< 1 Rois 3 >
1 Mais le peuple sacrifiait encore sur les hauts lieux, parce que le temple du Seigneur n'était pas encore bâti.
Solomoni sì bá Farao ọba Ejibiti dá àna, ó sì fẹ́ ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìyàwó. Ó sì mú un wá sí ìlú Dafidi títí tí ó fi parí kíkọ́ ààfin rẹ̀ àti tẹmpili Olúwa, àti odi tí ó yí Jerusalẹmu ká.
2 Mais le peuple sacrifiait encore sur les hauts lieux, parce que le temple du Seigneur n'était pas encore bâti.
Síbẹ̀síbẹ̀, àwọn ènìyàn ṣì ń rú ẹbọ ní ibi gíga, nítorí a kò tí ì kọ́ ilé fún orúkọ Olúwa títí di ìgbà náà
3 Or, Salomon aimait le Seigneur, et marchait en la voie des commandements du roi David son père; seulement il sacrifiait et encensait sur, les hauts lieux.
Solomoni sì fi ìfẹ́ rẹ̀ hàn sí Olúwa nípa rírìn gẹ́gẹ́ bí òfin Dafidi baba rẹ̀, àti pé, ó rú ẹbọ, ó sì fi tùràrí jóná ní ibi gíga.
4 Et il partit pour Gabaon, afin d'y offrir un sacrifice; car c'était le lieu le plus élevé et le plus célèbre. Salomon offrit en holocauste mille victimes sur l'autel de Gabaon.
Ọba sì lọ sí Gibeoni láti rú ẹbọ, nítorí ibẹ̀ ni ibi gíga tí ó ṣe pàtàkì jù, Solomoni sì rú ẹgbẹ̀rún ọrẹ ẹbọ sísun lórí pẹpẹ.
5 Et la nuit venue, le Seigneur apparut à Salomon pendant son sommeil, et le Seigneur lui dit: Demande-moi quelque chose pour toi.
Ní Gibeoni, Olúwa fi ara han Solomoni lójú àlá ní òru, Ọlọ́run sì wí pé, “Béèrè fún ohunkóhun tí o bá ń fẹ́ kí èmi ó fi fún ọ.”
6 Et Salomon répondit: Vous avez usé d'une grande miséricorde envers mon père David votre serviteur, parce qu'il avait marché devant vous dans les voies de la vérité et de la justice, et dans la droiture du cœur. Et gardant envers lui cette grande miséricorde, vous avez fait monter son fils sur le trône où il est aujourd'hui.
Solomoni sì dáhùn wí pé, “O ti fi inú rere oore ńlá hàn sí ìránṣẹ́ rẹ, Dafidi baba mi, nítorí ó jẹ́ olóòtítọ́ sí ọ àti olódodo àti ẹni tí ó ní ọkàn ìdúró ṣinṣin. Ìwọ sì tẹ̀síwájú nínú oore ńlá yìí fún un, ìwọ sì ti fún un ní ọmọkùnrin láti jókòó lórí ìtẹ́ rẹ ní gbogbo ọjọ́.
7 Vous venez, Seigneur mon Dieu, de mettre à la place de David mon père, moi votre serviteur, moi qui suis encore un jeune adolescent, et qui ne sais encore ni entrer, ni sortir.
“Nísinsin yìí, Olúwa Ọlọ́run mi, o ti mú ìránṣẹ́ rẹ jẹ ọba ní ipò Dafidi baba mi. Ṣùgbọ́n ọmọ kékeré ni mí, èmi kò sì mọ jíjáde àti wíwọlé mi.
8 Et votre serviteur se trouve au milieu de votre peuple, du peuple nombreux que vous vous êtes choisi, d'un peuple innombrable.
Ìránṣẹ́ rẹ nìyí láàrín àwọn ènìyàn tí o ti yàn, àwọn ènìyàn ńlá, wọ́n pọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí a kò sì lè kà wọ́n tàbí mọye wọn.
9 Donnez donc à votre serviteur un cœur qui écoute, qui juge votre peuple selon la justice, et qui sache discerner le bien et le mal; car qui pourrait juger votre peuple, ce peuple puissant?
Nítorí náà fi ọkàn ìmòye fún ìránṣẹ́ rẹ láti le ṣàkóso àwọn ènìyàn rẹ àti láti mọ ìyàtọ̀ láàrín rere àti búburú. Nítorí ta ni ó lè ṣe àkóso àwọn ènìyàn ńlá rẹ yìí?”
