< Lamentations 3 >
1 Je suis l’homme qui a connu la misère sous la verge de son courroux.
Èmi ni ọkùnrin tí ó rí ìpọ́njú pẹ̀lú ọ̀pá ìbínú rẹ.
2 C’Est moi qu’il a poussé et fait marcher dans des ténèbres que ne traverse aucune lueur.
Ó ti lé mi jáde ó sì mú mi rìn nínú òkùnkùn ju ti ìmọ́lẹ̀.
3 Oui, contre moi il revient à la charge et tourne sa main tout le temps.
Nítòótọ́, ó ti yí ọwọ́ rẹ̀ padà sí mi síwájú àti síwájú sí i ní gbogbo ọjọ́.
4 Il a consumé ma chair et ma peau, brisé mes os.
Ó jẹ́ kí àwọ̀ mi àti ẹran-ara mi gbó ó sì tún ṣẹ́ egungun mi.
5 Il a bâti une clôture autour de moi et m’a enveloppé de venin et de tribulations.
Ó ti fi mí sí ìgbèkùn, ó sì ti yí mi ká pẹ̀lú ìkorò àti làálàá.
6 Il m’a relégué dans des régions ténébreuses comme les morts, endormis pour toujours.
Ó mú mi gbé nínú òkùnkùn, bí ti àwọn tó ti kú fún ìgbà pípẹ́.
7 Il m’a entouré d’un mur que je ne puis franchir, chargé de lourdes chaînes.
Ó ti tì mí mọ́ ilé, nítorí náà n kò le è sálọ; ó ti fi ẹ̀wọ̀n mú mi mọ́lẹ̀.
8 En vain je crie et appelle au secours, il ferme tout accès à ma prière.
Pàápàá nígbà tí mo ké fún ìrànlọ́wọ́, ó kọ àdúrà mi.
9 Il barre mes routes avec des pierres de taille, il bouleverse mes sentiers.
Ó fi ògiri òkúta dí ọ̀nà mi; ó sì mú ọ̀nà mi wọ́.
10 Il est pour moi un ours aux aguets, un lion en embuscade.
Bí i beari tí ó dùbúlẹ̀, bí i kìnnìún tí ó sá pamọ́.
11 Il a rendu impraticables mes voies et m’a déchiré; il a fait de moi une ruine.
Ó wọ́ mi kúrò ní ọ̀nà, ó tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ ó fi mi sílẹ̀ láìsí ìrànlọ́wọ́.
12 Il a bandé son arc et m’a dressé comme une cible à ses traits.
Ó fa ọfà rẹ̀ yọ ó sì fi mí ṣe ohun ìtafàsí.
13 Il fait pénétrer dans mes reins les enfants de son carquois.
Ó fa ọkàn mí ya pẹ̀lú ọfà nínú àkọ̀ rẹ̀.
14 Je suis devenu la risée de tous les peuples, un thème de leurs chansons incessantes.
Mo di ẹni yẹ̀yẹ́ láàrín àwọn ènìyàn mi; wọn yẹ̀yẹ́ mi pẹ̀lú orin ní gbogbo ọjọ́.
15 Il m’a rassasié d’herbes amères, abreuvé d’absinthe.
Ó ti kún mi pẹ̀lú ewé kíkorò àti ìdààmú bí omi.
16 Il a broyé mes dents avec du gravier, il m’a roulé dans la cendre.
Ó ti fi òkúta kán eyín mi; ó ti tẹ̀ mí mọ́lẹ̀ nínú eruku.
17 Mon âme a dit adieu à la paix, j’ai perdu jusqu’au souvenir du bonheur,
Mo ti jìnnà sí àlàáfíà; mo ti gbàgbé ohun tí àṣeyege ń ṣe.
18 et j’ai dit: "C’En est fait de mon avenir et de ce que je pouvais espérer de l’Eternel."
Nítorí náà mo wí pé, “Ògo mi ti lọ àti ìrètí mi nínú Olúwa.”
19 Rappelle-toi ma misère et mon abandon: je ne connais que poison et absinthe.
Mo ṣe ìrántí ìpọ́njú àti ìdààmú mi, ìkorò àti ìbànújẹ́.
20 En évoquant ces souvenirs, mon âme s’affaisse en moi.
Mo ṣèrántí wọn, ọkàn mi sì gbọgbẹ́ nínú mi.
21 Mais voici la pensée qui s’éveille en moi, et c’est pourquoi j’espère.
Síbẹ̀, èyí ni mo ní ní ọkàn àti nítorí náà ní mo nírètí.
22 C’Est que les bontés de l’Eternel ne sont pas taries et que sa miséricorde n’est pas épuisée.
Nítorí ìfẹ́ Olúwa tí ó lágbára ni àwa kò fi ṣègbé, nítorí ti àánú rẹ kì í kùnà.
