< Job 40 >

1 L’Eternel, répondant à Job, dit:
Olúwa dá Jobu lóhùn sí pẹ̀lú, ó sì wí pé,
2 Le censeur du Tout-Puissant persistera-t-il à récriminer contre lui? Le critique de Dieu répondra-t-il à tout cela?
“Ẹni tí ń bá Olódùmarè wíjọ́ yóò ha kọ ní ẹ̀kọ́? Ẹni tí ń bá Ọlọ́run wí jẹ́ kí ó dáhùn!”
3 Job répondit à l’Eternel et dit:
Nígbà náà ni Jobu dá Olúwa lóhùn wá ó sì wí pé,
4 Hé quoi! Je suis trop peu de chose: que te répliquerai-je? Je mets ma main sur ma bouche.
“Kíyèsi i, ẹ̀gbin ni èmi—ohun kí ni èmi ó dà? Èmi ó fi ọwọ́ mi le ẹnu mi.
5 J’Ai parlé une fois… je ne prendrai plus la parole; deux fois… je ne dirai plus rien.
Ẹ̀ẹ̀kan ní mo sọ̀rọ̀, ṣùgbọ́n èmi kì yóò tún sọ mọ́; lẹ́ẹ̀kejì ni, èmi kò sì le ṣe é mọ́.”
6 Alors l’Eternel répondit à Job du sein de la tempête et dit:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àyíká wá, ó sì wí pé,
7 Ceins tes reins comme un homme: je vais t’interroger et tu m’instruiras.
“Di àmùrè gírí ní ẹgbẹ́ rẹ bí ọkùnrin, èmi ó bi ọ léèrè, kí ìwọ kí ó sì dá mi lóhùn.
8 Prétends-tu vraiment prendre en défaut ma justice, ‘me condamner pour te justifier?
“Ìwọ ha fẹ́ mú ìdájọ́ mi di asán? Ìwọ ó sì dá mi lẹ́bi, kí ìwọ lè ṣe olódodo.
9 As-tu donc un bras comme celui de Dieu? Fais-tu retentir comme lui la voix du tonnerre?
Ìwọ ni apá bí Ọlọ́run tàbí ìwọ lè fi ohùn sán àrá bí òun?
10 Alors pare-toi de majesté et de grandeur, revêts-toi de splendeur et de magnificence.
Fi ọláńlá àti ọlá ìtayọ rẹ̀ ṣe ara rẹ ní ọ̀ṣọ́, tí ó sì fi ògo àti títóbi ọ̀ṣọ́ bo ara ní aṣọ.
11 Lance de toutes parts les éclats de ta colère et, d’un regard, abaisse tout orgueilleux.
Mú ìrunú ìbínú rẹ jáde; kíyèsí gbogbo ìwà ìgbéraga rẹ kí o sì rẹ̀ ẹ́ sílẹ̀.
12 D’Un regard, humilie tout orgueilleux, et écrase les méchants sur place.
Wo gbogbo ìwà ìgbéraga, ènìyàn kí o sì rẹ ẹ sílẹ̀ kí o sì tẹ ènìyàn búburú mọ́lẹ̀ ní ipò wọn.
13 Enfouis-les tous ensemble dans la poussière, confine leur face dans la nuit du tombeau.
Sin gbogbo wọn papọ̀ nínú erùpẹ̀, kí o sì di ojú ìkọ̀kọ̀ wọn ní isà òkú.
14 Alors moi-même je te louerai de ce que ta droite t’aura donné la victoire.
Nígbà náà ní èmi ó yìn ọ́ pé, ọwọ́ ọ̀tún ara rẹ lè gbà ọ́ là.
15 Vois donc le Béhémoth que j’ai créé comme toi: il se nourrit d’herbe comme le bœuf.
“Ǹjẹ́ nísinsin yìí kíyèsi Behemoti, tí mo dá pẹ̀lú rẹ, òun a máa jẹ koríko bí ọ̀dá màlúù.
16 Admire la force qui est dans ses reins, la vigueur qui réside dans les muscles de son ventre.
Wò o nísinsin yìí, agbára rẹ wà ní ẹ̀gbẹ́ rẹ, àti ipa rẹ nínú ìṣàn ìkún rẹ.
17 Sa queue se dresse comme un cèdre, les nerfs de ses cuisses sont entrelacés.
Òun a máa jù ìrù rẹ̀ bí i igi kedari, iṣan itan rẹ̀ dìjọ pọ̀.
18 Ses os sont des tuyaux d’airain, ses vertèbres des barres de fer.
Egungun rẹ̀ ní ògùṣọ̀ idẹ, Egungun rẹ̀ dàbí ọ̀pá irin.
19 Il est une des œuvres capitales de Dieu: Celui qui l’a fait l’a gratifié d’un glaive.
Òun ni olórí nínú àwọn iṣẹ́ Ọlọ́run; síbẹ̀ Ẹlẹ́dàá rẹ̀ fi idà rẹ̀ lé e lọ́wọ́.
20 Les montagnes produisent du fourrage pour lui, et là toutes les bêtes des champs prennent leurs ébats.
Nítòótọ́ òkè ńlá ńlá ní i mu ohun jíjẹ fún un wá, níbi tí gbogbo ẹranko igbó máa ṣiré ní ẹ̀gbẹ́ ibẹ̀.
21 Il se couche sous les lotus, sous le couvert des roseaux et des marais,
Ó dùbúlẹ̀ lábẹ́ igi lótusì, lábẹ́ eèsún àti ẹrẹ̀.
22 Les lotus le protègent de leur ombre, les saules du torrent l’enveloppent.
Igi lótusì síji wọn bò o; igi arọrọ odò yí i káàkiri.
23 Voici que le fleuve se gonfle et il ne s’en émeut point; il demeurerait plein d’assurance si le Jourdain lui montait à la gueule.
Kíyèsi i, odò ńlá sàn jọjọ, òun kò sálọ; ó wà láìléwu bí ó bá ṣe pé odò Jordani ti ṣàn lọ sí ẹnu rẹ̀.
24 Peut-on s’en emparer quand il a les yeux ouverts, lui percer le nez avec des harpons?
Ẹnìkan ha lè mú un ní ojú rẹ̀, tàbí dẹkùn fún tàbí a máa fi ọ̀kọ̀ gún imú rẹ̀?

< Job 40 >