< Lamentations 5 >

1 Souviens-toi, ô Eternel, de ce qui nous est advenu; regarde et vois notre opprobre!
Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
2 Notre héritage a passé à des étrangers, nos maisons à des gentils.
Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
3 Nous sommes devenus des orphelins, privés de père; nos mères sont pareilles à des veuves.
Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
4 Notre eau, nous ne pouvons 'la boire qu’à prix d’argent; notre bois, nous n’en disposons qu’en l’achetant.
A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
5 On nous poursuit l’épée dans les reins; nous sommes à bout de forces: point de répit pour nous!
Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
6 En Egypte nous avons tendu la main, et à Achour, pour avoir du pain en suffisance.
Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
7 Nos pères avaient péché: ils ne sont plus, et nous portons le poids de leurs fautes.
Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
8 Des esclaves ont pris le dessus sur nous: personne ne nous soustrait à leur pouvoir.
Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
9 Au péril de notre vie nous nous procurons nos vivres, le glaive sévissant au désert.
Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
10 Notre peau est brûlante comme un four, par suite de la fièvre desséchante de la faim.
Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
11 On a violenté des femmes dans Sion, des vierges dans les villes de Juda.
Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
12 Des princes ont été pendus par leurs mains; on n’a témoigné nul égard pour la personne des vieillards.
Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
13 Les adolescents ont dû porter la meule, les jeunes gens ont trébuché, sous le faix des bûches.
Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
14 Les vieillards ont cessé de paraître à la Porte, les jeunes gens d’entonner leurs chansons.
Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
15 Toute joie est bannie de notre cœur; nos danses joyeuses sont changées en deuil.
Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
16 Elle est tombée, la couronne de notre tête; malheur à nous, parce que nous avons péché!
Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
17 Ce qui nous déchire le cœur, ce qui obscurcit nos yeux,
Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
18 c’est de voir le mont Sion en ruines, foulé par les renards.
Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
19 Toi, ô Eternel, qui sièges immuable, dont le trône subsiste d’âge en âge,
Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
20 pourquoi nous oublies-tu si obstinément, nous délaisses-tu de si longs jours?
Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
21 Ramène-nous vers toi, ô Eternel, nous voulons te revenir; renouvelle pour nous les jours d’autrefois.
Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
22 Se peut-il que tu nous aies complètement rejetés et que tu nourrisses contre nous une colère inexorable? Ramène-nous vers toi, ô Eternel, nous voulons te revenir; renouvelle pour nous les jours d’autrefois.
àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.

< Lamentations 5 >