< Jérémie 19 >

1 Ainsi parla l’Eternel: "Va, achète une cruche au potier qui travaille l’argile, emmène quelques-uns des anciens parmi le peuple et des anciens parmi les prêtres,
Èyí ní ohun tí Olúwa wí: “Lọ ra ìkòkò lọ́dọ̀ alámọ̀, mú dání lára àwọn àgbàgbà ọkùnrin àti wòlíì.
2 et sors dans la vallée de Ben-Hinnom, située à l’entrée de la porte de Harsit; là tu publieras les paroles que je te dicterai.
Kí o sì lọ sí àfonífojì ọmọ Beni-Hinnomu, níwájú ẹnu ibodè Harsiti, níbẹ̀ ni kí o sì kéde gbogbo ọ̀rọ̀ tí èmi yóò sọ fún ọ.
3 Tu diras: Ecoute la parole de l’Eternel, rois de Juda et habitants de Jérusalem! Ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël: Voici, je fais fondre sur cet endroit une calamité telle que les oreilles en tinteront à quiconque en entendra parler.
Kí o sì wí pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin ọba àwọn Juda àti ẹ̀yin ará Jerusalẹmu. Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli sọ. Dẹtí sí mi! Èmi yóò mú ìparun wá síbí, etí gbogbo wọn tó bá gbọ́ ọ yóò hó yaya.
4 Parce qu’ils m’ont abandonné, parce qu’ils ont déshonoré cet endroit en y offrant l’encens à des dieux étrangers, à eux inconnuseux et leurs ancêtres et les rois de Juda, en remplissant cet endroit du sang des innocents,
Nítorí wọ́n ti gbàgbé mi, wọ́n sì ti sọ ibí di ilé fún òrìṣà àjèjì; wọ́n ti sun ẹbọ nínú rẹ̀ fún òrìṣà tí àwọn baba wọn tàbí tí ọba Juda kò mọ̀ rí, wọ́n ti fi ẹ̀jẹ̀ aláìṣẹ̀ kún ilẹ̀ yìí.
5 en bâtissant les hauts-lieux de Baal, pour brûler leurs enfants comme holocaustes à Baal, ce que je n’ai ni prescrit ni recommandé et ce qui ne m’est jamais venu à la pensée.
Wọ́n ti kọ́ ibi gíga fún Baali láti sun ọmọkùnrin wọn gẹ́gẹ́ bí ohun ẹbọ sísun sí Baali—èyí tí èmi kò pàṣẹ láti ṣe, tí èmi kò sì sọ, tàbí tí kò sì ru sókè láti inú ọkàn mi.
6 Aussi des jours vont-ils venir, dit l’Eternel, où l’on n’appellera plus cet endroit Tofèt et Vallée de Ben-Hinnom, mais Vallée du Massacre.
Nítorí náà ṣọ́ra ọjọ́ ń bọ̀ ni Olúwa wí nígbà tí àwọn ènìyàn kì yóò pe ibí ní Tofeti mọ́ tàbí àfonífojì ọmọ Hinnomu, ṣùgbọ́n àfonífojì Ìpakúpa.
7 En ces mêmes lieux, je mettrai à néant les projets de Juda et de Jérusalem, que je ferai succomber sous le glaive de leurs ennemis et par la main de ceux qui en veulent à leur vie, et je livrerai leurs cadavres en pâture aux oiseaux du ciel et aux animaux de la terre.
“‘Ní ibí yìí ni èmi yóò ti pa èrò Juda àti Jerusalẹmu run. Èmí yóò mú wọn ṣubú nípa idà níwájú àwọn ọ̀tá wọn, lọ́wọ́ àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn. Èmi yóò sì fi òkú wọn ṣe oúnjẹ fún àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run àti ẹranko ilẹ̀.
8 Je ferai de cette ville une ruine et un objet de dérision; quiconque passera près d’elle sera stupéfait et se mettra à ricaner à la vue de toutes ses plaies.
