< Jérémie 5 >

1 Parcourez en tous sens les rues de Jérusalem, regardez donc et observez, faites des recherches dans ses places publiques; si vous trouvez un homme, un seul, qui pratique la justice, qui soit soucieux de loyauté, elle obtiendra de moi son pardon.
“Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
2 Même quand ils disent: "Par l’Eternel vivant!" à coup sûr, c’est pour prêter un faux serment!
Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
3 O Eternel, tes yeux peuvent-ils supporter autre chose que la vérité? Tu les as frappés, et ils ne se sentent pas atteints; tu les as ruinés, ils refusent d’accepter la leçon ils se font un visage plus dur que le roc, ils ne veulent pas se convertir.
Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
4 Je pensais alors en moi-même: "Ce ne sont que gens de rien; ils manquent d’intelligence, ignorants qu’ils sont de la voie de l’Eternel, de la justice de leur Dieu.
Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
5 Je vais me tourner vers les grands, leur adresser la parole; car ils connaissent, eux, la voie de l’Eternel, la justice de leur Dieu!" Mais ce sont eux qui, tous ensemble, ont brisé le joug, rompu les liens.
Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
6 C’Est pourquoi le lion, s’élançant des forêts, les attaque, le loup des steppes arides s’acharne sur eux; la panthère est tapie près de leurs villes, quiconque en sort est mis en pièces, car multiples sont leurs fautes, nombreux leurs égarements.
Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
7 Pour quelle raison te pardonnerais-je? Tes fils m’abandonnent, ils jurent par des dieux qui n’en sont pas; je les ai comblés de bien et ils trahissent leur foi, ils se rendent en foule aux mauvais lieux.
“Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
8 Comme des chevaux repus, ils courent de côté et d’autre, hennissant chacun après la femme d’autrui.
Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
9 Puis-je ne pas sévir contre de tels excès? dit l’Eternel; mon âme n’usera-t-elle pas de représailles contre un pareil peuple?
Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
10 Escaladez ses murailles et dévastez, mais sans consommer la ruine! Emondez ses branches, qui n’appartiennent pas à l’Eternel.
“Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
11 Car la maison d’Israël et la maison de Juda ont agi perfidement à mon égard, dit l’Eternel.
Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
12 Ils ont renié le Seigneur et dit: "Il n’est pas! Aucun malheur ne nous arrivera, nous ne verrons ni guerre ni famine.
Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
13 Les dires des prophètes seront comme du vent; de parole révélée, ils n’en possèdent pas: puisse un tel traitement leur être infligé!"
Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
14 C’Est pourquoi, ainsi parle l’Eternel, Dieu-Cebaot: "Puisque tels sont vos discours, les paroles que je mets dans ta bouche, je vais les transformer en feu, et ce peuple sera du bois, que ce feu consumera.
Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
15 Voici, je fais fondre sur vous un peuple venu de loin, ô maison d’Israël, dit l’Eternel, un peuple impétueux, peuple d’une haute antiquité, peuple dont tu ignores la langue et ne comprends pas le parier.
Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
16 Son carquois est comme un sépulcre béant, et il ne compte que des héros.
Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
17 Il dévorera ta moisson et ton pain, il dévorera tes fils et tes filles, il dévorera tes brebis et tes boeufs, il dévorera ta vigne et ton figuier; il ruinera par le glaive tes villes fortes, sur lesquelles tu fondes ton espoir.
Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
18 Mais même en ces jours-là, dit l’Eternel, je ne vous anéantirai pas complètement.
“Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
19 Et quand vous direz: "Quel motif a l’Eternel pour nous traiter de la sorte?" Tu leur répondras: "De même que vous m’avez délaissé pour servir des dieux étrangers dans votre pays, ainsi vous aurez à servir des étrangers dans un pays qui n’est pas le vôtre."
Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
20 Annoncez ceci dans la maison de Jacob, et proclamez-le dans Juda, à savoir:
“Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
21 Ecoutez donc ceci, peuple dénué d’intelligence et de coeur, vous qui avez des yeux pour ne pas voir, des oreilles pour ne pas entendre!
Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
22 Est-ce bien moi que vous ne vénérez pas, dit l’Eternel, est-ce bien moi devant qui vous refusez de trembler, moi qui ai donné le sable comme limite à la mer, comme une barrière éternelle qu’elle ne peut franchir? Ses flots se soulèvent, impuissants, ils mugissent, mais ne vont pas au delà.
Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
23 Mais ce peuple a le coeur indocile et rebelle, il s’est détourné et a suivi sa propre voie.
Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
24 Ils n’ont pas dit en leur coeur: "Adorons donc l’Eternel, notre Dieu, qui dispense la pluiela pluie de l’automne et du printempsen temps voulu, qui nous réserve régulièrement les semaines déterminées pour la moisson."
Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
25 Ce sont vos fautes qui ont dérangé le cours de ces lois, vos péchés qui vous ont privés de ces bienfaits,
Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
26 car il se rencontre dans mon peuple de mauvaises gens, l’oeil aux aguets comme des oiseleurs, qui ont dressé leurs panneaux; ils tendent leurs engins meurtriers, et ce sont des hommes qu’ils prennent au piège.
“Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
27 Comme une cage remplie d’oiseaux, leurs demeures sont remplies de fraude; aussi sont-ils prospères et opulents.
Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
28 Ils sont gras, reluisants: ne dépassent-ils pas toute mesure dans le mal? Ils ne rendent pas justice, justice à l’orphelin, et ils prospèrent! La cause des pauvres, ils ne la font pas triompher.
wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
29 Puis-je ne pas sévir contre de tels excès? dit l’Eternel; mon âme n’usera-t-elle pas de représailles contre un pareil peuple?
Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
30 II s’est passé des choses stupéfiantes et pleines d’horreur dans ce pays:
“Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
31 les prophètes font prédication de mensonges, les prêtres, forts de leur appui, exercent leur domination, et mon peuple aime cela! Mais que ferez-vous quand viendra la fin?
Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?

< Jérémie 5 >