< Jérémie 49 >
1 Aux fils d’Ammon. Ainsi parle l’Eternel: "Israël n’a-t-il point d’enfants? Est-il sans aucun héritier? Pourquoi Malcom a-t-il pris possession de Gad, et son peuple en a-t-il occupé les villes?
Nípa Ammoni. Báyìí ni Olúwa wí, “Israẹli kò ha ní ọmọkùnrin? Israẹli kò ha ní àrólé bí? Nítorí kí ni Malkomu ṣe jogún Gadi? Kí ló dé tí àwọn ènìyàn rẹ̀ ń gbé ìlú rẹ̀?
2 Assurément des jours vont venir, dit le Seigneur, où je ferai entendre à Rabba, capitale des fils d’Ammon, la sonnerie du combat: elle sera réduite à l’état de ruine lamentable, ses bourgades deviendront la proie des flammes, et Israël dépossédera ceux qui l’ont dépossédé, dit l’Eternel.
Ṣùgbọ́n ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí; “nígbà tí èmi yóò mú kí a gbọ́ ìdágìrì ogun ní Rabba tí Ammoni; yóò sì di òkìtì ahoro, gbogbo ìlú tí ó yí i ká ni a ó jó níná. Nígbà náà ni Israẹli yóò lé wọn, àwọn tí ó ti lé e jáde,” ni Olúwa wí.
3 Lamente-toi, ô Hesbon! car Aï a été dévastée; poussez des cris, filles de Rabba! Ceignez-vous de cilices, organisez un deuil et répandez-vous dans les parcs à troupeaux, car Malcom s’en va en exil, lui, ses prêtres et ses dignitaires tous ensemble.
“Hu, ìwọ Heṣboni, nítorí Ai tí rún! Kígbe ẹ̀yin olùgbé Rabba! Ẹ wọ aṣọ ọ̀fọ̀ kí ẹ sì ṣọ̀fọ̀. Ẹ sáré sókè sódò nínú ọgbà, nítorí Malkomu yóò lọ sí ìgbèkùn, pẹ̀lú àwọn àlùfáà àti ìjòyè rẹ̀.
4 Qu’as-tu à faire parade de tes vallées, de ta campagne qui déborde d’abondance, ô fille présomptueuse qui, pleine de confiance dans tes trésors, dis: "Qui osera m’attaquer?"
Èéṣe tí ìwọ fi ń ṣògo nínú àfonífojì rẹ, ṣògo nínú àfonífojì rẹ fún èso? Ẹ̀yin ọmọbìnrin Ammoni aláìṣòótọ́, ẹ gbẹ́kẹ̀lé ọrọ̀ yín, ẹ sì wí pé, ‘Ta ni yóò kò mí lójú?’
5 Eh bien! moi, dit l’Eternel, Dieu-Cebaot; je susciterai de toutes parts la terreur contre toi, et vous serez chassés, chacun droit devant lui, sans que personne rallie les fuyards.
Èmi yóò mu ẹ̀rù wá lórí rẹ láti ọ̀dọ̀ gbogbo àwọn tó yí ọ ká,” ni Olúwa, ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
6 Mais plus tard, je ramènerai les captifs des enfants d’Ammon, dit le Seigneur.
“Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Gbogbo yín ni ó lé jáde, kò sì ṣí ẹnìkan tí yóò dá ìkólọ Ammoni padà,” ni Olúwa wí.
7 A Edom. Ainsi parle l’Eternel-Cebaot: "N’Y a-t-il plus de sagesse à Têmân? l’entendement a-t-il péri chez les gens avisés? leur esprit s’est-il évanoui?
Nípa Edomu. Èyí ní ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí: “Ṣe kò ha sí ọgbọ́n mọ́ ni Temani? Ṣé a ti ké ìmọ̀ràn kúrò ní ọ̀dọ̀ olóyè? Ṣé ọgbọ́n wọn ti bàjẹ́ bí?
8 Fuyez, cédez la place, enfermez-vous dans des retraites profondes, ô habitants de Dedân; car je fais fondre sur Esaü la catastrophe qui le menace, c’est le temps où je lui demande des comptes.
Yípadà kí o sálọ, sá pamọ́ sínú ihò, ìwọ tí ó ń gbé ní Dedani, nítorí èmi yóò mú ibi wá sórí Esau, ní àkókò tí èmi ó bẹ̀ ẹ́ wò.
9 Si ce sont des vendangeurs qui viennent contre toi, ils ne laisseront pas de quoi grappiller; si ce sont des voleurs pendant la nuit, ils détruiront tout ce qu’ils pourront.
