auprès de Saül, qui fut pour lui ce qu'il était précédemment.
Nítorí náà Jonatani pe Dafidi, ó sì sọ gbogbo àjọsọ wọn fún un. Ó sì mú un wá fún Saulu, Dafidi sì wà lọ́dọ̀ Saulu gẹ́gẹ́ bí i ti tẹ́lẹ̀.
8 Or, Saül eut une nouvelle guerre; et David remporta la victoire; il combattit les Philistins; et il les frappa d'une très grande plaie, et ils s'enfuirent devant lui.
Lẹ́ẹ̀kan an sí i ogun tún wá, Dafidi sì jáde lọ, ó sì bá àwọn ara Filistini jà. Ó sì pa wọn pẹ̀lú agbára, wọ́n sì sálọ níwájú u rẹ̀.
9 Alors, un mauvais esprit de Dieu saisit Saül; celui-ci dormait dans sa maison la javeline à la main, et David touchait de la harpe.
Ṣùgbọ́n ẹ̀mí búburú láti ọ̀dọ̀ Olúwa wá sí orí Saulu bí ó ti jókòó ní ilé e rẹ̀ pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀ ní ọwọ́ rẹ̀. Bí Dafidi sì ti fọn ohun èlò orin olókùn,
10 Et Saül, s'éveillant, chercha à tuer David d'un coup de javeline, mais David s'esquiva, la javeline frappa le mur; David s'enfuit et fut sauvé.
Saulu sì wá ọ̀nà láti gún un mọ́ ògiri pẹ̀lú ọ̀kọ̀ rẹ̀, ṣùgbọ́n Dafidi yẹ̀ ẹ́ sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí Saulu ti ju ọ̀kọ̀ náà mọ́ ara ògiri. Ní alẹ́ ọjọ́ náà Dafidi sì fi ara pamọ́ dáradára.
11 Cette nuit-là, Saül envoya des messagers à la maison de David pour l'épier et le tuer dès le matin; mais Michol, femme de David, l'avertit, disant: Si cette nuit même tu ne sauves pas ta vie, demain tu seras mis à mort.
Saulu rán ènìyàn sí ilé Dafidi láti ṣọ́ ọ kí wọ́n sì pa á ní òwúrọ̀. Ṣùgbọ́n Mikali, ìyàwó Dafidi kìlọ̀ fún un pé, “Tí o kò bá sá fún ẹ̀mí rẹ ní alẹ́ yìí, ní ọ̀la ni a yóò pa ọ́.”
12 Et Michol fit sortir David par la fenêtre; il partit, s'enfuit et fut sauvé.
Nígbà náà Mikali sì gbé Dafidi sọ̀kalẹ̀ ó sì fi aṣọ bò ó.
13 Et Michol prit une image qu'elle posa sur le lit; à la tète elle mit du poil de chèvre, et elle couvrit le corps d'un manteau.
Mikali gbé ère ó sì tẹ́ e lórí ibùsùn, ó sì fi irun ewúrẹ́ sí ibi orí rẹ̀.
14 Or, Saül avait envoyé des messagers pour prendre David, et ils vinrent lui dire qu'il était malade.
Nígbà ti Saulu rán ènìyàn láti lọ fi agbára mú Dafidi, Mikali wí pé, “Ó rẹ̀ ẹ́.”
15 Il les renvoya chez David, disant: Amenez-le-moi et qu'il meure.
Nígbà náà ni Saulu rán ọkùnrin náà padà láti lọ wo Dafidi ó sì sọ fún wọn pé, “Mú wa fún mi láti orí ibùsùn rẹ̀ kí èmi kí ó le pa á.”
16 Les messagers retournèrent chez David et ils virent l'image sur le lit, et à la tète le poil de chèvre.
Ṣùgbọ́n nígbà tí ọkùnrin náà wọlé, ère ni ó bá lórí ibùsùn àti irun ewúrẹ́ ní orí ère náà.
17 Et Saül dit à Michol: Pourquoi m'avoir ainsi trompé en faisant échapper mon ennemi? Le voilà sauvé. Et Michol dit à Saül: Il m'a dit: Laisse-moi fuir; sinon je te tuerai.
