< Jérémie 29 >

1 Voici les termes de la lettre que le prophète Jérémie adressa de Jérusalem aux survivants parmi les Anciens de la captivité, aux prêtres, aux prophètes et à toute la population que Nabuchodonosor avait déportés de Jérusalem à Babylone,
Èyí ni ọ̀rọ̀ inú lẹ́tà tí wòlíì Jeremiah rán láti Jerusalẹmu sí ìyókù nínú àwọn àgbàgbà tí ó wà ní ìgbèkùn àti sí àwọn àlùfáà, àwọn wòlíì àti gbogbo àwọn ènìyàn tí Nebukadnessari tí kó ní ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
2 après que le roi leconia, avec la reine-mère et les chambellans, les princes de Juda et de Jérusalem ainsi que les forgerons et serruriers étaient sortis de Jérusalem.
Lẹ́yìn ìgbà tí Jekoniah, ọba, àti ayaba, àti àwọn ìwẹ̀fà, àti àwọn ìjòyè Juda àti Jerusalẹmu, àwọn gbẹ́nàgbẹ́nà àti àwọn olùyàwòrán tí wọ́n lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu.
3 Par l’intermédiaire d’Elassa, fils de Chafan, et de Ghemaria, fils de Hilkia, que Sédécias, roi de Juda, avait envoyés à Babylone, auprès de Nabuchodonosor, roi de Babylone, il leur mandait:
Ó fi lẹ́tà náà rán Eleasa ọmọ Ṣafani àti Gemariah ọmọ Hilkiah, ẹni tí Sedekiah ọba Juda rán sí Nebukadnessari ọba Babeli. Wí pé.
4 "Ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël, à tous les exilés que j’ai déportés de Jérusalem à Babylone:
Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli sọ fún gbogbo àwọn ènìyàn tí mo kó lọ ṣe àtìpó láti Jerusalẹmu ní Babeli:
5 Bâtissez des maisons et habitez-les, plantez des jardins et mangez-en les fruits.
“Ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.
6 Epousez des femmes et mettez au monde fils et filles; donnez des femmes à vos fils, des maris à vos filles, afin qu’elles aient des enfants. Multipliez-vous là-bas et ne diminuez pas en nombre.
Ẹ ṣe ìgbéyàwó, kí ẹ sì bí ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin, ẹ gbé ìyàwó fún àwọn ọmọkùnrin yín, kí ẹ sì fi àwọn ọmọbìnrin yín fún ọkọ. Kí àwọn náà lè ní ọmọkùnrin àti ọmọbìnrin. Ẹ máa pọ̀ sí i ní iye, ẹ kò gbọdọ̀ dínkù ní iye níbẹ̀ rárá.
7 Travaillez enfin à la prospérité de la ville où je vous ai relégués et implorez Dieu en sa faveur; car sa prospérité est le gage de votre prospérité.
Bákan náà, ẹ máa wá àlàáfíà àti ìre ìlú, èyí tí mo kó yín lọ láti ṣe àtìpó. Ẹ gbàdúrà sí Olúwa fún ìre ilẹ̀ náà; nítorí pé bí ó bá dára fún ilẹ̀ náà, yóò dára fún ẹ̀yin pẹ̀lú.”
8 Oui, ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël: Ne vous laissez pas induire en erreur par vos prophètes que vous comptez dans votre sein, n’ayez nul égard à vos songes que vous provoquez;
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí: “Ẹ má ṣe gbà kí àwọn wòlíì èké àti àwọn aláfọ̀ṣẹ àárín yín tàn yín jẹ. Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí àlá, èyí tí ẹ gbà wọ́n níyànjú láti lá.
9 car c’est mensongèrement qu’ils vous débitent des prophéties en mon nom: je ne les ai chargés d’aucune mission, dit l’Eternel.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún yín lórúkọ mi, Èmi kò rán wọn níṣẹ́,” ni Olúwa wí.
10 Voici, en vérité, ce que dit l’Eternel: Quand Babylone sera au terme de soixante-dix ans pleinement révolus, je prendrai soin de vous et j’accomplirai en votre faveur ma bienveillante promesse de vous ramener en ces lieux;
Báyìí ni Olúwa wí: “Nígbà tí ẹ bá lo àádọ́rin ọdún pé ní Babeli, èmi yóò tọ̀ yín wá láti ṣe àmúṣẹ ìlérí ńlá mi fún un yín, àní láti kó o yín padà sí Jerusalẹmu.
11 car je connais bien, moi, les desseins que j’ai conçus à votre égard, dit l’Eternel, desseins qui visent votre bonheur et non votre malheur et vous assurent un avenir plein d’espérances.
Nítorí mo mọ èrò tí mo rò sí yín,” ni Olúwa wí, “àní èrò àlàáfíà, kì í sì ṣe fún ibi, èrò láti fún un yín ní ìgbà ìkẹyìn àti ìrètí ọjọ́ iwájú.
