< Psaumes 52 >

1 Au chef des chantres. Maskîl, de David, lorsque Doëg l’Iduméen fut venu faire un rapport à Saül en lui disant: "David est entré dans la maison d’Abimélec." Pourquoi te glorifier de ta cruauté, homme vaillant? La bonté de Dieu ne se dément jamais.
Fún adarí orin. Maskili ti Dafidi. Nígbà tí Doegi ará Edomu tọ Saulu lọ láti sọ fún pé, “Dafidi wà ní ilé Ahimeleki.” Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣe féfé nínú ìwà ìkà, ìwọ alágbára ọkùnrin? Èéṣe tí ìwọ fi ń gbéraga nígbà gbogbo, ìwọ ẹni ẹ̀gàn níwájú Ọlọ́run?
2 Ta langue prépare des ruines, comme un rasoir effilé, ô artisan de perfidie!
Ahọ́n rẹ̀ ń gbìmọ̀ ìparun; ó dàbí abẹ mímú, ìwọ ẹni tí ń hùwà ẹ̀tàn.
3 Tu donnes la préférence au mal sur le bien, tu aimes mieux mentir que parler loyalement. (Sélah)
Ìwọ fẹ́ràn ibi ju ìre lọ, àti èké ju kí ó sọ òtítọ́ lọ.
4 Tu n’as de goût que pour les discours malfaisants, pour le langage de l’astuce.
Ìwọ fẹ́ràn ọ̀rọ̀ ìpanilára gbogbo, ìwọ ahọ́n ẹ̀tàn!
5 Aussi Dieu t’abattra-t-il pour toujours; il t’empoignera et t’arrachera de ta tente; il te déracinera de la terre des vivants. (Sélah)
Ọlọ́run yóò sì lù ọ́ bolẹ̀ láéláé, yóò sì dì ọ́ mú, yóò sì já ọ kúrò ni ibùjókòó rẹ, yóò sì fà ọ́ tu kúrò lórí ilẹ̀ alààyè. (Sela)
6 Les justes en seront témoins, saisis de respect, et ils riront de lui.
Àwọn olódodo yóò rí, wọn yóò sì bẹ̀rù wọn yóò sì rẹ́rìn-ín rẹ̀, wí pé,
7 "Le voilà, l’homme qui ne cherchait pas sa force en Dieu, mais qui se fiait à sa grande richesse, et faisait le fier dans sa passion du mal!"
“Èyí ni ọkùnrin náà ti kò fi Ọlọ́run ṣe agbára rẹ̀, bí kò ṣe ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọrọ̀ rẹ̀ ni ó gbẹ́kẹ̀lé, ó sì mu ara rẹ̀ le nínú ìwà búburú rẹ̀.”
8 Tandis que moi, je suis comme un olivier verdoyant, dans la maison de Dieu; je mets à jamais ma confiance dans la bonté de Dieu.
Ṣùgbọ́n èmi dàbí igi Olifi tí ó gbilẹ̀ nínú ilé Ọlọ́run; èmi gbẹ́kẹ̀lé ìfẹ́ Ọlọ́run tí kì í kùnà láé àti láéláé.
9 Eternellement, je veux te rendre grâce pour ce que tu as fait, et placer mon espoir en ton nom, car tu es bon à l’égard de tes pieux serviteurs.
Èmi yóò yìn ọ títí fún ohun tí ó ti ṣe; èmi ní ìrètí nínú orúkọ rẹ, nítorí orúkọ rẹ dára. Èmi yóò yìn ọ́ níwájú àwọn ènìyàn mímọ́.

< Psaumes 52 >