Saulu wí fún Mikali pé, “Èéṣe tí ìwọ fi tàn mí báyìí tí o sì jẹ́ kí ọ̀tá mi sálọ tí ó sì bọ́?” Mikali sọ fún un pé, “Ó wí fún mi, ‘Jẹ́ kí èmi ó lọ. Èéṣe tí èmi yóò fi pa ọ́?’”
18 Or, David s'était enfui, et il était sauvé; il se rendit chez Samuel en Armathaïm, et il lui raconta tout ce que lui avait fait Saül. Aussitôt, Samuel partit avec David, et ils séjournèrent à Navath en Rhama.
Nígbà tí Dafidi ti sálọ tí ó sì ti bọ́, ó sì lọ sọ́dọ̀ Samuẹli ní Rama ó sì sọ gbogbo ohun tí Saulu ti ṣe fún un. Òun àti Samuẹli lọ sí Naioti láti dúró níbẹ̀.
19 Et des gens le rapportèrent à Saül, disant: Voilà que David est à Navath en Rhama.
Ọ̀rọ̀ sì tọ Saulu wá pé, “Dafidi wà ní Naioti ní Rama,”
20 Et Saül envoya des messagers pour prendre David; or, ils virent l'assemblée des prophètes, Samuel à leur tète, et l'Esprit de Dieu vint sur les messagers de Saül, et ils prophétisèrent.
Saulu sì rán àwọn ènìyàn láti fi agbára mú Dafidi wá ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí ọ̀pọ̀ àwọn wòlíì tí ń sọtẹ́lẹ̀, pẹ̀lú Samuẹli dúró níbẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olórí, Ẹ̀mí Ọlọ́run sì wá sórí àwọn arákùnrin Saulu àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀.
21 Des gens l'allèrent dire à Saül, et il envoya d'autres messagers; et ceux-ci pareillement se mirent à prophétiser; Saül en envoya d'autres qui prophétisèrent encore.
Wọ́n sì sọ fún Saulu nípa rẹ̀, ó sì rán ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn mìíràn lọ àwọn náà sì ń sọtẹ́lẹ̀. Saulu tún rán oníṣẹ́ lọ ní ìgbà kẹta, àwọn náà bẹ̀rẹ̀ sí ní sọtẹ́lẹ̀.
22 Enfin, Saül s'enflamma de colère; il partit lui-même pour Armathaïm, et alla jusqu'au puits de l'aire qui est à Séphi; il s'informa et il dit: Où sont Samuel et David? On lui répondit: Ils sont à Navath en Rhama.
Nígbẹ̀yìn, òun fúnra rẹ̀ sì lọ sí Rama ó sì dé ibi àmù ńlá kan ní Seku. Ó sì béèrè, “Níbo ni Samuẹli àti Dafidi wà?” Wọ́n wí pé, “Wọ́n wà ní ìrékọjá ní Naioti ní Rama.”
23 Saül partit donc pour Navath en Rhama, et l'Esprit de Dieu vint aussi sur lui, et il alla prophétisant, jusqu'à l'entrée de Navath en Rhama.
Saulu sì lọ sí Naioti ni Rama. Ṣùgbọ́n, Ẹ̀mí Ọlọ́run bà lé e lórí ó sì ń lọ lọ́nà, ó sì ń sọtẹ́lẹ̀ títí tí ó fi dé Naioti.
24 Là, il se dépouilla de ses vêtements; il prophétisa devant l'assemblée, et il resta nu, tout ce jour-là et toute la nuit, se tenant prosterné; à cause de cela on dit: Saül aussi est-il au nombre des prophètes?
Ó sì bọ́ aṣọ rẹ̀, òun pẹ̀lú sì ń sọtẹ́lẹ̀ níwájú Samuẹli. Ó sì dùbúlẹ̀ bẹ́ẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà àti ní òru. Ìdí nìyìí tí àwọn ènìyàn fi wí pé, “Ṣé Saulu náà wà lára àwọn wòlíì ni?”