< Zacharie 11 >

1 Ouvre tes portes, ô Liban! Que le feu exerce ses ravages parmi tes cèdres!
Ṣí àwọn ìlẹ̀kùn rẹ sílẹ̀, ìwọ Lebanoni, kí iná bá lè jẹ igi kedari rẹ run.
2 Lamente-toi, cyprès, car le cèdre est tombé, les fiers géants sont abattus! Lamentez-vous, chèvres de Basan, car elle est à terre, la forêt si riche en fruits!
Hu, igi junifa; nítorí igi kedari ṣubú, nítorí tí a ba àwọn igi tí o lógo jẹ́: hu, ẹ̀yin igi óákù tí Baṣani, nítorí gé igbó àjàrà lulẹ̀.
3 On entend les sanglots des pasteurs, car leur splendeur est détruite; on entend les rugissements des lions, car les massifs du Jourdain sont ravagés.
Gbọ́ ohun igbe àwọn olùṣọ́-àgùntàn; ògo wọn bàjẹ́; gbọ́ ohùn bíbú àwọn ọmọ kìnnìún nítorí ògo Jordani bàjẹ́.
4 Ainsi parle l’Eternel, mon Dieu: "Mène paître ces brebis destinées à la boucherie,
Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run mi wí: “Bọ́ ọ̀wọ́ ẹran àbọ́pa.
5 puisque leurs acquéreurs les égorgent, sans se croire en faute, et ceux qui les vendent s’écrient: "Dieu soit loué! J’Ai fait fortune!" Et leurs pasteurs ne les épargnent point.
Tí àwọn olúwa wọn ń pa wọ́n, tí wọn kò sì ka ara wọn sí pé wọn jẹ̀bi: àti àwọn tí ń tà wọ́n wí pé, ‘Ìbùkún ni fún Olúwa, nítorí tí mo dí ọlọ́rọ̀!’ Àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn kò sì ṣàánú wọn.
6 C’Est que désormais je n’aurai plus de ménagement pour les habitants de ce pays, dit l’Eternel; je vais, au contraire, livrer ces hommes aux entreprises de l’un sur l’autre et au pouvoir de leur roi. Ils couvriront le pays de ruines, et je ne le sauverai pas de leurs mains."
Nítorí èmi kì yóò ṣàánú fún àwọn ara ilẹ̀ náà mọ́,” ni Olúwa wí, “Ṣí kíyèsi í, èmi yóò fi olúkúlùkù ènìyàn lé aládùúgbò rẹ̀ lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ ọba rẹ̀, wọn yóò sì fọ́ ilẹ̀ náà, èmi kì yóò sì gbà wọ́n lọ́wọ́ wọn.”
7 Je menai donc paître ces brebis destinées à la boucherie, à savoir les plus faibles du troupeau; et je me munis de deux bâtons, dont j’appelai l’un "Bienveillance" et l’autre "Liens". Tandis que je faisais paître les brebis,
Èmi yóò sì bọ́ ẹran àbọ́pa, àní ẹ̀yin òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran. Mo sì mu ọ̀pá méjì sọ́dọ̀; mo pè ọ̀kan ni Oore-ọ̀fẹ́, mo pè èkejì ni Àmùrè; mo sì bọ́ ọ̀wọ́ ẹran náà.
8 et anéantissais les trois pasteurs en un seul mois, ma patience se lassa à leur égard, et elles aussi en eurent assez de moi.
Olùṣọ́-àgùntàn mẹ́ta ni mo sì gé kúrò ní oṣù kan. Ọkàn mi sì kórìíra wọn, ọkàn wọn pẹ̀lú sì kórìíra mi.
9 Et je dis: "Je ne veux plus vous paître. Périsse celle qui doit périr, succombe celle qui doit succomber, et que celles qui restent se dévorent l’une l’autre!"
Mo sì wí pé, “Èmi kì yóò bọ́ yin: èyí ti ń ku lọ, jẹ́ kí òkú o kú; èyí tí a o ba sì gé kúrò, jẹ́ kí a gé e kúrò; ki olúkúlùkù nínú àwọn ìyókù jẹ́ ẹran-ara ẹnìkejì rẹ̀.”