Tí àwọn tí ń ṣa èso bá tọ̀ ọ́ wá; ǹjẹ́ wọn kò ní fi èso díẹ̀ sílẹ̀? Tí olè bá wá ní òru; ǹjẹ́ wọn kò ní kó gbogbo ohun tí wọ́n bá fẹ́?
10 Mais c’est moi qui mets à nu Esaü, je découvre ses mystérieuses retraites, il ne peut plus se cacher: ruinés sont ses enfants, ses frères, ses voisins, c’en est fait de lui.
Ṣùgbọ́n èmi yóò tu Esau sí ìhòhò, èmi ti fi ibi ìkọ̀kọ̀ rẹ̀ hàn, nítorí kí o máa ba à fi ara rẹ pamọ́. Àwọn ọmọ rẹ, ẹbí rẹ àti àwọn ará ilé rẹ yóò parun. Wọn kò sì ní sí mọ́.
11 Laisse là tes orphelins, moi je pourvoirai à leur subsistance; que tes veuves se confient à moi!"
Fi àwọn ọmọ aláìní baba sílẹ̀ èmi yóò dáàbò bo ẹ̀mí wọn. Àwọn opó rẹ gan an lè gbẹ́kẹ̀lé mi.”
12 Oui, ainsi parle le Seigneur: "Voici, ceux qui ne devaient point boire la coupe, ils ont été forcés de la boire, et justement toi, tu en serais dispensé! Non, tu n’en seras pas dispensé, tu seras forcé de boire.
Èyí ni ohun tí Olúwa wí bí ẹnikẹ́ni tí kò bá yẹ kí ó mu ago náà bá mú un, kí ló dé tí ìwọ yóò fi lọ láìjìyà? Ìwọ kò ní lọ láìjìyà; ṣùgbọ́n ìwọ yóò mú un.
13 Car, j’en jure par moi-même, dit l’Eternel, oui, Boçra deviendra une solitude, un opprobre, un désert et un objet d’exécration, et toutes ses bourgades seront des ruines éternelles.
Èmi fi ara mi búra ni Olúwa wí, wí pé, “Bosra yóò ba ayé ara rẹ̀ jẹ́. Yóò di ẹni ẹ̀gàn, ẹni èpè àti ẹni ègún, àti gbogbo ìlú rẹ̀ yóò di ìbàjẹ́ títí láé.”
14 J’Ai entendu une annonce de la part de l’Eternel, un messager a été envoyé parmi les nations: "Rassemblez-vous et marchez contre elle, levez-vous pour le combat!"
Ní gbígbọ́, èmi ti gbọ́ ìró kan láti ọ̀dọ̀ Olúwa, a rán ikọ̀ kan sí orílẹ̀-èdè pé, ẹ kó ara yín jọ, ẹ wá sórí rẹ̀, ẹ sì dìde láti jagun.
15 Car voici, je te fais petit parmi les peuples, méprisable parmi les hommes.
“Ní báyìí, èmi yóò sọ ọ́ di kékeré láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo; ẹni ẹ̀gàn láàrín àwọn ènìyàn.
16 Ta présomption, l’infatuation de ton coeur t’a égaré, toi qui habites les pentes des rochers, qui occupes la cime des collines. Quand même tu fixerais ton aire aussi haut que l’aigle, je t’en ferais descendre, dit le Seigneur.
Ìpayà tí ìwọ ti fà sínú ìgbéraga ọkàn rẹ sì ti tàn ọ́ jẹ; ìwọ tí ń gbé ní pàlàpálá àpáta, tí o jókòó lórí ìtẹ́ gíga síbẹ̀ o kọ́ ìtẹ́ rẹ ga gẹ́gẹ́ bí ẹyẹ idì; láti ibẹ̀ ni èmi yóò ti mú ọ sọ̀kalẹ̀ wá,” ni Olúwa wí.
17 Edom deviendra une ruine désolée; quiconque passera près de lui sera frappé de stupeur et ricanera à la vue de toutes ses plaies.
“Edomu yóò di ahoro gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò jáyà, wọn ó sì fi rẹ́rìn-ín ẹlẹ́yà nítorí gbogbo ìpalára rẹ.
18 Tel le bouleversement de Sodome, de Gomorrhe et de leurs environs, dit le Seigneur; personne n’y habitera, nul homme n’y séjournera.
Gẹ́gẹ́ bí wọ́n ṣe gba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó wà ní àyíká rẹ,” ní Olúwa wí. “Bẹ́ẹ̀ ni, kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé níbẹ̀; kò sì ní sí ènìyàn tí yóò tẹ̀dó síbẹ̀ mọ́.
