< Job 38 >

1 L’Eternel répondit à Job du sein de la tempête et dit:
Nígbà náà ní Olúwa dá Jobu lóhùn láti inú ìjì àjàyíká wá, ó sì wí pé,
2 Quel est celui qui dénigre les desseins de Dieu par des discours dépourvus de sens?
“Ta ni èyí tí ń fi ọ̀rọ̀ àìlóye láti fi ṣókùnkùn bo ìmọ̀ mi?
3 Ceins donc tes reins comme un homme: je vais t’interroger et tu m’instruiras.
Di ẹ̀gbẹ́ ara rẹ ní àmùrè bí ọkùnrin nísinsin yìí, nítorí pé èmi yóò béèrè lọ́wọ́ rẹ kí o sì dá mi lóhùn.
4 Où étais-tu lorsque je fondais la terre? Dis-le, si tu en as quelque connaissance.
“Níbo ni ìwọ wà nígbà tí mo fi ìpìlẹ̀ ayé sọlẹ̀? Wí bí ìwọ bá mòye.
5 Qui a fixé ses dimensions, si tu le sais, ou qui a tendu sur elle le cordeau?
Ta ni ó fi ìwọ̀n rẹ lélẹ̀, dájú bí ìwọ bá mọ̀ ọ́n? Tàbí ta ni ó ta okùn wíwọ̀n sórí rẹ?
6 Sur quoi sont assis ses piliers, ou qui a lancé sa pierre angulaire,
Lórí ibo ni a gbé kan ìpìlẹ̀ rẹ̀ mọ́, tàbí ta ni ó fi òkúta igun rẹ̀ lélẹ̀,
7 tandis que les étoiles du matin chantaient en chœur, et que tous les fils de Dieu poussaient des cris de joie?
nígbà náà àwọn ìràwọ̀ òwúrọ̀ jùmọ̀ kọrin pọ̀, tí gbogbo àwọn ọmọ Ọlọ́run hó ìhó ayọ̀?
8 Qui a fermé la mer avec des portes, quand elle sortit jaillissante du sein maternel,
“Tàbí ta ni ó fi ìlẹ̀kùn sé omi òkun mọ́, nígbà tí ó ya padà bí ẹni pé ó ti inú jáde wá.
9 quand je lui donnai la nuée pour vêtement et une brume épaisse pour langes;
Nígbà tí mo fi àwọsánmọ̀ ṣe aṣọ rẹ̀, tí mo sì fi òkùnkùn biribiri ṣe ọ̀já ìgbà inú rẹ̀.
10 quand je brisai son élan par mes barrières et lui posai des verrous et des portes,
Nígbà tí mo ti pàṣẹ ìpinnu mi fún un, tí mo sì ṣe bèbè àti ìlẹ̀kùn.
11 et que je lui dis: "Jusqu’ici tu viendras et non au-delà: ici s’arrêtera l’orgueil de tes flots?"
Tí mo sì wí pé níhìn-ín ni ìwọ ó dé, kí o má sì rékọjá, níhìn-ín sì ni ìgbéraga rẹ yóò gbé dúró mọ?
12 As-tu jamais de ta vie donné des ordres au matin, assigné sa place à l’aurore,
“Ìwọ pàṣẹ fún òwúrọ̀ láti ìgbà ọjọ́ rẹ̀ wá, ìwọ sì mú ìlà-oòrùn mọ ipò rẹ̀,
13 pour qu’elle saisisse les bords de la terre et en rejette les méchants en une secousse?
í ó lè di òpin ilẹ̀ ayé mú, ki a lè gbọ́n àwọn ènìyàn búburú kúrò nínú rẹ̀?
14 Quand elle paraît, la terre se transforme comme l’argile sous le sceau, et les choses se présentent comme un riche vêtement.
Kí ó yí padà bí amọ̀ fún èdìdì amọ̀, kí gbogbo rẹ̀ kí ó sì fi ara rẹ̀ hàn bí ẹni pé nínú aṣọ ìgúnwà.
15 Les méchants sont privés de leur lumière à eux, et leur bras déjà levé est brisé.
A sì fa ìmọ́lẹ̀ wọn sẹ́yìn kúrò lọ́dọ̀ ènìyàn búburú, apá gíga ni a sì ṣẹ́.
16 As-tu pénétré jusqu’aux sources de la mer, as-tu circulé au fonds de l’abîme?
“Ìwọ ha wọ inú ìsun òkun lọ rí bí? Ìwọ sì rìn lórí ìsàlẹ̀ ibú ńlá?
17 Les portes de la mort se sont-elles dévoilées devant toi? As-tu vu l’entrée du royaume des ombres?
A ha ṣílẹ̀kùn ikú sílẹ̀ fún ọ rí bí, ìwọ sì rí ìlẹ̀kùn òjìji òkú?
18 As-tu mesuré l’immense étendue de la terre? Dis-le, si tu sais tout cela.
Ìwọ mòye ìbú ayé bí? Sọ bí ìwọ bá mọ gbogbo èyí.
19 Quel chemin mène à la demeure de la lumière, et où est l’habitation des ténèbres,
“Ọ̀nà wo ni ìmọ́lẹ̀ ń gbé? Bí ó ṣe ti òkùnkùn, níbo ni ipò rẹ̀,
20 pour que tu les conduises dans leur domaine et reconnaisses les avenues de leur maison?
tí ìwọ í fi mú un lọ sí ibi àlá rẹ̀, tí ìwọ ó sì le mọ ipa ọ̀nà lọ sínú ilé rẹ̀?
