< 1 Chroniques 6 >

1 Fils de Lévi: Gerson, Caath et Mérari.
Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
2 Fils de Caath: Amram et Isaar, Hébron et Oziel.
Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni, àti Usieli.
3 Enfants d'Amram: Aaron, Moïse et Marie. Fils d'Aaron: Nadab et Abiud, Eléazar et Ithamar.
Àwọn ọmọ Amramu: Aaroni, Mose àti Miriamu. Àwọn ọmọkùnrin Aaroni: Nadabu, Abihu, Eleasari àti Itamari.
4 Eléazar engendra Phinéès, et Phinéès engendra Abisué.
Eleasari jẹ́ baba Finehasi, Finehasi baba Abiṣua
5 Abisué engendra Bocci, et Bocci engendra Ozi.
Abiṣua baba Bukki, Bukki baba Ussi,
6 Ozi engendra Zaraïas, et Zaraïas engendra Mariel.
Ussi baba Serahiah, Serahiah baba Meraioti,
7 Mariel engendra Amarias, et Amarias engendra Achitob.
Meraioti baba Amariah, Amariah baba Ahitubu
8 Achitob engendra Sadoc, et Sadoc engendra Achimaas.
Ahitubu baba Sadoku, Sadoku baba Ahimasi,
9 Achimaas engendra Azarias, et Azarias engendra Johanan,
Ahimasi baba Asariah, Asariah baba Johanani,
10 Johanan engendra Azarias; ce fut lui qui exerça le sacerdoce dans le temple que Salomon bâtit à Jérusalem.
Johanani baba Asariah. (Òhun ni ó sìn gẹ́gẹ́ bí àlùfáà nínú ilé Olúwa tí Solomoni kọ́ sí Jerusalẹmu).
11 Azarias engendra Amarias, et Amarias engendra Achitob.
Asariah baba Amariah Amariah baba Ahitubu
12 Achitob engendra Sadoc, et Sadoc engendra Salom.
Ahitubu baba Sadoku. Sadoku baba Ṣallumu,
13 Salom engendra Helcias, et Helcias engendra Azarias.
Ṣallumu baba Hilkiah, Hilkiah baba Asariah,
14 Azarias engendra Saraias, et Sareas engendra Josadac.
Asariah baba Seraiah, pẹ̀lú Seraiah baba Josadaki.
15 Josadac fut enlevé, avec Juda et Jérusalem, par Nabuchodonosor.
A kó Josadaki lẹ́rú nígbà tí Olúwa lé Juda àti Jerusalẹmu kúrò ní ìlú nípasẹ̀ Nebukadnessari.
16 Fils de Lévi: Gerson, Caath et Mérari.
Àwọn ọmọ Lefi: Gerṣoni, Kohati àti Merari.
17 Fils de Gerson: Lobeni et Sémei.
Wọ̀nyí ni àwọn orúkọ àwọn ọmọ Gerṣoni: Libni àti Ṣimei.
18 Fils de Caath: Amram et Isaac, Hébron et Oziel.
Àwọn ọmọ Kohati: Amramu, Isari, Hebroni àti Usieli.
19 Fils de Mérari: Mooli et Musi; voici les familles de Lévi, désignées par les noms de leurs pères.
Àwọn ọmọ Merari: Mahili àti Muṣi. Wọ̀nyí ni àwọn ìdílé ará Lefi tí a kọ ní ṣísẹ̀-n-tẹ̀lé gẹ́gẹ́ bí baba wọn.
20 A Gerson et Lobeni son fils succèdent Jeth fils de ce dernier, Zamath son fils,
Ti Gerṣoni: Libni ọmọkùnrin rẹ̀, Jahati. Ọmọkùnrin rẹ̀, Simma ọmọkùnrin rẹ̀,
21 Joab son fils, Addi son fils, Zara son fils, Jethri son fils.
Joah ọmọkùnrin rẹ̀, Iddo ọmọkùnrin rẹ̀, Sera ọmọkùnrin rẹ̀ àti Jeaterai ọmọkùnrin rẹ̀.
