< Psaumes 119 >

1 Heureux ceux dont la voie est intègre, qui suivent la Loi de l’Eternel!
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ọ̀nà wọn wà láìlẹ́ṣẹ̀, ẹni tí í rìn ní ìbámu pẹ̀lú òfin Olúwa.
2 Heureux ceux qui respectent ses statuts, le recherchent de tout leur cœur,
Ìbùkún ni fún àwọn ẹni tí ń pa òfin rẹ̀ mọ́ tí wọn sì ń wá a pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
3 qui, se gardant bien de commettre aucune injustice, marchent dans ses voies!
Wọn kò ṣe ohun tí kò dára; wọ́n rìn ní ọ̀nà rẹ̀.
4 Tu as promulgué tes ordonnances, pour qu’on les observe strictement.
Ìwọ ti la ìlànà rẹ̀ sílẹ̀ kí a sì pa wọ́n mọ́ gidigidi.
5 Ah! puissent mes pas être fermes, pour que j’observe tes préceptes!
Ọ̀nà mi ìbá dúró ṣinṣin láti máa pa òfin rẹ̀ mọ́!
6 Alors, je ne serai point déçu, en portant mes regards sur tous tes commandements.
Nígbà náà, ojú kò ní tì mí nígbà tí mo bá ń kíyèsi àṣẹ rẹ̀ gbogbo.
7 Je te rendrai grâce en toute droiture de cœur, en m’instruisant des règles de ta justice.
Èmi yóò yìn ọ́ pẹ̀lú ọkàn ìdúró ṣinṣin bí èmi bá ti kọ́ òfin òdodo rẹ̀.
8 Tes statuts, je les observerai: ne m’abandonne en aucun temps.
Èmi yóò gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, má ṣe kọ̀ mí sílẹ̀ pátápátá.
9 Comment le jeune homme rendra-t-il pure sa conduite? En se conformant à tes paroles.
Báwo ni àwọn ọ̀dọ́ yóò ti ṣe pa ọ̀nà rẹ̀ mọ́? Láti máa gbé ní ìbámu sí ọ̀rọ̀ rẹ.
10 De tout mon cœur je m’enquiers de toi, ne me laisse pas dévier de tes prescriptions.
Èmi wá ọ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi má ṣe jẹ́ kí èmi yapa kúrò nínú àṣẹ rẹ.
11 En mon sein j’ai déposé tes instructions, pour ne pas faillir à ton égard.
Èmi ti pa ọ̀rọ̀ rẹ mọ́ ní ọkàn mi kí èmi má ba à ṣẹ̀ sí ọ.
12 Béni sois-tu, ô Eternel! Enseigne-moi tes préceptes.
Ìyìn ni fún Olúwa; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
13 De mes lèvres je proclame toutes les règles sorties de ta bouche.
Pẹ̀lú ètè mi èmi tún ṣírò gbogbo òfin tí ó wá láti ẹnu rẹ.
14 Dans le chemin tracé par tes témoignages je trouve ma joie, comme si c’était le comble de la richesse.
Èmi ń yọ̀ ní ọ̀nà ẹ̀rí rẹ, bí ènìyàn ṣe ń yọ̀ nínú ọláńlá.
15 Je m’entretiens de tes commandements, et je contemple tes voies.
Èmi ń ṣe àṣàrò nínú ìlànà rẹ èmi sì kíyèsi ọ̀nà rẹ.
16 Je me délecte de tes préceptes, et n’oublie point tes paroles.
Inú mi dùn sí àṣẹ rẹ; èmi kì yóò gbàgbé ọ̀nà rẹ.
17 Accorde tes bienfaits à ton serviteur, pour que je vive et observe tes paroles.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ, èmi yóò sì wà láààyè; èmi yóò ṣe ìgbọ́ràn sí ọ̀rọ̀ rẹ.
18 Dessille-moi les yeux, pour que je puisse contempler les merveilles issues de ta Loi.
La ojú mi kí èmi lè ríran rí ohun ìyanu tí ó wà nínú òfin rẹ.
19 Je suis un simple étranger sur la terre, ne me tiens pas cachés tes commandements.
Àlejò ní èmi jẹ́ láyé, má ṣe pa àṣẹ rẹ mọ́ fún mi.
20 Mon âme est travaillée du désir de tes règlements, à toute époque.
Ọkàn mi pòruurù pẹ̀lú ìfojúsọ́nà nítorí òfin rẹ nígbà gbogbo.
21 Toi, tu réprouves les arrogants maudits, qui se fourvoient loin de tes commandements.
Ìwọ fi àwọn agbéraga bú, àwọn tí a fi gégùn ún tí ó ṣìnà kúrò nínú àṣẹ rẹ.
22 Affranchis-moi de la honte et du mépris, car je respecte tes témoignages.
Mú ẹ̀gàn àti àbùkù kúrò lára mi, nítorí èmi pa òfin rẹ mọ́.
23 Dussent même les grands prendre siège et déblatérer contre moi, ton serviteur méditera tes lois.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn alákòóso kójọpọ̀, wọ́n ń sọ̀rọ̀ ìbàjẹ́ sí mi, ṣùgbọ́n ìránṣẹ́ rẹ ń ṣe àṣàrò nínú àṣẹ rẹ.