19 Voici, tel un lion monte des rives escarpées du Jourdain contre les solides bergeries, en un clin d’oeil je délogerai Edom de là, et j’y établirai comme maître celui que j’aurai choisi; car qui est mon égal? qui m’appellera en justice? quel est le pasteur qui tiendra ferme devant moi?
“Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Edomu kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
20 Ecoutez donc le dessein que l’Eternel a formé contre Edom et les projets qu’il a médités contre les habitants de Têmân: Certes les plus humbles gardiens de troupeaux les entraîneront de force; certes on fera s’écrouler sur eux leurs bergeries.
Nítorí náà, ẹ gbọ́ ohun tí Olúwa ní fún Edomu, ohun tí ó ní ní pàtàkì fún àwọn tí ń gbé ní Temani. Àwọn ọ̀dọ́ àgbò ni à ó lé jáde; pápá oko wọn ni yóò run nítorí wọn.
21 Au bruit de leur chute, la terre frémira; il y aura des cris de douleur, dont l’écho sera perçu sur les bords de la Mer Rouge.
Ilẹ̀ yóò mì tìtì nípa ariwo ìṣubú wọn, a ó gbọ́ igbe wọn ní Òkun pupa.
22 Voici, tel qu’un aigle il prend son vol, l’ennemi, il plane dans les airs, et déploie ses ailes contre Boçra; en ce jour le coeur des plus braves dans Edom sera comme le coeur d’une femme en mal d’enfant."
Wò ó! Ẹyẹ idì yóò gòkè fò wálẹ̀, yóò tẹ ìyẹ́ rẹ̀ lórí Bosra. Ní ọjọ́ náà ọkàn àwọn ajagun Edomu yóò dàbí ọkàn obìnrin tí ń rọbí.
23 A Damas. "Hamath et Arpad sont dans la confusion, car elles ont appris une fâcheuse nouvelle et en sont consternées; leur trouble est celui d’une mer agitée, qui ne peut demeurer en repos.
Nípa Damasku. “Inú Hamati àti Arpadi bàjẹ́ nítorí wọ́n gbọ́ ìròyìn búburú, ìjayà dé bá wọn, wọ́n sì dààmú bí omi Òkun.
24 Damas a perdu courage, elle s’apprête à prendre la fuite et un tremblement s’empare d’elle; une angoisse et des douleurs l’empoignent comme une femme en travail.
Damasku di aláìlera, ó pẹ̀yìndà láti sálọ, ìwárìrì sì dé bá a; ìbẹ̀rù àti ìrora dìímú, ìrora bí ti obìnrin tí ó wà ní ipò ìrọbí.
25 Ah! pourquoi n’a-t-elle pas été épargnée, la ville glorieuse, la cité de mes délices?
Kí ló dé tí ìlú olókìkí di ohun ìkọ̀sílẹ̀; ìlú tí mo dunnú sí.
26 Certes, ses jeunes gens succombent sur ses places publiques, et tous les guerriers sont anéantis en ce jour, dit l’Eternel-Cebaot.
Lóòtítọ́, àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ yóò ṣubú lójú pópó, gbogbo àwọn ọmọ-ogun rẹ yóò pa ẹnu mọ́ ní ọjọ́ náà,” ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí.
27 Je mettrai le feu aux remparts de Damas, et il dévorera les palais de Ben-Hadad."
“Èmi yóò fi iná sí odi Damasku, yóò sì jó gbọ̀ngàn Beni-Hadadi run.”
28 A Kêdar et aux royaumes de Haçor, que défit Nabuchodonosor, roi de Babylone. Ainsi parle le Seigneur: "Levez-vous, montez contre Kédar et portez la dévastation chez ces enfants du Levant.
Nípa ìlú Kedari àti ìjọba Hasori èyí ti Nebukadnessari ọba Babeli dojú ìjà kọ, èyí ni ohun tí Olúwa sọ, “Dìde kí o sì dojú ìjà kọ ìlú Kedari, kí o sì pa àwọn ènìyàn ìlà-oòrùn run.
29 Qu’on enlève leurs tentes et leurs troupeaux, qu’on emporte leurs tapis, tous leurs meubles et leurs chameaux! Qu’on proclame contre eux: "Epouvante tout autour!"
Àgọ́ wọn àti agbo àgùntàn wọn ni wọn ó kó lọ; àgọ́ wọn yóò di ìṣínípò padà pẹ̀lú gbogbo ẹrù àti ìbákasẹ wọn. Àwọn ènìyàn yóò ké sórí wọ́n pé, ‘Ẹ̀rù yí káàkiri!’