10 Puis, je pris mon bâton "Bienveillance" et le brisai, afin de rompre mon alliance que j’avais conclue avec toutes les nations.
Mo sì mu ọ̀pá mi, ti a ń pè ní Oore-ọ̀fẹ́, mo ṣẹ́ si méjì, ki èmi bá lè da májẹ̀mú mi tí mo tí bá gbogbo àwọn ènìyàn náà dá.
11 Elle fut ainsi rompue ce jour-là, et elles reconnurent bien, les plus humbles du troupeau qui me voyaient faire, que c’était la parole de l’Eternel.
Ó sì dá ni ọjọ́ náà, bẹ́ẹ̀ ni àwọn òtòṣì nínú ọ̀wọ́ ẹran náà tí ó dúró tì mí mọ̀ pé, ọ̀rọ̀ Olúwa ni.
12 Je leur dis: "Si tel est votre bon plaisir, donnez-moi mon salaire, et sinon, laissez-le!" Alors ils me comptèrent mon salaire, trente pièces d’argent.
Mo sì wí fún wọn pé, “Bí ó bá dára ní ojú yin, ẹ fún mi ni owó ọ̀yà mi; bí bẹ́ẹ̀ kọ́, ẹ mú un lọ́wọ́.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wọn ọgbọ̀n owó fàdákà fún iye owó ọ̀yà mi.
13 Et l’Eternel me dit: "Jette-le au Trésor, ce prix magnifique auquel j’ai été estimé par eux, et je pris les trente pièces d’argent et les jetai au Trésor, dans la maison de l’Eternel.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Sọ ọ sí amọ̀kòkò.” Iye dáradára náà, tí wọn yọ owó mi sí. Mo sì mu ọgbọ̀n owó fàdákà náà, mo sì sọ wọ́n sí àpótí ìṣúra ní ilé Olúwa.
14 Puis je mis en pièces mon second bâton "Liens", afin d’abolir la fraternité entre Juda et Israël.
Mo sì ṣẹ́ ọ̀pá mi kejì, àní Àmùrè, sí méjì, kí èmi lè ya ìbátan tí ó wà láàrín Juda àti láàrín Israẹli.
15 L’Eternel me dit: "Munis toi encore du baggage d’un pasteur idiot.
Olúwa sì wí fún mi pé, “Tún mú ohun èlò aṣiwèrè olùṣọ́-àgùntàn kan sọ́dọ̀ rẹ̀.
16 Car voici, je vais établir un pasteur en ce pays, qui ne saura pas soigner les brebis en perdition, rechercher celle qui s’égare étourdiment, guérir celle qui a une fracture, nourrir celle qui est intacte, mais qui consommera la chair des plus grasses et leur brisera les ongles.
Nítorí Èmi o gbé Olùṣọ́-àgùntàn kan dìde ni ilẹ̀ náà, tí kí yóò bẹ àwọn tí ó ṣègbé wò, ti kì yóò sì wá èyí tí ó yapa; tí kì yóò ṣe ìtọ́jú èyí tí a pa lára tàbí kí ó bọ́ àwọn tí ara wọn dá pépé: Ṣùgbọ́n òun yóò jẹ ẹran èyí tí ó ni ọ̀rá, àwọn èyí tiwọn fi èékánná wọn ya ara wọn pẹ́rẹpẹ̀rẹ.
17 Oh! malheur au pasteur de néant qui délaisse son troupeau! Que la sécheresse atteigne son bras et son œil droit! Que son bras soit complètement paralysé et son œil droit tout à fait éteint!"
“Ègbé ni fún olùṣọ́-àgùntàn asán náà, tí ó fi ọ̀wọ́ ẹran sílẹ̀! Idà yóò gé apá rẹ̀ àti ojú ọ̀tún rẹ̀: apá rẹ̀ yóò gbẹ pátápátá, ojú ọ̀tún rẹ̀ yóò sì fọ́ pátápátá!”

< Zacharie 11 >