24 Oui, tes témoignages sont mes délices, mes meilleurs conseillers.
Òfin rẹ ni dídùn inú mi; àwọn ní olùbádámọ̀ràn mi.
25 Mon âme est collée à la poussière, conserve-moi en vie, suivant ta parole.
Ọkàn mí lẹ̀ mọ́ erùpẹ̀; ìwọ sọ mí di ààyè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
26 J’Ai exposé ma conduite, et tu m’as répondu; enseigne-moi tes lois.
Èmi tún ọ̀nà mi ṣírò ìwọ sì dá mi lóhùn; kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
27 Laisse-moi comprendre le chemin de tes préceptes, et je réfléchirai à tes merveilles.
Jẹ́ kí n mọ ẹ̀kọ́ ìlànà rẹ: nígbà náà ni èmi yóò ṣe àṣàrò iṣẹ́ ìyanu rẹ.
28 Mon âme, de chagrin, se fond en larmes, redresse-moi, selon ta parole.
Ọkàn mi ń ṣe àárẹ̀ pẹ̀lú ìbànújẹ́; fi agbára fún mi gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
29 Eloigne de moi le chemin du mensonge, gratifie-moi de ta Loi.
Pa mí mọ́ kúrò nínú ọ̀nà ẹ̀tàn fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ nípa òfin rẹ.
30 J’Ai choisi la voie de la fidélité, placé tes règles sous mes regards.
Èmi ti yan ọ̀nà òtítọ́ èmi ti gbé ọkàn mi lé òfin rẹ.
31 Je suis attaché à tes statuts, Seigneur, ne m’inflige aucune déception.
Èmi yára di òfin rẹ mú. Olúwa má ṣe jẹ́ kí ojú kí ó tì mí.
32 Je suivrai avec empressement le chemin de tes préceptes, car tu élargis mon cœur.
Èmi sáré ní ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ, nítorí ìwọ, ti tú ọkàn mi sílẹ̀.
33 Enseigne-moi le chemin de tes préceptes, je veux en suivre les traces.
Kọ́ mi, Olúwa, láti tẹ̀lé àṣẹ rẹ; nígbà náà ni èmi yóò pa wọ́n mọ́ dé òpin.
34 Donne-moi l’intelligence pour que je garde ta loi et l’observe de tout mon cœur.
Fún mi ní òye, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́ èmi yóò sì máa kíyèsi i pẹ̀lú ọkàn mi.
35 Dirige-moi dans le sentier de tes commandements, car j’y trouve ma satisfaction.
Fi ipa ọ̀nà àṣẹ rẹ hàn mí, nítorí nínú rẹ̀ ni èmi rí inú dídùn.
36 Incline mon cœur vers tes vérités, et non vers un vain lucre.
Yí ọkàn mi padà sí òfin rẹ kí ó má ṣe sí ojúkòkòrò mọ́.
37 Détourne mes yeux de la vue des choses frivoles, fais-moi vivre dans tes voies.
Yí ojú mi padà kúrò láti máa wo ohun asán: pa ọ̀nà mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
38 Accomplis ton dire en faveur de ton serviteur, car il amène à te révérer.
Mú ìlérí rẹ sẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí òfin rẹ dára.
39 Ecarte de moi la honte que je redoute, car tes jugements sont précieux.
Yí ẹ̀gàn mi padà tí mo bẹ̀rù nítorí tí ìdájọ́ rẹ dára.
40 Voici, j’ai la passion de tes préceptes, fais-moi vivre par ta justice.
Kíyèsi i, ọkàn mi ti fà sí ẹ̀kọ́ rẹ! Pa ayé mi mọ́ nínú òdodo rẹ.
41 Que tes bontés descendent sur moi, Eternel, ton salut, tel que tu l’as promis.
Jẹ́ kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà wá bá mi, Olúwa, ìgbàlà rẹ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
42 Je pourrai ainsi répliquer à qui m’outrage, car j’ai confiance en ta parole.
Nígbà náà ni èmi yóò dá ẹni tí ń sọ̀rọ̀ ẹ̀gàn sí mi lóhùn, nítorí èmi gbẹ́kẹ̀lé ọ̀rọ̀ rẹ.
43 Ne supprime jamais une parole de vérité de ma bouche, car je mets mon attente en tes jugements.
Má ṣe gba ọ̀rọ̀ òtítọ́ láti ẹnu mi nítorí èmi ti gbé ìrètí mi sínú àṣẹ rẹ.
44 Je veux observer ta Loi constamment, à tout jamais.
Èmi yóò máa gbọ́rọ̀ sí òfin rẹ nígbà gbogbo láé àti láéláé.
45 Ainsi je circulerai bien au large, car j’aurai eu le souci de tes préceptes.
Èmi yóò máa rìn káàkiri ní òmìnira, nítorí èmi ti kígbe ẹ̀kọ́ rẹ jáde.
46 Je ferai de tes vérités l’objet de mes discours, en face des rois, sans aucune fausse honte.
Èmi yóò sọ̀rọ̀ òfin rẹ níwájú àwọn ọba ojú kì yóò sì tì mí,
47 Et je ferai mes délices de tes commandements, qui me sont bien chers.
nítorí èmi ní inú dídùn nínú àṣẹ rẹ nítorí èmi ní ìfẹ́ wọn.
