< Jérémie 37 >

1 Sédécias, fils de Josias, exerça la royauté à la place de Coniahou, fils de Joïakim; car Nabuchodonosor, roi de Babylone, l’avait établi roi dans le pays de Juda.
Sedekiah ọmọ Josiah sì jẹ ọba ní ipò Jehoiakini ọmọ Jehoiakimu ẹni tí Nebukadnessari ọba Babeli fi jẹ ọba ní ilẹ̀ Juda.
2 Mais ni lui, ni ses serviteurs, ni le peuple du pays n’écoutèrent les paroles de l’Eternel, énoncées par l’organe du prophète Jérémie.
Ṣùgbọ́n àti òun àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti àwọn ènìyàn ilẹ̀ náà kò fetísí ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ nípa wòlíì Jeremiah.
3 Le roi Sédécias envoya dire au prophète Jérémie par léhoukhal, fils de Chélémia, et par Cefania, fils de Masséya, le prêtre: "De grâce, implore en notre faveur l’Eternel, notre Dieu."
Sedekiah ọba sì rán Jehukali ọmọ Ṣelemiah àti Sefaniah ọmọ Maaseiah sí Jeremiah wòlíì wí pé, “Jọ̀wọ́ gbàdúrà sí Olúwa Ọlọ́run wa fún wa.”
4 Or, Jérémie allait et venait au milieu du peuple, et on ne le tenait pas enfermé dans la prison.
Nígbà yìí Jeremiah sì ń wọlé, ó sì ń jáde láàrín àwọn ènìyàn nítorí wọ́n ti fi sínú túbú.
5 Cependant l’armée de Pharaon étant sortie de l’Egypte, les Chaldéens qui cernaient Jérusalem en furent informés et ils levèrent le siège de Jérusalem.
Àwọn ọmọ-ogun Farao ti jáde kúrò nílẹ̀ Ejibiti àti nígbà tí àwọn ará Babeli tó ń ṣàtìpó ní Jerusalẹmu gbọ́ ìròyìn nípa wọn, wọ́n kúrò ní Jerusalẹmu.
6 C’Est alors que la parole de l’Eternel fut adressée à Jérémie, le prophète, en ces termes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wòlíì Ọlọ́run wá:
7 "Ainsi parle l’Eternel, Dieu d’Israël: Voici ce que vous direz au roi de Juda qui vous envoie à moi pour me solliciter: Cette armée de Pharaon qui s’est mise en marche pour vous secourir, elle rebrousse chemin vers son pays, l’Egypte.
“Èyí ni, ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn Israẹli sọ fún ọba àwọn Juda tó rán ọ láti wádìí nípa mi. ‘Àwọn ọmọ-ogun Farao tó jáde láti kún ọ lọ́wọ́ yóò padà sílẹ̀ wọn sí Ejibiti.
8 Aussi les Chaldéens reviendront-ils pour attaquer cette ville, ils l’emporteront de vive force et la livreront aux flammes."
Nígbà náà ni àwọn ará Babeli yóò padà láti gbógun ti ìlú. Wọn yóò mú wọn nígbèkùn, wọn yóò sì fi iná jó ìlú náà kanlẹ̀.’
9 Ainsi parle l’Eternel: "Ne vous leurrez pas vous-mêmes en disant: Assurément, les Chaldéens partiront de chez nous, car ils ne partiront pas.
“Èyí ni ohun tí Olúwa wí, ẹ má ṣe tan ara yín jẹ ní èrò wí pé, ‘Àwọn ará Babeli yóò fi wá sílẹ̀ pẹ̀lú ìdánilójú.’ Wọn kò ní ṣe bẹ́ẹ̀.
10 Et dussiez-vous même tailler en pièces toute l’armée des Chaldéens qui combat contre vous, de sorte qu’il n’en restât que quelques hommes blessés par la lance, ceux-ci se redresseraient dans leur tente et mettraient le feu à cette ville!"
Kódà tó bá ṣe pé wọn yóò ṣẹ́gun àwọn ọmọ-ogun Babeli tí ń gbóguntì yín àti àwọn tí ìjàǹbá ṣe, tí wọ́n ti fi sílẹ̀ ní ibùdó wọn; wọn yóò jáde láti jó ìlú náà kanlẹ̀.”
11 Alors que l’armée des Chaldéens s’éloignait de Jérusalem à cause de l’armée de Pharaon,
Lẹ́yìn tí àwọn ọmọ-ogun Babeli ti kúrò ní Jerusalẹmu nítorí àwọn ọmọ-ogun Farao.
12 Jérémie se disposa à sortir de Jérusalem pour se rendre sur le territoire de Benjamin, et de là se glisser dans la foule.
