< Juges 10 >

1 Après Abimélec, vint au secours d’Israël Thola, fils de Poua, fils de Dôdô, de la tribu d’Issachar, lequel demeurait à Chamir, ville de la montagne d’Ephraïm.
Lẹ́yìn ikú Abimeleki, ọkùnrin kan láti ẹ̀yà Isakari tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Tola ọmọ Pua, ọmọ Dodo, dìde láti gba Israẹli sílẹ̀. Ní Ṣamiri tí ó wà ní òkè Efraimu ni ó gbé.
2 Après avoir gouverné Israël vingt-trois ans, il mourut et fut enseveli à Chamir.
Ó ṣe àkóso Israẹli ní ọdún mẹ́tàlélógún. Nígbà tí ó kú wọ́n sìn ín sí Ṣamiri.
3 Il eut pour successeur Jaïr, de Galaad, qui gouverna Israël vingt-deux ans.
Jairi ti ẹ̀yà Gileadi ni ó dìde lẹ́yìn rẹ̀, ó ṣàkóso Israẹli ní ọdún méjìlélógún.
4 Celui-ci eut trente fils, qui avaient trente ânons pour montures et possédaient trente villes, celles qu’on nomme, aujourd’hui encore, Bourgs de Jaïr, et qui sont au pays de Galaad.
Àwọn ọgbọ̀n ọmọ tí ó n gun ọgbọ̀n kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́. Wọ́n ṣe àkóso ọgbọ̀n ìlú ní Gileadi, tí a pe orúkọ wọn ní Hafoti-Jairi títí di òní.
5 Jaïr mourut, et fut enseveli à Kamôn.
Nígbà tí Jairi kú wọ́n sin ín sí Kamoni.
6 Or, les enfants d’Israël recommencèrent à faire ce qui déplaît au Seigneur: ils servirent les Bealim et les Astarot, les dieux d’Aram, ceux de Sidon, ceux de Moab, ceux des Ammonites, ceux des Philistins, et ils abandonnèrent l’Eternel, au lieu de le servir.
Àwọn ọmọ Israẹli sì túnṣe ohun tí ó burú lójú Olúwa. Wọ́n sin Baali àti Aṣtoreti àti àwọn òrìṣà Aramu, òrìṣà Sidoni, òrìṣà Moabu, òrìṣà àwọn ará Ammoni àti òrìṣà àwọn ará Filistini. Nítorí àwọn ará Israẹli kọ Olúwa sílẹ̀ tí wọn kò sì sìn ín mọ́,
7 Alors la colère de l’Eternel s’alluma contre eux, et il les livra au pouvoir des Philistins et des Ammonites.
ó bínú sí wọn, ó fi wọ́n sílẹ̀ fún àwọn ará Filistini àti Ammoni láti jẹ ẹ́ ní ìyà.
8 Et cette année-là, et dix-huit années durant, ils opprimèrent et persécutèrent les enfants d’Israël, tous les Israélites qui étaient au-delà du Jourdain, dans le pays des Amorréens, dans le Galaad.
Ní ọdún náà, wọ́n tú wọn ká wọ́n sì pọ́n wọn lójú. Fún ọdún méjìdínlógún ni wọ́n fi ni gbogbo àwọn ọmọ Israẹli tí ó wà ní ìlà-oòrùn odò Jordani ní ilẹ̀ àwọn ará Amori lára (èyí nì ní Gileadi).
9 Les Ammonites passèrent même le Jourdain pour attaquer Juda, Benjamin et la maison d’Ephraïm; et Israël fut dans une grande détresse.
Àwọn ará Ammoni sì la odò Jordani kọjá láti bá Juda, Benjamini àti àwọn ará ilé Efraimu jagun: Israẹli sì dojúkọ ìpọ́njú tó lágbára.
10 Les enfants d’Israël implorèrent le Seigneur, disant: "Nous avons péché contre toi, et en abandonnant notre Dieu, et en servant les Bealim!
Nígbà tí èyí ti ṣẹlẹ̀ àwọn ọmọ Israẹli ké pe Olúwa wí pé, “Àwa ti ṣẹ̀ sí ọ, nítorí pé àwa ti kọ Ọlọ́run wa sílẹ̀, àwa sì ń sin Baali.”
11 Le Seigneur répondit aux enfants d’Israël: "Ne vous ai-je pas sauvés de l’Egypte et des Amorréens, des enfants d’Ammon et des Philistins?
Olúwa sì dáhùn pé, “Ǹjẹ́ nígbà tí àwọn ará Ejibiti, Amori, Ammoni, Filistini,
12 Molestés par les Sidoniens, par Amalec, par Maôn, vous vous êtes plaints à moi, et je vous ai délivrés de leur main.
àwọn ará Sidoni, Amaleki pẹ̀lú Maoni ni yín lára, tí ẹ sì ké pè mí fún ìrànlọ́wọ́, ǹjẹ́ èmi kò gbà yín sílẹ̀ kúrò ní ọwọ́ wọn?
13 Mais vous, vous m’avez abandonné pour servir d’autres dieux; aussi ne vous viendrai-je plus en aide.
Síbẹ̀síbẹ̀ ẹ̀yin kọ̀ mí sílẹ̀ láti sin àwọn ọlọ́run mìíràn, torí ìdí èyí, èmi kì yóò sì tún gbà yín mọ́.
14 Allez vous plaindre aux dieux que vous avez préférés! que ceux-là vous secourent dans votre détresse!"
Ẹ lọ kí ẹ sì ké pe àwọn òrìṣà tí ẹ̀yin ti yàn fún ara yín. Jẹ́ kí wọn gbà yín sílẹ̀ ní àsìkò ìpọ́njú yín!”
15 Et les enfants d’Israël dirent au Seigneur: "Nous sommes coupables, traite-nous comme il te plaira; seulement, de grâce, sauve-nous cette fois!"
Àwọn ọmọ Israẹli sì dá Olúwa lóhùn pé, “Àwa ti ṣẹ̀, ṣe ohun tí ó bá fẹ́ pẹ̀lú wa, ṣùgbọ́n, jọ̀wọ́ gbà wá sílẹ̀ náání àsìkò yìí.”
16 Ils firent disparaître du milieu d’eux les divinités étrangères et revinrent au culte de l’Eternel; et sa résolution fléchit devant la misère d’Israël.
Nígbà náà ni wọ́n kó gbogbo ọlọ́run àjèjì tí ó wà láàrín wọn kúrò wọ́n sì sin Olúwa nìkan, ọkàn rẹ̀ kò sì le gbàgbé ìrora Israẹli mọ́.
17 Donc, les enfants d’Ammon, à l’appel de leurs chefs, s’étant campés en Galaad, les enfants d’Israël se réunirent et se campèrent à Miçpa.
Nígbà tí àwọn ará Ammoni kógun jọ ní Gileadi láti bá Israẹli jà, àwọn ọmọ Israẹli gbárajọpọ̀, wọ́n sì tẹ̀dó ogun ní Mispa.
18 Et le peuple et les princes de Galaad se dirent entre eux: "L’Homme qui le premier attaquera les Ammonites, celui-là sera le chef de tous les habitants de Galaad."
Àwọn ìjòyè: aṣíwájú àwọn ará Gileadi wí fún ará wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí yóò kọ́ ṣígun si àwọn ará Ammoni ni yóò jẹ́ orí fún gbogbo àwọn tí ń gbé ní Gileadi.”

< Juges 10 >