48 Je tendrai mes mains vers tes commandements, que j’aime, et consacrerai mes méditations à tes préceptes.
Èmi gbé ọwọ́ mi sókè nítorí àṣẹ rẹ, èyí tí èmi fẹ́ràn, èmi sì ń ṣe àṣàrò òfin rẹ̀.
49 Rappelle-toi, en faveur de ton serviteur, la promesse où tu as voulu que je mette mon attente.
Rántí ọ̀rọ̀ rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ, nítorí ìwọ ti fún mi ní ìrètí.
50 C’Est là ma consolation dans la misère, que ta parole me rende la vie.
Ìtùnú mi nínú ìpọ́njú mi ni èyí: ìpinnu rẹ pa ayé mi mọ́.
51 Des arrogants m’ont raillé au possible: je n’ai point dévié de ta Loi.
Àwọn agbéraga fi mí ṣe ẹlẹ́yà láì dádúró, ṣùgbọ́n èmi kò padà nínú òfin rẹ.
52 Je me remémore tes jugements de jadis, ô Eternel, et j’y trouve du réconfort.
Èmi rántí àwọn òfin rẹ ìgbàanì, Olúwa, èmi sì rí ìtùnú nínú wọn.
53 Un violent frisson m’avait saisi à cause des méchants, qui abandonnent ta Loi.
Ìbínú dì mímú ṣinṣin nítorí àwọn ẹni búburú, tí wọ́n ti kọ òfin rẹ sílẹ̀.
54 Mais tes préceptes sont devenus pour moi un sujet de cantiques dans ma demeure passagère.
Òfin rẹ ni ọ̀rọ̀ ìpìlẹ̀ orin mi níbikíbi tí èmi ń gbé.
55 Je me souviens de ton nom pendant la nuit, Seigneur, et j’observe ta Loi.
Ní òru èmi rántí orúkọ rẹ, Olúwa, èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́
56 C’Est là mon bonheur à moi, de m’attacher à tes préceptes.
nítorí tí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ gbọ́.
57 "C’Est mon lot à moi, ô Eternel, me suis-je dit, d’observer tes paroles."
Ìwọ ni ìpín mi, Olúwa: èmi ti pinnu láti tẹríba sí ọ̀rọ̀ rẹ.
58 Je t’implore de tout mon cœur, sois-moi propice, selon ta promesse.
Èmi ti wá ojú rẹ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: fún mi ní oore-ọ̀fẹ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
59 J’Ai médité sur mes voies, et ramené mes pas vers tes statuts.
Èmi ti kíyèsi ọ̀nà mi èmi sì ti gbé ìgbésẹ̀ mi sí òfin rẹ.
60 Je me suis empressé, sans perdre un moment, d’observer tes commandements.
Èmi yóò yára, ń kò ni lọ́ra láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
61 Les liens des méchants m’avaient enserré: je n’ai point oublié ta Loi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn ẹni búburú dì mí pẹ̀lú okùn, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
62 Au milieu de la nuit je me lève pour te rendre grâce, à cause de tes équitables jugements.
Ní àárín ọ̀gànjọ́ òru èmi dìde láti fi ọpẹ́ fún ọ nítorí òfin òdodo rẹ.
63 Je suis l’allié de tous ceux qui te révèrent et qui pratiquent tes lois.
Èmi jẹ́ ọ̀rẹ́ sí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ, sí gbogbo àwọn tí ń tẹ̀lé ẹ̀kọ́ rẹ.
64 De ta grâce, Eternel, la terre est remplie: enseigne-moi tes préceptes.
Ayé kún fún ìfẹ́ rẹ, Olúwa, kọ́ mi ní òfin rẹ.
65 Tu as traité avec bienveillance ton serviteur, ô Eternel, conformément à ta parole.
Ṣe rere sí ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa.
66 Enseigne-moi ces choses précieuses: le jugement et la science, car j’ai foi en tes commandements.
Kọ́ mi ní ìmọ̀ àti ìdájọ́ rere, nítorí mo gbàgbọ́ nínú àṣẹ rẹ.
67 Avant que je fusse humilié, je m’égarais; maintenant, je suis attentif à tes discours.
Kí a tó pọ́n mi lójú èmi ti ṣìnà, ṣùgbọ́n ni ìsinsin yìí èmi gbọ́rọ̀ sí ọ̀rọ̀ rẹ.
68 Tu es bon et tu exerces le bien, instruis-moi dans tes préceptes.
Ìwọ dára, ohun tí ìwọ sì ń ṣe rere ni; kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
69 Des orgueilleux inventent des mensonges contre moi, et moi, de tout cœur, j’observe tes ordonnances.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àwọn agbéraga ti gbìmọ̀ èké sí mí, èmi pa ẹ̀kọ́ rẹ mọ́ pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi.
70 Leur cœur est bouché comme par la graisse: moi, je fais mes délices de ta Loi.
Ọkàn wọn yigbì kò sì ní àánú, ṣùgbọ́n èmi ní inú dídùn nínú òfin rẹ.
