< Psaumes 45 >

1 Au chef des chantres. Sur les Chochanim. Par les fils de Coré. Maskîl. Chant d’amour. Mon cœur agite un beau dessein; je veux consacrer mon poème au roi! Ma langue est le burin d’un scribe expert.
Fún adarí orin. Tí ohun orin “Lílì.” Ti orin àwọn ọmọ Kora. Maskili. Orin ìgbéyàwó. Ọkàn mi mọ ọ̀rọ̀ rere gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń sọ ohun tí mo ti ṣe fún ọba ahọ́n mi ni kálámù ayára kọ̀wé.
2 Tu es beau entre tous les fils de l’homme, la grâce est répandue sur tes lèvres; aussi Dieu t’a-t-il béni pour toujours.
Ìwọ yanjú ju àwọn ọmọ ènìyàn lọ: a da oore-ọ̀fẹ́ sí ọ ní ètè: nítorí náà ni Ọlọ́run ṣe bùkún fún ọ láéláé.
3 Ceins ton glaive sur ton flanc, ô héros, c’est ta parure et ton honneur;
Gba idà rẹ mọ́ ìhà rẹ, ìwọ alágbára jùlọ wọ ara rẹ ní ògo àti ọláńlá.
4 oui, ton honneur! Bon courage et en selle, pour défendre la vérité, la modestie, la justice! Que ta droite t’enseigne de beaux exploits!
Nínú ọláńlá rẹ, máa gẹṣin lọ ní àlàáfíà lórí òtítọ́, ìwà tútù àti òtítọ́; jẹ́ kí ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ohun ẹ̀rù.
5 Tes flèches sont aiguës, des peuples succombent sous tes coups elles percent le cœur des ennemis du roi.
Jẹ́ kí ọfà mímú rẹ̀ dá ọkàn àwọn ọ̀tá ọba lu jẹ́ kí àwọn orílẹ̀-èdè ṣubú sí abẹ́ ẹsẹ̀ rẹ̀.
6 Ton trône, fondé par Dieu, durera à jamais; le sceptre de ta royauté est un sceptre de droiture.
Ọlọ́run láé, àti láéláé ni ìtẹ́ rẹ, ọ̀pá aládé ìjọba rẹ, ọ̀pá aládé òtítọ́ ni.
7 Tu aimes la justice, tu hais l’iniquité; voilà pourquoi Dieu ton Dieu t’a consacré par une huile d’allégresse, de préférence à tes compagnons.
Ìwọ fẹ́ olódodo, ìwọ sì kórìíra ìwà búburú nígbà náà Ọlọ́run, Ọlọ́run rẹ ti yàn ọ́ ṣe olórí àwọn ẹlẹgbẹ́ rẹ, nípa fífi àmì òróró ayọ̀ kùn ọ́.
8 Myrrhe, aloès et casse parfument tes vêtements; du fond des palais d’ivoire les concerts te ravissent.
Gbogbo aṣọ rẹ̀ ni ó ń rùn pẹ̀lú òjìá àti aloe àti kasia; láti inú ààfin tí a fi eyín erin ṣe orin olókùn tẹ́ẹ́rẹ́ mú inú rẹ̀ dùn.
9 Des filles de rois figurent parmi tes favorites; la reine se tient à ta droite, parée de l’or d’Ophir.
Àwọn ọmọbìnrin àwọn ọba wà nínú àwọn àyànfẹ́ rẹ̀, ní ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni ayaba náà gbé dúró nínú wúrà Ofiri.
10 Ecoute ma fille, ouvre les yeux, tends l’oreille: oublie ton peuple et la maison de ton père!
Gbọ́ ìwọ ọmọbìnrin, ronú kí o sì dẹtí rẹ sí mi gbàgbé àwọn ènìyàn rẹ àti ilé baba rẹ.
11 Que le roi s’éprenne de ta beauté, car il est ton maître incline-toi devant lui.
Bẹ́ẹ̀ ni ọba yóò fẹ́ ẹwà rẹ gidigidi nítorí òun ni olúwa rẹ kí ìwọ sì máa tẹríba fún un.
12 La fille de Tyr… Chargés de présents, les gens les plus opulents recherchent ta bienveillance.
Ọmọbìnrin ọba Tire yóò wá pẹ̀lú ẹ̀bùn àwọn ọkùnrin ọlọ́rọ̀ yóò máa wá ojúrere rẹ̀.
13 Toute resplendissante est la fille du roi dans son intérieur, sa robe est faite d’un tissu d’or.
Gbogbo ògo ni ti ọmọbìnrin ọba ní àárín ilé rẹ̀, iṣẹ́ wúrà ọnà abẹ́rẹ́ ní aṣọ rẹ̀.
14 Couverte de broderies, elle est introduite auprès du roi, suivie d’un cortège de jeunes filles, ses compagnes, qui sont amenées pour toi;
Nínú aṣọ olówó iyebíye ni a mú un tọ́ ọba wá, àwọn wúńdíá ẹgbẹ́ rẹ̀ tẹ̀lé e, wọ́n sí mú un tọ̀ ọ́ wá.
15 amenées avec des cris de joie et d’allégresse, elles pénètrent dans le palais du roi.
Wọ́n sì mú un wá pẹ̀lú ayọ̀ àti inú dídùn wọ́n sì wọ ààfin ọba.
16 Que la place de tes pères soit occupée par tes fils! Puisses-tu les établir comme princes sur tout le pays!
Ọmọ rẹ̀ ni yóò gba ipò baba rẹ̀ ìwọ yóò sì fi wọ́n joyè lórí ilẹ̀ gbogbo.
17 Je ferai en sorte que ton nom vive de siècle en siècle; aussi les nations te rendront-elles hommage à tout jamais!
Èmí yóò máa rántí orúkọ rẹ̀ ní ìran gbogbo, nígbà náà ni orílẹ̀-èdè yóò yìn ọ́ láé àti láéláé.

< Psaumes 45 >