12 Alors vous m’invoquerez et vous pourrez vous mettre en route, vous m’adresserez des prières et je vous exaucerai.
Nígbà náà ni ẹ̀yin yóò ké pè mí, tí ẹ̀yin yóò sì gbàdúrà sí mi, tí èmi yóò sì gbọ́ àdúrà yín.
13 Vous vous mettrez en quête de moi et vous me trouverez, oui, si vous me recherchez de tout votre coeur.
Ẹ̀yin yóò wá mi, bí ẹ̀yin bá sì fi gbogbo ọkàn yín wá mi: ẹ̀yin yóò rí mi ni Olúwa Ọlọ́run wí.
14 Je vous deviendrai accessible, dit l’Eternel, je ramènerai vos exilés, je vous rassemblerai du milieu de toutes les nations et de toutes les localités où je vous ai relégués, dit l’Eternel, et je vous ferai réintégrer les lieux d’où je vous ai bannis.
Èmi yóò di rí rí fún yín ni Olúwa wí, Èmi yóò sì mú yín padà kúrò ní ìgbèkùn. Èmi yóò ṣà yín jọ láti gbogbo orílẹ̀-èdè àti ibi gbogbo tí Èmi ti lé yín jáde, ni Olúwa wí. Èmi yóò sì kó yín padà sí ibi tí mo ti mú kí a kó yín ní ìgbèkùn lọ.”
15 Que si vous dites: l’Eternel nous a suscité des prophètes à Babylone.
Ẹ̀yin lè wí pé, “Olúwa ti gbé àwọn wòlíì dìde fún wa ní Babeli.”
16 Eh bien! Voici comment l’Eternel s’exprime au sujet du roi assis sur le trône de David, au sujet de tout le peuple qui réside en cette ville, de vos frères qui ne sont pas partis en exil avec vous;
Ṣùgbọ́n èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa ní ti ọba tí ó jókòó lórí ìtẹ́ Dafidi àti ní ti gbogbo ènìyàn tó ṣẹ́kù ní ìlú yìí; àní ní ti àwọn ènìyàn yín tí kò bá yín lọ sí ìgbèkùn,
17 voici ce que déclare l’Eternel-Cebaot: Je vais déchaîner contre eux le glaive, la famine et la peste, et les rendre semblables à des figues exécrables qu’on ne peut manger tant elles sont mauvaises.
bẹ́ẹ̀ ni, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí pé, “Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí àárín wọn; Èmi yóò ṣe wọ́n bí èso ọ̀pọ̀tọ́ búburú tí kò ṣe é jẹ.
18 Je m’attacherai à leur poursuite avec le glaive, la famine et la peste; je ferai d’eux une épouvante pour tous les royaumes de la terre, un objet d’imprécation, de stupeur, de dérision et d’opprobre parmi tous les peuples où je les aurai relégués;
Èmi yóò fi idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn lépa wọn, Èmi yóò sì sọ wọ́n di ìríra lójú gbogbo ìjọba ayé, fún ègún, àti ìyanu, àti ẹ̀sín, àti ẹ̀gàn láàrín gbogbo orílẹ̀-èdè ayé, ní ibi tí Èmi yóò lé wọn sí.
19 et cela, parce qu’ils n’ont pas prêté attention à mes discours, déclare l’Eternel, lorsque, sans cesse et dès la première heure, j’envoyais auprès d’eux mes serviteurs les prophètes; mais vous n’avez point écouté, dit l’Eternel.
Nítorí wọ́n kọ̀ láti gbọ́ ọ̀rọ̀ mi,” ni Olúwa Ọlọ́run wí. Ọ̀rọ̀ tí mo tún ti ẹnu àwọn ìránṣẹ́ mi wòlíì sọ ní ẹ̀yin tí ń ṣe àtìpó kò gbọ́ ni Olúwa Ọlọ́run wí.
20 Or, vous donc, écoutez la parole de l’Eternel, vous tous, exilés, que j’ai envoyés de Jérusalem à Babylone!
Nítorí náà, gbogbo ẹ̀yin ìgbèkùn, ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin tí mo rán lọ kúrò ní Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
21 Voici ce que. dit l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël, touchant Achab, fils de Kolaya, et Sédécias, fils de Masseya, qui vous adressent des prophéties mensongères en mon nom: "Je vais les livrer au pouvoir de Nabuchodonosor, roi de Babylone, qui les fera périr sous vos yeux."
Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli sọ nípa Ahabu ọmọ Kolaiah àti nípa Sedekiah ọmọ Maaseiah tí wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké fún un yín lórúkọ mi: “Èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́. Òun yóò sì gba ẹ̀mí wọn ní ìṣẹ́jú yìí gan an.
22 Et on leur empruntera une formule de malédiction à l’usage de tous les exilés de Juda, qui se trouvent à Babylone, on dira: "Que l’Eternel te rende semblable à Sédécias et à Achab, que le roi de Babylone a fait consumer par les flammes!"