22 De Caath descendent: Aminadab son fils, Coré son fils, Aser son fils,
Àwọn ìran ọmọ Kohati: Amminadabu ọmọkùnrin rẹ̀, Kora ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
23 Elcana son fils, Abisaph son fils, Aser son fils,
Elkana ọmọkùnrin rẹ̀, Ebiasafi ọmọkùnrin rẹ̀, Asiri ọmọkùnrin rẹ̀.
24 Thaat son fils, Uriel son fils, Saül son fils.
Tahati ọmọkùnrin rẹ̀, Urieli ọmọkùnrin rẹ̀, Ussiah ọmọkùnrin rẹ̀ àti Saulu ọmọkùnrin rẹ̀.
25 D'Elcana descendent encore: Amessi et Achimoth.
Àwọn ìran ọmọ Elkana: Amasai, Ahimoti
26 Elcana son fils, Saphi son fils, Cénaath son fils,
Elkana ọmọ rẹ̀, Sofai ọmọ rẹ̀ Nahati ọmọ rẹ̀,
27 Eliab son fils, Jéroboam son fils, Elcana son fils.
Eliabu ọmọ rẹ̀, Jerohamu ọmọ rẹ̀, Elkana ọmọ rẹ̀ àti Samuẹli ọmọ rẹ̀.
28 Fils de Samuel: Sari, premier-né, et Ables.
Àwọn ọmọ Samuẹli: Joẹli àkọ́bí àti Abijah ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì.
29 Fils de Mérari: Mooli son fils, Lobeni son fils, Sémei son fils, Oza son fils,
Àwọn ìran ọmọ Merari: Mahili, Libni ọmọ rẹ̀. Ṣimei ọmọ rẹ̀, Ussa ọmọ rẹ̀.
30 Samaa son fils, Aggia son fils, Asaïas son fils.
Ṣimea ọmọ rẹ̀, Haggiah ọmọ rẹ̀ àti Asaiah ọmọ rẹ̀.
31 Et voici ceux que David institua chefs des chœurs du tabernacle, lorsqu'il eut transféré l'arche à Jérusalem.
Èyí ní àwọn ọkùnrin Dafidi tí a fi sí ìdí orin nínú ilé Olúwa lẹ́yìn tí àpótí ẹ̀rí ti wá láti sinmi níbẹ̀.
32 Et ils s'accompagnaient avec des instruments, devant le tabernacle du témoignage, jusqu'à ce que Salomon eût bâti le temple du Seigneur à Jérusalem. Et ils servaient, chacun selon la fonction qui lui était assignée.
Wọ́n jíṣẹ́ pẹ̀lú orin níwájú àgọ́ ìpàdé títí tí Solomoni fi kọ́ ilé Olúwa ní Jerusalẹmu. Wọ́n ṣe iṣẹ́ ìsìn wọn ní ìbámu pẹ̀lú ìlànà tí a fi lélẹ̀ fún wọn.
33 Voici leurs noms et ceux de leurs pères: de Caath descendait: Hëman, chantre et harpiste, fils de Johel, fils de Samuel,
Wọ̀nyí ni àwọn ọkùnrin tí ó sìn pẹ̀lú ọmọ wọn. Láti ọ̀dọ̀ àwọn ará Kohati: Hemani olùkọrin, ọmọ Joẹli, ọmọ Samuẹli,