71 C’Est un avantage pour moi d’avoir connu la misère, pour mieux apprendre tes préceptes.
Ó dára fún mi kí a pọ́n mi lójú nítorí kí èmi lè kọ́ òfin rẹ.
72 Plus précieux est pour moi l’enseignement de ta bouche que des monceaux de pièces d’or et d’argent.
Òfin tí ó jáde láti ẹnu rẹ ju iyebíye sí mi lọ ó ju ẹgbẹ̀rún ẹyọ fàdákà àti wúrà lọ.
73 Ce sont tes mains qui m’ont formé et organisé, donne-moi l’intelligence pour que j’apprenne à connaître tes commandements.
Ọwọ́ rẹ ni ó dá mi tí ó sì mọ mí; fún mi ní òye láti kọ́ àṣẹ rẹ.
74 Ceux qui te craignent, en me voyant, seront dans la joie, car j’espère en ta parole.
Jẹ́ kí gbogbo àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ máa yọ̀ nígbà tí wọ́n bá rí mi, nítorí èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
75 Je sais, ô Seigneur, que tes arrêts sont toute justice, et que c’est en équité que tu m’as humilié.
Èmi mọ, Olúwa, nítorí òfin rẹ òdodo ni, àti ní òtítọ́ ni ìwọ pọ́n mi lójú.
76 Que ta grâce s’applique donc à me consoler, comme tu l’avais promis à ton serviteur.
Kí ìfẹ́ rẹ tí kì í kùnà jẹ́ ìtùnú mi, gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ sí ìránṣẹ́ rẹ.
77 Que ta miséricorde s’étende sur moi et que je vive, puisque ta Loi fait mes délices.
Jẹ́ kí àánú rẹ kí ó tọ̀ mí wá, kí èmi kí ó lè yè, nítorí òfin rẹ jẹ́ ìdùnnú mi.
78 Que les orgueilleux soient déçus, pour m’avoir maltraité gratuitement; moi, je méditerai tes préceptes.
Kí ojú kí ó ti àwọn agbéraga nítorí wọn pa mí lára láìnídìí ṣùgbọ́n èmi yóò máa ṣe àṣàrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
79 Que tes adorateurs reviennent à moi, et ceux qui connaissent tes vérités.
Kí àwọn tí ó bẹ̀rù rẹ yí padà sí mi, àwọn tí ó ní òye òfin rẹ.
80 Que mon cœur soit sincèrement attaché à tes lois, afin que je n’aie point à rougir.
Jẹ́ kí ọkàn mi wà láìlẹ́bi sí òfin rẹ, kí ojú kí ó má ṣe tì mí.
81 Mon âme languit après ton secours, c’est en ta parole que je mets mon espoir.
Ọkàn mi ń fojú ṣọ́nà nítorí ìgbàlà rẹ, ṣùgbọ́n èmi ti fi ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
82 Mes yeux se consument dans l’attente de ta parole, tandis que je dis: "Quand me consoleras-tu?"
Ojú mi kùnà, pẹ̀lú wíwo ìpinnu rẹ; èmi wí pé, “Nígbà wo ni ìwọ yóò tù mí nínú?”
83 Car je suis comme une outre dans des flots de fumée: tes préceptes, je ne les ai point oubliés.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi dàbí awọ-wáìnì lójú èéfín, èmi kò gbàgbé ìlànà rẹ.
84 Que dureront les jours de ton serviteur? Quand feras-tu justice de mes persécuteurs?
Báwo ni ìránṣẹ́ rẹ̀ yóò ṣe dúró pẹ́ tó? Nígbà wo ni ìwọ yóò bá àwọn tí ń ṣe inúnibíni sí mi wí?
85 Des pervers m’ont creusé des fosses, au mépris de ta Loi.
Àwọn agbéraga wa ihò ìṣubú fún mi, tí ó lòdì sí òfin rẹ.
86 Tous tes commandements sont loyauté parfaite, eux me pourchassent sans motif: viens à mon aide.
Gbogbo àṣẹ rẹ yẹ ní ìgbẹ́kẹ̀lé; ràn mí lọ́wọ́, nítorí ènìyàn ń ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí.
87 Peu s’en faut qu’ils ne m’aient anéanti sur terre, alors que moi, je n’ai point délaissé tes préceptes.
Wọ́n fẹ́rẹ pa mí rẹ́ kúrò nínú ayé, ṣùgbọ́n èmi kò kọ ẹ̀kọ́ rẹ.
88 Fidèle à ta bonté, conserve-moi en vie, et je respecterai le témoignage de ta bouche.
Pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ, èmi yóò sì gba ẹ̀rí ẹnu rẹ̀ gbọ́.
89 Pour l’éternité, Seigneur, ta parole demeure immuable dans les cieux.
Ọ̀rọ̀ rẹ, Olúwa, títí láé ni; ó dúró ṣinṣin ní ọ̀run.
90 D’Âge en âge dure ta fidélité: tu as affermi la terre, et elle est inébranlable.
Òtítọ́ rẹ̀ ń lọ dé gbogbo ìran dé ìran; ìwọ ti dá ayé, ó sì dúró ṣinṣin.