Jeremiah múra láti fi ìlú náà sílẹ̀, láti lọ sí olú ìlú Benjamini láti gba ẹ̀tọ́ rẹ̀ nínú ohun ìní láàrín àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀.
13 Mais s’étant présenté à la porte de Benjamin, il y rencontra un chef de poste du nom de Yriya, fils de Chélémia, fils de Hanania. Celui-ci arrêta le prophète Jérémie en disant: "Tu veux passer aux Chaldéens!"
Ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n dé ẹnu ibodè Benjamini, olórí àwọn olùṣọ́ tí orúkọ rẹ ń jẹ́ Irijah ọmọ Ṣelemiah ọmọ Hananiah mú un, ó wí pé, “Ìwọ ń fi ara mọ́ àwọn ará Babeli.”
14 Jérémie répliqua: "C’Est faux! je ne passe pas aux Chaldéens!" Mais Yriya ne l’écouta point, il se saisit de Jérémie et l’amena aux officiers.
Jeremiah sọ wí pé, “Èyí kì í ṣe òtítọ́! Èmi kò yapa sí àwọn ará Babeli.” Ṣùgbọ́n Irijah ko gbọ́ tirẹ̀, dípò èyí a mú Jeremiah, ó sì mú un lọ sí ọ̀dọ̀ àwọn ìjòyè.
15 Les officiers s’emportèrent contre Jérémie, le frappèrent et le firent incarcérer dans la maison de Jonathan, le secrétaire, transformée en prison.
Nítorí náà ni àwọn ìjòyè ṣe bínú sí Jeremiah, wọ́n jẹ ẹ́ ní yà, wọ́n tún fi sí túbú nílé Jonatani akọ̀wé nítorí wọ́n ti fi èyí ṣe ilé túbú.
16 C’Est ainsi que Jérémie fut confiné dans la chambre souterraine, qui servait de dépôt, et il y demeura de longs jours.
Wọ́n fi Jeremiah sínú túbú tí ó ṣókùnkùn biribiri; níbi tí ó wà fún ìgbà pípẹ́.
17 Or, le roi Sédécias l’envoya chercher et l’interrogea secrètement en son palais en lui disant: "Y a-t-il une communication de la part de l’Eternel?" Jérémie répondit: "Il y en a;" il ajouta: "Tu seras livré aux mains du roi de Babylone."
Nígbà náà ni ọba Sedekiah ránṣẹ́ sí i, tí ó sì pàṣẹ pé kí wọ́n mú wá sí ààfin níbi tí ó ti bi í ní ìkọ̀kọ̀ pé, “Ǹjẹ́ ọ̀rọ̀ kan wà láti ọ̀dọ̀ Olúwa?” Jeremiah fèsì pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, wọn ó fi ọ́ lé ọwọ́ ọba Babeli.”
18 Jérémie dit encore au roi Sédécias: "Quel crime ai-je commis contre toi, tes serviteurs et ce peuple, que vous m’ayez enfermé dans la maison de détention?
Nígbà náà, Jeremiah sọ fún ọba Sedekiah pé, “Irú ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ yín, àwọn ìjòyè yín pẹ̀lú àwọn ènìyàn tí ẹ fi sọ mí sínú túbú?
19 Où sont donc vos prophètes qui vous ont fait cette prédiction: Jamais le roi de Babylone ne marchera contre vous et contre ce pays?
Níbo ni àwọn wòlíì yín tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín wí pé ọba Babeli kò ní gbóguntì yín wá?
20 Et maintenant écoute, de grâce, ô Seigneur roi, et laisse ma supplication arriver jusqu’à toi: Ne me fais pas rentrer dans la maison de Jonathan, le secrétaire, sans cela, ma mort est certaine."
Ṣùgbọ́n ní báyìí, olúwa mi ọba, èmí bẹ̀ ọ. Jẹ́ kí n mú ẹ̀dùn ọkàn mi tọ̀ ọ́ wá; má ṣe rán mi padà sí ilé Jonatani akọ̀wé, àfi kí n kú síbẹ̀.”
21 Le roi Sédécias donna des ordres, à la suite desquels on mit Jérémie sous garde dans la cour de la geôle; et chaque jour on lui fournissait une miche de pain de la rue des boulangers, jusqu’au moment où le pain vint à manquer tout à fait dans la ville. Jérémie demeura donc dans la cour de la geôle.
Ọba Sedekiah wá pàṣẹ pé kí wọ́n fi Jeremiah sínú àgbàlá àwọn ẹ̀ṣọ́, àti kí wọn sì fún ní àkàrà ní ọjọ́ kọ̀ọ̀kan títí tí àkàrà tó wà ní ìlú yóò fi tán; bẹ́ẹ̀ ni Jeremiah wà nínú àgbàlá náà.

< Jérémie 37 >