23 Elles se renouvellent chaque matin, infinie est ta bienveillance.
Wọ́n jẹ́ ọ̀tún ní àárọ̀; títóbi ni òdodo rẹ̀.
24 "L’Eternel est mon lot, dit mon âme, aussi espéré-je en lui."
Mo wí fún ara mi, ìpín mi ni Olúwa; nítorí náà èmi yóò dúró dè ọ́.
25 L’Eternel est bon pour ceux qui mettent leur confiance en lui, pour l’âme qui le recherche.
Dídára ni Olúwa fún àwọn tí ó ní ìrètí nínú rẹ̀, sí àwọn tí ó ń wá a.
26 C’Est une bonne chose d’attendre en silence le secours de l’Eternel;
Ó dára kí a ní sùúrù fún ìgbàlà Olúwa.
27 une bonne chose aussi pour l’homme de porter le joug dès sa jeunesse;
Ó dára fún ènìyàn láti gbé àjàgà nígbà tí ó wà ní èwe.
28 de s’asseoir solitaire en se résignant silencieusement, lorsque Dieu le lui impose.
Jẹ́ kí ó jókòó ní ìdákẹ́ jẹ́ẹ́, nítorí Olúwa ti fi fún un.
29 Qu’il incline sa bouche vers la poussière: peut-être est-il quelque espoir.
Jẹ́ kí ó bo ojú rẹ̀ sínú eruku— ìrètí sì lè wà.
30 Qu’il présente la joue à celui qui le frappe et se rassasie d’humiliation
Jẹ́ kí ó fi ẹ̀rẹ̀kẹ́ fún àwọn tí yóò gbá a, sì jẹ́ kí ó wà ní ìdójútì.
31 car le Seigneur ne délaisse pas à tout jamais;
Ènìyàn kò di ìtanù lọ́dọ̀ Olúwa títí láé.
32 mais quand il a frappé, il exerce sa pitié selon l’étendue de sa bonté.
Lóòtítọ́ ó mú ìbànújẹ́ wá, yóò fi àánú hàn, nítorí títóbi ni ìfẹ́ rẹ̀.
33 Car ce n’est pas de bon cœur qu’il moleste et afflige les fils de l’homme.
Nítorí kò mọ̀ ọ́n mọ̀ mú ìpọ́njú wá tàbí ìrora wá fún ọmọ ènìyàn.
34 Lorsqu’on foule aux pieds tous les captifs du pays,
Láti tẹ mọ́lẹ̀ lábẹ́ ẹsẹ̀ gbogbo àwọn ẹlẹ́wọ̀n ní ilẹ̀ náà.
35 lorsqu’on fait fléchir le droit d’un homme à la face du Très-Haut,
Láti ṣẹ́ ọmọ ènìyàn fún ẹ̀tọ́ rẹ̀ níwájú Ọ̀gá-ògo jùlọ,
36 lorsqu’on fait tort à un homme dans sa juste cause, le Seigneur ne peut l’approuver.
láti yí ìdájọ́ ènìyàn padà, ǹjẹ́ Olúwa kò rí ohun bẹ́ẹ̀.
37 A qui donc suffit-il d’ordonner pour qu’une chose soit, si le Seigneur n’en a décidé ainsi?
Ta ni yóò sọ̀rọ̀ tí yóò rí bẹ́ẹ̀ tí Olúwa kò bá fi àṣẹ sí i.
38 N’Est-ce pas de la bouche de l’Eternel qu’émanent les maux et les biens?
Ǹjẹ́ kì í ṣe láti ẹnu Ọ̀gá-ògo jùlọ ni rere àti búburú tí ń wá?
39 Pourquoi donc se plaindrait l’homme sa vie durant, l’homme chargé de péchés?
Kí ló dé tí ẹ̀dá alààyè ṣe ń kùn nígbà tí ó bá ń jìyà ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀?
40 Examinons nos voies, scrutons-les et retournons à l’Eternel!
Ẹ jẹ́ kí a yẹ ọ̀nà wa, kí a sì dán an wò, kí a sì tọ Olúwa lọ.
41 Elevons nos cœurs avec nos mains vers Dieu qui est au ciel!
Ẹ jẹ́ kí a gbé ọkàn àti ọwọ́ wa sókè sí Ọlọ́run ní ọ̀run, kí a wí pé,
42 Nous, nous avons failli et désobéi: toi, tu n’as point pardonné.
“Àwa ti ṣẹ̀ a sì ti ṣọ̀tẹ̀ ìwọ kò sì fi ẹ̀ṣẹ̀ wa jì wá.
43 Tu t’es enveloppé de colère et tu nous as persécutés; tu as tué sans ménagement.
“Ìwọ fi ìbínú bo ara rẹ ìwọ sì ń lépa wa; ìwọ ń parun láìsí àánú.