10 Et il fut agréable au Seigneur que Salomon eût fait cette demande.
Inú Olúwa sì dùn pé Solomoni béèrè nǹkan yìí.
11 Et le Seigneur lui dit: Parce que tu m'as demandé cette chose, et que tu ne m'as pas demandé pour toi de longs jours, que tu ne m'as pas demandé des richesses, que tu ne m'as pas demandé la mort de tes ennemis, mais que tu m'as demandé pour toi la sagesse, afin de discerner ce qui est juste,
Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un pé, “Nítorí tí ìwọ ti béèrè fún èyí, tí kì í ṣe ẹ̀mí gígùn tàbí ọrọ̀ fún ara rẹ, tàbí béèrè fún ikú àwọn ọ̀tá rẹ, ṣùgbọ́n fún òye láti mọ ẹjọ́ dá,
12 J'ai déjà fait selon ta parole: voilà que je t'ai doué d'un cœur prudent et sage; il n'a existé avant toi personne qui te ressemble, et après toi, on ne verra jamais ton semblable.
èmi yóò ṣe ohun tí ìwọ ti béèrè. Èmi yóò fún ọ ní ọgbọ́n àti ọkàn ìmòye, tó bẹ́ẹ̀ tí kò fi ní sí ẹnìkan tí ó dàbí rẹ ṣáájú rẹ, bẹ́ẹ̀ ni ẹnìkan kì yóò dìde tí yóò dàbí rẹ lẹ́yìn rẹ.
13 Je t'ai donné, en outre, ce que tu n'as pas demandé, la richesse et la gloire, au point que nul des rois ne t'a jamais égalé.
Síwájú sí i, èmi yóò fi ohun tí ìwọ kò béèrè fún ọ: ọrọ̀ àti ọlá ní gbogbo ayé rẹ, tí kì yóò sí ẹnìkan nínú àwọn ọba tí yóò dàbí rẹ.
14 Si tu marches en ma voie comme a marché David ton père, en gardant mes commandements et mes ordonnances, je t'accorderai, de plus, de longs jours.
Àti bí ìwọ bá rìn ní ọ̀nà mi, tí o sì pa òfin àti àṣẹ mi mọ́ bí Dafidi baba rẹ ti ṣe, èmi yóò fún ọ ní ẹ̀mí gígùn.”
15 Et Salomon s'éveilla, et il n'oublia point ce songe; il se leva, et rentra dans Jérusalem; il se plaça debout devant l'autel et devant l'arche du Seigneur en Sion; puis, il sacrifia des holocaustes et des hosties pacifiques; enfin il fit préparer un grand festin pour lui-même et pour tous ses serviteurs.
Solomoni jí: ó sì mọ̀ pé àlá ni. Ó sì padà sí Jerusalẹmu, ó sì dúró níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa, ó sì rú ẹbọ sísun àti ẹbọ àlàáfíà. Nígbà náà ni ó ṣe àsè fún gbogbo àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀.
16 Alors, deux femmes prostituées apparurent en présence du roi, et elles se tinrent debout devant lui.
Lẹ́yìn náà ni àwọn obìnrin alágbèrè méjì wá sọ́dọ̀ ọba, wọ́n sì dúró níwájú rẹ̀.
17 L'une des deux femmes dit: Je te prie, Seigneur: Moi et cette femme nous habitons la même maison, et dans cette maison nous avons enfanté.
Ọ̀kan nínú wọn sì wí pé, “Olúwa mi, èmi àti obìnrin yìí ń gbé nínú ilé kan. Èmi sì bí ọmọ ní ilé pẹ̀lú rẹ̀.
18 Trois jours après que je fus accouchée, cette femme est accouchée aussi; nous étions ensemble, et il n'y avait personne que nous deux dans la maison.
Ní ọjọ́ kẹta lẹ́yìn ìgbà tí mo bímọ tan, obìnrin yìí sì bímọ pẹ̀lú. A sì nìkan dá wà; kò sí àlejò ní ilé bí kò ṣe àwa méjèèjì nìkan.
19 Or, l'enfant de cette femme est mort la nuit dernière, parce qu'elle s'était couchée sur lui.
“Ní òru, ọmọ obìnrin yìí kú nítorí tí ó sùn lé e.
20 Et elle s'est levée au milieu de la nuit; et elle a pris mon enfant dans mes bras, et elle l'a mis en son sein; et son fils mort elle l'a placé en mon sein.
