< 1 Chroniques 2 >

1 Voici les noms des fils d'Israël: Ruben, Siméon, Lévi, Juda, Issachar, Zabulon,
Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Israẹli. Reubeni, Simeoni, Lefi, Juda, Isakari, Sebuluni,
2 Dan, Joseph, Benjamin, Nephthali, Gad, Aser.
Dani, Josẹfu, Benjamini; Naftali, Gadi: àti Aṣeri.
3 Fils de Juda: Her, Onan, Sela; tous trois naquirent de la fille de Savas (Sué), la Chananéenne; et Her, le premier-né de Juda, fit le mal devant le Seigneur, qui le tua.
Àwọn ọmọ Juda: Eri, Onani àti Ṣela, àwọn mẹ́tẹ̀ẹ̀ta wọ̀nyí ni wọ́n bí fún un láti ọ̀dọ̀ arábìnrin Kenaani, ọmọbìnrin Ṣua. Eri àkọ́bí Juda, ó sì burú ní ojú Olúwa, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa sì pa á.
4 Et Thamar, bru de Juda, enfanta Pharès et Zara; en tout: cinq fils de Juda.
Tamari, aya ọmọbìnrin Juda, ó sì bí Peresi àti Sera sì ní ọmọ márùn-ún ní àpapọ̀.
5 Fils de Pharès: Esron et Jemuhel.
Àwọn ọmọ Peresi: Hesroni àti Hamulu.
6 Fils de Zara: Zambri, Etham, Aimuan, Calchal et Darad; en tout: cinq.
Àwọn ọmọ Sera: Simri, Etani, Hemani, Kalkoli àti Dara, gbogbo wọn jẹ́ márùn-ún.
7 Fils de Charmi: Achar, le perturbateur d'Israël, qui désobéit au sujet de l'anathème.
Àwọn ọmọ Karmi: Akani, ẹni tí ó mú ìyọnu wá sórí Israẹli nípa ẹ̀ṣẹ̀ ìfibú lórí mímú ohun ìyàsọ́tọ̀.
8 Fils d'Etham: Azarias.
Àwọn ọmọ Etani: Asariah.
9 Fils d'Esron, qui lui furent enfantés: Jeraméel, Aram et Caleb.
Àwọn ọmọ tí a bí fún Hesroni ni: Jerahmeeli, Ramu àti Kalebu.
10 Aram engendra Aminadab; Aminadab engendra Nahasson, chef de la maison de Juda.
Ramu sì ni baba Amminadabu, àti Amminadabu baba Nahiṣoni olórí àwọn ènìyàn Juda.
11 Nahasson engendra Salmon; Salmon engendra Booz;
Nahiṣoni sì ni baba Salmoni, Salmoni ni baba Boasi,
12 Booz engendra Obed; Obed engendra Jessé;
Boasi baba Obedi àti Obedi baba Jese.
13 Jessé engendra son premier-né Eliab, le second Aminadab, le troisième Samaa,
Jese sì ni baba Eliabu àkọ́bí rẹ̀; ọmọ ẹlẹ́ẹ̀kejì sì ni Abinadabu, ẹlẹ́ẹ̀kẹta ni Ṣimea,
14 Nathanael le quatrième, Zabdé le cinquième,
ẹlẹ́ẹ̀kẹrin Netaneli, ẹlẹ́ẹ̀karùnún Raddai,
15 Azam le sixième, et David le septième.
ẹlẹ́ẹ̀kẹfà Osemu àti ẹlẹ́ẹ̀keje Dafidi.
16 Et leurs sœurs furent: Sarvia et Abigaïl. Les fils de Sarvia furent: Abessa, Joab et Asaël; trois.
Àwọn arábìnrin wọn ni Seruiah àti Abigaili. Àwọn ọmọ mẹ́ta Seruiah ni Abiṣai, Joabu àti Asaheli.
17 Abagaïl enfanta Amessab, et le père d'Amessab fut Jolhor l'Ismaélite.
Abigaili ni ìyá Amasa, ẹni tí baba rẹ̀ sì jẹ́ Jeteri ará Iṣmaeli.
18 Caleb, fils d'Esron, prit pour femmes Gazuba et Jerioth; voici ses fils: Jasar, Subab et Ardon.
Kalebu ọmọ Hesroni ní ọmọ láti ọ̀dọ̀ ìyàwó rẹ̀ Asuba (láti ọ̀dọ̀ Jerioti). Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ọmọ rẹ̀: Jeṣeri, Ṣobabu àti Ardoni.
19 Et Gazuba mourut, et Caleb prit pour femme Ephratha, et elle lui enfanta Hur.
Nígbà tí Asuba sì kú, Kalebu sì fẹ́ Efrata ní aya, ẹni tí ó bí Huri fún un.
20 Hur engendra Urias; Urias engendra Beseléel.
Huri ni baba Uri, Uri sì jẹ́ baba Besaleli.