44 Tu t’es entouré de nuages, pour empêcher les prières de passer.
Ìwọ ti fi àwọsánmọ̀ bo ara rẹ pé kí àdúrà wa má ba à dé ọ̀dọ̀ rẹ.
45 Tu as fait de nous une balayure, un objet de dégoût au milieu des nations.
Ó ti sọ wá di èérí àti ààtàn láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
46 Tous nos ennemis ont ouvert la bouche contre nous.
“Gbogbo àwọn ọ̀tá wa ti la ẹnu wọn gbòòrò sí wa.
47 Notre partage, ce furent la terreur et le piège, la ruine et le désastre.
Àwa ti jìyà àti ìparun, nínú ìbẹ̀rù àti ewu.”
48 Mes yeux se répandent en torrents de larmes à cause de la catastrophe de mon peuple.
Omijé ń sàn ní ojú mi bí odò nítorí a pa àwọn ènìyàn mi run.
49 Mes yeux se fondent en eau sans s’arrêter, car il n’est point de répit au mal,
Ojú mi kò dá fún omijé, láì sinmi,
50 jusqu’à ce que l’Eternel regarde et voie du haut du ciel.
títí ìgbà tí Olúwa yóò síjú wolẹ̀ láti òkè ọ̀run tí yóò sì rí i.
51 Le spectacle qui s’offre à mes regards accable mon âme à cause de toutes les filles de ma ville.
Ohun tí mo rí mú ìbẹ̀rù wá ọkàn mi nítorí gbogbo àwọn obìnrin ìlú mi.
52 Ils m’ont pourchassé comme un passereau, ceux qui me haïssent sans motif.
Àwọn tí ó jẹ́ ọ̀tá mi láìnídìí dẹ mí bí ẹyẹ.
53 Ils ont confiné ma vie dans la fosse et jeté des pierres sur moi.
Wọ́n gbìyànjú láti mú òpin dé bá ayé mi nínú ihò wọ́n sì ju òkúta lù mí.
54 Les eaux ont monté par-dessus ma tête, et j’ai dit: "Je suis perdu!"
Orí mi kún fún omi, mo sì rò pé ìgbẹ̀yìn dé.
55 Mais j’ai invoqué ton nom des profondeurs de la fosse.
Mo pe orúkọ rẹ, Olúwa, láti ọ̀gbun ìsàlẹ̀ ihò.
56 Tu as entendu mon appel: "Ne ferme pas ton oreille alors que je supplie pour ma délivrance."
Ìwọ gbọ́ ẹ̀bẹ̀ mi, “Má ṣe di etí rẹ sí igbe ẹ̀bẹ̀ mi fún ìtura.”
57 Tu es venu près de moi le jour où je t’ai invoqué, tu as dit: "Sois sans crainte!"
O wá tòsí nígbà tí mo ké pè ọ́, o sì wí pé, “Má ṣe bẹ̀rù.”
58 Tu as pris en mains les causes qui me touchent, tu sauves ma vie.
Olúwa, ìwọ gba ẹjọ́ mi rò, o ra ẹ̀mí mi padà.
59 Tu as vu, Eternel, le tort qu’on m’a fait: défends mon droit!
O ti rí i, Olúwa, búburú tí a ṣe sí mi. Gba ẹjọ́ mi ró!
60 Tu as été témoin de leurs représailles, de tous leurs complots contre moi.
Ìwọ ti rí ọ̀gbun ẹ̀san wọn, gbogbo ìmọ̀ wọn sí mi.
61 Tu as entendu, Eternel, 'leurs outrages, toutes leurs machinations contre moi.
Olúwa ìwọ ti gbọ́ ẹ̀gàn wọn àti ìmọ̀ búburú wọn sí mi,
62 Les lèvres de mes adversaires et leurs pensées sont dirigées contre ma personne.
ohun tí àwọn ọ̀tá mi ń sọ sí mi ní gbogbo ọjọ́.
63 Regarde leurs faits et gestes: je suis l’objet de leurs chants moqueurs.
Wò wọ́n! Ní jíjòkòó tàbí ní dídìde, wọ́n ń ṣẹlẹ́yà mi nínú orin wọn.
64 Puisses-tu leur rendre la pareille, ô Eternel, les traiter selon l’oeuvre de leurs mains!
Olúwa san wọ́n lẹ́san ohun tí ó tọ́ sí wọn fún ohun tí ọwọ́ wọn ti ṣe.
65 Inflige-leur l’angoisse du cœur: ta malédiction vienne sur eux!
Fi ìbòjú bò wọ́n ní ọkàn, kí o sì fi wọ́n ré.
66 Poursuis-les de ton courroux et anéantis-les de dessous la voûte de tes cieux.
Ni wọ́n lára kí o sì pa wọ́n run pẹ̀lú ìbínú, lábẹ́ ọ̀run Olúwa.