91 Selon tes lois, les êtres subsistent aujourd’hui, car ils sont tous tes serviteurs.
Òfin rẹ dúró di òní nítorí ohun gbogbo ń sìn ọ́.
92 Si ta Loi n’avait fait mes délices, j’aurais succombé dans ma misère.
Bí òfin rẹ̀ kò bá jẹ́ dídùn inú mi, èmi ìbá ti ṣègbé nínú ìpọ́njú mi.
93 Jamais je n’oublierai tes préceptes, car par eux tu m’assures la vie.
Èmi kì yóò gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ láé, nítorí nípa wọn ni ìwọ ti pa ayé mi mọ́.
94 Je suis à toi, prête-moi secours, car je m’enquiers de tes ordres.
Gbà mí, nítorí èmi jẹ́ tìrẹ èmi ti wá ẹ̀kọ́ rẹ.
95 Des méchants me guettent pour me perdre: je cherche à pénétrer le sens de tes prescriptions.
Àwọn ẹni búburú dúró láti pa mí run, ṣùgbọ́n èmi yóò kíyèsi ẹ̀rí rẹ.
96 A tout bien j’ai vu des limites: ta Loi est infiniment vaste.
Sí ohun pípé gbogbo èmi ti rí òpin; ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ aláìlópin ni.
97 Combien j’aime ta Loi! Tout le temps elle est l’objet de mes méditations.
Báwo ni èmi ti fẹ́ òfin rẹ tó! Èmi ń ṣe àṣàrò nínú rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ pípẹ́ wá.
98 Tes commandements me rendent plus sage que mes ennemis, car ils sont pour moi un bien inépuisable.
Àṣẹ rẹ mú mi gbọ́n ju àwọn ọ̀tá mi lọ, nítorí wọ́n wà pẹ̀lú mi láé.
99 Je suis plus avisé que tous mes précepteurs, car tes vérités sont le thème de mes réflexions.
Èmi ní iyè inú ju gbogbo olùkọ́ mi lọ, nítorí èmi ń ṣe àṣàrò nínú òfin rẹ.
100 J’Ai plus d’expérience que les vieillards, car je respecte tes préceptes.
Èmi ni òye ju àwọn àgbà lọ, nítorí mo gba ẹ̀kọ́ rẹ.
101 J’Ai tenu mes pas éloignés de tout mauvais chemin, en vue d’observer tes paroles.
Èmi ti pa ẹsẹ̀ mi mọ́ nínú gbogbo ọ̀nà ibi nítorí kí èmi lè gba ọ̀rọ̀ rẹ.
102 Je n’ai point dévié de tes règles, car c’est toi qui m’as instruit.
Èmi kò yà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ìwọ fúnra rẹ̀ ni ó kọ́ mi.
103 Que tes paroles sont douces à mon palais! Le miel l’est moins à ma bouche.
Báwo ni ọ̀rọ̀ rẹ̀ ṣe dùn mọ́ mi lẹ́nu tó, ó dùn ju oyin lọ ní ẹnu mi!
104 J’Ai puisé mon savoir dans tes préceptes, c’est pourquoi je hais toute voie mensongère.
Èmi rí òye gbà nínú ẹ̀kọ́ rẹ; nítorí náà èmi kórìíra gbogbo ọ̀nà tí kò tọ́.
105 Ta parole est un flambeau qui éclaire mes pas, une lumière qui rayonne sur ma route.
Ọ̀rọ̀ rẹ ni fìtílà sí ẹsẹ̀ mi àti ìmọ́lẹ̀ sí ipa ọ̀nà mi.
106 J’Ai fait le serment, et je le tiendrai, d’observer les règles de ta justice.
Èmi ti ṣe ìbúra èmi sì ti tẹnumọ́ ọn wí pé èmi yóò máa tẹ̀lé òfin òdodo rẹ.
107 Je suis extrêmement accablé, Eternel, conserve-moi en vie selon ta parole.
A pọ́n mi lójú gidigidi; Olúwa, sọ mi di ààyè, gẹ́gẹ́ bi ọ̀rọ̀ rẹ
108 Agrée de grâce, Seigneur, les vœux de ma bouche, et enseigne-moi tes lois.
Olúwa, gba ìyìn àtinúwá ẹnu mi, kí o sì kọ́ mi ní òfin rẹ̀.
109 Mon âme court sans cesse des dangers, et je n’ai point oublié ta loi.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ayé mi wà ni ọwọ́ mi nígbà gbogbo, èmi kò ní gbàgbé òfin rẹ.
110 Des méchants me dressent des pièges, pourtant je ne dévie point de tes préceptes.
Àwọn ẹni búburú ti dẹ okùn sílẹ̀ fún mi, ṣùgbọ́n èmi kò ṣìnà kúrò nínú ẹ̀kọ́ rẹ.
111 Je reste pour toujours en possession de tes vérités, car elles sont la joie de mon cœur.
Òfin rẹ ni ogún mi láéláé; àwọn ni ayọ̀ ọkàn mi.
112 J’Ai incliné mon cœur à accomplir tes lois à tout jamais, jusqu’à la fin dernière.
Ọkàn mi ti lé pípa òfin rẹ mọ́ láé dé òpin.
