< Jérémie 24 >

1 L’Eternel m’invita à regarder, et voici, deux corbeilles de figues étaient placées devant le sanctuaire de l’Eternel. (C’Était après que Nabuchodonosor, roi de Babylone, eut exilé de Jérusalem et emmené à Babylone leconia, fils de Joaïkim, roi de Juda, les princes judéens ainsi que les forgerons et les serruriers.)
Lẹ́yìn tí Nebukadnessari ọba Babeli ti kó Jekoniah ọmọ Jehoiakimu ọba Juda àti àwọn ìjòyè wọn, àwọn oníṣọ̀nà àti oníṣẹ́ ọwọ́ ti Juda lọ sí ìgbèkùn láti Jerusalẹmu lọ sí ilẹ̀ àjèjì Babeli tán. Olúwa fi agbọ̀n èso ọ̀pọ̀tọ́ méjì hàn mí tí a gbé sí iwájú pẹpẹ Olúwa.
2 L’Une des corbeilles contenait des figues de tout point excellentes, telles que des primeurs d’entre les figues; l’autre des figues tout à fait mauvaises, si mauvaises qu’elles n’étaient pas mangeables.
Agbọ̀n kan ni èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó dára bí èyí tí ó tètè pọ́n; èkejì sì ní èso ọ̀pọ̀tọ́ tí ó burú rékọjá tí kò sì le è ṣe é jẹ.
3 Et l’Eternel me dit: "Que vois-tu, Jérémie?" Je répondis: "Des figues; les bonnes sont extrêmement bonnes et les mauvaises extrêmement mauvaises, si mauvaises qu’elles ne sont pas mangeables."
Nígbà náà ni Olúwa bi mí pé, “Kí ni ìwọ rí Jeremiah?” Mo dáhùn pe, “Èso ọ̀pọ̀tọ́.” Mo dáhùn. “Èyí tí ó dáradára púpọ̀, ṣùgbọ́n èyí tí ó burú burú rékọjá tí kò sì ṣe é jẹ.”
4 La parole de Dieu me fut adressée en ces termes:
Nígbà náà ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ̀ mí wá:
5 "Ainsi parle l’Eternel: Comme on fait des figues d’excellente qualité, ainsi je distinguerai avec complaisance les exilés de Juda que j’ai relégués de ce lieu-ci au pays des Chaldéens.
“Èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Gẹ́gẹ́ bí àwọn èso ọ̀pọ̀tọ́ dáradára yìí ni Èmi yóò ka àwọn tí wọ́n lọ sí ilẹ̀ àjèjì láti Juda sí tí èmi rán jáde kúrò ní ibí yìí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Kaldea.
6 Je les regarderai d’un oeil favorable et les ramènerai sur cette terre-ci, je les édifierai et ne les détruirai pas, je les planterai et ne les déracinerai pas,
Ojú mi yóò máa ṣọ́ wọn lọ fún rere, Èmi yóò gbé wọn ró, n kò ní já wọn lulẹ̀. Èmi yóò gbìn wọ́n, n kò sì ní fà wọ́n tu.
7 et je leur donnerai un coeur pour me connaître, pour savoir que je suis l’Eternel; ils seront mon peuple, je serai, moi, leur Dieu, pourvu qu’ils reviennent à moi de tout leur coeur.
Èmi yóò fún wọn ní ọkàn láti mọ̀ mí pé, “Èmi ni Olúwa.” Wọn yóò jẹ́ ènìyàn mi; Èmi ni yóò sì jẹ́ Ọlọ́run wọn; nítorí pé wọn yóò padà sọ́dọ̀ mi pẹ̀lú gbogbo ọkàn wọn.
8 Mais pareillement aux figues mauvaises, que leur mauvaise qualité rend immangeablestelle est la parole de l’Eternelje traiterai Sédécias, roi de Juda, avec ses grands et les survivants de Jérusalem qui seront restés dans ce pays ou qui se seront établis en Egypte.
“‘Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí èso ọ̀pọ̀tọ́ tí kò dára, tí ó burú tí kò ṣe é jẹ,’ ni Olúwa wí, ‘bẹ́ẹ̀ ni Èmi yóò ṣe pẹ̀lú Sedekiah ọba Juda, àwọn ìjòyè rẹ̀ àti àwọn tí ó yẹ ní Jerusalẹmu, yálà wọ́n wà lórí ilẹ̀ yìí tàbí wọ́n ń gbé Ejibiti.
9 Je ferai d’eux un exemple de terreur et de ruine pour tous les royaumes de la terre, un opprobre, une fable, un objet de dérision et d’exécration dans toutes! es localités où je les aurai rejetés.
Èmi yóò sọ wọ́n di ìwọ̀sí àti ẹni ibi nínú gbogbo ìjọba ayé, láti di ẹni ìfibú àti ẹni òwe, ẹni ẹ̀sín, àti ẹni ẹ̀gàn ní ibi gbogbo tí Èmi ó lé wọn sí.
10 Je déchaînerai contre eux le glaive, la famine et la peste, jusqu’à leur complète disparition de la terre que je leur avais donnée à eux et à leurs ancêtres."
Èmi yóò rán idà, ìyàn àti àjàkálẹ̀-ààrùn sí wọn, títí tí gbogbo wọn yóò parun lórí ilẹ̀ tí a fún wọn àti fún àwọn baba wọn.’”

< Jérémie 24 >