21 Après cela, Esron eut commerce avec la fille de Machir, père de Galaad, et il la prit pour femme; il avait alors soixante-cinq ans, et elle lui enfanta Seruch.
Nígbà tí ó yá, Hesroni sì dùbúlẹ̀ pẹ̀lú ọmọbìnrin Makiri baba Gileadi (ó sì ti fẹ́ ní aya láti ìgbà tí ó ti wà ní ẹni ọgọ́ta ọdún) ó sì bí Segubu.
22 Seruch engendra Jaïr; il possédait vingt-trois villes en Galaad.
Segubu sì jẹ́ baba Jairi, ẹni tí ó jẹ́ olùdarí ìlú mẹ́tàlélógún ní ilẹ̀ Gileadi.
23 Il prit de plus Gessur et Aram, villes de Jaïr, parmi les siennes, et la terre de Canath avec ses villes: soixante villes; toutes appartenaient aux fils de Machir, père de Galaad.
(Ṣùgbọ́n Geṣuri àti Aramu sì fi agbára gba Hafoti-Jairi, àti Kenati pẹ̀lú gbogbo agbègbè rẹ̀ tí wọn tẹ̀dó sí jẹ́ ọgọ́ta ìlú.) Gbogbo wọ̀nyí ni àwọn ọmọ Makiri baba Gileadi.
24 Après la mort d'Esron, Caleb épousa Ephratha; or, Abia, femme d'Esron, lui avait enfanté Ascho, père de Thécoé.
Lẹ́yìn tí Hesroni sì kú ni Kalebu Efrata, Abijah ìyàwó rẹ̀ ti Hesroni sì bí Aṣihuri baba Tekoa fún un.
25 Les fils de Jeraméel, premier-né d'Esron, furent: Ram, premier-né; puis, Banaa, Aram et Asan, son frère.
Ọmọ Jerahmeeli àkọ́bí Hesroni: Ramu ọmọ àkọ́bí rẹ̀ Buna, Oreni, Osemu àti Ahijah.
26 Et Jeraméel avait une autre femme qui se nommait Atara; celle-ci fut la mère d'Ozom.
Jerahmeeli ní ìyàwó mìíràn, ẹni tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Atara; ó sì jẹ́ ìyá fún Onamu.
27 Les fils de Ram, premier-né de Jeraméel, furent: Mass, Jamin et Acor.
Àwọn ọmọ Ramu àkọ́bí Jerahmeeli: Maasi, Jamini àti Ekeri.
28 Les fils d'Ozom furent: Samaï et Jadaé, et les fils de Samaï: Nadab et Abisur.
Àwọn ọmọ Onamu: Ṣammai àti Jada. Àwọn ọmọ Ṣammai: Nadabu àti Abiṣuri.
29 La femme d'Abisur se nommait Abihaïl, et elle lui enfanta Achobor et Moêl.
Orúkọ ìyàwó Abiṣuri ni Abihaili ẹni tí ó bí Ahbani àti Molidi.
30 Fils de Nadab: Salad et Aphaïn; Salad mourut sans enfants.
Àwọn ọmọ Nadabu Seledi àti Appaimu. Seledi sì kú láìsí ọmọ.
31 Fils d'Aphaïn: Iséuniel; fils d'Isémiel: Sosan; fils de Sosan: Dadaï.
Àwọn ọmọ Appaimu: Iṣi, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Ṣeṣani. Ṣeṣani sì jẹ́ baba fún Ahlai.
32 Fils de Dadaï: Achisamas, Jéther, Jonatham; Jéther mourut sans enfants.
Àwọn ọmọ Jada, arákùnrin Ṣammai: Jeteri àti Jonatani. Jeteri sì kú láìní ọmọ.
33 Fils de Jonathan: Phaleth et Ozam; voilà les fils de Jonathan.
Àwọn ọmọ Jonatani: Peleti àti Sasa. Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Jerahmeeli.
34 Sosan n'eut pas de fils, mais des filles; or, il avait un serviteur égyptien qui se nommait Johel.
Ṣeṣani kò sì ní ọmọkùnrin àwọn ọmọbìnrin nìkan ni ó ní. Ó sì ní ìránṣẹ́ ará Ejibiti tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Jariha.
35 Et Sosan donna sa fille, pour femme, à son serviteur Johel; elle lui enfanta Ethi.
Ṣeṣani sì fi ọmọ obìnrin rẹ̀ ní aya fún ìránṣẹ́ rẹ̀ Jariha, ó sì bí ọmọ fún tí orúkọ rẹ̀ jẹ́ Attai.
