< Psaumes 138 >
1 De David. Je te rendrai hommage de tout mon cœur; en ta présence, ô Dieu, je te célébrerai.
Ti Dafidi. Èmi yóò yìn ọ́ tinútinú mi gbogbo; níwájú àwọn òrìṣà ni èmi ó kọrin ìyìn sí ọ.
2 Je me prosternerai dans ton saint tabernacle, et je louerai ton nom pour ta bonté et ta bienveillance; car tu as élevé au-dessus de tout ton nom, ta parole.
Èmi ó máa gbàdúrà sí ìhà tẹmpili mímọ́ rẹ̀ èmi ó sì máa yin orúkọ rẹ nítorí ìṣeun ìfẹ́ rẹ àti òtítọ́ rẹ; nítorí ìwọ gbé ọ̀rọ̀ rẹ ga ju orúkọ rẹ lọ.
3 Le jour où je t’appelai, tu me répondis, tu me donnas du courage en fortifiant mon âme.
Ní ọjọ́ tí mo ké pè é ọ́, ìwọ dá mi lóhùn, ìwọ sì fi ipa mú mi lára le ní ọkàn mi.
4 Tous les rois de la terre, ô Eternel, te rendront hommage, après avoir entendu les paroles de ta bouche;
Gbogbo àwọn ọba ayé yóò yìn ọ́, Olúwa, ní ìgbà tí wọn bá gbọ́ ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ.
5 ils chanteront les voies du Seigneur, car grande est la gloire de l’Eternel.
Nítòótọ́, wọn ó máa kọrin ní ipa ọ̀nà Olúwa; nítorí pé ńlá ni ògo Olúwa.
6 Oui, l’Eternel réside dans les hauteurs et il voit celui qui est humble, comme il discerne de loin celui qui est élevé.
Bí Olúwa tilẹ̀ ga, síbẹ̀ ó júbà àwọn onírẹ̀lẹ̀; ṣùgbọ́n agbéraga ni ó mọ̀ ní òkèrè réré.
7 Quand je m’avance en pleine détresse, c’est toi qui préserves ma vie; tu appesantis ta main sur mes ennemis en fureur, et ta droite me prête assistance.
Bí èmi tilẹ̀ ń rìn nínú ìpọ́njú ìwọ ni yóò sọ mi di ààyè; ìwọ ó na ọwọ́ rẹ sí àwọn ọ̀tá mi, ọwọ́ ọ̀tún rẹ yóò sì gbà mí.
8 L’Eternel mettra le comble à ses bienfaits envers moi; ta bonté, ô Seigneur, dure à jamais: ne laisse pas inachevées les œuvres de tes mains.
Olúwa yóò ṣe ohun tí ń ṣe tèmi láṣepé; Olúwa, àánú rẹ dúró láéláé; má ṣe kọ iṣẹ́ ọwọ́ ara rẹ sílẹ̀.