Nígbà náà ni ó sì dìde ní ọ̀gànjọ́, ó sì gbé ọmọ tèmi lẹ́gbẹ̀ẹ́ mi, nígbà tí èmi ìránṣẹ́ rẹ̀ ti sùn lọ. Ó sì tẹ́ ẹ sí àyà rẹ̀, ó sì tẹ́ òkú ọmọ tirẹ̀ sí àyà mi.
21 Je me suis réveillée de grand matin pour allaiter mon fils, et l'enfant était mort; or, comme je le regardais bien attentivement aux premières lueurs du jour, je vis que ce n'était pas le fils que j'avais enfanté.
Ní òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, mo sì dìde láti fi ọmú fún ọmọ mi: ó sì ti kú! Ṣùgbọ́n, nígbà tí mo sì wò ó fín ní òwúrọ̀, mo sì rí i pé kì í ṣe ọmọ mi tí mo bí.”
22 L'autre femme s'écria: Du tout, mais mon fils est vivant, c'est ton fils qui est mort. Et elles parlaient ainsi devant le roi.
Obìnrin kejì sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí alààyè ni ọmọ mi, èyí òkú ni ọmọ tirẹ̀.” Èyí òkú ni tirẹ̀; èyí alààyè ni tèmi. Ṣùgbọ́n èyí àkọ́kọ́ tún wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Èyí òkú ni tìrẹ; èyí alààyè ni tèmi.” Báyìí ni wọ́n sì ń jiyàn níwájú ọba.
23 Et le roi dit à l'une: Tu dis: Celui-ci, le vivant, est mon fils, et le fils de cette femme est mort; puis il dit à l'autre: Tu dis: Du tout, mais mon fils est vivant, et c'est ton fils qui est mort.
Ọba sì wí pé, “Ẹni yìí wí pé, ‘Ọmọ mi ni ó wà láààyè, ọmọ tirẹ̀ ni ó kú,’ nígbà tí ẹni èkejì náà ń wí pé, ‘Bẹ́ẹ̀ kọ́! Ọmọ tirẹ̀ ni ó kú, ọmọ tèmi ni ó wà láààyè.’”
24 Et le roi ajouta: Que l'on prenne un glaive. Et l'on apporta un glaive devant le roi.
Nígbà náà ni ọba wí pé, “Ẹ mú idà fún mi wá.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú idà wá fún ọba.
25 Et le roi dit: Coupez en deux cet enfant vivant qui est à la mamelle, donnez-en la moitié à celle-ci, la moitié à celle-là.
Ọba sì pàṣẹ pé, “Ẹ gé alààyè ọmọ sí méjì, kí ẹ sì mú ìdajì fún ọ̀kan, àti ìdajì fún èkejì.”
26 Et la femme à qui était l'enfant vivant se hâta de parler au roi, car ses entrailles étaient troublées à cause de son fils, et elle dit: Je te prie, Seigneur, qu'on lui donne l'enfant, qu'on ne le fasse pas mourir. Mais l'autre dit: Qu'il ne soit ni pour elle, ni pour moi, partagez-le.
Obìnrin tí ọmọ tirẹ̀ wà láààyè sì kún fún àánú fún ọmọ rẹ̀, ó sì wí fún ọba pé, “Jọ̀wọ́, olúwa mi, ẹ fún un ní alààyè ọmọ! Ẹ má ṣe pa á!” Ṣùgbọ́n obìnrin èkejì sì wí pé, “Kì yóò jẹ́ tèmi tàbí tìrẹ. Ẹ gé e sí méjì!”
27 Et le roi prit la parole, et il dit: Donnez l'enfant à celle qui a dit: Donnez-lui l'enfant, ne le faites pas mourir; celle-là est sa mère.
Nígbà náà ni ọba dáhùn, ó wí pé, “Ẹ fi alààyè ọmọ fún obìnrin àkọ́kọ́. Ẹ má ṣe pa á: òun ni ìyá rẹ̀.”
28 Et tout Israël citât le jugement qu'avait rendu le roi, et ils eurent crainte du roi, car ils virent que la sagesse de Dieu était en lui quand il rendait la justice.
Nígbà tí gbogbo Israẹli gbọ́ ìdájọ́ tí ọba ṣe, wọ́n sì bẹ̀rù níwájú ọba, nítorí wọ́n ti rí í pé ó ní ọgbọ́n láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run láti ṣe ìdájọ́.