< Jérémie 50 >

1 Parole que prononça l’Eternel au sujet de Babel, du pays des Chaldéens par l’organe de Jérémie le prophète:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
2 "Annoncez-le parmi les nations, proclamez-le, dressez un signal, publiez-le sans rien dissimuler! dites: Babel est prise, Bel est confondu, Merodac est abattu; ses divinités sont couvertes de honte, ses idoles sont en pièces.
“Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
3 Car du Nord un peuple s’avance contre elle, qui fait de son territoire une solitude où nul n’habite plus: hommes et bêtes, tous émigrent, s’en vont.
Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
4 En ces jours et en ce temps-là, dit le Seigneur, les fils d’Israël unis aux fils de Juda reviendront; ils chemineront, tout en pleurant, à la recherche de l’Eternel, leur Dieu.
“Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
5 C’Est de Sion qu’ils s’enquerront, le visage tourné dans sa direction; ils viendront et s’attacheront au Seigneur par un pacte éternel, qui ne sera pas oublié.
Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
6 Mon peuple se composait de brebis égarées; leurs pasteurs les avaient fourvoyées, les laissant errer par les montagnes; elles vaguaient de hauteur en hauteur; oublieuses de leur gîte.
“Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
7 Tous ceux qui les rencontraient en faisaient leur pâture, et leurs ennemis disaient: "Nous ne faisons pas de mal, puisqu’ils ont péché contre l’Eternel, leur abri véridique, contre l’Eternel, espoir de leurs ancêtres."
Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
8 Fuyez de l’enceinte de Babel, sortez du pays des Chaldéens, et soyez comme des béliers à la tête du troupeau!
“Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
9 Car voici, du pays du Nord je fais surgir et marcher sur Babel une ligue de grandes nations, qui feront campagne contre elle, et c’est ainsi qu’elle sera prise. Leurs flèches ressemblent à un guerrier triomphant qui ne subit pas d’échec.
Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
10 La Chaldée sera mise à sac; tous ceux qui la pilleront seront comblés, dit le Seigneur.
A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
11 Ah! réjouissez-vous, triomphez donc, vous les spoliateurs de mon héritage! Oui, ébattez-vous comme une génisse qui foule le blé et hennissez comme de fiers coursiers!
“Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
12 Elle va être entièrement confondue, votre mère; celle qui vous a donné le jour va connaître la rougeur de la honte. Tel sera le sort de ces nations: l’abandon, la ruine, la solitude.
Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
13 Par suite de la colère du Seigneur, elle deviendra inhabitable, complètement désolée. Quiconque passera près de Babel Sera stupéfait et ricanera à la vue de toutes ses plaies.
Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
14 A vos rangs de bataille contre Babel, tout autour, vous tous qui bandez l’arc! tirez sur elle, ne ménagez pas les flèches, car elle s’est rendue coupable envers l’Eternel.
“Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
15 Poussez le cri de guerre contre elle de toutes parts: elle tend les mains, ses créneaux tombent, ses murs s’écroulent, car ce sont les représailles de l’Eternel. Vengez-vous sur elle, faites-lui ce qu’elle a fait elle-même.
Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
16 Exterminez dans Babel quiconque sème et quiconque manie la faucille au temps de la moisson. Devant le glaive meurtrier, que chacun se dirige vers son peuple, que chacun se réfugie dans son pays!
Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
17 Israël était une brebis pourchassée, que des lions avaient mise en fuite; le roi d’Assyrie fut le premier à le dévorer et voilà que ce dernier lui a broyé les os, Nabuchodonosor, roi de Babylone.
“Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
18 Aussi l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël, s’exprime-t-il en ces termes: Je vais demander des comptes au roi de Babylone et à son pays comme j’ai demandé des comptes au roi d’Assyrie.
Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
19 Et je ramènerai Israël à son pâturage, il pâturera sur le Carmel et le Basan, et sur le mont d’Ephraim et le Ghilead il se nourrira à satiété.
Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
20 En ces jours et en ce temps-là, dit le Seigneur, on recherchera le péché d’Israël, et il aura disparu, les prévarications de Juda, et on ne les retrouvera point; car mon pardon est assuré à ceux que j’aurai conservés.
Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
21 Sus au pays de "la double rébellion" et aux habitants de la ville du "châtiment!" Frappe par l’épée, extermine-les jusqu’au bout, dit le Seigneur, et exécute tout ce que je t’ai ordonné.
“Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
22 Un bruit de guerre retentit dans le pays, c’est une chute terrible.
Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
23 Comme il est abattu et brisé, le marteau qui broyait toute la terre! Comme elle est devenue, cette Babel, une ruine parmi toutes les nations!
Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
24 Je t’ai dressé un piège, ô Babel, et tu y as été prise, sans t’en apercevoir; te voilà atteinte et appréhendée, parce que tu t’étais insurgée contre le Seigneur!
Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
25 L’Eternel a ouvert son arsenal, et en a sorti les instruments de sa colère, car il y a une oeuvre à accomplir pour l’Eternel-Cebaot sur la terre des Chaldéens.
Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
26 Marchez contre elle de toutes les extrémités, ouvrez ses greniers, piétinez-la comme des javelles, détruisez-la: que rien d’elle ne subsiste!
Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
27 Frappez du glaive tous ses taureaux! Qu’ils s’en aillent à la boucherie! Malheur à eux, car leur jour est arrivé, le temps de leur châtiment!
Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
28 Entendez les cris des fuyards, de ceux qui se sauvent du pays de Babei, annonçant dans Sion les représailles de l’Eternel, notre Dieu, la revanche de son sanctuaire.
Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
29 Convoquez contre Babel des archers, tous les tireurs d’arbalète; cernez-la de toutes parts. Point de merci pour elle! Payez-la selon ses oeuvres, faites-lui comme elle a fait elle-même; car elle a défié le Seigneur, le Saint d’Israël.
“Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
30 Aussi ses jeunes gens tomberont-ils sur ses places publiques, et tous ses combattants seront anéantis en ce jour, dit le Seigneur.
Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
31 Voici, je vais m’en prendre à toi, modèle d’arrogance, dit le Seigneur, Eternel-Cebaot; car ton jour est venu, l’époque pour te châtier.
“Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
32 Ce modèle d’arrogance trébuchera et tombera, sans personne pour le relever; je mettrai le feu à ses villes. et il dévorera tous ses alentours.
Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
33 Ainsi parle l’Eternel-Cebaot: Opprimés sont les enfants d’Israël, et les enfants de Juda tous ensemble; tous ceux qui les ont réduits en captivité les retiennent de force, refusent de les relâcher.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
34 Mais leur sauveur est puissantEternel-Cebaot est son nom, il prendra en mains leur cause, de façon à rendre la paix à la terre et à faire trembler les habitants de Babel.
Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
35 Guerre aux Chaldéens, dit le Seigneur, aux habitants de Babel, à ses princes et à ses sages!
“Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
36 Guerre aux trafiquants de mensonge! ils perdront la tête. Guerre à ses braves! ils seront brisés.
Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
37 Guerre à ses coursiers, à ses chars et à tout ce ramassis de gens qu’elle abrite et qui deviendront comme des femmes! Guerre à ses trésors! Qu’ils soient pillés!
Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
38 Sécheresse sur ses eaux, pour qu’elles tarissent! car c’est un pays d’idoles, et on s’y targue follement de ces épouvantails.
Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
39 C’Est pourquoi chiens sauvages et chats sauvages s’y rencontreront, et des autruches en feront leur séjour: elle ne sera plus jamais habitée, jusqu’aux dernières générations personne ne s’y établira
“Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
40 Tel le bouleversement de Sodome, de Gomorrhe et de leurs environs, dit le Seigneur; aucun homme n’y habitera, nul mortel n’y séjournera.
Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
41 Voici, une nation arrive du Nord, un grand peuple et des rois puissants surgissent des extrémités de la terre.
“Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
42 Ils sont armés d’arcs et de lances; ils sont inexorables et ne connaissent point la pitié. Leur voix est mugissante comme la mer; ils sont montés sur des chevaux, rangés en bataille comme des braves, contre toi, b fille de Babel.
Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
43 Leur renommée est parvenue au roi de Babel, et ses mains sont devenues défaillantes; l’effroi s’est emparé de lui, une angoisse comme celle d’une femme qui enfante.
Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
44 Voici, tel un lion monte des rives escarpées du Jourdain contre les solides bergeries, en un clin d’oeil je délogerai les habitants de Babel de là, et j’y établirai comme maître celui que j’aurai choisi; car qui est mon égal? Qui m’appellera en justice? Quel est le pasteur qui tiendra ferme contre moi?
Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
45 Ecoutez donc les desseins de l’Eternel, qu’il a formés contre Babel et les projets qu’il a médités contre la terre des Chaldéens: certes, les plus humbles gardiens des troupeaux les traîneront dans la poussière, certes on fera s’écrouler sur eux leurs bergeries.
Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
46 Au bruit de la prise de Babel, la terre a frémi et une clameur se fait entendre parmi les nations.
Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.

< Jérémie 50 >