< Proverbes 30 >

1 Paroles d’Agour, fils de Yakéh. Déclaration solennelle. Ce personnage disait: "J’Ai peiné, ô Dieu, j’ai peiné, ô Dieu, et je m’y suis épuisé.
Àwọn ọ̀rọ̀ Aguri ọmọ Jake, ọ̀rọ̀ ìsọtẹ́lẹ̀ tí ọkùnrin yìí sọ fún Itieli. Sí Itieli àti sí Ukali.
2 Car je suis le plus borné des mortels, l’intelligence humaine me fait défaut.
“Èmi ni aláìmòye ju nínú àwọn ènìyàn; n kò ní òye ènìyàn.
3 Je n’ai pas étudié la sagesse, de façon à concevoir une notion exacte du Très-Saint.
Èmi kò tilẹ̀ kọ́ ọgbọ́n tàbí ní ìmọ̀ ẹni mímọ́ nì.
4 Qui est monté au Ciel et en est redescendu? Qui a recueilli le vent dans le creux de sa main? Qui a enserré les eaux dans le pan de son manteau? Qui a établi toutes les limites de la terre? Quel est son nom, quel est le nom de son fils? Dis-le si tu le sais."
Ta ni ó ti gòkè lọ sí ọ̀run tí ó sì padà sọ̀kalẹ̀? Ta ni ó ti kó afẹ́fẹ́ jọ sí ihò àtẹ́lẹwọ́ rẹ̀? Ta ni ó ti ta kókó omi sétí aṣọ? Ta ni ó fi gbogbo ìpìlẹ̀ ayé lélẹ̀? Kí ni orúkọ rẹ̀, àti orúkọ ọmọ rẹ̀? Sọ fún mi bí o bá mọ̀.
5 Toute parole émanée de Dieu est parfaite: il est un bouclier pour ceux qui s’abritent en lui.
“Gbogbo ọ̀rọ̀ Ọlọ́run jẹ́ aláìlábùkù; òun ni ààbò fún gbogbo ẹni fi í ṣe ibi ìpamọ́ wọn.
6 Ne te permets aucune addition à ses dires, il te réprouverait et tu serais convaincu de mensonge.
Má ṣe fi kún ọ̀rọ̀ rẹ̀, àìṣe bẹ́ẹ̀ yóò bá ọ wí yóò sì sọ ọ́ di òpùrọ́.
7 Je te demande deux choses; ne me les refuse pas avant que je meure!
“Ohun méjì ni mo ń béèrè lọ́wọ́ rẹ, Olúwa; má ṣe fi wọ́n dù mí kí ń tó kú.
8 Eloigne de moi la fausseté et la parole mensongère, ne me donne ni pauvreté ni richesse; accorde-moi la part de nourriture qui m’est indispensable;
Mú èké ṣíṣe àti irọ́ jìnnà sí mi; má ṣe fún mi ní òsì tàbí ọrọ̀, ṣùgbọ́n fún mi ní oúnjẹ òòjọ́ mi nìkan.
9 car, vivant dans l’abondance, je pourrais te renier en disant: "Qui est l’Eternel?" ou bien, poussé par la misère, je pourrais voler et offenser le nom de mon Dieu.
Àìṣe bẹ́ẹ̀, mo lè ní àníjù kí n sì gbàgbé rẹ kí ń sì wí pé, ‘Ta ni Olúwa?’ Tàbí kí ń di òtòṣì kí ń sì jalè kí ń sì ṣe àìbọ̀wọ̀ fún orúkọ Ọlọ́run mi.
10 Ne dénigre pas l’esclave auprès de son maître: il te maudirait, et ta faute serait punie.
“Má ṣe ba ìránṣẹ́ lórúkọ jẹ́ lọ́dọ̀ ọ̀gá rẹ̀, kí ó má ba fi ọ́ bú, kí ìwọ má ba jẹ̀bi.
11 Ah! la génération où l’on maudit son père, où l’on n’a pas de bénédiction pour sa mère!
“Àwọn kan wá ṣépè fún àwọn baba wọn tí wọn kò sì súre fún àwọn ìyá wọn.
12 La génération qui se prétend pure et qui ne s’est pas lavée Je ses souillures!
Àwọn tí ó mọ́ ní ojú ara wọn síbẹ̀ tí wọn kò sì mọ́ kúrò nínú èérí wọn;
13 La génération aux yeux démesurément hautains et au regard altier!
àwọn ẹni tí ojú wọn gbéga nígbà gbogbo, tí ìwolẹ̀ wọn sì kún fún ìgbéraga.
14 La génération dont les dents sont comme des glaives et les mâchoires comme des couteaux, servant à dévorer les pauvres de la terre et les indigents parmi les hommes!
Àwọn ẹni tí eyín wọn jẹ́ idà àwọn tí èrìgì wọn kún fún ọ̀bẹ láti jẹ àwọn tálákà run kúrò ní ilẹ̀ ayé àwọn aláìní kúrò láàrín àwọn ọmọ ènìyàn.
