< Jérémie 27 >

1 Au début du règne de Joïakim, fils de Josias, roi de Juda, la révélation suivante fut adressée à Jérémie de la part de l’Eternel.
Ní ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀ ìṣèjọba Sedekiah ọmọ Josiah ọba Juda, ọ̀rọ̀ yìí tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa wí pé.
2 Voici ce que me dit l’Eternel: "Fais-toi des liens et des jougs, pose-les sur ton cou;
Èyí ni ohun tí Olúwa wí, “Ṣe àjàgà àti ọ̀pá irin fún ara rẹ, kí o sì fiwé ọrùn rẹ.
3 puis, tu les enverras au roi d’Edom, au roi de Moab, au roi des Ammonites, au roi de Tyr et au roi de Sidon par l’entremise des ambassadeurs qui sont venus à Jérusalem auprès de Sédécias, roi de Juda.
Kí o rán ọ̀rọ̀ sí ọba ti Edomu, Moabu, Ammoni, Tire àti Sidoni láti ọwọ́ àwọn ikọ̀ tí ó wá sí Jerusalẹmu sọ́dọ̀ Sedekiah ọba Juda.
4 Tu leur recommanderas de dire à leurs maîtres: Ainsi parle l’Eternel-Cébaoth, Dieu d’Israël: Vous direz ceci à vos maîtres:
Kí o sì pàṣẹ fún wọn láti wí fún àwọn olúwa wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: “Sọ èyí fún àwọn olúwa rẹ.
5 C’Est moi qui, par ma grande puissance et mon bras étendu, ai créé la terre, les hommes et les animaux qui couvrent la terre, et je l’ai donnée à qui il me plaisait.
Pẹ̀lú agbára ńlá mi àti ọwọ́ nínà mi ni Èmi dá ayé, ènìyàn àti ẹranko tí ó wà lórí ilẹ̀ ayé, mo sì fún ẹni tí ó wu ọkàn mi.
6 Or, maintenant je livre tous ces pays au pouvoir de Nabuchodonosor, roi de Babylone, mon serviteur; même les animaux des champs, je les lui livre pour qu’ils le servent.
Nísinsin yìí, Èmi yóò fa gbogbo orílẹ̀-èdè rẹ fún Nebukadnessari ọba Babeli ìránṣẹ́ mi; Èmi yóò sì mú àwọn ẹranko búburú wọ̀n-ọn-nì jẹ́ tirẹ̀.
7 Tous les peuples le serviront, lui, son fils et son petit-fils, jusqu’à ce que pour son pays aussi arrive le jour où des peuples puissants et de grands rois le réduiront en servitude.
Gbogbo orílẹ̀-èdè ni yóò máa sìn ín àti àwọn ọmọdọ́mọ rẹ̀ títí ilẹ̀ rẹ yóò fi dé; ọ̀pọ̀lọpọ̀ orílẹ̀-èdè àti àwọn ọba ńlá ni yóò tẹríba fún.
8 S’Il est un peuple, un royaume qui refuse de se soumettre à lui, Nabuchodonosor, roi de Babylone, et d’engager son cou dans le joug du roi de Babylone, ce peuple, je le châtierai par le glaive, la famine et la peste, dit l’Eternel, jusqu’à ce que je l’aie anéanti par sa main.
“‘“Ṣùgbọ́n tí orílẹ̀-èdè tàbí ìjọba kan kò bá ní sin Nebukadnessari ọba Babeli, tàbí kí ó tẹ orí rẹ̀ ba ní abẹ́ àjàgà rẹ̀, Èmi yóò fi ìyà jẹ orílẹ̀-èdè náà nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, ni Olúwa wí títí Èmi yóò fi run wọ́n nípa ọwọ́ rẹ̀.
9 Vous donc, n’écoutez ni vos prophètes, ni vos devins, ni vos songes, ni vos augures, ni vos magiciens qui, eux, vous disent: Vous ne serez point asservis au roi de Babylone!
Nítorí náà, ẹ má ṣe tẹ́tí sílẹ̀ sí àwọn wòlíì yín, àwọn aláfọ̀ṣẹ yín, àwọn tí ń rọ́ àlá fún un yín, àwọn oṣó yín, tàbí àwọn àjẹ́ yín tí wọ́n ń sọ fún un yín pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli.’
10 Car c’est des mensonges qu’ils vous prophétisent, qui auront pour conséquence que vous serez éloignés de votre pays, que je vous bannirai et consommerai votre ruine.
Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ irọ́ fún un yín èyí tí yóò mú u yín jìnnà réré kúrò ní ilẹ̀ yín; kí Èmi kí ó lè lé yín jáde, kí ẹ̀yin ó sì ṣègbé.
11 Tandis que le peuple qui engagera son cou dans le joug du roi de Babylone et qui se soumettra à lui, je le maintiendrai, dit l’Eternel, dans son pays, qu’il pourra cultiver et habiter.
Ṣùgbọ́n bí orílẹ̀-èdè kankan bá tẹ orí rẹ̀ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, tí ó sì sìn ín, Èmi yóò jẹ́ kí orílẹ̀-èdè náà wà lórí ilẹ̀ rẹ̀ láti máa ro ó, àti láti máa gbé ibẹ̀ ni Olúwa wí.”’”