36 Et Ethi engendra Nathan, et Nathan engendra Zabed.
Attai sì jẹ́ baba fún Natani, Natani sì jẹ́ baba fún Sabadi,
37 Zabed engendra Aphamel, et Aphamel engendra Obed.
Sabadi ni baba Eflali, Eflali jẹ́ baba Obedi,
38 Obed engendra Jéhu, et Jéhu engendra Azarias.
Obedi sì ni baba Jehu, Jehu ni baba Asariah,
39 Azarias engendra Hellès, et Hellès engendra Eléaza.
Asariah sì ni baba Helesi, Helesi ni baba Eleasa,
40 Eléaza engendra Sosomaï, et Sosomaï engendra Salum.
Eleasa ni baba Sismai, Sismai ni baba Ṣallumu,
41 Salum engendra Jéhémie; Jéhémie engendra Elisama, et Elisama engendra Ismaël.
Ṣallumu sì ni baba Jekamiah, Jekamiah sì ni baba Eliṣama.
42 Fils de Caleb, frère de Jeraméel Marisa, premier-né; c'est le père de Siph; Marisa eut encore des fils, il fut le père d'Hébron.
Àwọn ọmọ Kalebu arákùnrin Jerahmeeli: Meṣa àkọ́bí rẹ̀, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Sifi, àti àwọn ọmọ rẹ̀ Meraṣa, ẹni tí ó jẹ́ baba fún Hebroni.
43 Fils d'Hébron: Coré, Thaphus, Rhicom et Samaa.
Àwọn ọmọ Hebroni: Kora, Tapua, Rekemu, àti Ṣema.
44 Samaa engendra Rahem, père de Jéclan, et Jéclan engendra Samaï.
Ṣema ni baba Rahamu, Rahamu sì jẹ́ baba fún Jorkeamu. Rekemu sì ni baba Ṣammai.
45 Mahon fut son fils, et Mahon fut le père de Bethsur.
Àwọn ọmọ Ṣammai ni Maoni, Maoni sì ni baba Beti-Suri.
46 Gaïpha, concubine de Caleb, enfanta Aram, et Mosa et Gézué.
Efani obìnrin Kalebu sì ni ìyá Harani, Mosa àti Gasesi, Harani sì ni baba Gasesi.
47 Fils d'Adaï: Rahem, Joatham, Sagar, Phalec, Gaïpha et Sagaé.
Àwọn ọmọ Jahdai: Regemu, Jotamu, Geṣani, Peleti, Efani àti Ṣaafu.
48 Mocha, concubine de Caleb, enfanta Saber et Tharam.
Maaka obìnrin Kalebu sì ni ìyá Seberi àti Tirhana.
49 Sagaé engendra le père de Madmena, et Sahu, père de Mahabena, et le père de Gébal; la fille de Caleb s'appelait Ascha.
Ó sì bí Ṣaafu baba Madmana, Ṣefa baba Makbena àti baba Gibeah, ọmọbìnrin Kalebu sì ni Aksa.
50 Voilà les fils de Caleb. Voici les fils d'Hur, premier-né d'Ephratha: Sobal, père de Cariathiarim,
Àwọn wọ̀nyí ni ọmọ Kalebu. Àwọn ọmọ Huri, àkọ́bí Efrata: Ṣobali baba Kiriati-Jearimu.
51 Salomon, père de Bétha, Lammon, père de Béthalaem, et Arim, père de Bethgedor.
Salma baba Bẹtilẹhẹmu àti Harefu baba Beti-Gaderi.
52 Fils de Sobal, père de Cariathiarim: Araa, Aïsi, Ammanith
Àwọn ọmọ Ṣobali baba Kiriati-Jearimu ni: Haroe, ìdajì àwọn ará Manaheti.
53 Et Umasphaé; villes de Jdir: Ethalim, Miphitim, Hésamathim et Hémasaraïm, d'où sont sortis les Sarathéens et les fils d'Esthaam.
Àti ìdílé Kiriati-Jearimu: àti àwọn ara Itri, àti àwọn ará Puti, àti àwọn ará Ṣumati àti àwọn ará Miṣraiti: láti ọ̀dọ̀ wọn ni àwọn ọmọ ará Sorati àti àwọn ará Eṣtaoli ti wá.
54 Fils de Salomon: Béthalaem le Netophatite, Ataroth de la maison de Joab, la moitié de Manathi, et Esari.
Àwọn ọmọ Salma: Bẹtilẹhẹmu, àti àwọn ará Netofa, Atrotu Beti-Joabu, ìdajì àwọn ará Manahati, àti ará Sori,
55 Familles de lettrés, demeurant en Jabis: Thargathiim, et Samathiim et Sohathim. Ce sont les Cinéens, issus d'Emath, père de la maison de Rhéchab.
àti àwọn ìdílé àwọn akọ̀wé, ẹni tí ń gbé ní Jabesi: àti àwọn ọmọ Tirati àti àwọn ará Ṣimeati àti àwọn ará Sukati. Àwọn wọ̀nyí ni àwọn ará Keni, ẹni tí ó wá láti ọ̀dọ̀ Hamati, baba ilé Rekabu.

< 1 Chroniques 2 >