Èmi yóò sọ ìlú yìí di ahoro àti ohun ẹ̀gàn, gbogbo àwọn tí ń kọjá yóò bẹ̀rù wọn yóò sì máa fòyà nítorí gbogbo ọgbẹ́ rẹ̀.
9 Et je les réduirai à dévorer la chair de leurs fils et la chair de leurs filles; l’un dévorera la chair de l’autre par suite du siège et de la détresse où les étreindront leurs ennemis et leurs mortels adversaires.
Èmi yóò mú kí wọ́n jẹ ẹran-ara ọmọ wọn ọkùnrin àti ẹran-ara ọmọ wọn obìnrin, ẹnìkínní yóò sì jẹ ẹran-ara ẹnìkejì, nígbà ìdótì àti ìhámọ́ láti ọwọ́ ọ̀tá wọn, àti àwọn tí ó ń wá ẹ̀mí wọn.’
10 Puis tu briseras la cruche sous les yeux des gens qui t’auront accompagné,
“Nígbà náà ni ìwọ yóò fọ́ ìkòkò náà ní ojú àwọn tí ó bá ọ lọ.
11 et leur diras: Ainsi parle l’Eternel-Cebaot: C’Est de la sorte que je briserai ce peuple et cette ville, comme on met en pièces un vase de potier, qui ne peut plus être réparé; c’est au Tofèt qu’on ensevelira, faute d’autre place pour la sépulture.
Kí o sì sọ fún wọn pé, ‘Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí. Èmi a fọ́ orílẹ̀-èdè yìí àti ìlú yìí gẹ́gẹ́ bí ìkòkò amọ̀ yìí ṣe fọ́ tí kò sì ní sí àtúnṣe. Wọn a sì sin àwọn òkú sí Tofeti títí tí kò fi ní sí ààyè mọ́.
12 Voilà comme je traiterai cet endroit, dit l’Eternel, et ses habitants, en rendant cette ville semblable au Tofèt.
Èyí ni ohun tí èmi yóò ṣe sí ibí yìí àti àwọn tí ń gbé ní ibí yìí ni Olúwa wí. Èmi yóò mú ìlú yìí dàbí Tofeti.
13 Les maisons de Jérusalem et les demeures des rois de Juda seront comme les sites impurs du Tofèt, oui, toutes les maisons sur les terrasses desquelles on offrait de l’encens aux milices célestes, où l’on faisait des libations aux dieux étrangers.
Àwọn ilé tí ó wà ní Jerusalẹmu àti ti ọba ìlú Juda ni a ó sọ di àìmọ́ bí Tofeti, gbogbo ilé tí wọ́n ti ń sun tùràrí ni orí òrùlé sí gbogbo ogun ọ̀run, tí a sì ń rú ẹbọ mímu sí ọlọ́run mìíràn.’”
14 Puis, Jérémie revint du Tofèt, où Dieu l’avait envoyé pour prophétiser, il s’arrêta dans la cour de la maison de l’Eternel et dit à tout le peuple:
Jeremiah sì padà láti Tofeti níbi tí Olúwa rán an sí láti sọ àsọtẹ́lẹ̀ ó sì dúró ní gbangba tẹmpili Olúwa, ó sì sọ fún gbogbo ènìyàn pé,
15 "Ainsi parle l’Eternel-Cebaot, Dieu d’Israël: Je vais faire fondre sur cette cité et sur toutes les villes qui en dépendent toute la calamité dont je l’ai menacée, car ils ont raidi leur cou et refusé d’écouter mes paroles."
“Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí: ‘Tẹ́tí sílẹ̀! Èmi yóò mú ìdààmú tí mo ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ bá ìlú yìí àti ìgbèríko tí ó yí i ká, nítorí ọlọ́rùn líle ni wọ́n, wọn kò si ní fẹ́ fetí sí ọ̀rọ̀ mi.’”

< Jérémie 19 >