34 Fils d'Elcana, fils de Jéroboam, fils d'Eliel, fils de Thoü,
ọmọ Elkana, ọmọ Jerohamu, ọmọ Elieli, ọmọ Toha,
35 Fils de Suph, fils d'Elcana, fils de Maath, fils d'Amathi,
ọmọ Sufu, ọmọ Elkana, ọmọ Mahati, ọmọ Amasai,
36 Fils d'Elcana, fils de Johel, fils d'Azarias, fils de Saphanie,
ọmọ Elkana, ọmọ Joẹli, ọmọ Asariah, ọmọ Sefaniah,
37 Fils de Thaath, fils d'Aser, fils d'Abiasaph, fils de Coré,
ọmọ Tahati, ọmọ Asiri, ọmọ Ebiasafi, ọmọ Kora,
38 Fils d'Isaar, fils de Caath, fils de Lévi, fils d'Israël.
ọmọ Isari, ọmọ Kohati, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli;
39 Et Asaph, chantre comme lui, qui se tenait à sa droite, était fils de Barachias, fils de Samaa,
Hemani sì darapọ̀ mọ́ Asafu, ẹni tí o sìn ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀: Asafu ọmọ Berekiah, ọmọ Ṣimea,
40 Fils de Michel, fils de Baasie, fils de Melchias,
ọmọ Mikaeli, ọmọ Baaseiah, ọmọ Malkiah
41 Fils d'Athani, fils de Zaaraï, fils d'Adaï,
ọmọ Etini, ọmọ Sera, ọmọ Adaiah,
42 Fils d'Etham, fils de Zamnaam, fils de Sémeï,
ọmọ Etani, ọmọ Simma, ọmọ Ṣimei,
43 Fils de Jeth, petit-fils de Gerson, fils de Lévi.
ọmọ Jahati, ọmọ Gerṣoni, ọmọ Lefi;
44 Et de Mérari descendaient les chantres qui se tenaient à gauche, dont le chef était: Ethan, fils de Cisa, fils d'Abe, fils de Maloch,
láti ìbákẹ́gbẹ́ wọn, àwọn ará Merari wà ní ọwọ́ òsì rẹ̀: Etani ọmọ Kiṣi, ọmọ Abdi, ọmọ Malluki,
45 Fils d'Asebi,
ọmọ Haṣabiah, ọmọ Amasiah, ọmọ Hilkiah,
46 Fils d'Amessias, fils de Bani, fils de Semer,
ọmọ Amisi, ọmọ Bani, ọmọ Ṣemeri,
47 Fils de Mooli, fils de Musi, fils de Mérari, fils de Lévi.
ọmọ Mahili, ọmọ Muṣi, ọmọ Merari, ọmọ Lefi.
48 Et les lévites leurs frères, selon leurs familles paternelles, étaient attachés aux divers services du tabernacle de Dieu.
Àwọn Lefi ẹgbẹ́ wọn ni wọn yan àwọn iṣẹ́ yòókù ti àgọ́ fún, èyí tí í ṣe ilé Ọlọ́run.
49 Aaron, et, après lui, ses fils sacrifiaient sur l'autel des holocaustes et sur l'autel des parfums; ils remplissaient toutes les fonctions relatives au Saint des saints; et ils priaient pour Israël, conformément à ce que leur avait commandé Moïse serviteur de Dieu.
Ṣùgbọ́n Aaroni àti àwọn ìran ọmọ rẹ̀ jẹ́ àwọn tí ó gbé ọrẹ kalẹ̀ lórí pẹpẹ ẹbọ sísun àti lórí pẹpẹ tùràrí ní ìbátan pẹ̀lú gbogbo ohun tí a ṣe ní Ibi Mímọ́ Jùlọ. Ṣíṣe ètùtù fún Israẹli, ní ìbámu pẹ̀lú gbogbo ohun tí Mose ìránṣẹ́ Ọlọ́run ti pàṣẹ.
50 Voici les fils d'Aaron: Eléazar son fils, Phinéès son fils, Abisué son fils,
Wọ̀nyí ni àwọn ìránṣẹ́ Aaroni: Eleasari ọmọ rẹ̀, Finehasi ọmọ rẹ̀, Abiṣua ọmọ rẹ̀,
51 Bocci son fils, Ozi son fils, Saraïa son fils,
Bukki ọmọ rẹ̀, Ussi ọmọ rẹ̀, Serahiah ọmọ rẹ̀,
52 Mariel son fils, Amarias son fils, Achitob son fils,
Meraioti ọmọ rẹ̀, Amariah ọmọ rẹ̀, Ahitubu ọmọ rẹ̀,
53 Sadoc son fils, Achimais son fils.
Sadoku ọmọ rẹ̀ àti Ahimasi ọmọ rẹ̀.