30 Fuyez, éloignez-vous rapidement, enfermez-vous dans des retraites profondes, habitants de Haçor, dit le Seigneur, car Nabuchodonosor, roi de Babylone, a conçu contre vous des projets et arrêté des résolutions.
“Sálọ kíákíá! Fi ara pamọ́ sí ibi jíjìn, ẹ̀yin olùgbé Hasori,” ni Olúwa wí. “Nebukadnessari ọba Babeli ti dojú ìjà kọ ọ́.
31 Debout! Marchez contre un peuple paisible, qui demeure en pleine sécurité, dit le Seigneur; il n’a ni portes ni verrous et vit dans l’isolement.
“Dìde kí o sì dojú ìjà kọ orílẹ̀-èdè tí ó wà nínú ìrọ̀rùn, èyí tí ó gbé ní àìléwu,” ní Olúwa wí. “Orílẹ̀-èdè tí kò ní odi tàbí irin, àwọn ènìyàn rẹ̀ ń dágbé.
32 Leurs chameaux deviendront une proie et la multitude de leurs troupeaux un butin; je les disperserai à tous les vents, ces gens qui se taillent la barbe, et de tous les côtés je ferai fondre la ruine sur eux.
Àwọn ìbákasẹ á di ẹrù àti àwọn ẹran ọ̀sìn, wọ́n á di ìkógun. Èmi yóò tú àwọn tí ó wà ní òkèèrè sí inú afẹ́fẹ́. Èmi yóò sì mú ibi wá sí àyíká gbogbo,” báyìí ní Olúwa wí.
33 Ainsi Haçor deviendra un repaire de chacals, dit le Seigneur, une éternelle solitude, où personne n’habitera, où nul homme ne séjournera."
“Hasori yóò di ibi ìdọdẹ àwọn akátá, ibi ìkọ̀sílẹ̀ ayérayé, kò sí ẹni tí yóò gbé ní ibẹ̀.”
34 Voici quelle fut la parole de l’Eternel adressée à Jérémie, le prophète, au sujet d’Elam, au début du règne de Sédécias, roi de Juda; il dit:
Èyí ní ọ̀rọ̀ Olúwa èyí tí ó tọ Jeremiah wòlíì wá nípa Elamu ní ìbẹ̀rẹ̀ ìjọba Sedekiah ọba Juda.
35 "Ainsi parle l’Eternel-Cebaot: Voici, je vais briser l’arc des Elamites, le meilleur de leur force.
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “Wò ó, èmi yóò fọ́ ìtẹ̀gùn Elamu, ẹni tí wọ́n sinmi lé nípa agbára.
36 Je susciterai contre Elam quatre vents des quatre extrémités du ciel, et je les disperserai au gré de ces vents; il n’y a aucune nation qui ne verra arriver chez elle des fugitifs d’Elam.
Èmi yóò mú kí afẹ́fẹ́ orígun mẹ́rẹ̀ẹ̀rin àgbáyé lòdì sí Elamu. Èmi yóò tú wọn ká sí ìpín afẹ́fẹ́ mẹ́rin àti pé, kò sí orílẹ̀-èdè tí ilẹ̀ àjèjì Elamu kò ní lọ.
37 J’Abattrai les Elamites devant leurs ennemis, devant ceux qui en veulent à leur existence; je ferai fondre sur eux le malheur, le feu de ma colère, dit le Seigneur, et je lâcherai le glaive contre eux, de façon à les anéantir.
Èmi yóò kẹ́gàn Elamu níwájú àwọn ọ̀tá wọn, àti níwájú àwọn tí wọ́n ń wá ẹ̀mí wọn, Èmi yóò mú ibi wá sí orí wọn, àní, ìbínú gbígbóná mi,” bẹ́ẹ̀ ni Olúwa wí. “Èmi yóò lé wọn pẹ̀lú idà, di ìgbà tí èmi yóò rẹ́yìn wọn.
38 Puis j’établirai mon trône à Elam, et j’en extirperai rois et princes, dit le Seigneur.
Èmi yóò sì gbé ìtẹ́ mi kalẹ̀ ní Elamu, èmí yóò sì pa ọba wọn àti ìjòyè wọn run,” báyìí ni Olúwa wí.
39 Mais il arrivera que dans la suite des temps je ramènerai les captifs d’Elam." dit le Seigneur.
“Síbẹ̀, èmi yóò dá ìkólọ Elamu padà láìpẹ́ ọjọ́,” báyìí ni Olúwa wí.