< Psaumes 108 >
1 Cantique. Psaume de David. Mon cœur reste ferme, ô Dieu! Je puis chanter, célébrer tes louanges; c’est là mon honneur.
Orin. Saamu ti Dafidi. Ọlọ́run, ọkàn mi dúró ṣinṣin èmi ó máa kọrin, èmi ó máa fi ọkàn mi kọrin.
2 Réveillez-vous, ô luth et harpe! Je veux réveiller l’aurore.
Jí ohun èlò orin àti haapu! Èmi ó jí ní kùtùkùtù,
3 Je te louerai parmi les nations, ô Seigneur, je te chanterai parmi les peuples.
èmi ó yìn ọ́, Olúwa, nínú àwọn orílẹ̀-èdè, èmi ó kọrin rẹ nínú àwọn ènìyàn.
4 Car ta grâce s’élève par-dessus les cieux, et ta bonté atteint jusqu’au firmament.
Nítorí tí o tóbi ní àánú rẹ ju àwọn ọ̀run lọ àti òdodo rẹ dé àwọsánmọ̀.
5 Montre ta grandeur, ô Dieu, qui dépasse les cieux; que ta gloire brille sur toute la terre!
Gbé ara rẹ ga, Ọlọ́run, lórí àwọn ọ̀run, àti ògo rẹ lórí gbogbo ayé.
6 Afin que tes bien-aimés échappent au danger, secours-nous avec ta droite, et exauce-moi!
Kí a sì lè gba àwọn olùfẹ́ rẹ là; fi ọwọ́ ọ̀tún rẹ ṣe ìgbàlà, kí o sì dá mi lóhùn
7 L’Eternel l’a annoncé en son sanctuaire: "Je triompherai, je veux m’adjuger Sichem, mesurer au cordeau la vallée de Souccot.
Ọlọ́run ti sọ̀rọ̀ láti ibi mímọ́ rẹ̀ pé, “Èmi yóò yọ̀, èmi yóò pín Ṣekemu, èmi yóò sì wọn àfonífojì Sukkoti kúrò.
8 A moi Galaad! à moi Manassé! Ephraïm est la puissante sauvegarde de ma tête, Juda est mon sceptre.
Gileadi ni tèmi, Manase ni tèmi, Efraimu ni ìbòrí mi, Juda ni olófin mi,
9 Moab est le bassin où je me lave; sur Edom, je jette ma sandale, je triomphe du pays des Philistins."
Moabu sì ni ìkòkò ìwẹsẹ̀ mi, lórí Edomu ni èmi ó bọ́ bàtà mi sí, lórí òkè Filistia ni èmi yóò hó ìhó ayọ̀.”
10 Qui me conduira à la ville forte? Qui saura me mener jusqu’à Edom?
Ta ni yóò mú mi wá sí ìlú olódi? Ta ni yóò sìn mí wá sí Edomu?
11 Ne sera-ce pas toi, ô Dieu, toi qui nous avais délaissés, qui ne faisais plus campagne avec nos armées?
Ìwọ Ọlọ́run ha kọ́, ìwọ tí ó ti kọ̀ wá sílẹ̀. Ọlọ́run ìwọ kì yóò bá àwọn jagunjagun wa jáde mọ́.
12 Prête-nous secours contre l’adversaire, puisque trompeuse est l’aide de l’homme.
Fún wa ní ìrànlọ́wọ́ nínú ìpọ́njú, nítorí ìrànlọ́wọ́ ènìyàn asán ni.
13 Avec Dieu, nous ferons des prouesses: c’est lui qui écrasera nos ennemis.
Nípasẹ̀ Ọlọ́run ni àwa ó ṣe akin nítorí òun ó tẹ àwọn ọ̀tá wa mọ́lẹ̀.