< Psaumes 70 >

1 Au chef des chantres. De David. Pour la Commémoration. Consens, ô Dieu, à me sauver; Eternel, hâte-toi de me porter secours.
Fún adarí orin. Ti Dafidi. Ẹ̀bẹ̀. Yára, Ọlọ́run, láti gbà mí là, Olúwa, wá kánkán láti ràn mí lọ́wọ́.
2 Qu’ils soient confondus et couverts de honte, ceux qui attentent à ma vie: qu’ils lâchent pied et reculent, en rougissant, ceux qui souhaitent mon malheur!
Kí àwọn tí ń wá ọkàn mi kí a dójútì wọ́n, kí wọn sì dààmú; kí àwọn tó ń wá ìparun mi yí ẹ̀yìn padà nínú ìtìjú.
3 Qu’ils s’en retournent, punis par leur honte, ceux qui disent de moi: "Ha! Ha!"
Kí a pa wọ́n ní ẹ̀yìn dà fún èrè ìtìjú àwọn tí ń wí pé, “Háà! Háà!”
4 Mais qu’ils jubilent et se réjouissent en toi, tous ceux qui te recherchent! Qu’ils disent constamment: "Dieu est grand", ceux qui aiment ta protection!
Ṣùgbọ́n kí àwọn tí ó ń wá ọ ó máa yọ̀ kí inú wọn kí ó sì máa dùn nípa rẹ, kí àwọn tí ó ń fẹ́ ìgbàlà rẹ máa wí pé, “Jẹ́ kí a gbé Ọlọ́run ga!”
5 Quant à moi, pauvre et malheureux, ô Dieu, hâte-toi en ma faveur; tu es mon aide et ma sauvegarde: Eternel, n’attends pas trop longtemps.
Ṣùgbọ́n mo jẹ́ òtòṣì àti aláìní; wa kánkán sí ọ̀dọ̀ mi, Ọlọ́run. Ìwọ ni olùrànlọ́wọ́ àti olùdáǹdè mi; Olúwa, má ṣe dúró pẹ́.

< Psaumes 70 >