113 Je hais les gens à double face, mais ta Loi, je l’aime.
Èmi kórìíra àwọn ọlọ́kàn méjì, ṣùgbọ́n èmi fẹ́ òfin rẹ.
114 Tu es mon abri et mon bouclier, j’espère en ta parole.
Ìwọ ni ààbò mi àti asà mi; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
115 Loin de moi, ô malfaiteurs! Je veux observer les commandements de mon Dieu.
Ẹ kúrò lọ́dọ̀ mi, ẹ̀yin olùṣe búburú, kí èmi lè pa àṣẹ Ọlọ́run mi mọ́!
116 Soutiens-moi selon ta promesse pour que je vive, et ne laisse pas mon espoir se changer en déception.
Gbé mi sókè gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ, kí èmi kí ó lè yè Má sì jẹ́ kí ojú ìrètí mi kí ó tì mí.
117 Accorde-moi ton appui pour que je sois sauvé, je me tournerai sans cesse vers tes lois.
Gbé mi sókè, èmí yóò sì wa láìléwu; nígbà gbogbo ni èmi yóò máa júbà òfin rẹ.
118 Tu foules aux pieds ceux qui errent loin de tes préceptes, car leurs ruses habiles ne sont que mensonge.
Ìwọ kọ gbogbo àwọn tí ó ṣìnà kúrò nínú òfin rẹ, nítorí ẹ̀tàn wọn asán ni.
119 Comme des scories, tu élimines tous les méchants sur terre, c’est pourquoi j’aime tes vérités.
Gbogbo àwọn ẹni búburú ní ayé ni ìwọ yọ kúrò bí i ìdàrọ́; nítorí náà, èmi fẹ́ òfin rẹ̀.
120 Ma chair frissonne de la terreur que tu inspires, et je redoute tes jugements.
Ara mi wárìrì ní ìbẹ̀rù nítorí rẹ̀: èmi dúró ní ìbẹ̀rù òfin rẹ.
121 J’Ai pratiqué la justice et l’équité, ne m’abandonne pas à mes oppresseurs.
Èmi ti ṣe ohun tí i ṣe òdodo àti ẹ̀tọ́: má ṣe fi mí sílẹ̀ fún àwọn tó ń ni mí lára.
122 Interviens pour le bonheur de ton serviteur, que des arrogants ne m’accablent point.
Mú kí àlàáfíà ìránṣẹ́ rẹ dájú: má ṣe jẹ́ kí àwọn agbéraga ni mi lára.
123 Mes yeux languissent après ton secours, et après ta parole de salut.
Ojú mi kùnà, fún wíwo ìgbàlà rẹ, fún wíwo ìpinnu òdodo rẹ.
124 Traite ton serviteur selon ta grâce, et enseigne-moi tes préceptes.
Ṣe pẹ̀lú ìránṣẹ́ rẹ gẹ́gẹ́ bí dídúró ṣinṣin ìfẹ́ rẹ kí o sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
125 Je suis ton serviteur, donne-moi la sagacité, pour que je comprenne tes vérités.
Èmi ni ìránṣẹ́ rẹ; ẹ fún mi ní òye kí èmi lè ní òye òfin rẹ
126 Le temps est venu d’agir pour l’Eternel: on a violé ta Loi.
Ó tó àsìkò fún ọ láti ṣe iṣẹ́, Olúwa; nítorí òfin rẹ ti fọ́.
127 C’Est pourquoi j’aime tes commandements, plus que l’or et le métal fin.
Nítorí èmi fẹ́ràn àṣẹ rẹ ju wúrà, àní ju wúrà dídára lọ,
128 C’Est pourquoi je reconnais la parfaite droiture de tous tes préceptes, et déteste toute voie mensongère.
nítorí èmi kíyèsi gbogbo ẹ̀kọ́ òtítọ́ rẹ̀, èmi kórìíra gbogbo ipa ọ̀nà búburú.
129 Merveilleux sont tes statuts, aussi mon âme les garde-t-elle avec soin.
Òfin rẹ̀ ìyanu ni: nítorí náà èmi gbà wọ́n gbọ́.
130 La révélation de tes paroles projette de la lumière, donne de l’intelligence aux simples.
Ìṣípayá ọ̀rọ̀ rẹ̀ mú ìmọ́lẹ̀ wá; ó fi òye fún àwọn òpè.
131 J’Ouvre largement la bouche pour aspirer, car j’ai la passion de tes commandements.
Èmi ya ẹnu mi mo sì mí hẹlẹ, nítorí èmi fojú ṣọ́nà sí àṣẹ rẹ.
132 Tourne-toi vers moi et sois-moi propice, comme tu le fais pour ceux qui aiment ton nom.
Yí padà sí mi kí o sì ṣàánú fún mi, bí ìwọ ṣe máa ń ṣe nígbà gbogbo sí àwọn tí ó fẹ́ràn orúkọ rẹ.
133 Affermis mes pas par tes discours, qu’aucune mauvaise passion ne prenne le dessus sur moi.
Fi ìṣísẹ̀ mi múlẹ̀ nínú ọ̀rọ̀ rẹ, má ṣe jẹ́ kí ẹ̀ṣẹ̀ borí mi.
