< Psaumes 54 >

1 Au chef des chantres. Avec les instruments à cordes. Maskîl de David, lorsque les gens de Ziph furent venus dire à Saül: "David se tient caché dans notre voisinage." O Dieu, secours-moi par ton nom, et rends-moi justice par ta puissance.
Fún adarí orin. Pẹ̀lú ohun èlò orin olókùn. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí àwọn ará Sifi lọ sọ fún Saulu pé, “Dafidi sá pamọ́ sọ́dọ̀ wa?” Gbà mí, Ọlọ́run nípa orúkọ rẹ: dá mi láre nípa agbára rẹ.
2 Ecoute ma prière, ô Dieu, prête l’oreille aux paroles de ma bouche;
Gbọ́ àdúrà mi, Ọlọ́run; fi etí sí ọ̀rọ̀ ẹnu mi.
3 car des barbares se dressent contre moi, des gens violents en veulent à ma vie: ils n’ont pas de pensée pour Dieu. (Sélah)
Àwọn agbéraga àlejò dìde sí mí. Àwọn aninilára sì ń wá mi láti pa, àwọn ẹni tí kò ka Ọlọ́run sí ní ojú wọn.
4 Oui certes, Dieu vient à mon aide, le Seigneur est le soutien de ma vie.
Kíyèsi i Ọlọ́run ni olùrànlọ́wọ́ mi; Olúwa ní ẹni tí ó mú mi dúró, pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
5 Il fera retomber le mal sur mes adversaires: dans ton équité, tu les anéantiras.
Jẹ́ kí ibi padà sẹ́yìn sí àwọn tí ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi; pa wọ́n run nínú òtítọ́ rẹ.
6 De tout cœur je veux t’offrir des sacrifices; je louerai ton nom, car il signifie bonté.
Èmí yóò rú ẹbọ àtinúwá sí ọ, èmi yóò yin orúkọ rẹ, Olúwa, nítorí tí ó dára.
7 Oui, il me délivre de toute angoisse, et mes yeux se repaissent de la vue de mes ennemis.
Nítorí tí ó yọ mí kúrò nínú ibi gbogbo ojú mi ti wo ìṣẹ́gun lórí ọ̀tá mi.

< Psaumes 54 >