12 A Sédécias aussi, roi de Juda, j’ai adressé des discours exactement pareils, disant: Engagez votre cou dans le joug du roi de Babylone, soumettez-vous à lui et à son peuple, et vous vivrez.
Èmi sì sọ ọ̀rọ̀ náà fún Sedekiah ọba Juda wí pé: “Tẹ orí rẹ ba lábẹ́ àjàgà ọba Babeli, sìn ín ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ, ìwọ yóò sì yè.
13 Pourquoi voudriez-vous périr, toi et ton peuple, par le glaive, la famine et la peste, comme Dieu l’a prédit au peuple qui refuserait soumission au roi de Babylone?
Kí ló dé tí ìwọ àti àwọn ènìyàn rẹ yóò ṣe kú nípa idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn, èyí tí Olúwa fi ń halẹ̀ mọ́ àwọn orílẹ̀-èdè tí kò bá sin ọba Babeli?
14 N’Écoutez donc pas les paroles des prophètes vous disant: Ne vous soumettez point au roi de Babylone! car c’est des mensonges qu’ils vous prophétisent.
Ẹ má ṣe fetísílẹ̀ sí ọ̀rọ̀ àwọn wòlíì tí ó ń sọ wí pé, ‘Ẹ̀yin kò ní sin ọba Babeli,’ nítorí pé àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ fún un yín.
15 Car je ne les ai chargés d’aucune mission, dit l’Eternel; mais eux prophétisent en mon nom mensongèrement, de façon à ce que je vous bannisse et que vous périssiez, vous et les prophètes qui vous adressent ces prophéties.
‘Èmi kò rán wọn ni Olúwa wí. Wọ́n ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké ní orúkọ mi. Nítorí náà, Èmi yóò lé wọn, wọn yóò sì ṣègbé, ẹ̀yin pẹ̀lú àwọn wòlíì tí ó ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ fún un yín.’”
16 Aux prêtres aussi et à tout ce peuple j’ai parlé en ces termes: Voici ce que dit l’Eternel: N’Écoutez point les discours de vos prophètes qui vous annoncent ceci: Bientôt maintenant les vases du Temple de l’Eternel seront rapportés de Babylone; car c’est des mensonges qu’ils vous débitent.
Nígbà náà ni mo sọ fún àwọn àlùfáà àti gbogbo àwọn ènìyàn náà wí pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa sọ, ẹ má ṣe fetí sí nǹkan tí àwọn wòlíì ń sọ pé, ‘Láìpẹ́ ohun èlò ilé Olúwa ni a ó kó padà láti Babeli,’ àsọtẹ́lẹ̀ èké ni wọ́n ń sọ. Ẹ má tẹ́tí sí wọn.
17 Ne les écoutez point! Servez plutôt le roi de Babylone et vous aurez la vie sauve! Pourquoi cette ville deviendrait-elle une ruine?
Má ṣe tẹ́tí sí wọn, ẹ máa sin ọba Babeli, ẹ̀yin yóò sì yè. Èéṣe tí ìlú yóò fi di ahoro?
18 Si ce sont réellement des prophètes et si la parole de Dieu se communique à eux, eh bien! qu’ils sollicitent donc l’Eternel-Cebaot, afin que les vases qui restent encore dans le Temple de l’Eternel, dans le palais du roi de Juda et à Jérusalem, ne soient pas aussi transportés à Babylone.
Tí wọ́n bá jẹ́ wòlíì, tí wọ́n sì ní ọ̀rọ̀ Olúwa, jẹ́ kí wọ́n bẹ Olúwa àwọn ọmọ-ogun kí a má ṣe kó ohun èlò tí ó kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti Jerusalẹmu lọ sí Babeli.
19 Car voici ce que dit l’Eternel-Cebaot au sujet des colonnes, de la Mer, des supports et des autres vases qui sont restés dans cette ville,
Nítorí pé, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ nípa àwọn opó, omi Òkun ní ti ìpilẹ̀ṣẹ̀ àti ní ti ohun èlò ìyókù tí ó kù ní ìlú náà.
20 que Nabuchodonosor n’a pas enlevés quand il exila leconia, fils de Joïakim, roi de Juda, de Jérusalem à Babylone, avec tous les grands de Juda et de Jérusalem;
Èyí tí Nebukadnessari ọba Babeli kò kó lọ nígbà tí ó mú Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí Babeli, pẹ̀lú àwọn ọlọ́lá Juda àti Jerusalẹmu.
21 oui, voici ce que dit l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël, au sujet des vases qui sont restés dans la maison de l’Eternel, dans le palais du roi de Juda et à Jérusalem:
Lóòótọ́, èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí nípa àwọn ohun ìṣúra tí ó ṣẹ́kù ní ilé Olúwa àti ní ààfin ọba Juda àti ní Jerusalẹmu:
22 Ils seront transportés à Babylone et y resteront jusqu’au jour où je me souviendrai d’eux, dit l’Eternel, pour les faire rapporter et réintégrer en ces lieux.
‘A ó mú wọn lọ sí ilẹ̀ Babeli, ní ibẹ̀ ni wọn ó sì wà títí di ìgbà tí mo bá padà,’ èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa. ‘Lẹ́yìn èyí, Èmi yóò mú wọn padà, Èmi yóò sì ṣe wọ́n lọ́jọ̀ ní ibí yìí.’”

< Jérémie 27 >