< Psaumes 71 >

1 En toi, Seigneur, je m’abrite! Puissé-je n’être jamais déçu!
Nínú rẹ, Olúwa, ni mo ní ààbò; má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
2 Dans ta justice, sauve-moi, retire-moi du danger; incline vers moi ton oreille, et viens à mon secours.
Gbà mí kí o sì tú mi sílẹ̀ nínú òdodo rẹ; dẹ etí rẹ sí mi, kí o sì gbà mí.
3 Sois pour moi un rocher tutélaire, toujours accessible; fais-toi une loi de me prêter assistance, car tu es bien mon rocher et ma citadelle.
Jẹ́ àpáta ààbò mi, níbi tí èmi lè máa lọ, pa àṣẹ láti gbà mí, nítorí ìwọ ni àpáta àti odi agbára mi.
4 Mon Dieu, délivre-moi de la main du méchant, de la poigne de l’homme inique et violent.
Gbà mí, Ọlọ́run mi, lọ́wọ́ àwọn olùṣe búburú, ní ọwọ́ aláìṣòdodo àti ìkà ọkùnrin.
5 Car tu es mon espoir, Seigneur Dieu, ma sauvegarde depuis ma jeunesse.
Nítorí ìwọ jẹ́ ìrètí mi, Olúwa Olódùmarè, ìwọ ni ìgbẹ́kẹ̀lé mi láti ìgbà èwe.
6 Sur toi je m’appuie depuis mon enfance; c’est toi qui m’as tiré des entrailles de ma mère: tu es l’objet constant de mes louanges.
Mo gbẹ́kẹ̀lé ọ láti ìgbà ìbí mi; Ìwọ mú mi jáde láti inú ìyá mi wá èmi ó máa yìn ọ́ títí láé.
7 Pour beaucoup, j’ai l’air d’un insigne prodige; mais toi, tu es mon solide abri.
Mo di àmì fún ọ̀pọ̀ ènìyàn, ṣùgbọ́n ìwọ ni ààbò mi tí ó lágbára.
8 J’Ai la bouche pleine de louanges; sans cesse je prône ta gloire.
Ìyìn rẹ̀ kún ẹnu mi, ó ń sọ ti ọlá rẹ ní ọjọ́ gbogbo.
9 Ne me rejette pas au temps de ma vieillesse; alors que ma vigueur est épuisée, ne m’abandonne point.
Má ṣe ta mí nù ní ọjọ́ ogbó mi, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ nígbà tí kò sí okun mọ́.
10 Car mes ennemis s’entretiennent de moi, ceux qui guettent ma vie se concertent ensemble.
Nítorí àwọn ọ̀tá mi ń sọ̀rọ̀-òdì sí mi, àwọn tí wọn dúró láti pa mí gbìmọ̀ pọ̀.
11 Ils disent: "Dieu l’a délaissé, courez-lui sus, empoignez-le, car il n’est personne pour le sauver!"
Wọ́n wí pé, “Ọlọ́run ti kọ̀ ọ́ sílẹ̀; lépa rẹ̀ kí ẹ sì mu, nítorí kò sí ẹni tí yóò gbà á.”
12 O Dieu, ne te tiens pas éloigné de moi; mon Dieu, hâte-toi de me venir en aide.
Má ṣe jìnnà sí mi, Ọlọ́run; wa kánkán, Ọlọ́run mi, láti ràn mí lọ́wọ́.
13 Qu’ils soient confondus, réduits à néant, ceux qui me vouent leur haine; qu’ils soient enveloppés de honte et d’ignominie, ceux qui cherchent mon malheur!
Jẹ́ kí wọn kí ó dààmú, kí a sì run àwọn tí ń ṣe ọ̀tá ọkàn mi kí a sì fi ẹ̀gàn àti àbùkù bo àwọn tí ń wá ìpalára mi.
