< Jérémie 21 >

1 Révélation que reçut Jérémie de la part de l’Eternel, au moment où le roi Sédécias lui envoya Pachhour, fils de Malkia, et le prêtre Cephania, fils de Masséya, pour lui dire:
Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
2 "Veuille donc solliciter l’Eternel en notre faveur, puisque Nabuchodonosor, roi de Babylone, nous fait la guerre; peut-être l’Eternel agira-t-il à notre égard selon les merveilles qu’il accomplit, et le fera-t-il s’éloigner de nous."
“Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
3 Jérémie leur répondit: "Voici ce que vous direz à Sédécias:
Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
4 Telle est la parole de l’Eternel, Dieu d’Israël: Voici, tous les engins de guerre qui sont en vos mains, qui vous servent à combattre le roi de Babylone et les Chaldéens qui vous assiègent, je vais changer leur direction qui est vers l’extérieur de l’enceinte et les faire converger vers le centre de la ville.
‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
5 Et moi-même j’engagerai la lutte avec vous d’une main tendue et d’un bras puissant, avec colère, emportement et violente fureur.
Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
6 Je frapperai les habitants de cette ville, hommes et bêtes: ils périront par une peste violente.
Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
7 Et après cela, dit l’Eternel, je livrerai Sédécias, roi de Juda, ses serviteurs, le peuple, tout ce qui, dans cette ville, aura échappé à la peste, au glaive et à la famine, je les livrerai au pouvoir de Nabuchodonosor, roi de Babylone, au pouvoir de leurs ennemis, au pouvoir de ceux qui en veulent à leur vie, on les fera passer au fil de l’épée, sans ménagement, ni pitié ni merci.
Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
8 Quant à ce peuple, tu lui diras: Voici ce que déclare l’Eternel: je mets devant vous le chemin de la vie et le chemin de la mort.
“Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
9 Celui qui restera dans cette ville périra par le glaive, la famine et la peste; mais celui qui en sortira et se rendra aux Chaldéens qui vous assiègent, aura la vie sauve, et son existence sera sa part de butin.
Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
10 Car j’ai dirigé ma face vers cette ville pour sa perte et non pour son salut, dit l’Eternel elle sera livrée à la merci du roi de Babylone, pour qu’il la réduise en cendres.
Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
11 Quant à la maison du roi de Juda tu lui diras: Ecoutez la parole de l’Eternel:
“Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
12 Maison de David, ainsi parle l’Eternel: "Rendez bonne justice dès la première heure, sauvez celui qui a été spolié de la main de l’oppresseur: sans cela, ma colère éclatera comme un incendie et brûlera inextinguible, à cause de la perversité de vos oeuvres."
Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
13 Voici, j’en veux à toi, habitante de la vallée, rocher qui te dresses dans la plaine, dit l’Eternel, à vous qui dites: Qui descendra contre nous? Qui pénétrera dans nos demeures?
Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
14 Je vous châtierai selon le fruit de vos oeuvres, dit l’Eternel; dans sa forêt, j’allumerai un feu qui consumera tous ses alentours.
Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”

< Jérémie 21 >