21 Tu le sais sans doute! Car tu étais né dès lors, et grand est le nombre de tes jours!
Ìwọ mọ èyí, nítorí nígbà náà ni a bí ọ? Iye ọjọ́ rẹ sì pọ̀.
22 Es-tu entré dans les trésors de la neige, as-tu aperçu les dépôts de la grêle,
“Ìwọ ha wọ inú ìṣúra ìdì òjò lọ rí bí, ìwọ sì rí ilé ìṣúra yìnyín rí,
23 que je tiens en réserve pour les temps de détresse, pour le jour du combat et de la guerre?
tí mo ti fi pamọ́ de ìgbà ìyọnu, dé ọjọ́ ogun àti ìjà?
24 Quelle est la voie par où se disperse la lumière, par où le vent d’Est se répand sur la terre?
Ọ̀nà wo ni ó lọ sí ibi tí ìmọ́lẹ̀ fi ń la, tí afẹ́fẹ́ ìlà-oòrùn ń tàn káàkiri lórí ilẹ̀ ayé?
25 Qui a creusé des rigoles à l’averse, une route à l’éclair sonore,
Ta ni ó la ipadò fún ẹ̀kún omi, àti ọ̀nà fún mọ̀nàmọ́ná àrá,
26 pour arroser des régions inhabitées, le désert où il n’y a pas d’hommes,
láti mú u rọ̀jò sórí ayé níbi tí ènìyàn kò sí, ní aginjù níbi tí ènìyàn kò sí;
27 pour abreuver les terres incultes et sauvages et faire pousser l’herbe nouvelle des prairies?
láti mú ilẹ̀ tútù, ijù àti aláìro láti mú àṣẹ̀ṣẹ̀yọ ewéko rú jáde?
28 La pluie a-t-elle un père? Qui engendre les gouttes de la rosée?
Òjò ha ní baba bí? Tàbí ta ni o bí ìkún ìṣe ìrì?
29 De quel sein sort la glace, et le givre du ciel, qui l’a enfanté?
Láti inú ta ni ìdì omi ti jáde wá? Ta ni ó bí ìrì dídì ọ̀run?
30 Les eaux se condensent comme la pierre et la surface des eaux se contracte.
Nígbà tí omi di líle bí òkúta, nígbà tí ojú ibú ńlá sì dìpọ̀.
31 Est-ce toi qui noues les bandeaux des Pléiades ou qui relâches les liens de l’Orion?
“Ìwọ ha le fi ọ̀já de àwọn ìràwọ̀ Pleiadesi dáradára? Tàbí ìwọ le tún di ìràwọ̀ Orioni?
32 Est-ce toi qui fais paraître les planètes en leur temps et qui diriges la Grande-Ourse avec ses petits?
Ìwọ le mú àwọn àmì méjìlá ìràwọ̀ Masaroti jáde wá nígbà àkókò wọn? Tàbí ìwọ le ṣe amọ̀nà Beari pẹ̀lú àwọn ọmọ rẹ̀?
33 Connais-tu les lois du ciel? Est-ce toi qui règles sa force d’action sur la terre?
Ǹjẹ́ ìwọ mọ ìlànà ọ̀run? Ìwọ le fi ìjọba Ọlọ́run lélẹ̀ lórí ayé?
34 Te suffit-il d’élever ta voix vers la nuée, pour qu’elle t’envoie des masses d’eau?
“Ìwọ le gbé ohùn rẹ sókè dé àwọsánmọ̀ kí ọ̀pọ̀lọpọ̀ omi kí ó lè bò ọ́?
35 Est-ce toi qui commandes aux éclairs de partir? Te disent-ils: "Nous voici?"
Ìwọ le rán mọ̀nàmọ́ná kí wọn kí ó le lọ, ní ọ̀nà wọn kí wọn kí ó sì wí fún wọn pé, ‘Àwa nìyí’?
36 Qui a mis de la sagesse, dans la brume sombre, ou qui a donné au météore l’intelligence?
Ta ni ó fi ọgbọ́n pamọ́ sí odò ikùn tàbí tí ó fi òye sínú àyà?
37 Qui pourrait dénombrer les nuages avec sagacité, et qui incline les amphores du ciel,
Ta ni ó fi ọgbọ́n ka iye àwọsánmọ̀? Ta ni ó sì mú ìgò ọ̀run dà jáde,
38 de manière à agréger la poussière en une masse compacte et à coller ensemble les glèbes de la terre?
nígbà tí erùpẹ̀ di líle, àti ògúlùtu dìpọ̀?
39 Est-ce toi qui poursuis la proie pour le lion, qui assouvis la voracité des lionceaux,
“Ìwọ ha dẹ ọdẹ fún abo kìnnìún bí? Ìwọ ó sì tẹ ebi ẹgbọrọ kìnnìún lọ́rùn,
40 lorsqu’ils sont tapis dans leurs tanières ou se tiennent aux aguets dans les fourrés?
nígbà tí wọ́n bá mọ́lẹ̀ nínú ihò tí wọ́n sì ba ní ibùba de ohun ọdẹ?
41 Qui prépare au corbeau sa pâture, quand ses petits crient vers Dieu et errent çà et là faute de nourriture?
Ta ni ó ń pèsè ohun jíjẹ fún ẹyẹ ìwò, nígbà tí àwọn ọmọ rẹ ń ké pe Ọlọ́run, tí wọ́n sì máa ń fò kiri nítorí àìní ohun jíjẹ?

< Job 38 >