Nítorí tiwọn, ègún yìí yóò ran gbogbo àwọn àtìpó tó wà ní ilẹ̀ Babeli láti Juda: ‘Olúwa yóò ṣe yín bí i Sedekiah àti Ahabu tí ọba Babeli dáná sun.’
23 C’Est qu’ils ont commis des infamies en Israël, en déshonorant les femmes de leurs amis, en prononçant en mon nom des discours mensongers que je ne leur ai point dictés; je le sais, moi, et je puis l’attester, dit l’Eternel.
Nítorí wọ́n ti ṣe ibi ní ilé Israẹli, wọ́n ti ṣe àgbèrè pẹ̀lú àwọn ìyàwó aládùúgbò wọn, àti ní orúkọ mi ni wọ́n ti ṣe èké, èyí tí Èmi kò rán wọn láti ṣe. Ṣùgbọ́n, Èmi mọ àwọn nǹkan wọ̀nyí, mo sì jẹ́ ẹlẹ́rìí sí i,” ni Olúwa wí.
24 Et à Chemaya, le Néhélamite, tu diras ce qui suit:
Wí fún Ṣemaiah tí í ṣe Nehalami pé,
25 Ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël: Puisque tu t’es permis d’adresser, en ton nom, à tout le peuple de Jérusalem, à Cefania, fils de Masseya, le prêtre, et à tous les prêtres, des lettres conçues en ces termes:
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára Israẹli wí: Ìwọ fi lẹ́tà ránṣẹ́ sí gbogbo àwọn ènìyàn ní Jerusalẹmu sí Sefaniah ọmọ Maaseiah tí í ṣe àlùfáà ní orúkọ mi; ó sì sọ fún Sefaniah wí pé,
26 L’Eternel t’a établi pontife à la place de Joïada le prêtre pour exercer, dans la maison de Dieu, une surveillance étroite sur tous les gens exaltés et vaticinant, pour les jeter en prison et mettre aux fers;
‘Olúwa ti yàn ọ́ gẹ́gẹ́ bí àlùfáà rọ́pò Jehoiada láti máa jẹ́ alákòóso ilé Olúwa, kí o máa fi èyíkéyìí nínú àwọn aṣiwèrè tó bá ṣe bí i wòlíì si inú àgò irin.
27 et pourquoi donc n’as-tu pas admonesté Jérémie d’Anatot qui fait le prophète parmi vous?
Nítorí náà, èéṣe tí o kò fi bá Jeremiah ará Anatoti wí. Ẹni tí ó ń dúró bí i wòlíì láàrín yín?
28 C’Est à ce titre qu’il nous a envoyé ce message à Babylone: Elle sera longue la captivité, bâtissez des maisons et habitez-les, plantez des jardins et mangez-en les fruits."
Ó ti rán iṣẹ́ yìí sí wa ni Babeli wí pé, àtìpó náà yóò pẹ́ kí ó tó parí, nítorí náà, ẹ kọ́ ilé kí ẹ sì máa gbé ibẹ̀, ẹ dá oko, kí ẹ sì máa jẹ èso ohun ọ̀gbìn oko yín.’”
29 Or, le prêtre Cefania avait donné lecture de cette lettre au prophète Jérémie.
Sefaniah àlùfáà ka lẹ́tà náà sí etí ìgbọ́ Jeremiah tí í ṣe wòlíì.
30 La parole de l’Eternel fut adressée à Jérémie en ces termes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé,
31 "Mande à tous les exilés les paroles suivantes Voici ce que décrète l’Eternel au sujet de Chemaya, le Néhélamite: Puisque Chemaya vous a adressé des prophéties, sans que je lui en aie donné mission, puisqu’il vous a leurrés par de fausses assurances,
“Rán iṣẹ́ yìí sí gbogbo àwọn ìgbèkùn wí pé: ‘Èyí ni ohun tí Olúwa wí ní ti Ṣemaiah, ará Nehalami: Nítorí pé Ṣemaiah ti sọtẹ́lẹ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n èmi kò ran an, tí òun sì ń mú u yín gbẹ́kẹ̀lé èké.
32 eh bien! voici ce que dit l’Eternel Je vais sévir contre Chemaya, le Néhélamite, et contre sa race Il n’y aura plus aucun des siens établi parmi ce peuple, il ne sera pas témoin du bien que je ferai à mon peuple, dit l’Eternel; car il a prêché la révolte contre l’Eternel."
Nítorí náà báyìí ni Olúwa wí: Wò ó, èmi yóò bẹ Ṣemaiah, ará Nehalami wò, àti irú-ọmọ rẹ̀; òun kì yóò ní ọkùnrin kan láti máa gbé àárín ènìyàn yìí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò rí rere náà tí èmi yóò ṣe fún àwọn ènìyàn mi ni Olúwa wí, nítorí ó ti ti kéde ìṣọ̀tẹ̀ sí mi.’”

< Jérémie 29 >