54 Voici les demeures, les bourgs et les territoires, assignés par le sort, selon leurs familles, aux fils d'Aaron, et aux fils de Caath.
Wọ̀nyí ni ibùgbé wọn tí a pín fún wọn gẹ́gẹ́ bí agbègbè wọn (tí a fi lé àwọn ìran ọmọ Aaroni lọ́wọ́ tí ó wá láti ẹ̀yà Kohati, nítorí kèké alákọ́kọ́ jẹ́ tiwọn).
55 Il leur fut donné Hébron, en la terre de Juda, et sa banlieue tout alentour.
A fún wọn ní Hebroni ní Juda pẹ̀lú àyíká pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
56 Mais les champs de la ville et ses bourgs appartenaient à Caleb, fils de Jéphoné.
Ṣùgbọ́n àwọn pápá àti ìletò tí ó yí ìlú ńlá náà ká ni a fi fún Kalebu ọmọ Jefunne.
57 Les villes de refuge furent aussi concédées aux fils d'Aaron, savoir: Hébron, Lobna et sa banlieue, Selna et sa banlieue, Esthamo et sa banlieue,
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ìran ọmọ Aaroni ni a fún ní Hebroni (ìlú ti ààbò), àti Libina, Jattiri, Eṣitemoa,
58 Jethar et sa banlieue, Dabir et sa banlieue,
Hileni, Debiri,
59 Asan et sa banlieue, Bethsamys et sa banlieue.
Aṣani, Jutta àti Beti-Ṣemeṣi lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ rẹ̀.
60 Et, dans la tribu de Benjamin, Gabée et sa banlieue, Galemath et sa banlieue, Anathoth et sa banlieue. En tout treize villes par familles.
Àti láti inú ẹ̀yà Benjamini, a fún wọn ní Gibeoni, Geba, Alemeti àti Anatoti lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn. Àwọn ìlú wọ̀nyí, tí a pín láàrín àwọn ẹ̀yà Kohati jẹ́ mẹ́tàlá ní gbogbo rẹ̀.
61 Et le sort assigna au reste des fils de Caath, par familles, dix villes de la demi-tribu de Manassé, en deçà du Jourdain.
Ìyókù àwọn ìran ọmọ Kohati ní a pín ìlú mẹ́wàá fún láti àwọn ìdílé ní ti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase.
62 Et aux fils de Gerson, par familles, treize villes des tribus d'Issachar, d'Aser, de Nephthali et de la demi-tribu de Manassé en Hasan.
Àwọn ìran ọmọ Gerṣoni, sí ìdílé ni a pín ìlú mẹ́tàlá fún láti ẹ̀yà àwọn ẹ̀yà Isakari, Aṣeri àti Naftali, àti láti apá ẹ̀yà Manase tí ó wà ní Baṣani.
63 Et aux fils de Mérari, par familles, douze villes des tribus de Ruben, de Gad et de Zabulon.
Sebuluni àwọn ìran ọmọ Merari, ìdílé sí ìdílé, ní a pín ìlú méjìlá fún láti ẹ̀yà Reubeni, Gadi àti Sebuluni.
64 Et les fils d'Israël accordèrent aux lévites ces villes et leurs banlieues.
Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli fún àwọn ará Lefi ní ìlú wọ̀nyí pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
65 Le sort désigna dans les tribus de Juda, de Siméon et de Benjamin, les villes auxquelles les lévites donnèrent leurs noms,
Láti ẹ̀yà Juda, Simeoni àti Benjamini ni a pín ìlú tí a ti dárúkọ wọn sẹ́yìn fún.
