< 1 Chroniques 5 >

1 Voici les fils de Ruben; il était le premier-né; mais parce qu'il s'était introduit dans la couche de son père, Jacob ayant donné sa bénédiction à son fils Joseph, le droit d'aînesse de Ruben ne lui était plus compté.
Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Reubeni, àkọ́bí Israẹli. (Nítorí òun ni àkọ́bí; ṣùgbọ́n, bí ó ti ṣe pé ó ba ibùsùn baba rẹ̀ jẹ́, a fi ogún ìbí rẹ̀ fún àwọn ọmọ Josẹfu ọmọ Israẹli: a kì yóò sì ka ìtàn ìdílé náà gẹ́gẹ́ bí ipò ìbí.
2 Car Juda était fort parmi ses frères; le chef est sorti de lui, la bénédiction est restée à Joseph.
Nítorí Juda borí àwọn arákùnrin rẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni aláṣẹ ti ń jáde wá; ṣùgbọ́n ogún ìbí jẹ́ ti Josẹfu),
3 Fils de Ruben, premier-né d'Israël: Enoch, Phallus, Asron et Charmi.
àwọn ọmọ Reubeni àkọ́bí Israẹli ni: Hanoku àti Pallu, Hesroni àti Karmi.
4 Fils de Johel: Sémeï et Banaïas son fils. Fils de Gug, fils de Sémeï,
Àwọn ọmọ Joẹli: Ṣemaiah ọmọ rẹ̀, Gogu ọmọ rẹ̀, Ṣimei ọmọ rẹ̀.
5 Micha, son fils Recha, son fils Johel,
Mika ọmọ rẹ̀, Reaiah ọmọ rẹ̀, Baali ọmọ rẹ̀.
6 Son fils Behel, qu'emmena Thelgath-Phalnasar, roi des Assyriens; il était le chef des Rubénites.
Beera ọmọ rẹ̀, tí Tiglat-Pileseri ọba Asiria kó ní ìgbèkùn lọ. Ìjòyè àwọn ọmọ Reubeni ni Beera jẹ́.
7 Et, avec lui, furent emmenés ses frères, selon le dénombrement qui en fut fait par familles; les chefs de ces familles étaient: Johel, Zacharie,
Àti àwọn arákùnrin rẹ̀ nípa ìdílé wọn, nígbà tí a ń ka ìtàn ìdílé ìran wọn: Jeieli àti Sekariah ni olórí,
8 Et Balec, fils d'Azuz, fils de Sama, fils de Johel. Balec demeurait en Aroer, et vers Nebo et Belmasson.
àti Bela ọmọ Asasi ọmọ Ṣema, ọmọ Joẹli. Wọ́n tí ń gbé Aroeri àní títí dé Nebo àti Baali-Meoni.
9 Et il s'était étendu à l'orient jusqu'au désert, du côté de l'Euphrate, parce qu'il avait de nombreux troupeaux en la terre de Galaad.
Àti níhà àríwá, o tẹ̀dó lọ títí dé àtiwọ aginjù láti odò Eufurate; nítorí tí ẹran ọ̀sìn wọn pọ̀ sí i ní ilẹ̀ Gileadi.
10 Et, sous le règne de Saül, ils furent en guerre avec leurs voisins, et ceux qui habitaient sous des tentes tombèrent entre leurs mains, et ils maîtrisèrent toute la contrée à l'orient de Galaad.
Àti ní ọjọ́ Saulu, wọ́n bá àwọn ọmọ Hagari jagun, ẹni tí ó ṣubú nípa ọwọ́ wọn; wọ́n sì ń gbé inú àgọ́ wọn ní gbogbo ilẹ̀ àríwá Gileadi.
11 Les fils de Gad, en face, demeurèrent en la terre de Basan jusqu'à Sela.
Àti àwọn ọmọ Gadi ń gbé lékè wọn, ní ilẹ̀ Baṣani títí dé Saleka:
12 Le premier-né fut Johel; le second Saphan; puis, venaient Jania, le scribe de Basan,
Joẹli jẹ́ olórí, Ṣafamu ìran ọmọ Janai, àti Ṣafati ni Baṣani.
13 Et ses frères, par familles paternelles: Michel, Mosollam, Sébée, Joré, Joachan, Zué et Obed; sept.
Àti àwọn arákùnrin wọn ti ilẹ̀ àwọn baba wọn ní: Mikaeli, Meṣullamu Ṣeba, Jorai, Jaka, Sia àti Eberi méje.
14 Les fils d'Abihaïl, fils d'Uri, fils d'Isaïe, fils de Galaad, fils de Michel, fils de Jésé, fils de Jeddé, fils de Bas,
Wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Abihaili, ọmọ Huri, ọmọ Jeroa, ọmọ Gileadi, ọmọ Mikaeli, ọmọ Jeṣiṣai, ọmọ Jado, ọmọ Busi.
15 Frère du fils d'Abdiel, fils de Guni, chef de la maison paternelle,
Ahi, ọmọ Adbeeli, ọmọ Guni, olórí ilé àwọn baba wọn.
16 Habitaient en Galaad, en Basan, en leurs bourgs et en tout le territoire de Saron jusqu'à ses limites.
Wọ́n sì ń gbé Gileadi ní Baṣani àti nínú àwọn ìlú rẹ̀, àti nínú gbogbo ìgbèríko Ṣaroni, ní agbègbè wọn.