134 Délivre-moi de l’oppression des hommes, pour que je puisse observer tes préceptes.
Rà mí padà lọ́wọ́ aninilára ènìyàn, kí èmi lè gbọ́ ẹ̀kọ́ rẹ.
135 Fais luire ta face sur ton serviteur, et enseigne-moi tes préceptes.
Jẹ́ kí ojú rẹ kí ó tàn sí ìránṣẹ́ rẹ lára kí ó sì kọ́ mi ní àṣẹ rẹ.
136 Mes yeux ont versé des torrents de larmes, parce qu’on n’observe pas ta Loi.
Omijé sàn jáde ní ojú mi, nítorí wọn kò gba pé òfin rẹ̀ jẹ́ òtítọ́.
137 Tu es juste, ô Seigneur, et équitables sont tes jugements.
Olódodo ni ìwọ Olúwa ìdájọ́ rẹ sì dúró ṣinṣin.
138 Tu as imposé tes justes ordonnances: elles sont tout à fait infaillibles.
Òfin ti ìwọ gbé kalẹ̀ jẹ́ òdodo: wọ́n yẹ ni ìgbẹ́kẹ̀lé.
139 Je suis consumé par mon zèle jaloux, car mes adversaires oublient tes paroles.
Ìtara mi ti pa mí run, nítorí àwọn ọ̀tá mi fi ojú fo ọ̀rọ̀ rẹ dá.
140 Ta parole est infiniment épurée, elle est chère à ton serviteur.
Wọ́n ti dán ìpinnu rẹ wò pátápátá ìránṣẹ́ rẹ sì fẹ́ràn wọ́n.
141 Je suis chétif et méprisé: tes préceptes, je ne les ai point oubliés.
Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé èmi jẹ́ onírẹ̀lẹ̀ àti ẹni ẹ̀gàn èmi kò ni gbàgbé ẹ̀kọ́ rẹ.
142 Ta justice est éternellement équitable, et ta Loi est vérité.
Òdodo rẹ wà títí láé òtítọ́ ni òfin rẹ̀.
143 La détresse et l’angoisse m’ont atteint: tes commandements sont mes délices.
Ìyọnu àti ìpọ́njú wá sórí mi, ṣùgbọ́n àṣẹ rẹ ni inú dídùn mi.
144 Tes statuts sont à jamais équitables, permets-moi de les comprendre, pour que je vive.
Òfin rẹ jẹ́ òtítọ́ láé; fún mi ní òye kí èmi lè yè.
145 Je t’invoque de tout cœur, exauce-moi, Seigneur! Je veux observer tes préceptes.
Èmi kígbe pẹ̀lú gbogbo ọkàn mi: dá mi lóhùn Olúwa, èmi yóò sì gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ.
146 Je t’appelle, viens à mon secours, et je garderai tes statuts.
Èmi kígbe pè ọ́; gbà mí èmi yóò sì pa òfin rẹ mọ́.
147 Dès l’aurore je m’empresse d’implorer, j’espère en ta parole.
Èmi dìde ṣáájú àfẹ̀mọ́júmọ́ èmi ké fún ìrànlọ́wọ́; èmi ti mú ìrètí mi sínú ọ̀rọ̀ rẹ.
148 Mes yeux devancent les veilles de la nuit, pour méditer ta parole.
Ojú mi ṣáájú ìṣọ́ òru, nítorí kí èmi lè ṣe àṣàrò nínú ọ̀rọ̀ rẹ.
149 Daigne écouter ma voix, selon ta bonté, Eternel; fais-moi vivre selon l’arrêt de ta justice.
Gbọ́ ohùn mi ní ìṣọ̀kan pẹ̀lú ìfẹ́ rẹ: pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
150 Ils m’approchent, ceux qui courent après l’infamie, il s’éloignent de ta Loi.
Àwọn tí ń gbìmọ̀ ìlànà búburú wà ní tòsí, ṣùgbọ́n wọ́n jìnnà sí òfin rẹ.
151 Toi, Seigneur, tu es près de moi, tous tes commandements sont vérité.
Síbẹ̀ ìwọ wà ní tòsí, Olúwa, àti gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òtítọ́.
152 Dès longtemps j’avais connaissance de tes statuts, car tu les as établis pour l’éternité.
Láti ọjọ́ pípẹ́ wá èmi ti kọ́ nínú òfin rẹ tí ìwọ ti fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé.
153 Vois ma misère et tire-moi du danger, car je n’ai pas oublié ta Loi.
Wo ìpọ́njú mi kí o sì gbà mí, nítorí èmi kò gbàgbé òfin rẹ.
154 Prends en main ma cause et délivre-moi, fais-moi vivre pour me consacrer à ta parole.
Gba ẹjọ́ mi rò kí o sì rà mí padà; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
155 Le salut est loin des méchants, car ils ne se soucient pas de tes préceptes.
Ìgbàlà jìnnà sí àwọn ẹni búburú nítorí wọn kò wá àṣẹ rẹ.
156 Grande est ta miséricorde, Eternel, fais-moi vivre selon l’arrêt de ta justice.
Ìyọ́nú rẹ̀ tóbi, Olúwa; pa ayé mi mọ́ gẹ́gẹ́ bí òfin rẹ.