15 Alouka a deux filles: "Hab, Hab!" II est trois choses qui sont insatiables, quatre qui ne disent pas: "Assez!"
“Eṣúṣú ni ọmọbìnrin méjì. ‘Mú wá! Mú wá!’ ní wọn ń ké. “Àwọn nǹkan mẹ́ta kan wà tí kò ní ìtẹ́lọ́rùn láéláé, mẹ́rin tí kò jẹ́ wí láéláé pé, ‘Ó tó!’:
16 c’est le. Cheol, le sein qui n’a point conçu, la terre qui n’est jamais rassasiée d’eau et le feu qui ne dit pas: "Assez!" (Sheol h7585)
Ibojì, inú tí ó yàgàn, ilẹ̀ tí omi kì í tẹ́lọ́rùn láéláé, àti iná, tí kì í wí láéláé pé, ‘Ó tó!’ (Sheol h7585)
17 L’Œil qui se rit d’un père et n’a que dédain pour les rides d’une mère, puisse-t-il être arraché par les corbeaux de la vallée, dévoré par les aigles!
“Ojú tí ń fi baba ṣẹ̀fẹ̀, tí ó kẹ́gàn ìgbọ́ràn sí ìyá, ẹyẹ ìwò ẹ̀bá odò ni yóò yọ ọ́, igún yóò mú un jẹ.
18 Il est trois choses qui me sont inaccessibles et quatre que je ne connais point:
“Àwọn nǹkan mẹ́ta wà tí ó jẹ́ ìyàlẹ́nu fún mi, mẹ́rin tí kò yé mi,
19 la trace de l’aigle dans les cieux, la trace du serpent sur le rocher, la trace du navire au sein des mers et la trace de l’homme chez la jeune femme.
ipa ẹyẹ idì ní òfúrufú ipa ejò lórí àpáta ipa ọkọ̀ ojú omi lójú agbami Òkun àti ipa ọ̀nà ọkùnrin tí ó mú wúńdíá lọ́wọ́.
20 Tel est le secret de la conduite d’une femme adultère: elle satisfait ses appétits, s’essuie la bouche et dit: "Je n’ai rien fait de mal!"
“Èyí ni ọ̀nà alágbèrè obìnrin ó jẹun ó sì nu ẹnu rẹ̀ ó sì wí pé, ‘N kò ṣe ohunkóhun tí kò tọ́.’
21 Il est trois spectacles qui font frémir la terre et quatre qu’elle ne peut tolérer:
“Lábẹ́ nǹkan mẹ́ta ni ilé ayé ti ń wárìrì lábẹ́ ohun mẹ́rin ni kò ti lè mí fín ín.
22 le spectacle de l’esclave qui devient roi, le spectacle du scélérat qui vit dans l’abondance:
Ìránṣẹ́ tí ó di ọba aláìgbọ́n tí ó ní ọ̀pọ̀lọpọ̀ oúnjẹ,
23 le spectacle d’une femme digne d’aversion qui trouve un épouseur, et le spectacle de la servante qui supplante sa maîtresse.
obìnrin tí gbogbo ènìyàn kórìíra tí ó sì wá lọ́kọ ìránṣẹ́bìnrin tí ó gbọkọ mọ́ ọ̀gá rẹ̀ lọ́wọ́.
24 Il existe sur terre quatre êtres tout petits, et qui sont sages par excellence:
“Àwọn ohun mẹ́rin ló kéré láyé síbẹ̀ wọ́n gbọ́n gidigidi.
25 les fourmis, peuple sans force, font en été leurs provisions;
Àwọn èèrà jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá, síbẹ̀ wọ́n kó oúnjẹ wọn pamọ́ ní àsìkò òjò.
26 les gerboises, peuple sans puissance, établissent leur demeure dans les rochers;
Ehoro jẹ́ aláìlágbára ẹ̀dá; síbẹ̀ wọ́n ń ṣe ihò wọn sí ibi pálapàla àpáta;
27 les sauterelles n’ont pas de roi et elles se mettent toutes en campagne par bandes;
àwọn eṣú kò ní ọba, síbẹ̀ gbogbo wọ́n ń jáde lọ ní ọ̀wọ̀ọ̀wọ́
28 l’araignée, tu peux l’attraper avec la main, et elle se tient dans le palais des rois!
Ọmọnílé fi ọwọ́ rẹ̀ dì mú, síbẹ̀ a ń rí i ní ààfin ọba.
29 Il y a trois êtres qui s’avancent d’un pas imposant et quatre qui ont une noble démarche:
“Àwọn ohun mẹ́ta ní ń bẹ tí ń rìn rere, ohun mẹ́rin ni ó dára púpọ̀ ní ìrìn rírìn:
30 le lion, le plus fort des animaux, qui ne recule devant rien;
Kìnnìún, alágbára láàrín ẹranko tí kì í sá fún ohunkóhun
31 le lévrier aux reins cambrés, ou le bouc, et le roi à la tête de son armée.
Ẹsin tí a dì lẹ́gbẹ̀ẹ́; àti òbúkọ, àti ọba láàrín àwọn ènìyàn rẹ̀.
32 Que tu aies agi follement en cherchant à t’élever ou après de sages réflexions, mets-toi la main sur la bouche:
“Bí ìwọ bá ti hùwà aṣiwèrè nípa gbígbé ara rẹ ga, tàbí tí o bá ti gbèrò ibi, da ọwọ́ rẹ bo ẹnu rẹ!
33 Car la compression du lait produit le beurre, la compression du nez fait jaillir le sang, et la pression de la colère fait éclater les disputes!
Nítorí bí fífún omi ọmú tí í mú wàrà wá, tí fífún imú sì ń mú ẹ̀jẹ̀ jáde, bẹ́ẹ̀ ni rírú ìbínú sókè í mú ìjà wá.”

< Proverbes 30 >