66 D'après les familles des fils de Caath. Et ils eurent aussi des villes du territoire d'Ephraïm,
Lára àwọn ìdílé Kohati ni a fún ní ìlú láti ẹ̀yà Efraimu gẹ́gẹ́ bí ìlú agbègbè wọn.
67 Y compris les villes de refuge: Sichem et sa banlieue, dans la montagne d'Ephraïm, Gazer et sa banlieue,
Ní òkè orílẹ̀-èdè Efraimu, a fún wọn ní Ṣekemu (ìlú ńlá ti ààbò), àti Geseri
68 Jecmaan et sa banlieue, Béthoron et sa banlieue.
Jokimeamu, Beti-Horoni.
69 Et, en d'autres territoires, Aïlon et sa banlieue, Gethremmon et sa banlieue.
Aijaloni àti Gati-Rimoni lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
70 Et de la demi-tribu de Manassé: Anar et sa banlieue, Jemblaan et sa banlieue, selon les familles du reste des fils de Caath.
Pẹ̀lú láti apá ààbọ̀ ẹ̀yà Manase àwọn ọmọ Israẹli fún Aneri àti Bileamu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn, fún ìyókù àwọn ìdílé Kohati.
71 Les fils de Gerson, par familles, eurent dans l'autre demi-tribu de Manassé, Golan en Basan et sa banlieue, Aseroth et sa banlieue.
Àwọn ará Gerṣoni gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ààbọ̀ ẹ̀yà ti Manase wọ́n gba Golani ní Baṣani àti pẹ̀lú Aṣtarotu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù wọn.
72 Et dans la tribu d'Issachar: Cédés et sa banlieue, Deberi et sa banlieue, Dabor et sa banlieue,
Láti ẹ̀yà Isakari wọ́n gba Kedeṣi, Daberati
73 Ramoth, Aïnan et sa banlieue.
Ramoti àti Anenu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
74 Et dans la tribu d'Aser: Maasal et sa banlieue, Abdon et sa banlieue,
Láti ẹ̀yà Aṣeri wọ́n gba Maṣali, Abdoni,
75 Acac et sa banlieue, Rhoob et sa banlieue.
Hukoki àti Rehobu lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
76 Et dans la tribu de Nephthali: Cédés en Gaulée et sa banlieue, Hamoth et sa banlieue, Cariathaïm et sa banlieue.
Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Naftali wọ́n gba Kedeṣi ní Galili, Hammoni àti Kiriataimu, lápapọ̀ pẹ̀lú pápá oko tútù ilẹ̀ wọn.
77 Et dans la tribu de Zabulon: le sort attribua au reste des fils de Mérari, Remmon et sa banlieue, Thabor et sa banlieue.
Àwọn ará Merari (ìyókù àwọn ará Lefi) gbà nǹkan wọ̀nyí. Láti ẹ̀yà Sebuluni wọ́n gba Jokneamu, Karta, Rimoni àti Tabori, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
78 Et dans la vallée du Jourdain à l'occident du fleuve: Jéricho, et dans la tribu de Ruben: Bosor dans le désert et sa banlieue, Jasa et sa banlieue,
Láti ẹ̀yà Reubeni rékọjá Jordani ìlà-oòrùn Jeriko wọ́n gba Beseri nínú aginjù Jahisa,
79 Cadmoth et sa banlieue, Maephla et sa banlieue.
Kedemoti àti Mefaati, lápapọ̀ pẹ̀lú ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.
80 Dans la tribu de Gad: Ramoth-Galaad et sa banlieue, Maanaïm et sa banlieue,
Pẹ̀lú láti ẹ̀yà Gadi wọ́n gba Ramoti ní Gileadi Mahanaimu,
81 Esébon et sa banlieue, Jazer et sa banlieue.
Heṣboni àti Jaseri lápapọ̀ pẹ̀lú àwọn ilẹ̀ pápá oko tútù wọn.

< 1 Chroniques 6 >