< Zacharie 4 >

1 L’Ange qui conversait avec moi revint; il me réveilla comme un homme qu’on réveillerait de son sommeil.
Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ sì tún dé, ó sì jí mi, bí ọkùnrin tí a jí lójú oorun rẹ̀,
2 Et il me dit: "Que vois-tu?" Je répondis: "Je vois un chandelier tout en or son récipient sur son sommet, ses sept lampes alignéeset sept conduits pour les lampes qui en couronnent le sommet.
ó sì wí fún mi pé, “Kí ni ìwọ rí?” Mo sì wí pé, “Mo wò, sì kíyèsi i, ọ̀pá fìtílà tí gbogbo rẹ̀ jẹ́ wúrà, pẹ̀lú àwokòtò rẹ̀ lórí rẹ̀ pẹ̀lú fìtílà méje rẹ̀ lórí rẹ̀, àti ẹnu méje fún fìtílà méjèèje, tí ó wà lórí rẹ̀.
3 Puis, deux oliviers à ses côtés, l’un à droite du récipient, l’autre à gauche."
Igi olifi méjì sì wà létí rẹ̀, ọ̀kan ní apá ọ̀tún àwokòtò náà, àti èkejì ní apá òsì rẹ̀.”
4 Je repris et je dis à l’ange qui conversait avec moi: "Qu’est-ce que ces choses, Seigneur?"
Mo sì dáhùn mo sì wí fún angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀, pé, “Kín ni wọ̀nyí, olúwa mi?”
5 L’Ange qui conversait avec moi me répondit: "Quoi! Tu ne sais donc pas ce que signifient ces choses?" Je répondis: "Non, Seigneur!"
Angẹli tí ó ń bá mi sọ̀rọ̀ dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Èmi kò mọ̀ ọ́n, olúwa mi.”
6 Il reprit et me parla en ces termes: "Ceci est la parole de l’Eternel à Zorobabel: Ni par la puissance ni par la force, mais bien par mon esprit! dit l’Eternel-Cebaot.
Ó sì dáhùn ó sì wí fún mi pé, “Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa sí Serubbabeli tó wí pé: ‘Kì í ṣe nípa ipá, kì í ṣe nípa agbára, bí kò ṣe nípa Ẹ̀mí mi,’ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
7 Qu’es-tu, grande montagne, devant Zorobabel? une simple plaine. Qu’il amène la pierre du faîte au milieu des acclamations: "Qu’elle est belle! Qu’elle est belle!"
“Ta ni ìwọ, ìwọ òkè ńlá? Ìwọ yóò di pẹ̀tẹ́lẹ̀ níwájú Serubbabeli: òun yóò sì fi ariwo mú òkúta téńté orí rẹ̀ wá, yóò máa kígbe wí pé, ‘Ọlọ́run bùkún fun! Ọlọ́run bùkún fun!’”
8 La parole de l’Eternel me fut adressée en ces termes:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ̀ mí wá, wí pé:
9 "Les mains de Zorobabel ont fondé cette maison, et ses mains l’achèveront, afin que tu reconnaisses que c’est l’Eternel-Cebaot qui m’a envoyé vers vous.
“Ọwọ́ Serubbabeli ni a ti ṣe ìpìlẹ̀ ilé yìí, ọwọ́ rẹ̀ ni yóò sì parí rẹ̀; ìwọ yóò sì mọ̀ pé, Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni ó rán mi sí i yín.
10 Car qui mépriserait le jour de ces humbles commencements? Plutôt se réjouiront-ils de voir la pierre du niveau dans la main de Zorobabel. Ces sept-là sont les yeux de l’Eternel qui parcourent toute la terre."
“Ṣùgbọ́n ta ni ha kẹ́gàn ọjọ́ ohun kékeré? Nítorí wọn ó yọ̀ nígbà ti wọ́n bá rí okùn ìwọ̀n nì lọ́wọ́ Serubbabeli. “(Àwọn méje wọ̀nyí ni àwọn ojú Olúwa, tí ó ń sáré síyìn-ín sọ́hùn-ún ní gbogbo ayé.)”
11 Je pris la parole et lui dis: "Qu’est-ce que ces deux oliviers à droite et à gauche du chandelier?"
Mo sì béèrè, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn igi olifi méjì wọ̀nyí jásí, tí ó wà ní apá ọ̀tún fìtílà àti ní apá òsì rẹ̀?”
12 Je repris pour la seconde fois et lui dis: "Qu’est-ce que ces deux branches d’olivier à côté des deux tuyaux d’or qui laissent couler le liquide doré?"
Mo sì tún dáhùn, mo sì sọ fún un pé, “Kí ni àwọn ẹ̀ka méjì igi olifi wọ̀nyí jásí, tí ń tú òróró wúrà jáde nínú ara wọn láti ẹnu ọ̀pá oníhò wúrà méjì.”
13 Il me répondit en ces termes: "Quoi! Tu ne sais pas ce qu’elles signifient? Non, Seigneur!" répliquai-je.
Ó sì dáhùn, ó wí fún mi pé, “Ìwọ kò mọ ohun tí àwọn wọ̀nyí jásí?” Mo sì wí pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́, olúwa à mi.”
14 Alors, il dit: "Ce sont les deux hommes consacrés par l’huile, qui se tiennent auprès du Maître de toute la terre!"
Ó sì wí pé, “Àwọn méjì wọ̀nyí ni àwọn tí a fi òróró yàn, tí ó dúró ti Olúwa gbogbo ayé.”

< Zacharie 4 >