157 Nombreux sont mes persécuteurs et mes ennemis; je n’ai point dévié de tes statuts.
Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ni àwọn ọ̀tá tí wọ́n ń ṣe inúnibíni sí mi, ṣùgbọ́n èmi kò tí ì yípadà kúrò nínú òfin rẹ.
158 J’Ai observé les traîtres et j’en ai été écœuré, car ils ne respectent pas ta parole.
Èmi wo àwọn ẹlẹ́tàn, inú mi sì bàjẹ́ nítorí wọn kò gba ọ̀rọ̀ rẹ gbọ́.
159 Vois comme j’aime tes prescriptions, Seigneur, selon ta bonté, fais-moi vivre.
Wo bí èmi ṣe fẹ́ràn ẹ̀kọ́ rẹ; pa ayé mi mọ́, Olúwa, gẹ́gẹ́ bí ìfẹ́ rẹ.
160 L’Ensemble de tes paroles est vérité, éternels sont tous les arrêts de ta justice.
Òtítọ́ ni gbogbo ọ̀rọ̀ rẹ; gbogbo òfin òdodo rẹ láéláé ni.
161 Des grands me persécutent gratuitement, et mon cœur tremble devant ta parole.
Àwọn alákòóso ṣe inúnibíni sí mi láìnídìí, ṣùgbọ́n ọkàn mi wárìrì sí ọ̀rọ̀ rẹ.
162 Je me réjouis de tes promesses, comme quelqu’un qui a trouvé un riche butin.
Èmi yọ̀ nínú ìpinnu rẹ bí ẹni tí ó rí ìkógun púpọ̀.
163 Je hais le mensonge, je l’ai en horreur, c’est ta Loi que j’aime.
Èmi kórìíra mo sì kọ èké ṣíṣe ṣùgbọ́n mo fẹ́ràn òfin rẹ.
164 Sept fois par jour je célèbre tes louanges, en raison de tes justes arrêts.
Èmi yìn ọ́ ní ìgbà méje lójúmọ́ nítorí òfin òdodo rẹ.
165 Un grand bonheur attend ceux qui aiment ta Loi: pour eux point de cause de chute.
Àlàáfíà púpọ̀ wà fún àwọn tí ó ní ìfẹ́ sí òfin rẹ, kò sì ṣí ohun tí ó lè mú wọn kọsẹ̀.
166 J’Ai pleine confiance en ton secours, Seigneur, et j’accomplis tes commandements.
Èmi yóò dúró de ìgbàlà rẹ, Olúwa, èmi yóò sì tẹ̀lé àṣẹ rẹ.
167 Mon âme observe tes témoignages, je les aime infiniment.
Èmi gba òfin rẹ gbọ́, nítorí mo fẹ́ràn wọn púpọ̀púpọ̀.
168 J’Observe tes prescriptions et tes statuts, car toutes mes voies sont sous tes regards.
Èmi ṣe ìgbọ́ràn sí ẹ̀kọ́ rẹ àti òfin rẹ, nítorí ìwọ mọ gbogbo ọ̀nà mi.
169 Que mon hymne arrive jusqu’à toi, Eternel, fais-moi comprendre le sens de ta parole.
Jẹ́ kí igbe mi wá sí iwájú rẹ, Olúwa; fún mi ní òye gẹ́gẹ́ bí ọ̀rọ̀ rẹ.
170 Que ma supplication vienne devant toi, sauve-moi selon ta promesse.
Jẹ́ kí ẹ̀bẹ̀ mi wá sí iwájú rẹ; gbà mí gẹ́gẹ́ bí ìpinnu rẹ.
171 Mes lèvres laisseront s’échapper tes louanges, car tu m’enseignes tes préceptes.
Ètè mi yóò sọ ìyìn jáde, nítorí ìwọ kọ́ mi ní ìlànà rẹ.
172 Ma langue chantera ta parole, car tous tes commandements sont équité.
Jẹ́ kí ahọ́n mi kọ orin ọ̀rọ̀ rẹ, nítorí gbogbo àṣẹ rẹ jẹ́ òdodo.
173 Puisse ta main s’appliquer à me secourir, puisque j’ai fait choix de tes prescriptions!
Jẹ́ kí ọwọ́ rẹ ṣetán láti ràn mí lọ́wọ́, nítorí èmi ti yan ẹ̀kọ́ rẹ.
174 J’Aspire à ton secours, Eternel, et ta Loi fait mes délices.
Èmi wo ọ̀nà fún ìgbàlà rẹ, Olúwa, àti òfin rẹ jẹ́ dídùn inú mi.
175 Que mon âme vive pour te louer, que tes jugements soient mon soutien.
Jẹ́ kí èmi wà láààyè ki èmi lè yìn ọ́, kí o sì jẹ́ kí òfin rẹ mú mi dúró.
176 J’Erre comme une brebis égarée; mets-toi à la recherche de ton serviteur! Car je n’ai pas oublié tes commandements.
Èmí ti ṣìnà bí àgùntàn tí ó sọnù. Wá ìránṣẹ́ rẹ, nítorí èmi kò gbàgbé àṣẹ rẹ.

< Psaumes 119 >