14 Pour moi, je serai toujours plein d’espoir, et j’ajouterai encore à toutes tes louanges.
Ṣùgbọ́n ní tèmi, ìgbà gbogbo ní ìrètí mi; èmi ó yìn ọ́ síwájú àti síwájú sí i.
15 Ma bouche proclamera ton équité, tout le temps, ta protection; car je suis impuissant à tout énumérer.
Ẹnu mi yóò sọ nípa ti òdodo rẹ, ti ìgbàlà rẹ, ni gbogbo ọjọ́, lóòtítọ́, èmi kò mọ iye rẹ̀.
16 Je me présenterai avec tes hauts faits, ô Seigneur Dieu, je célébrerai ta justice à toi seul.
Èmi ó wá láti wá kéde agbára, Olúwa Olódùmarè; èmi ó kéde òdodo rẹ̀ nìkan.
17 O Dieu, tu m’as appris à les connaître dès ma jeunesse, et jusqu’à ce jour, j’annonce tes merveilles.
Láti ìgbà èwe, Ọlọ́run ni ìwọ ti kọ́ mi títí di òní ni mo ń sọ ti iṣẹ́ ìyanu rẹ.
18 Aussi, jusque dans ma vieillesse et sous les cheveux blancs, tu ne m’abandonneras pas, ô Dieu, pour que je puisse révéler ta force à ma génération, ta puissance à toute la postérité.
Pẹ̀lúpẹ̀lú, nígbà tí èmi di arúgbó tán tí mo sì hewú, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀, Ọlọ́run mi, títí èmi ó fi ipá rẹ han ìran tí ń bọ̀, àti agbára rẹ fún gbogbo àwọn tí ń bọ̀ lẹ́yìn.
19 Ta justice, ô Dieu, atteint, en effet, jusqu’au ciel: tu accomplis de grandes choses: ô Dieu, qui est comme toi?
Ọlọ́run, òdodo rẹ dé ọ̀run, ìwọ tí o ti ṣe ohun ńlá. Ta ni ó dàbí rẹ, Ọlọ́run?
20 Toi qui m’as fait voir des épreuves nombreuses et cruelles, à nouveau tu me rendras la vie, à nouveau tu me feras remonter du fond des abîmes.
Pẹ̀lúpẹ̀lú ìwọ ti mú mi rí ìdààmú, tí ó pọ̀ tí ó sì korò, ìwọ yóò tún sọ ayé mi jí ìwọ yóò sì tún mú mi sọ sókè láti ọ̀gbun ilẹ̀ wá. Ìwọ yóò sọ ọlá mi di púpọ̀.
21 Tu accroîtras ma grandeur, et tu te retourneras vers moi pour me consoler.
Ìwọ yóò fi kún ọwọ́ mi ìwọ yóò tù mí nínú ní ha gbogbo.
22 En retour, moi, je te louerai au son du luth, pour ta bonté fidèle, ô mon Dieu; je te chanterai avec la harpe, ô Saint d’Israël!
Èmi yóò fi dùùrù mi yìn fún òtítọ́ rẹ, Ọlọ́run mi; èmi ó kọrin ìyìn sí ọ pẹ̀lú dùùrù ìwọ ẹni mímọ́ Israẹli.
23 Mes lèvres entonneront des cantiques, lorsque je voudrai te célébrer, ainsi que mon âme qui te doit sa délivrance.
Ètè mi yóò kígbe fún ìyìn nígbà tí mo bá kọrin ìyìn sí ọ: èmi, ẹni tí o rà padà.
24 Oui, ma langue proclamera ta justice tout le long du jour, car ils auront été confondus, couverts de honte, ceux qui voulaient mon malheur.
Ahọ́n mi yóò sọ ti òdodo rẹ ní gbogbo ọjọ́, fún àwọn tí ó fẹ́ pa mí lára, a sì dójúti àwọn tí ń wá ìdààmú mi.

< Psaumes 71 >