17 Leur dénombrement fut fait du temps de Joatham, roi de Juda, et de Jéroboam, roi d'Israël.
Gbogbo wọ̀nyí ni a kà nípa ìtàn ìdílé, ní ọjọ́ Jotamu ọba Juda, àti ní ọjọ́ Jeroboamu ọba Israẹli.
18 Les fils de Ruben, Gad et la demi-tribu de Manassé comptaient quarante- quatre mille sept cent soixante hommes, dans la force de l'âge, portant glaive et bouclier, tendant l'arc, exercés à la guerre, propres à marcher au combat.
Àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase, nínú àwọn ọkùnrin alágbára tí wọ́n ń gbé asà àti idà, tí wọ́n sì ń fi ọrun tafà, tí wọ́n sì mòye ogun, jẹ́ ọ̀kẹ́ méjì ó lé ẹgbẹ̀rìnlélógún dín ogójì ènìyàn, tí ó jáde lọ sí ogún náà.
19 Et ils furent en guerre avec les Agaréens, les Ituréens, les Naphiséens et les Nadabéens.
Wọ́n sì bá àwọn ọmọ Hagari jagun, pẹ̀lú Jeturi, àti Nafiṣi àti Nadabu.
20 Et ils l'emportèrent sur eux. Et les Agaréens, avec toutes leurs tentes, tombèrent entre leurs mains, parce que les vainqueurs avaient invoqué Dieu pendant la bataille; et Dieu les exauça, parce qu'ils avaient espéré en lui.
Nígbà tí wọ́n sì rí ìrànlọ́wọ́ gbà si, a sì fi àwọn ọmọ Hagari lé wọn lọ́wọ́, àti gbogbo àwọn tí ó wà pẹ̀lú wọn; nítorí tiwọn ké pe Ọlọ́run ní ogun náà, òun sì gbọ́ ẹ̀bẹ̀ wọn; nítorí tí wọ́n gbẹ́kẹ̀ wọn lé e.
21 Et ils prirent tout ce que les autres possédaient: cinquante mille chameaux, deux cent cinquante mille brebis, deux mille ânes; et la vie de cent mille hommes.
Wọ́n sì kó ẹran ọ̀sìn wọn lọ; ìbákasẹ ẹgbàá mẹ́ẹ̀ẹ́dọ́gbọ̀n àti àgùntàn ọ̀kẹ́ méjìlá ó lé ẹgbàárùn-ún, àti kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ ẹgbẹ̀rún méjì, àti ènìyàn ọ̀kẹ́ márùn-ún.
22 Car une grande multitude de blessés succomba, parce que cette guerre s'était faite selon la volonté de Dieu, et les vainqueurs habitèrent le territoire des vaincus Jusqu'à la captivité.
Nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni ó ṣubú tí a pa, nítorí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run ni ogun náà, wọ́n sì jókòó ní ipò wọn títí di ìgbà ìkólọ sí ìgbèkùn.
23 Et la demi-tribu de Manassé s'étendit de Basan Baal, Hermon, Sanir et la montagne d'Hermon; ses fils se multiplièrent dans le Liban.
Àwọn ọmọkùnrin ààbọ̀ ẹ̀yà Manase ń gbé ní ilẹ̀ náà: wọ́n bí sí i láti Baṣani títí dé Baali-Hermoni, àti Seniri àti títí dé òkè Hermoni.
24 Et voici leurs chefs, par familles: Opher, Sei, Eliel, Jérémie, Oduïa et Jediel; hommes riches et renommés, chefs des familles de la demi-tribu.
Wọ̀nyí sì ni àwọn olórí ilé àwọn baba wọn. Eferi, Iṣi, Elieli, Asrieli, Jeremiah, Hodafiah àti Jahdieli àwọn alágbára akọni ọkùnrin, ọkùnrin olókìkí, àti olórí ilé àwọn baba wọn.
25 Et ils répudièrent le Dieu de leurs pères, et ils se prostituèrent à la suite des dieux de la terre que le Seigneur avait effacés devant leur face.
Wọ́n sì ṣẹ̀ sí Ọlọ́run àwọn baba wọn, wọ́n sì ṣe àgbèrè tọ àwọn ọlọ́run ènìyàn ilẹ̀ náà lẹ́yìn, tí Ọlọ́run ti parun ní iwájú wọn.
26 Et le Dieu d'Israël excita l'esprit de Phaloch (Phul), roi d'Assur, et l'esprit de Thelgath-Phalnasar, roi d'Assur. Ce roi enleva Ruben, et Gad, et la demi-tribu de Manassé, et il les transporta en Haach, en Hahor, et sur le fleuve Gozan, où ils sont restés jusqu'à nos jours.
Nítorí náà Ọlọ́run Israẹli ru ẹ̀mí Pulu ọba Asiria sókè (èyí ni Tiglat-Pileseri ọba Asiria), ó si kó wọn lọ, àní àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi, àti ààbọ̀ ẹ̀yà Manase lọ sí ìgbèkùn. Ó sì kó wọn wá sí Hala, àti Habori, àti Harani, àti sí etí odò Gosani; títí dí òní yìí.

< 1 Chroniques 5 >