< Psaumes 115 >

1 Non pour nous, Eternel, non pour nous, mais pour faire honneur à ton nom, donne cours à ta bonté et à ta bienveillance.
Kì í ṣe fún wa, Olúwa kì í ṣe fún wa, ṣùgbọ́n fún orúkọ rẹ ni a fi ògo fún, fún àánú àti òtítọ́ rẹ.
2 Pourquoi les peuples diraient-ils: "Où donc est leur Dieu?"
Torí kí ni àwọn kèfèrí yóò ṣe sọ pé, níbo ni Ọlọ́run wa wà.
3 Or notre Dieu est dans les cieux, il accomplit toutes ses volontés.
Ṣùgbọ́n Ọlọ́run wa wà lọ́run: tí ó ń ṣe èyí tí ó wù ú.
4 Leurs idoles sont d’argent et d’or, œuvre de mains humaines.
Fàdákà òun wúrà ni èrè àwọn aláìkọlà, iṣẹ́ ọwọ́ ènìyàn ni.
5 Elles ont une bouche et ne parlent point, des yeux, et elles ne voient pas;
Wọ́n ní ẹnu, ṣùgbọ́n wọn kò le sọ̀rọ̀, wọ́n ní ojú, ṣùgbọ́n wọn kò fi ríran.
6 elles ont des oreilles et elles n’entendent pas, des narines, et elles n’ont point d’odorat.
Wọ́n ní etí, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbọ́rọ̀: wọ́n ní imú, ṣùgbọ́n wọn kò fi gbóòórùn.
7 Malgré leurs mains, elles n’ont pas le sens du toucher, malgré leurs pieds, elles ne sauraient marcher; aucun son ne s’échappe de leur gosier.
Wọ́n ní ọwọ́, ṣùgbọ́n wọn kò lò ó, wọ́n ní ẹsẹ̀, ṣùgbọ́n wọn kò rìn; bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sọ̀rọ̀ nínú òfin wọn.
8 Puissent leur ressembler ceux qui les confectionnent, tous ceux qui leur témoignent de la confiance!
Àwọn tí ń ṣe wọ́n dàbí wọn; gẹ́gẹ́ bẹ́ẹ̀ ni olúkúlùkù ẹni tí ó gbẹ́kẹ̀ rẹ̀ lé wọn.
9 Israël, confie-toi à Dieu! Il est leur aide et leur bouclier.
Ìwọ Israẹli gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn
10 Maison d’Aaron, confie-toi à Dieu! Il est leur aide et leur bouclier.
Ẹ̀ yin ilé Aaroni, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ni ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
11 Vous, adorateurs de l’Eternel, confiez-vous à lui! Il est leur aide et leur bouclier.
Ẹ̀ yin tí ó bẹ̀rù Olúwa, gbẹ́kẹ̀lé Olúwa: òun ní ìrànwọ́ àti ààbò wọn.
12 L’Eternel se souvient de nous pour nous bénir; qu’il bénisse la maison d’Israël, qu’il bénisse la maison d’Aaron!
Olúwa tí ń ṣe ìrántí wa; yóò bùkún ilé Israẹli; yóò bùkún ilé Aaroni.
13 Qu’il bénisse ceux qui le révèrent, les petits ainsi que les grands!
Ìbùkún ni fún àwọn tí ó bẹ̀rù Olúwa, àti kékeré àti ńlá.
14 Que l’Eternel multiplie ses bontés pour vous, pour vous et pour vos enfants!
Olúwa yóò mú ọ pọ̀ sí i síwájú àti síwájú, ìwọ àti àwọn ọmọ rẹ̀.
15 Soyez bénis par l’Eternel, qui a créé le ciel et la terre!
Ẹ fi ìbùkún fún Olúwa ẹni tí ó dá ọ̀run òun ayé.
16 Les cieux, oui, les cieux sont à l’Eternel, mais la terre, il l’a octroyée aux fils de l’homme.
Ọ̀run àní ọ̀run ni ti Olúwa: ṣùgbọ́n ayé ló fi fún ọmọ ènìyàn.
17 Ce ne sont pas les morts qui loueront le Seigneur, ni aucun de ceux qui sont descendus dans l’empire du silence,
Òkú kò lè yìn Olúwa, tàbí ẹni tí ó ti lọ sí ìsàlẹ̀ ìdákẹ́ jẹ́ẹ́.
18 tandis que nous, nous bénissons l’Eternel, maintenant et à tout jamais. Alléluia!
Ṣùgbọ́n àwa ó fi ìbùkún fún Olúwa láti ìsinsin yìí lọ àti títí láéláé. Ẹ yin Olúwa.

< Psaumes 115 >