< Psaumes 24 >

1 De David. Psaume. A l’Eternel appartient la terre et ce qu’elle renferme, le globe et ceux qui l’habitent.
Ti Dafidi. Saamu. Ti Olúwa ni ilẹ̀, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti àwọn tí ó tẹ̀dó sínú rẹ̀;
2 Car c’est lui qui l’a fondée sur les mers et affermie sur les flots.
nítorí ó fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ lórí òkun ó sì gbé e kalẹ̀ lórí àwọn ìṣàn omi.
3 Qui s’élèvera sur la montagne du Seigneur? Qui se tiendra dans sa sainte résidence?
Ta ni yóò gun orí òkè Olúwa lọ? Ta ni yóò dúró ní ibi mímọ́ rẹ̀?
4 Celui dont les mains sont sans tache, le cœur pur, qui n’atteste pas ma personne pour la fausseté, et ne prête pas de serment frauduleux:
Ẹni tí ó ní ọwọ́ mímọ́ àti àyà funfun, ẹni tí kò gbé ọkàn rẹ̀ sókè sí asán tí kò sì búra èké.
5 celui-là obtiendra la bénédiction de l’Eternel, la bienveillance du Dieu de son salut.
Òun ni yóò rí ìbùkún gbà láti ọ̀dọ̀ Olúwa, àti òdodo lọ́wọ́ Ọlọ́run ìgbàlà rẹ̀.
6 Tel est le sort de ses adorateurs, de ceux qui recherchent ta face, de Jacob. (Sélah)
Èyí ni ìran àwọn tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, tí ń ṣe àfẹ́rí rẹ̀, Ọlọ́run Jakọbu. (Sela)
7 Exhaussez, ô portes, vos frontons, relevez-vous, portails antiques, pour qu’il entre, le roi de gloire!
Ẹ gbé orí yín sókè, háà! Ẹ̀yin ọ̀nà; kí á sì gbe yín sókè, ẹyin ìlẹ̀kùn ayérayé! Kí ọba ògo le è wọlé.
8 Qui donc est ce roi de gloire?" L’Eternel fort et puissant, l’Eternel, héros dans la guerre.
Ta ni ọba ògo náà? Olúwa tí ó lágbára tí ó sì le, Olúwa gan an, tí ó lágbára ní ogun.
9 Exhaussez, ô portes, vos frontons, relevez-vous, portails antiques, pour qu’il entre, le roi de gloire!
Gbé orí yín sókè, ẹyin ọ̀nà; kí a sì gbé e yín sókè, ẹ̀yin ìlẹ̀kùn ayérayé, kí Ọba ògo le è wọlé wá.
10 "Qui donc est ce roi de gloire?" L’Eternel-Cebaot, c’est lui qui est le roi de gloire! (Sélah)
Ta ni Ọba ògo náà? Olúwa àwọn ọmọ-ogun Òun ni Ọba ògo náà. (Sela)

< Psaumes 24 >